< 1 Samuel 30 >

1 Ó sì ṣe nígbà ti Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì bọ̀ sí Siklagi ní ọjọ́ kẹta, àwọn ará Amaleki sì ti kọlu ìhà gúúsù, àti Siklagi, wọ́n sì ti kùn ún ní iná.
A, no ka tae a Rawiri ratou ko ana tangata ki Tikiraka i te toru o nga ra, na kua huaki nga Amareki ki te tonga, ki Tikiraka ano, patua ana a Tikiraka e ratou, tahuna ake ki te ahi;
2 Wọ́n sì kó àwọn obìnrin tí ń bẹ nínú rẹ̀ ní ìgbèkùn, wọn kò sì pa ẹnìkan, ọmọdé tàbí àgbà, ṣùgbọ́n wọ́n kó wọn lọ, wọ́n sì bá ọ̀nà tiwọn lọ.
Whakaraua ana hoki e ratou nga wahine me nga mea o reira, te iti, te rahi; kihai i whakamatea tetahi, engari i kahakina atu, a haere ana i to ratou ara.
3 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin sì wọ ìlú Siklagi, sì wò ó, a ti kùn ún ni iná; àti obìnrin wọn, àti ọmọkùnrin wọn àti ọmọbìnrin wọn ni a kó ni ìgbèkùn lọ.
Heoi, i te taenga o Rawiri ratou ko ana tangata ki te pa, kua oti te tahu ki te ahi, a kau whakaraua atu a ratou wahine, a ratou tama, a ratou tamahine.
4 Dafidi àti àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún títí agbára kò fi sí fún wọn mọ́ láti sọkún.
Katahi ka puaki te reo o Rawiri ratou ko ana tangata, tangi ana ratou, a kahore noa o ratou kaha ki te tangi.
5 A sì kó àwọn aya Dafidi méjèèjì nígbèkùn lọ, Ahinoamu ará Jesreeli àti Abigaili aya Nabali ará Karmeli.
I riro whakarau ano nga wahine tokorua a Rawiri, a Ahinoama o Ietereere, raua ko Apikaira wahine a Napara o Karamere.
6 Dafidi sì banújẹ́ gidigidi, nítorí pé àwọn ènìyàn náà sì ń sọ̀rọ̀ láti sọ ọ́ lókùúta, nítorí ti inú gbogbo àwọn ènìyàn náà sì bàjẹ́, olúkúlùkù ọkùnrin nítorí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti nítorí ọmọ rẹ̀ obìnrin ṣùgbọ́n Dafidi mú ara rẹ̀ lọ́kàn le nínú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
Na mamae rawa a Rawiri, no te mea i kupukupu te nuinga kia akina ia ki te kohatu; i mamae hoki te ngakau o te iwi katoa, o tera, o tera, ki a ratou tama, ki a ratou tamahine: ko Rawiri ia i whakapakari i a ia i roto i a Ihowa, i tona Atua.
7 Dafidi sì wí fún Abiatari àlùfáà, ọmọ Ahimeleki pé, èmí bẹ̀ ọ́, mú efodu fún mi wá níhìn-ín yìí. Abiatari sì mú efodu náà wá fún Dafidi.
Na ka mea a Rawiri ki a Apiatara tohunga, tama a Ahimereke, Tena, maua mai te epora ki ahau. Na maua ana te epora e Apiatara ki a Rawiri.
8 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa wí pé, “Kí èmi ó lépa ogun yìí bi? Èmi lè bá wọn?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Lépa, nítorí pé ni bíbá ìwọ yóò bá wọn, ni gbígbà ìwọ yóò sì rí wọn gbà.”
Na ka ui a Rawiri ki a Ihowa, ka mea, Ki te whai ahau i tenei taua e mau ranei ratou i ahau? Na ka mea ia, Whaia; ka mau pu hoki ratou i a koe, a ka riro katoa mai au i a koe.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wá sí ibi àfonífojì Besori, apá kan sì dúró.
Heoi haere ana a Rawiri ratou ko ana tangata e ono rau, kua tae ki te awa, ki Pehoro, ki te wahi i noho ai te hunga i mahue iho.
10 Ṣùgbọ́n Dafidi àti irinwó ọmọkùnrin lépa wọn: igba ènìyàn tí àárẹ̀ mú, tiwọn kò lè kọjá odò Besori sì dúró lẹ́yìn.
Otiia whai tonu ana a Rawiri ratou ko nga tangata e wha rau: e rua hoki nga rau i noho; i ruha rawa hoki, te whiti ai i te awa, i Pehoro.
11 Wọ́n sì rí ará Ejibiti kan ní oko, wọ́n sì mú un tọ Dafidi wá, wọ́n sì fún un ní oúnjẹ, ó sì jẹ; wọ́n sì fún un ní omi mu.
Na ka tupono atu ratou ki tetahi tangata o Ihipa i te parae, a kawea ana ia ki a Rawiri. Na ka hoatu he taro mana, a kai ana ia; i whakainu ano ratou i a ia ki te wai.
12 Wọ́n sì fún un ní àkàrà, èso ọ̀pọ̀tọ́ àti síírí àjàrà gbígbẹ́ méjì: nígbà tí ó sì jẹ ẹ́ tán, ẹ̀mí rẹ̀ sì sọjí: nítorí pé kò jẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi ní ọjọ́ mẹ́ta ní ọ̀sán, àti ní òru.
I hoatu ano e ratou tetahi wahi o te keke piki me etahi tautau karepe e rua, na ka kai ia, a ka hoki tona wairua ki a ia; e toru hoki nga ra, e toru nga po ona kihai nei ia i kai i te kai, kihai i inu i te wai.
13 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ? Àti níbo ni ìwọ ti wá?” Òun sì wí pé, “Ọmọ ará Ejibiti ni èmi, ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin kan ará Amaleki. Olúwa mi fi mí sílẹ̀, nítorí pé láti ọjọ́ mẹ́ta ni èmi ti ṣe àìsàn.
Na ka mea a Rawiri ki a ia, Na wai koe? no hea hoki koe? Ano ra ko ia, He tamaiti ahau no Ihipa, he pononga na tetahi Amareki; i whakarerea hoki ahau e toku ariki, he panga noku e te mate ka toru enei ra.
14 Àwa sì gbé ogun lọ sí ìhà gúúsù tí ará Kereti, àti sí ìhà ti Juda, àti sí ìhà gúúsù ti Kalebu; àwa sì kun Siklagi ní iná.”
I huakina e matou te tonga o nga Kereti, me te wahi i a Hura, me te tonga o Karepe; i tahuna ano e matou a Tikiraka ki te ahi.
15 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ìwọ lè mú mí sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun yìí lọ bí?” Òun sì wí pé, “Fi Ọlọ́run búra fún mi pé, ìwọ kì yóò pa mí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò sì fi mi lé olúwa mi lọ́wọ́; èmi yóò sì mú ọ sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun náà lọ.”
Na ka mea a Rawiri ki a ia, E taea ranei ahau te kawe e koe ki raro, ki te ope ra? Ano ra ko ia, Oati mai ki ahau ki te Atua hoki, e kore ahau e whakamatea e koe, e kore e tukua ki nga ringa o toku rangatira, a ka kawea koe e ahau ki raro ki tau a ope.
16 Ó sì mú un sọ̀kalẹ̀, sì wò ó, wọ́n sì tàn ká ilẹ̀, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n sì ń jó, nítorí ìkógun púpọ̀ tí wọ́n kó láti ilẹ̀ àwọn Filistini wá, àti láti ilẹ̀ Juda.
A, no tana kawenga i a ia ki raro, kua wawa noa atu ratou ki te mata o te whenua katoa, e kai ana, e inu ana, e kanikani ana, mo nga taonga nui katoa, taonga parakete, i riro i a ratou i te whenua o nga Pirihitini, i te whenua hoki o Hura.
17 Dafidi sì pa wọ́n láti àfẹ̀mọ́júmọ́ títí ó fi di àṣálẹ́ ọjọ́ kejì: kò sí ẹnìkan tí ó là nínú wọn, bí kọ̀ ṣe irinwó ọmọkùnrin tí wọ́n gun ìbákasẹ tí wọ́n sì sá.
Na patua iho ratou e Rawiri i te puaotanga a taea noatia te ahiahi o te aonga ake: kihai hoki tetahi o ratou i mawhiti, heoi ano ko etahi taitamariki e wha rau i eke ki nga kamera, a rere ana.
18 Dafidi sì gbà gbogbo nǹkan tí àwọn ará Amaleki ti kó: Dafidi sì gba àwọn obìnrin rẹ̀ méjèèjì.
I riro ano hoki i a Rawiri nga mea katoa i tangohia e nga Amareki: i riro ano i a Rawiri ana wahine tokorua.
19 Kò sì ṣí nǹkan tí ó kù fún wọn, kékeré tàbí ńlá, ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin, tàbí ìkógun, tàbí gbogbo nǹkan tí wọ́n ti kó: Dafidi sì gba gbogbo wọn.
Kihai hoki i ngaro tetahi o a ratou mea; te iti, te rahi, nga tama, nga tamahine, nga taonga parakete, nga mea katoa i tangohia e ratou; i hoki katoa mai a Rawiri.
20 Dafidi sì kó gbogbo àgùntàn, àti màlúù tí àwọn ènìyàn rẹ̀ dà ṣáájú àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn tí wọ́n gbà, wọ́n sì wí pé, “Èyí yìí ni ìkógun ti Dafidi.”
I mau ano i a Rawiri nga hipi katoa me nga kahui; a ka arahina e ratou i mua i era atu karerehe, i mea, Ko te taonga parakete tenei a Rawiri.
21 Dafidi sì wá sọ́dọ̀ igba ọkùnrin tí àárẹ̀ ti mú jú, tiwọn kò lè tọ́ Dafidi lẹ́yìn mọ́, ti òun ti fi sílẹ̀, ni àfonífojì Besori: wọ́n sì lọ pàdé Dafidi, àti láti pàdé àwọn ènìyàn tí ó lọ pẹ̀lú rẹ̀: Dafidi sì pàdé àwọn ènìyàn náà, ó sì kí wọn.
A ka tae a Rawiri ki nga tangata e rua rau i ruha nei, kihai nei i aru i a Rawiri, i meinga ra kia noho ki te awa, ki Pehoro: ka puta ratou ki te whakatau i a Rawiri, ki te whakatau hoki i te iwi i a ia: a ka tata a Rawiri ki aua tangata, ka oha ia ki a ratou.
22 Gbogbo àwọn ènìyàn búburú àti àwọn ọmọ Beliali nínú àwọn tí o bá Dafidi lọ sì dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Bí wọn kò ti bá wa lọ, àwa ki yóò fi nǹkan kan fún wọn nínú ìkógun ti àwa rí gbà bí kò ṣe obìnrin olúkúlùkù wọn, àti ọmọ wọn; ki wọn sì mú wọn, ki wọn sì máa lọ.”
Katahi ka oho ake te hunga kino katoa, nga tangata o Periara i roto i te hunga i haere tahi ratou ko Rawiri, ka mea, Kihai ratou i haere tahi tatou, na, e kore e hoatu ki a ratou etahi o nga taonga i rio mai i a tatou, heoi ano ko te wahine me n ga tamariki a tenei, a tenei, na ma ratou e arahi atu, e haere.
23 Dafidi sì wí pé, “Ẹ má ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin ara mi: Olúwa ni ó fi nǹkan yìí fún wa, òun ni ó sì pa wá mọ́, òun ni ó sì fi ẹgbẹ́ ogun ti ó dìde sí wa lé wa lọ́wọ́.
Katahi a Rawiri ka mea, Kaua e pena, e oku teina, ki ta Ihowa i homai ai ki a tatou; nana nei hoki tatou i tiaki, a homai ana e ia ki a tatou ringa taua ope i haere ake ra ki a tatou.
24 Ta ni yóò gbọ́ tiyín nínú ọ̀ràn yìí? Ṣùgbọ́n bi ìpín ẹni tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ si ìjà ti rí, bẹ́ẹ̀ ni ìpín ẹni ti ó dúró ti ẹrù; wọn ó sì pín in bákan náà.”
Ko wai hoki hei whakarongo ki tenei mea a koutou? Ko te wahi hoki a te tangata i haere ki te whawhai kia rite ki te wahi a te tangata i noho ki nga mea: kia rite tonu te wahi ma ratou.
25 Láti ọjọ́ náà lọ, ó sì pàṣẹ, ó sì sọ ọ di òfin fún Israẹli títí di òní yìí.
Na waiho tonu iho e ia tena hei tikanga, hei ritenga mo Iharaira no taua rangi a tuku iho ki tenei ra.
26 Dafidi sì padà sí Siklagi, ó sì rán nínú ìkógun náà si àwọn àgbàgbà Juda, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ni ẹ̀bùn fún un yín, láti inú ìkógun àwọn ọ̀tá Olúwa wa.”
A, i te taenga o Rawiri ki Tikiraka, ka tonoa e ia etahi o nga taonga ki nga kaumatua o Hura, ki ona hoa, a ka mea, Tena tetahi manaaki mo koutou no nga taonga a nga hoariri o Ihowa;
27 Ó sì rán an sí àwọn tí ó wà ni Beteli àti sí àwọn tí ó wà ní gúúsù tí Ramoti, àti sí àwọn tí ó wà ní Jattiri.
Ki nga tangata hoki o Peteere, ki o Ramoto ki te tonga, ki era hoki i Iatiri;
28 Àti sí àwọn tí ó wà ní Aroeri, àti sí àwọn tí ó wà ní Sifimoti, àti sí àwọn tí ó wà ni Eṣitemoa.
Ki a Aroere, ki o Hipimoto, ki o Ehetemoa.
29 Àti si àwọn tí ó wà ni Rakeli, àti sí àwọn tí ó wà ní ìlú àwọn Jerahmeeli, àti sí àwọn tí ó wà ni ìlú àwọn ará Keni,
Ki o Rakara, ki o nga pa o nga Ierameeri, ki o nga pa o nga Keni;
30 àti sí àwọn tí ó wà ni Horma, àti sí àwọn ti ó wà ní Bori-Aṣani, àti sí àwọn tí ó wà ni Ataki.
Ki o Horema, ki o Korahana, ki o Ataka;
31 Àti àwọn tí ó wà ni Hebroni, àti sí gbogbo àwọn ìlú ti Dafidi tìkára rẹ̀ àti tí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ máa ń rìn ká.
Ki o Heperona, ki o nga wahi katoa i haereere ai a Rawiri ratou ko ana tangata.

< 1 Samuel 30 >