< 1 Samuel 30 >

1 Ó sì ṣe nígbà ti Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì bọ̀ sí Siklagi ní ọjọ́ kẹta, àwọn ará Amaleki sì ti kọlu ìhà gúúsù, àti Siklagi, wọ́n sì ti kùn ún ní iná.
И бысть приходящу Давиду и мужем его к Секелагу в день третий, и Амалик нападе на южную страну и на Секелаг, и порази Секелаг и сожже его огнем:
2 Wọ́n sì kó àwọn obìnrin tí ń bẹ nínú rẹ̀ ní ìgbèkùn, wọn kò sì pa ẹnìkan, ọmọdé tàbí àgbà, ṣùgbọ́n wọ́n kó wọn lọ, wọ́n sì bá ọ̀nà tiwọn lọ.
жен же и всех сущих в нем от мала до велика не умертвиша мужа ни жены, но плениша, и отидоша в путь свой.
3 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin sì wọ ìlú Siklagi, sì wò ó, a ti kùn ún ni iná; àti obìnrin wọn, àti ọmọkùnrin wọn àti ọmọbìnrin wọn ni a kó ni ìgbèkùn lọ.
И прииде Давид и мужие его во град, и се, сожжен бяше огнем, жены же их и сынове их и дщери их пленени быша.
4 Dafidi àti àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún títí agbára kò fi sí fún wọn mọ́ láti sọkún.
И воздвиже Давид и мужие его глас свой и плакашася дондеже не бе в них силы ктому плакатися.
5 A sì kó àwọn aya Dafidi méjèèjì nígbèkùn lọ, Ahinoamu ará Jesreeli àti Abigaili aya Nabali ará Karmeli.
И жены обе Давидовы пленени быша, Ахинаам Иезраилитыня, и Авигеа бывшая жена Навала Кармилскаго.
6 Dafidi sì banújẹ́ gidigidi, nítorí pé àwọn ènìyàn náà sì ń sọ̀rọ̀ láti sọ ọ́ lókùúta, nítorí ti inú gbogbo àwọn ènìyàn náà sì bàjẹ́, olúkúlùkù ọkùnrin nítorí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti nítorí ọmọ rẹ̀ obìnrin ṣùgbọ́n Dafidi mú ara rẹ̀ lọ́kàn le nínú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
И оскорбе Давид зело, яко совещашася людие камением побити его, яко скорбна бяше душа всех людий коегождо о сынех своих и о дщерех своих. И укрепися Давид о Господе Бозе своем,
7 Dafidi sì wí fún Abiatari àlùfáà, ọmọ Ahimeleki pé, èmí bẹ̀ ọ́, mú efodu fún mi wá níhìn-ín yìí. Abiatari sì mú efodu náà wá fún Dafidi.
и рече Давид ко Авиафару иерею сыну Авимелехову: принеси ефуд. И принесе Авиафар ефуд к Давиду.
8 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa wí pé, “Kí èmi ó lépa ogun yìí bi? Èmi lè bá wọn?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Lépa, nítorí pé ni bíbá ìwọ yóò bá wọn, ni gbígbà ìwọ yóò sì rí wọn gbà.”
И вопроси Давид Господа, глаголя: пожену ли вслед полчища сего? И постигну ли их? И рече Господь: гони, яко постизая постигнеши их и избавляя избавиши.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wá sí ibi àfonífojì Besori, apá kan sì dúró.
И иде Давид сам и шесть сот мужей с ним, и приидоша даже до потока Восорска, прочии же осташася:
10 Ṣùgbọ́n Dafidi àti irinwó ọmọkùnrin lépa wọn: igba ènìyàn tí àárẹ̀ mú, tiwọn kò lè kọjá odò Besori sì dúró lẹ́yìn.
и гна с четырми сты мужей, двести же мужей осташася, иже седоша об он пол потока Восорска.
11 Wọ́n sì rí ará Ejibiti kan ní oko, wọ́n sì mú un tọ Dafidi wá, wọ́n sì fún un ní oúnjẹ, ó sì jẹ; wọ́n sì fún un ní omi mu.
И обретоша мужа Египтянина на селе, и яша его, и приведоша его к Давиду, и даша ему хлеба, и яде, и напоиша его водою:
12 Wọ́n sì fún un ní àkàrà, èso ọ̀pọ̀tọ́ àti síírí àjàrà gbígbẹ́ méjì: nígbà tí ó sì jẹ ẹ́ tán, ẹ̀mí rẹ̀ sì sọjí: nítorí pé kò jẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi ní ọjọ́ mẹ́ta ní ọ̀sán, àti ní òru.
и даша ему часть смоквей, и яде, и укрепися дух его в нем, яко не яде хлеба и не пи воды три дни и три нощы.
13 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ? Àti níbo ni ìwọ ti wá?” Òun sì wí pé, “Ọmọ ará Ejibiti ni èmi, ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin kan ará Amaleki. Olúwa mi fi mí sílẹ̀, nítorí pé láti ọjọ́ mẹ́ta ni èmi ti ṣe àìsàn.
И рече ему Давид: откуду еси, и чий еси ты? И рече отрок Египтянин: аз есмь раб мужа Амаликитянина, и остави мя господин мой, яко изнемогох днесь уже третий день:
14 Àwa sì gbé ogun lọ sí ìhà gúúsù tí ará Kereti, àti sí ìhà ti Juda, àti sí ìhà gúúsù ti Kalebu; àwa sì kun Siklagi ní iná.”
и мы ходихом на юг до Хелефи и на Иудейския страны и на Гелвуй, и Секелагу пожгохом огнем.
15 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ìwọ lè mú mí sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun yìí lọ bí?” Òun sì wí pé, “Fi Ọlọ́run búra fún mi pé, ìwọ kì yóò pa mí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò sì fi mi lé olúwa mi lọ́wọ́; èmi yóò sì mú ọ sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun náà lọ.”
И рече ему Давид: доведеши ли мя до полчища сего? И рече: кленися ми Богом, яко не убиеши мя и не предаси мя в руце господину моему, и доведу тя до полчища сего.
16 Ó sì mú un sọ̀kalẹ̀, sì wò ó, wọ́n sì tàn ká ilẹ̀, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n sì ń jó, nítorí ìkógun púpọ̀ tí wọ́n kó láti ilẹ̀ àwọn Filistini wá, àti láti ilẹ̀ Juda.
(И клятся ему Давид: ) и приведе его онамо, и се, тии разсеяни быша по лицу всея земли, ядуще и пиюще и празднующе о всех корыстех великих, яже взяша от земли иноплеменничи и от земли Иудины.
17 Dafidi sì pa wọ́n láti àfẹ̀mọ́júmọ́ títí ó fi di àṣálẹ́ ọjọ́ kejì: kò sí ẹnìkan tí ó là nínú wọn, bí kọ̀ ṣe irinwó ọmọkùnrin tí wọ́n gun ìbákasẹ tí wọ́n sì sá.
И прииде на них Давид, и изби их от утра даже до вечера и наутрие: и не спасеся от них муж, разве четыреста отрок, иже вседоша на велблюды и убежаша.
18 Dafidi sì gbà gbogbo nǹkan tí àwọn ará Amaleki ti kó: Dafidi sì gba àwọn obìnrin rẹ̀ méjèèjì.
И отя Давид вся елика взяша Амаликиты, и обе жены своя отя,
19 Kò sì ṣí nǹkan tí ó kù fún wọn, kékeré tàbí ńlá, ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin, tàbí ìkógun, tàbí gbogbo nǹkan tí wọ́n ti kó: Dafidi sì gba gbogbo wọn.
и не погибе им от мала даже до велика, и от корыстей, и даже до сынов и дщерей и даже до всех, яже взяша, и вся возврати Давид:
20 Dafidi sì kó gbogbo àgùntàn, àti màlúù tí àwọn ènìyàn rẹ̀ dà ṣáájú àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn tí wọ́n gbà, wọ́n sì wí pé, “Èyí yìí ni ìkógun ti Dafidi.”
и взя Давид вся стада и паствины, и погна пред пленом: и плен оный нарицашеся сей плен Давидов.
21 Dafidi sì wá sọ́dọ̀ igba ọkùnrin tí àárẹ̀ ti mú jú, tiwọn kò lè tọ́ Dafidi lẹ́yìn mọ́, ti òun ti fi sílẹ̀, ni àfonífojì Besori: wọ́n sì lọ pàdé Dafidi, àti láti pàdé àwọn ènìyàn tí ó lọ pẹ̀lú rẹ̀: Dafidi sì pàdé àwọn ènìyàn náà, ó sì kí wọn.
И прииде Давид к двема стом мужем оставшымся ити вслед Давида, ихже посади на потоце Восорсте, и изыдоша на сретение Давиду и на сретение людем иже с ним: и прииде Давид до людий, и вопросиша его о мирных.
22 Gbogbo àwọn ènìyàn búburú àti àwọn ọmọ Beliali nínú àwọn tí o bá Dafidi lọ sì dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Bí wọn kò ti bá wa lọ, àwa ki yóò fi nǹkan kan fún wọn nínú ìkógun ti àwa rí gbà bí kò ṣe obìnrin olúkúlùkù wọn, àti ọmọ wọn; ki wọn sì mú wọn, ki wọn sì máa lọ.”
И отвещаша вси мужие пагубнии и лукавнии от мужей ратных ходивших с Давидом и реша: яко не гониша с нами, не дадим им от плена, егоже взяхом, но токмо кийждо жену свою и чада своя да возмут и возвратятся.
23 Dafidi sì wí pé, “Ẹ má ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin ara mi: Olúwa ni ó fi nǹkan yìí fún wa, òun ni ó sì pa wá mọ́, òun ni ó sì fi ẹgbẹ́ ogun ti ó dìde sí wa lé wa lọ́wọ́.
И рече Давид: не сотворите, братия моя, тако, повнегда предаде Господь нам и сохрани нас, и предаде Господь полчище сие нашедшее на ны в руки нашя:
24 Ta ni yóò gbọ́ tiyín nínú ọ̀ràn yìí? Ṣùgbọ́n bi ìpín ẹni tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ si ìjà ti rí, bẹ́ẹ̀ ni ìpín ẹni ti ó dúró ti ẹrù; wọn ó sì pín in bákan náà.”
и кто послушает ваших словес сих? Яко не менши нас суть: понеже по части исходящаго на брань, тако будет часть седящаго при сосудех, по томужде разделятся.
25 Láti ọjọ́ náà lọ, ó sì pàṣẹ, ó sì sọ ọ di òfin fún Israẹli títí di òní yìí.
И бысть от дне того и выше, и бысть в повеление и на оправдание Израилю даже до дне сего.
26 Dafidi sì padà sí Siklagi, ó sì rán nínú ìkógun náà si àwọn àgbàgbà Juda, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ni ẹ̀bùn fún un yín, láti inú ìkógun àwọn ọ̀tá Olúwa wa.”
И прииде Давид в Секелаг, и посла старейшинам от корыстей Иудиных и искренним своим, глаголя: се, вам благословение от корыстей врагов Господних,
27 Ó sì rán an sí àwọn tí ó wà ni Beteli àti sí àwọn tí ó wà ní gúúsù tí Ramoti, àti sí àwọn tí ó wà ní Jattiri.
сущым в Вефсуре и в Раме южней и в Гефоре,
28 Àti sí àwọn tí ó wà ní Aroeri, àti sí àwọn tí ó wà ní Sifimoti, àti sí àwọn tí ó wà ni Eṣitemoa.
и во Ароире и во Аммаде, и во Сафе и во Есфифе и в Гефе,
29 Àti si àwọn tí ó wà ni Rakeli, àti sí àwọn tí ó wà ní ìlú àwọn Jerahmeeli, àti sí àwọn tí ó wà ni ìlú àwọn ará Keni,
и в Кинане и в Сафеце, и в Фимафе и в Кармиле, и сущым во градех Иеремиила и во градех Кенезия,
30 àti sí àwọn tí ó wà ni Horma, àti sí àwọn ti ó wà ní Bori-Aṣani, àti sí àwọn tí ó wà ni Ataki.
и сущым во Иеримуфе и во Вирсавеи и в Номве,
31 Àti àwọn tí ó wà ni Hebroni, àti sí gbogbo àwọn ìlú ti Dafidi tìkára rẹ̀ àti tí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ máa ń rìn ká.
и сущым в Хевроне, и во вся места, яже пройде Давид тамо сам и мужие его.

< 1 Samuel 30 >