< 1 Samuel 30 >
1 Ó sì ṣe nígbà ti Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì bọ̀ sí Siklagi ní ọjọ́ kẹta, àwọn ará Amaleki sì ti kọlu ìhà gúúsù, àti Siklagi, wọ́n sì ti kùn ún ní iná.
Byl pak, když se navrátil David a muži jeho do Sicelechu, den třetí, jakž Amalechitští byli vpád učinili k straně polední i k Sicelechu, a vyhubili Sicelech, a vypálili jej.
2 Wọ́n sì kó àwọn obìnrin tí ń bẹ nínú rẹ̀ ní ìgbèkùn, wọn kò sì pa ẹnìkan, ọmọdé tàbí àgbà, ṣùgbọ́n wọ́n kó wọn lọ, wọ́n sì bá ọ̀nà tiwọn lọ.
A zajali ženy, kteréž byly v něm. Nezabili žádného, ani malého ani velikého, ale szajímali a odešli cestou svou.
3 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin sì wọ ìlú Siklagi, sì wò ó, a ti kùn ún ni iná; àti obìnrin wọn, àti ọmọkùnrin wọn àti ọmọbìnrin wọn ni a kó ni ìgbèkùn lọ.
A když přišel David a muži jeho k městu, aj, vypáleno bylo ohněm, a ženy jejich, též synové a dcery jejich zajati byli.
4 Dafidi àti àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún títí agbára kò fi sí fún wọn mọ́ láti sọkún.
Tedy David i lid jeho, kterýž s ním byl, pozdvihše hlasu svého, plakali, až již více plakati nemohli.
5 A sì kó àwọn aya Dafidi méjèèjì nígbèkùn lọ, Ahinoamu ará Jesreeli àti Abigaili aya Nabali ará Karmeli.
Obě také manželky Davidovy zajaty jsou, Achinoam Jezreelitská, a Abigail žena někdy Nábale Karmelského.
6 Dafidi sì banújẹ́ gidigidi, nítorí pé àwọn ènìyàn náà sì ń sọ̀rọ̀ láti sọ ọ́ lókùúta, nítorí ti inú gbogbo àwọn ènìyàn náà sì bàjẹ́, olúkúlùkù ọkùnrin nítorí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti nítorí ọmọ rẹ̀ obìnrin ṣùgbọ́n Dafidi mú ara rẹ̀ lọ́kàn le nínú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
I ssoužen jest David náramně, nebo se smlouval lid, aby ho ukamenovali, (hořkostí zajisté naplněna byla duše všeho lidu, jednoho každého pro syny jeho a pro dcery jeho). Však posilnil se David v Hospodinu Bohu svém.
7 Dafidi sì wí fún Abiatari àlùfáà, ọmọ Ahimeleki pé, èmí bẹ̀ ọ́, mú efodu fún mi wá níhìn-ín yìí. Abiatari sì mú efodu náà wá fún Dafidi.
I řekl David Abiatarovi knězi, synu Achimelechovu: Medle, vezmi na sebe efod. I vzal Abiatar efod pro Davida.
8 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa wí pé, “Kí èmi ó lépa ogun yìí bi? Èmi lè bá wọn?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Lépa, nítorí pé ni bíbá ìwọ yóò bá wọn, ni gbígbà ìwọ yóò sì rí wọn gbà.”
Tázal se pak David Hospodina, řka: Mám-li honiti lotříky ty? A dohoním-li se jich? I řekl jemu: Hoň, nebo se jich jistě dohoníš, a své mocně vysvobodíš.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wá sí ibi àfonífojì Besori, apá kan sì dúró.
A tak odšed David sám i těch šest set mužů, kteříž byli s ním, přišli až ku potoku Bezor; někteří pak tu pozůstali.
10 Ṣùgbọ́n Dafidi àti irinwó ọmọkùnrin lépa wọn: igba ènìyàn tí àárẹ̀ mú, tiwọn kò lè kọjá odò Besori sì dúró lẹ́yìn.
I honil je David se čtyřmi sty mužů; nebo bylo pozůstalo dvě stě mužů, kteříž ustavše, nemohli přejíti potoka Bezor.
11 Wọ́n sì rí ará Ejibiti kan ní oko, wọ́n sì mú un tọ Dafidi wá, wọ́n sì fún un ní oúnjẹ, ó sì jẹ; wọ́n sì fún un ní omi mu.
A nalezše muže Egyptského v poli, přivedli jej k Davidovi. I dali jemu chleba, aby pojedl; dali jemu také i vody píti.
12 Wọ́n sì fún un ní àkàrà, èso ọ̀pọ̀tọ́ àti síírí àjàrà gbígbẹ́ méjì: nígbà tí ó sì jẹ ẹ́ tán, ẹ̀mí rẹ̀ sì sọjí: nítorí pé kò jẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi ní ọjọ́ mẹ́ta ní ọ̀sán, àti ní òru.
Dali jemu též kus hrudy fíků a dva hrozny suché. A tak pojedl a okřál zase, (nebo byl nic nejedl ani nepil tři dni a tři noci).
13 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ? Àti níbo ni ìwọ ti wá?” Òun sì wí pé, “Ọmọ ará Ejibiti ni èmi, ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin kan ará Amaleki. Olúwa mi fi mí sílẹ̀, nítorí pé láti ọjọ́ mẹ́ta ni èmi ti ṣe àìsàn.
Zatím řekl jemu David: Čí jsi ty? A odkud jsi? Kterýž odpověděl: Rodem jsem z Egypta, služebník muže Amalechitského, a opustil mne pán můj, proto že jsem stonal, dnes třetí den.
14 Àwa sì gbé ogun lọ sí ìhà gúúsù tí ará Kereti, àti sí ìhà ti Juda, àti sí ìhà gúúsù ti Kalebu; àwa sì kun Siklagi ní iná.”
Byli jsme zajisté vpád učinili k straně polední Ceretejského, a v tu stranu, kteráž jest Judova, a ku poledni, kteráž jest Kálefova, a Sicelech jsme vypálili ohněm.
15 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ìwọ lè mú mí sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun yìí lọ bí?” Òun sì wí pé, “Fi Ọlọ́run búra fún mi pé, ìwọ kì yóò pa mí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò sì fi mi lé olúwa mi lọ́wọ́; èmi yóò sì mú ọ sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun náà lọ.”
Tedy řekl jemu David: Mohl-li bys dovésti mne k těm lotříkům? Kterýž řekl: Přisáhni mi skrze Boha, že mne nezabiješ, a že mne nevydáš v ruku pána mého, a přivedu tě na ty lotříky.
16 Ó sì mú un sọ̀kalẹ̀, sì wò ó, wọ́n sì tàn ká ilẹ̀, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n sì ń jó, nítorí ìkógun púpọ̀ tí wọ́n kó láti ilẹ̀ àwọn Filistini wá, àti láti ilẹ̀ Juda.
I přivedl ho. (A aj, byli se rozprostřeli po vší té zemi, jedouce a pijíce a provyskujíce nade všemi kořistmi tak velikými, kteréž pobrali z země Filistinské a z země Judovy.)
17 Dafidi sì pa wọ́n láti àfẹ̀mọ́júmọ́ títí ó fi di àṣálẹ́ ọjọ́ kejì: kò sí ẹnìkan tí ó là nínú wọn, bí kọ̀ ṣe irinwó ọmọkùnrin tí wọ́n gun ìbákasẹ tí wọ́n sì sá.
Protož bil je David od večera až do večera druhého dne, aniž kdo z nich ušel, kromě čtyř set mládenců, kteříž vsedše na velbloudy, utekli.
18 Dafidi sì gbà gbogbo nǹkan tí àwọn ará Amaleki ti kó: Dafidi sì gba àwọn obìnrin rẹ̀ méjèèjì.
A tak odjal David všecko, což byli pobrali Amalechitští; také obě ženy své vysvobodil David.
19 Kò sì ṣí nǹkan tí ó kù fún wọn, kékeré tàbí ńlá, ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin, tàbí ìkógun, tàbí gbogbo nǹkan tí wọ́n ti kó: Dafidi sì gba gbogbo wọn.
A nezhynulo jim nic, ani malého ani velikého, i z synů i ze dcer, i z loupeže a ze všeho, což jim vzato bylo; všecko zase David přivedl.
20 Dafidi sì kó gbogbo àgùntàn, àti màlúù tí àwọn ènìyàn rẹ̀ dà ṣáájú àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn tí wọ́n gbà, wọ́n sì wí pé, “Èyí yìí ni ìkógun ti Dafidi.”
Nadto szajímal David všecka stáda bravů i skotů, kteráž hnali před dobytkem svým, a pravili: Totoť jsou kořisti Davidovy.
21 Dafidi sì wá sọ́dọ̀ igba ọkùnrin tí àárẹ̀ ti mú jú, tiwọn kò lè tọ́ Dafidi lẹ́yìn mọ́, ti òun ti fi sílẹ̀, ni àfonífojì Besori: wọ́n sì lọ pàdé Dafidi, àti láti pàdé àwọn ènìyàn tí ó lọ pẹ̀lú rẹ̀: Dafidi sì pàdé àwọn ènìyàn náà, ó sì kí wọn.
Přišel pak David k těm dvěma stům mužů, kteříž byli ustali, tak že nemohli jíti za Davidem, jimž byli kázali zůstati při potoku Bezor; tedy vyšli vstříc Davidovi a lidu, kterýž byl s ním. A přistoupiv David k tomu lidu, pozdravil jich přátelsky.
22 Gbogbo àwọn ènìyàn búburú àti àwọn ọmọ Beliali nínú àwọn tí o bá Dafidi lọ sì dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Bí wọn kò ti bá wa lọ, àwa ki yóò fi nǹkan kan fún wọn nínú ìkógun ti àwa rí gbà bí kò ṣe obìnrin olúkúlùkù wọn, àti ọmọ wọn; ki wọn sì mú wọn, ki wọn sì máa lọ.”
Ale všickni, což jich koli bylo zlých a bezbožných mezi těmi muži, kteříž chodili s Davidem, mluvili, řkouce: Poněvadž nešli s námi, nedáme jim z kořistí, kteréž jsme odjali, toliko každému manželku jeho a syny jeho, aby vezmouce je, odešli.
23 Dafidi sì wí pé, “Ẹ má ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin ara mi: Olúwa ni ó fi nǹkan yìí fún wa, òun ni ó sì pa wá mọ́, òun ni ó sì fi ẹgbẹ́ ogun ti ó dìde sí wa lé wa lọ́wọ́.
David pak řekl: Nečiňte tak, bratří moji, s tím, což nám dal Hospodin, kterýž nás ostříhal a dal vojsko, jenž vytáhlo proti nám, v ruku naši.
24 Ta ni yóò gbọ́ tiyín nínú ọ̀ràn yìí? Ṣùgbọ́n bi ìpín ẹni tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ si ìjà ti rí, bẹ́ẹ̀ ni ìpín ẹni ti ó dúró ti ẹrù; wọn ó sì pín in bákan náà.”
A kdož vás uposlechne v té věci? Nebo jakýž bude díl toho, kterýž vyšel k bitvě, takovýž bude díl i toho, kterýž hlídal břemen; rovně se děliti budou.
25 Láti ọjọ́ náà lọ, ó sì pàṣẹ, ó sì sọ ọ di òfin fún Israẹli títí di òní yìí.
A tak bývalo od toho dne i potom, nebo to za právo a obyčej uložil v Izraeli až do tohoto dne.
26 Dafidi sì padà sí Siklagi, ó sì rán nínú ìkógun náà si àwọn àgbàgbà Juda, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ni ẹ̀bùn fún un yín, láti inú ìkógun àwọn ọ̀tá Olúwa wa.”
A když přišel David do Sicelechu, poslal z těch kořistí starším Juda, přátelům svým, řka: Teď máte dar z loupeží nepřátel Hospodinových.
27 Ó sì rán an sí àwọn tí ó wà ni Beteli àti sí àwọn tí ó wà ní gúúsù tí Ramoti, àti sí àwọn tí ó wà ní Jattiri.
Těm, kteříž byli v Bethel, a kteříž v Rámat ku poledni, a kteříž byli v Jeter;
28 Àti sí àwọn tí ó wà ní Aroeri, àti sí àwọn tí ó wà ní Sifimoti, àti sí àwọn tí ó wà ni Eṣitemoa.
Též kteříž v Aroer, a kteříž v Sefama, a kteříž v Estemo;
29 Àti si àwọn tí ó wà ni Rakeli, àti sí àwọn tí ó wà ní ìlú àwọn Jerahmeeli, àti sí àwọn tí ó wà ni ìlú àwọn ará Keni,
A kteříž v Rachal, a kteříž v městech Jerachmeelových, a kteříž v městech Cinejského;
30 àti sí àwọn tí ó wà ni Horma, àti sí àwọn ti ó wà ní Bori-Aṣani, àti sí àwọn tí ó wà ni Ataki.
I těm, kteříž v Horma, a kteříž v Korasan, a kteříž v Atach;
31 Àti àwọn tí ó wà ni Hebroni, àti sí gbogbo àwọn ìlú ti Dafidi tìkára rẹ̀ àti tí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ máa ń rìn ká.
A kteříž byli v Hebronu, i po všech místech, na nichž býval David s lidem svým.