< 1 Samuel 30 >

1 Ó sì ṣe nígbà ti Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì bọ̀ sí Siklagi ní ọjọ́ kẹta, àwọn ará Amaleki sì ti kọlu ìhà gúúsù, àti Siklagi, wọ́n sì ti kùn ún ní iná.
När David med sina män på tredje dagen kom till Siklag, hade amalekiterna infallit i Sydlandet och i Siklag; och de hade intagit Siklag och bränt upp det i eld.
2 Wọ́n sì kó àwọn obìnrin tí ń bẹ nínú rẹ̀ ní ìgbèkùn, wọn kò sì pa ẹnìkan, ọmọdé tàbí àgbà, ṣùgbọ́n wọ́n kó wọn lọ, wọ́n sì bá ọ̀nà tiwọn lọ.
Och kvinnorna som voro därinne, både små och stora, hade de fört bort såsom fångar, utan att döda någon; de hade allenast fört bort dem och gått sin väg.
3 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin sì wọ ìlú Siklagi, sì wò ó, a ti kùn ún ni iná; àti obìnrin wọn, àti ọmọkùnrin wọn àti ọmọbìnrin wọn ni a kó ni ìgbèkùn lọ.
När nu David med sina män kom till staden och fick se att den var uppbränd i eld, och att deras hustrur jämte deras söner och döttrar voro bortförda såsom fångar,
4 Dafidi àti àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún títí agbára kò fi sí fún wọn mọ́ láti sọkún.
brast han ut i gråt, så ock hans folk; och de gräto, till dess att de icke förmådde gråta mer.
5 A sì kó àwọn aya Dafidi méjèèjì nígbèkùn lọ, Ahinoamu ará Jesreeli àti Abigaili aya Nabali ará Karmeli.
Davids båda hustrur, Ahinoam från Jisreel och Abigail, karmeliten Nabals hustru, voro också fångna.
6 Dafidi sì banújẹ́ gidigidi, nítorí pé àwọn ènìyàn náà sì ń sọ̀rọ̀ láti sọ ọ́ lókùúta, nítorí ti inú gbogbo àwọn ènìyàn náà sì bàjẹ́, olúkúlùkù ọkùnrin nítorí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti nítorí ọmọ rẹ̀ obìnrin ṣùgbọ́n Dafidi mú ara rẹ̀ lọ́kàn le nínú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
Och David kom i stor nöd, ty folket tänkte stena honom; så förbittrat var allt folket, var och en för sina söners och döttrars skull. Men David hämtade styrka hos HERREN, sin Gud.
7 Dafidi sì wí fún Abiatari àlùfáà, ọmọ Ahimeleki pé, èmí bẹ̀ ọ́, mú efodu fún mi wá níhìn-ín yìí. Abiatari sì mú efodu náà wá fún Dafidi.
Och David sade till prästen Ebjatar, Ahimeleks son: "Bär hit till mig efoden." Då bar Ebjatar fram efoden till David.
8 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa wí pé, “Kí èmi ó lépa ogun yìí bi? Èmi lè bá wọn?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Lépa, nítorí pé ni bíbá ìwọ yóò bá wọn, ni gbígbà ìwọ yóò sì rí wọn gbà.”
David frågade nu HERREN: "Skall jag sätta efter denna rövarskara? Kan jag då hinna upp den?" Han svarade honom: "Sätt efter dem; ty du skall förvisso hinna upp dem och skaffa räddning."
9 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wá sí ibi àfonífojì Besori, apá kan sì dúró.
Då begav sig David åstad med sina sex hundra man, och de kommo till bäcken Besor; där stannade de som nödgades bliva efter.
10 Ṣùgbọ́n Dafidi àti irinwó ọmọkùnrin lépa wọn: igba ènìyàn tí àárẹ̀ mú, tiwọn kò lè kọjá odò Besori sì dúró lẹ́yìn.
Men David fortsatte förföljelsen med fyra hundra man; ty de som sade blivit för trötta, och som därför stannade, utan att gå över bäcken Besor, utgjorde två hundra man.
11 Wọ́n sì rí ará Ejibiti kan ní oko, wọ́n sì mú un tọ Dafidi wá, wọ́n sì fún un ní oúnjẹ, ó sì jẹ; wọ́n sì fún un ní omi mu.
Sedan träffade de på fältet en egyptisk man; honom togo de med sig till David. Och när de hade givit honom bröd att äta och vatten att dricka
12 Wọ́n sì fún un ní àkàrà, èso ọ̀pọ̀tọ́ àti síírí àjàrà gbígbẹ́ méjì: nígbà tí ó sì jẹ ẹ́ tán, ẹ̀mí rẹ̀ sì sọjí: nítorí pé kò jẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi ní ọjọ́ mẹ́ta ní ọ̀sán, àti ní òru.
och när de ytterligare hade givit honom ett stycke fikonkaka och två russinkakor att äta, kom livskraften tillbaka i honom igen. På tre dygn hade han nämligen varken ätit eller druckit.
13 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ? Àti níbo ni ìwọ ti wá?” Òun sì wí pé, “Ọmọ ará Ejibiti ni èmi, ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin kan ará Amaleki. Olúwa mi fi mí sílẹ̀, nítorí pé láti ọjọ́ mẹ́ta ni èmi ti ṣe àìsàn.
Och David frågade honom: "Vem tillhör du, och varifrån är du?" Han svarade: "Jag är en egyptisk yngling, tjänare åt en amalekitisk man; men min herre övergav mig för tre dagar sedan, därför att jag blev sjuk.
14 Àwa sì gbé ogun lọ sí ìhà gúúsù tí ará Kereti, àti sí ìhà ti Juda, àti sí ìhà gúúsù ti Kalebu; àwa sì kun Siklagi ní iná.”
Vi hade nämligen infallit i den del av Sydlandet, som tillhör keretéerna, och i det område som tillhör Juda, och i den del av Sydlandet, som tillhör Kaleb, och vi hade bränt upp Siklag i eld."
15 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ìwọ lè mú mí sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun yìí lọ bí?” Òun sì wí pé, “Fi Ọlọ́run búra fún mi pé, ìwọ kì yóò pa mí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò sì fi mi lé olúwa mi lọ́wọ́; èmi yóò sì mú ọ sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun náà lọ.”
David sade till honom: "Vill du föra mig ned till den rövarskaran?" Han svarade: "Lova mig med ed vid Gud att du icke dödar mig eller utlämnar mig åt min herre, så vill jag föra dig ned till den rövarskaran."
16 Ó sì mú un sọ̀kalẹ̀, sì wò ó, wọ́n sì tàn ká ilẹ̀, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n sì ń jó, nítorí ìkógun púpọ̀ tí wọ́n kó láti ilẹ̀ àwọn Filistini wá, àti láti ilẹ̀ Juda.
Så förde han honom ditned, och de lågo då kringspridda överallt på marken och åto och drucko och förlustade sig med allt det stora byte som de hade tagit ur filistéernas land och ur Juda land.
17 Dafidi sì pa wọ́n láti àfẹ̀mọ́júmọ́ títí ó fi di àṣálẹ́ ọjọ́ kejì: kò sí ẹnìkan tí ó là nínú wọn, bí kọ̀ ṣe irinwó ọmọkùnrin tí wọ́n gun ìbákasẹ tí wọ́n sì sá.
Och ända från skymningen intill nästa dags afton höll David på med att nedgöra dem; och ingen enda av dem kom undan, utom fyra hundra tjänare som satte sig upp på kamelerna och flydde.
18 Dafidi sì gbà gbogbo nǹkan tí àwọn ará Amaleki ti kó: Dafidi sì gba àwọn obìnrin rẹ̀ méjèèjì.
Och David räddade allt vad amalekiterna hade tagit; sina båda hustrur räddade David också.
19 Kò sì ṣí nǹkan tí ó kù fún wọn, kékeré tàbí ńlá, ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin, tàbí ìkógun, tàbí gbogbo nǹkan tí wọ́n ti kó: Dafidi sì gba gbogbo wọn.
Ingen saknades, varken liten eller stor, ingens son och ingens dotter, ej heller något av bytet eller något av det som de hade tagit med sig; David förde alltsammans tillbaka.
20 Dafidi sì kó gbogbo àgùntàn, àti màlúù tí àwọn ènìyàn rẹ̀ dà ṣáájú àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn tí wọ́n gbà, wọ́n sì wí pé, “Èyí yìí ni ìkógun ti Dafidi.”
David tog ock alla får och fäkreatur, och man drev dessa framför den övriga boskapen och ropade: "Detta är Davids byte."
21 Dafidi sì wá sọ́dọ̀ igba ọkùnrin tí àárẹ̀ ti mú jú, tiwọn kò lè tọ́ Dafidi lẹ́yìn mọ́, ti òun ti fi sílẹ̀, ni àfonífojì Besori: wọ́n sì lọ pàdé Dafidi, àti láti pàdé àwọn ènìyàn tí ó lọ pẹ̀lú rẹ̀: Dafidi sì pàdé àwọn ènìyàn náà, ó sì kí wọn.
Och när David kom tillbaka till de två hundra man som hade varit för trötta att följa honom, och som därför hade fått stanna kvar vid bäcken Besor, gingo dessa åstad för att möta David och det folk som han hade med sig; då gick David fram till folket och hälsade dem.
22 Gbogbo àwọn ènìyàn búburú àti àwọn ọmọ Beliali nínú àwọn tí o bá Dafidi lọ sì dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Bí wọn kò ti bá wa lọ, àwa ki yóò fi nǹkan kan fún wọn nínú ìkógun ti àwa rí gbà bí kò ṣe obìnrin olúkúlùkù wọn, àti ọmọ wọn; ki wọn sì mú wọn, ki wọn sì máa lọ.”
Men allahanda onda och illasinnade män, bland dem som hade följt med David, togo till orda och sade: "Eftersom dessa icke följde med oss, skola vi icke giva dem något av bytet som vi hava räddat; var och en av dem må allenast taga sin hustru och sina barn med sig och gå hem."
23 Dafidi sì wí pé, “Ẹ má ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin ara mi: Olúwa ni ó fi nǹkan yìí fún wa, òun ni ó sì pa wá mọ́, òun ni ó sì fi ẹgbẹ́ ogun ti ó dìde sí wa lé wa lọ́wọ́.
Men David svarade: "Så skolen I icke göra, mina bröder, med det som HERREN har givit oss, då han bevarade oss och gav i vår hand denna rövarskara, som kom över oss.
24 Ta ni yóò gbọ́ tiyín nínú ọ̀ràn yìí? Ṣùgbọ́n bi ìpín ẹni tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ si ìjà ti rí, bẹ́ẹ̀ ni ìpín ẹni ti ó dúró ti ẹrù; wọn ó sì pín in bákan náà.”
Och vem skulle för övrigt härutinnan vilja lyssna till eder? Nej, sådan deras lott är, som draga med i striden, sådan skall deras lott vara, som stanna vid trossen; de skola dela jämnt med varandra."
25 Láti ọjọ́ náà lọ, ó sì pàṣẹ, ó sì sọ ọ di òfin fún Israẹli títí di òní yìí.
Och därvid blev det, från den dagen och allt framgent; ty han gjorde detta till lag och rätt i Israel, såsom det är ännu i dag.
26 Dafidi sì padà sí Siklagi, ó sì rán nínú ìkógun náà si àwọn àgbàgbà Juda, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ni ẹ̀bùn fún un yín, láti inú ìkógun àwọn ọ̀tá Olúwa wa.”
När sedan David kom till Siklag, sände han en del av bytet till de äldste i Juda, sina vänner, i det han lät säga: "Detta är en skänk till eder av bytet från HERRENS fiender."
27 Ó sì rán an sí àwọn tí ó wà ni Beteli àti sí àwọn tí ó wà ní gúúsù tí Ramoti, àti sí àwọn tí ó wà ní Jattiri.
Han sände till de äldste i Betel, de äldste i Ramot i Sydlandet och de äldste i Jattir;
28 Àti sí àwọn tí ó wà ní Aroeri, àti sí àwọn tí ó wà ní Sifimoti, àti sí àwọn tí ó wà ni Eṣitemoa.
till de äldste i Aroer, de äldste i Sifamot och de äldste i Estemoa;
29 Àti si àwọn tí ó wà ni Rakeli, àti sí àwọn tí ó wà ní ìlú àwọn Jerahmeeli, àti sí àwọn tí ó wà ni ìlú àwọn ará Keni,
till de äldste i Rakal, de äldste i jerameeliternas städer och de äldste i kainéernas städer;
30 àti sí àwọn tí ó wà ni Horma, àti sí àwọn ti ó wà ní Bori-Aṣani, àti sí àwọn tí ó wà ni Ataki.
till de äldste i Horma, de äldste i Bor-Asan och de äldste i Atak;
31 Àti àwọn tí ó wà ni Hebroni, àti sí gbogbo àwọn ìlú ti Dafidi tìkára rẹ̀ àti tí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ máa ń rìn ká.
till de äldste i Hebron och till alla de orter där David hade vandrat omkring med sina män.

< 1 Samuel 30 >