< 1 Samuel 30 >

1 Ó sì ṣe nígbà ti Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì bọ̀ sí Siklagi ní ọjọ́ kẹta, àwọn ará Amaleki sì ti kọlu ìhà gúúsù, àti Siklagi, wọ́n sì ti kùn ún ní iná.
A gdy się wrócił Dawid i mężowie jego do Sycelegu, był dzień trzeci, jako Amalekitowie wtargnęli byli na południe, i do Sycelegu, a zburzyli Syceleg, i spalili go ogniem.
2 Wọ́n sì kó àwọn obìnrin tí ń bẹ nínú rẹ̀ ní ìgbèkùn, wọn kò sì pa ẹnìkan, ọmọdé tàbí àgbà, ṣùgbọ́n wọ́n kó wọn lọ, wọ́n sì bá ọ̀nà tiwọn lọ.
I pobrali w niewolę niewiasty, które były w nim; od najmniejszego aż do wielkiego, nie zabili nikogo, ale tylko pojmali, i odeszli drogą swą.
3 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin sì wọ ìlú Siklagi, sì wò ó, a ti kùn ún ni iná; àti obìnrin wọn, àti ọmọkùnrin wọn àti ọmọbìnrin wọn ni a kó ni ìgbèkùn lọ.
A gdy przyszedł Dawid i mężowie jego do miasta, oto, spalone było ogniem, a żony ich, i syny ich, i córki ich w niewolę zabrano.
4 Dafidi àti àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún títí agbára kò fi sí fún wọn mọ́ láti sọkún.
Tedy podniósł Dawid, i lud, który był z nim, głos swój, i płakali, aż im siły do płaczu nie stało.
5 A sì kó àwọn aya Dafidi méjèèjì nígbèkùn lọ, Ahinoamu ará Jesreeli àti Abigaili aya Nabali ará Karmeli.
Obiedwie też żony Dawidowe były wzięte w niewolą: Achinoam Jezreelitka, i Abigail, przedtem żona Nabalowa z Karmelu.
6 Dafidi sì banújẹ́ gidigidi, nítorí pé àwọn ènìyàn náà sì ń sọ̀rọ̀ láti sọ ọ́ lókùúta, nítorí ti inú gbogbo àwọn ènìyàn náà sì bàjẹ́, olúkúlùkù ọkùnrin nítorí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti nítorí ọmọ rẹ̀ obìnrin ṣùgbọ́n Dafidi mú ara rẹ̀ lọ́kàn le nínú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
I był utrapiony Dawid bardzo; bo się zmawiał lud ukamionować go, gdyż gorzkości pełna była dusza wszystkiego ludu, każdego dla synów swych, i dla córek swych; wszakże Dawid zmocnił się w Panu, Bogu swoim.
7 Dafidi sì wí fún Abiatari àlùfáà, ọmọ Ahimeleki pé, èmí bẹ̀ ọ́, mú efodu fún mi wá níhìn-ín yìí. Abiatari sì mú efodu náà wá fún Dafidi.
Tedy rzekł Dawid do Abijatara kapłana, syna Achimelechowego: Weźmij proszę dla mnie efod; i wziął Abijatar efod dla Dawida.
8 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa wí pé, “Kí èmi ó lépa ogun yìí bi? Èmi lè bá wọn?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Lépa, nítorí pé ni bíbá ìwọ yóò bá wọn, ni gbígbà ìwọ yóò sì rí wọn gbà.”
A tak się Dawid radził Pana, mówiąc; Mamli gonić to wojsko, i dogonięli go? A Pan mu rzekł: Goń; bo zapewne ich dogonisz, i zapewne odbijesz plon.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wá sí ibi àfonífojì Besori, apá kan sì dúró.
Szedł tedy Dawid, sam i one sześć set mężów, które miał z sobą, a przyszli aż do potoku Besor; a niektórzy pozostali.
10 Ṣùgbọ́n Dafidi àti irinwó ọmọkùnrin lépa wọn: igba ènìyàn tí àárẹ̀ mú, tiwọn kò lè kọjá odò Besori sì dúró lẹ́yìn.
I gonił je Dawid, sam i cztery sta mężów; bo pozostało było dwieście mężów spracowanych, a nie poszli za potok Besor.
11 Wọ́n sì rí ará Ejibiti kan ní oko, wọ́n sì mú un tọ Dafidi wá, wọ́n sì fún un ní oúnjẹ, ó sì jẹ; wọ́n sì fún un ní omi mu.
I znaleźli męża Egipczanina na polu, a przywiedli go do Dawida, i dali mu chleba, i jadł; dali mu też wody, i pił;
12 Wọ́n sì fún un ní àkàrà, èso ọ̀pọ̀tọ́ àti síírí àjàrà gbígbẹ́ méjì: nígbà tí ó sì jẹ ẹ́ tán, ẹ̀mí rẹ̀ sì sọjí: nítorí pé kò jẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi ní ọjọ́ mẹ́ta ní ọ̀sán, àti ní òru.
Dali mu także i wiązankę fig i dwie gronie rodzynków. Jadł tedy, i wrócił się duch jego weń; bo nie jadł chleba, ani pił wody przez trzy dni i przez trzy nocy.
13 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ? Àti níbo ni ìwọ ti wá?” Òun sì wí pé, “Ọmọ ará Ejibiti ni èmi, ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin kan ará Amaleki. Olúwa mi fi mí sílẹ̀, nítorí pé láti ọjọ́ mẹ́ta ni èmi ti ṣe àìsàn.
I rzekł do niego Dawid: Czyjeś ty? a skądeś? Który odpowiedział: jestem rodem z Egiptu, sługa męża Amalekity, i zostawił mię pan mój, żem się rozniemógł dziś trzeci dzień.
14 Àwa sì gbé ogun lọ sí ìhà gúúsù tí ará Kereti, àti sí ìhà ti Juda, àti sí ìhà gúúsù ti Kalebu; àwa sì kun Siklagi ní iná.”
Wtargnęliśmy byli na południe do Cerety i do Juda, i na południe do Kaleb, i spaliliśmy Syceleg ogniem.
15 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ìwọ lè mú mí sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun yìí lọ bí?” Òun sì wí pé, “Fi Ọlọ́run búra fún mi pé, ìwọ kì yóò pa mí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò sì fi mi lé olúwa mi lọ́wọ́; èmi yóò sì mú ọ sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun náà lọ.”
I rzekł mu Dawid: Mógłżebyś mię dowieść do tego wojska? Który rzekł: Przysięż mi przez Boga, iż mię nie zabijesz, ani mię wydasz w rękę pana mego; tedy cię nawiodę na to wojsko.
16 Ó sì mú un sọ̀kalẹ̀, sì wò ó, wọ́n sì tàn ká ilẹ̀, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n sì ń jó, nítorí ìkógun púpọ̀ tí wọ́n kó láti ilẹ̀ àwọn Filistini wá, àti láti ilẹ̀ Juda.
Nawiódł go tedy; a oto, oni leżeli po wszystkiej onej ziemi, jedząc i pijąc, i weseląc się ze wszystkich korzyści wielkich, które byli zabrali z ziemi Filistyńskiej, i z ziemi Judzkiej.
17 Dafidi sì pa wọ́n láti àfẹ̀mọ́júmọ́ títí ó fi di àṣálẹ́ ọjọ́ kejì: kò sí ẹnìkan tí ó là nínú wọn, bí kọ̀ ṣe irinwó ọmọkùnrin tí wọ́n gun ìbákasẹ tí wọ́n sì sá.
Przetoż bił je Dawid od wieczora aż do wieczora dnia drugiego, tak iż z nich żaden nie uszedł, oprócz czterech set młodzieńców, którzy wsiadłszy na wielbłądy, uciekli.
18 Dafidi sì gbà gbogbo nǹkan tí àwọn ará Amaleki ti kó: Dafidi sì gba àwọn obìnrin rẹ̀ méjèèjì.
A tak odjął Dawid wszystko, co byli pobrali Amalekitowie, i dwie żony swoje odjął też Dawid;
19 Kò sì ṣí nǹkan tí ó kù fún wọn, kékeré tàbí ńlá, ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin, tàbí ìkógun, tàbí gbogbo nǹkan tí wọ́n ti kó: Dafidi sì gba gbogbo wọn.
Tak iż im nic nie zginęło od mała aż do wiela, i aż do synów, i córek, i do korzyści, i aż do wszystkiego, cokolwiek im zabrali, wszystko zasię przywiódł Dawid.
20 Dafidi sì kó gbogbo àgùntàn, àti màlúù tí àwọn ènìyàn rẹ̀ dà ṣáájú àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn tí wọ́n gbà, wọ́n sì wí pé, “Èyí yìí ni ìkógun ti Dafidi.”
Przytem zabrał Dawid wszystkie trzody i stada, które gnano przed bydłem jego, i mówiono: Toć jest korzyść Dawidowa.
21 Dafidi sì wá sọ́dọ̀ igba ọkùnrin tí àárẹ̀ ti mú jú, tiwọn kò lè tọ́ Dafidi lẹ́yìn mọ́, ti òun ti fi sílẹ̀, ni àfonífojì Besori: wọ́n sì lọ pàdé Dafidi, àti láti pàdé àwọn ènìyàn tí ó lọ pẹ̀lú rẹ̀: Dafidi sì pàdé àwọn ènìyàn náà, ó sì kí wọn.
I przyszedł Dawid do onych dwóch set mężów, którzy byli spracowani, że nie mogli iść za Dawidem, którym był kazał zostać u potoku Besor, którzy wyszli przeciw Dawidowi i przeciw ludowi, który z nim był; a przystąpiwszy Dawid do ludu, pozdrowił je spokojnie.
22 Gbogbo àwọn ènìyàn búburú àti àwọn ọmọ Beliali nínú àwọn tí o bá Dafidi lọ sì dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Bí wọn kò ti bá wa lọ, àwa ki yóò fi nǹkan kan fún wọn nínú ìkógun ti àwa rí gbà bí kò ṣe obìnrin olúkúlùkù wọn, àti ọmọ wọn; ki wọn sì mú wọn, ki wọn sì máa lọ.”
A odpowiadając wszyscy mężowie źli i niepobożni, którzy chodzili z Dawidem, rzekli: Ponieważ ci nie chodzili z nami, nie damy im z łupów, któreśmy odjęli, tylko każdemu żonę jego, i syny jego; te wziąwszy, niech odejdą.
23 Dafidi sì wí pé, “Ẹ má ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin ara mi: Olúwa ni ó fi nǹkan yìí fún wa, òun ni ó sì pa wá mọ́, òun ni ó sì fi ẹgbẹ́ ogun ti ó dìde sí wa lé wa lọ́wọ́.
Tedy rzekł Dawid: Nie uczynicie tak, bracia moi, z tem, co nam dał Pan, który nas strzegł, a podał wojsko, które było wyszło przeciwko nam, w ręce nasze.
24 Ta ni yóò gbọ́ tiyín nínú ọ̀ràn yìí? Ṣùgbọ́n bi ìpín ẹni tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ si ìjà ti rí, bẹ́ẹ̀ ni ìpín ẹni ti ó dúró ti ẹrù; wọn ó sì pín in bákan náà.”
I któż was w tem usłucha? Bo jaki dział tego, który wyszedł na wojnę, taki dział i tego, który został przy tłomokach; równo się podzielą.
25 Láti ọjọ́ náà lọ, ó sì pàṣẹ, ó sì sọ ọ di òfin fún Israẹli títí di òní yìí.
I stało się od onego dnia i napotem, że uchwalono to prawo i ten zwyczaj w Izraelu, aż do dnia tego.
26 Dafidi sì padà sí Siklagi, ó sì rán nínú ìkógun náà si àwọn àgbàgbà Juda, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ni ẹ̀bùn fún un yín, láti inú ìkógun àwọn ọ̀tá Olúwa wa.”
A tak przyszedł Dawid do Sycelega, i posłał z onego łupu starszym w Juda, przyjaciołom swym, mówiąc: Oto macie błogosławieństwo z korzyści nieprzyjaciół Pańskich:
27 Ó sì rán an sí àwọn tí ó wà ni Beteli àti sí àwọn tí ó wà ní gúúsù tí Ramoti, àti sí àwọn tí ó wà ní Jattiri.
Tym, co byli w Betel, i co w Ramacie na południe, i co byli w Gieter,
28 Àti sí àwọn tí ó wà ní Aroeri, àti sí àwọn tí ó wà ní Sifimoti, àti sí àwọn tí ó wà ni Eṣitemoa.
I co byli w Aroer, i co byli w Sefamot, i co byli w Estamo;
29 Àti si àwọn tí ó wà ni Rakeli, àti sí àwọn tí ó wà ní ìlú àwọn Jerahmeeli, àti sí àwọn tí ó wà ni ìlú àwọn ará Keni,
I co byli w Racha, i co byli w miastach Jerameel, i co byli w miastach Ceni,
30 àti sí àwọn tí ó wà ni Horma, àti sí àwọn ti ó wà ní Bori-Aṣani, àti sí àwọn tí ó wà ni Ataki.
I co byli w Horma, i co byli w Chorasan, i co byli w Atach,
31 Àti àwọn tí ó wà ni Hebroni, àti sí gbogbo àwọn ìlú ti Dafidi tìkára rẹ̀ àti tí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ máa ń rìn ká.
I co byli w Hebronie, i co byli na wszystkich miejscach, kędy przemieszkiwał Dawid, sam i mężowie jego.

< 1 Samuel 30 >