< 1 Samuel 30 >

1 Ó sì ṣe nígbà ti Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì bọ̀ sí Siklagi ní ọjọ́ kẹta, àwọn ará Amaleki sì ti kọlu ìhà gúúsù, àti Siklagi, wọ́n sì ti kùn ún ní iná.
David neh a hlang rhoek loh a thum hnin ah Ziklag a pha uh. Te vaengah Amalek loh tuithim neh Ziklag ah cu uh. Te phoeiah Ziklag te a tloek uh tih hmai neh a hoeh uh.
2 Wọ́n sì kó àwọn obìnrin tí ń bẹ nínú rẹ̀ ní ìgbèkùn, wọn kò sì pa ẹnìkan, ọmọdé tàbí àgbà, ṣùgbọ́n wọ́n kó wọn lọ, wọ́n sì bá ọ̀nà tiwọn lọ.
Te vaengah a khuikah huta rhoek te tanoe kangham la a sol uh. Hlang tah a duek sak muehla a vai uh tih a longpuei ah cet uh.
3 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin sì wọ ìlú Siklagi, sì wò ó, a ti kùn ún ni iná; àti obìnrin wọn, àti ọmọkùnrin wọn àti ọmọbìnrin wọn ni a kó ni ìgbèkùn lọ.
Tedae David neh a hlang rhoek te khopuei la ha pawk uh vaengah hmai ah tarha ana hoeh tih a yuu a canu neh a oila te ana sol pa uh.
4 Dafidi àti àwọn ènìyàn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún títí agbára kò fi sí fún wọn mọ́ láti sọkún.
Te dongah David neh amah taengkah pilnam loh a ol a huel tih rhap uh. Te vaengah a khuikah thadueng a bawt hil rhap uh.
5 A sì kó àwọn aya Dafidi méjèèjì nígbèkùn lọ, Ahinoamu ará Jesreeli àti Abigaili aya Nabali ará Karmeli.
David yuu rhoi Jezreel Ahinoam neh Karmel Nabal yuu Abigail khaw a khuen uh.
6 Dafidi sì banújẹ́ gidigidi, nítorí pé àwọn ènìyàn náà sì ń sọ̀rọ̀ láti sọ ọ́ lókùúta, nítorí ti inú gbogbo àwọn ènìyàn náà sì bàjẹ́, olúkúlùkù ọkùnrin nítorí ọmọ rẹ̀ ọkùnrin, àti nítorí ọmọ rẹ̀ obìnrin ṣùgbọ́n Dafidi mú ara rẹ̀ lọ́kàn le nínú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀.
Pilnam pum loh amah ca amah ca ham neh a tanu rhoek ham a hinglu te rhip a phaep uh. Te dongah amah te dae ham te pilnam loh a thui coeng dongah David loh puen a cak tangkik. Tedae David tah BOEIPA a Pathen dongah ni a pangtung.
7 Dafidi sì wí fún Abiatari àlùfáà, ọmọ Ahimeleki pé, èmí bẹ̀ ọ́, mú efodu fún mi wá níhìn-ín yìí. Abiatari sì mú efodu náà wá fún Dafidi.
Te phoeiah David loh Ahimelek capa, khosoih Abiathar taengah, “Hnisui te kai taengla hang khuen dae,” a ti nah tih Abiathar loh hnisui te David taengla a khuen pah.
8 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa wí pé, “Kí èmi ó lépa ogun yìí bi? Èmi lè bá wọn?” Ó sì dá a lóhùn pé, “Lépa, nítorí pé ni bíbá ìwọ yóò bá wọn, ni gbígbà ìwọ yóò sì rí wọn gbà.”
David loh BOEIPA te a dawt tih, “Caem hnukah he ka hloem koinih ka kae aya?” a ti nah hatah, “Hloem, na kae rhoe na kae vetih na huul rhoe na huul bitni,” a ti nah.
9 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti ẹgbẹ̀ta ọmọkùnrin tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wá sí ibi àfonífojì Besori, apá kan sì dúró.
Te dongah David neh amah taengkah hlang ya rhuk loh cet uh. Tedae Besor soklong a pha uh vaengah aka coih rhoek loh uelh uh.
10 Ṣùgbọ́n Dafidi àti irinwó ọmọkùnrin lépa wọn: igba ènìyàn tí àárẹ̀ mú, tiwọn kò lè kọjá odò Besori sì dúró lẹ́yìn.
Te dongah David amah neh hlang ya li loh a hloem uh dae Besor soklong a poeng uh lamkah aka tawn hlang yahnih tah paa uh.
11 Wọ́n sì rí ará Ejibiti kan ní oko, wọ́n sì mú un tọ Dafidi wá, wọ́n sì fún un ní oúnjẹ, ó sì jẹ; wọ́n sì fún un ní omi mu.
Te vaengah lohma li ah Egypt hlang te a hmuh uh tih David taengla a khuen uh. Te phoeiah anih te buh a paek uh tih a caak phoeiah tui a tul uh.
12 Wọ́n sì fún un ní àkàrà, èso ọ̀pọ̀tọ́ àti síírí àjàrà gbígbẹ́ méjì: nígbà tí ó sì jẹ ẹ́ tán, ẹ̀mí rẹ̀ sì sọjí: nítorí pé kò jẹ oúnjẹ, bẹ́ẹ̀ ni kò sì mu omi ní ọjọ́ mẹ́ta ní ọ̀sán, àti ní òru.
Te phoeiah anih te thaidae phaklung pakhat neh misur rhae panit a paek uh. Anih te khothaih hnin thum neh khoyin hnin thum buh ca pawt tih tui a ok pawt dongah tekah te a caak daengah ni anih te a hil a sang pueng.
13 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ọmọ ta ni ìwọ? Àti níbo ni ìwọ ti wá?” Òun sì wí pé, “Ọmọ ará Ejibiti ni èmi, ọmọ ọ̀dọ̀ ọkùnrin kan ará Amaleki. Olúwa mi fi mí sílẹ̀, nítorí pé láti ọjọ́ mẹ́ta ni èmi ti ṣe àìsàn.
Anih te David loh, “Nang ulae? Nang me lamkah lae?” a ti nah vaengah, “Kai tah Amalek hlang kah sal, Egypt ca dae ni, hnin thum ka tloh dongah ka boei loh n'hnoo.
14 Àwa sì gbé ogun lọ sí ìhà gúúsù tí ará Kereti, àti sí ìhà ti Juda, àti sí ìhà gúúsù ti Kalebu; àwa sì kun Siklagi ní iná.”
Kaimih loh Kerethi tuithim, Judah neh Kaleb tuithim te ka muk uh tih Ziklag te hmai neh ka hoeh uh,” a ti nah.
15 Dafidi sì bi í léèrè pé, “Ìwọ lè mú mí sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun yìí lọ bí?” Òun sì wí pé, “Fi Ọlọ́run búra fún mi pé, ìwọ kì yóò pa mí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò sì fi mi lé olúwa mi lọ́wọ́; èmi yóò sì mú ọ sọ̀kalẹ̀ tọ ẹgbẹ́ ogun náà lọ.”
Te dongah anih te David loh, “Tekah caem taengla kai nan suntlak puei aya?” a ti nah. Te vaengah, “Kai nan duek sak ham neh ka boeipa kut ah kai nan det pawt ham mah, Pathen taengah kai hamla toemngam lamtah nang te caem taengla kan suntlak puei bitni,” a ti nah.
16 Ó sì mú un sọ̀kalẹ̀, sì wò ó, wọ́n sì tàn ká ilẹ̀, wọ́n ń jẹ, wọ́n ń mu, wọ́n sì ń jó, nítorí ìkógun púpọ̀ tí wọ́n kó láti ilẹ̀ àwọn Filistini wá, àti láti ilẹ̀ Juda.
Tedae anih a suntlak vaengah tah Philisti kho lamkah neh Judah kho lamkah kutbuem boeih te muep a loh uh coeng dongah diklai hman boeih ah aka ca, aka o neh aka lam rhoek te khawk ana yaal uh.
17 Dafidi sì pa wọ́n láti àfẹ̀mọ́júmọ́ títí ó fi di àṣálẹ́ ọjọ́ kejì: kò sí ẹnìkan tí ó là nínú wọn, bí kọ̀ ṣe irinwó ọmọkùnrin tí wọ́n gun ìbákasẹ tí wọ́n sì sá.
Amih te David loh hlaemhmah lamloh a vuen kholaeh duela a ngawn. Te dongah amih lamkah hlang tah loeih pawh. Kalauk dongah aka ngol camoe hlang ya li bueng rhaelrham uh.
18 Dafidi sì gbà gbogbo nǹkan tí àwọn ará Amaleki ti kó: Dafidi sì gba àwọn obìnrin rẹ̀ méjèèjì.
Te daengah Amalek kah a loh rhoek te David loh boeih a lat tih a yuu rhoi te khaw David loh a lat.
19 Kò sì ṣí nǹkan tí ó kù fún wọn, kékeré tàbí ńlá, ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin, tàbí ìkógun, tàbí gbogbo nǹkan tí wọ́n ti kó: Dafidi sì gba gbogbo wọn.
Te vaengah amih te tanoe kangham, capa, canu khaw kutbuem khaw a hmaai moenih. Amih lamkah a loh uh boeih te David loh boeih a mael puei.
20 Dafidi sì kó gbogbo àgùntàn, àti màlúù tí àwọn ènìyàn rẹ̀ dà ṣáájú àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn tí wọ́n gbà, wọ́n sì wí pé, “Èyí yìí ni ìkógun ti Dafidi.”
Te vaengah David loh boiva neh saelhung te boeih a loh tih a hmai la a vai uh. Te vaengah, “Boiva he David kah kutbuem ni he,” a ti uh.
21 Dafidi sì wá sọ́dọ̀ igba ọkùnrin tí àárẹ̀ ti mú jú, tiwọn kò lè tọ́ Dafidi lẹ́yìn mọ́, ti òun ti fi sílẹ̀, ni àfonífojì Besori: wọ́n sì lọ pàdé Dafidi, àti láti pàdé àwọn ènìyàn tí ó lọ pẹ̀lú rẹ̀: Dafidi sì pàdé àwọn ènìyàn náà, ó sì kí wọn.
Te vaengah David taengla hlang yahnih ha pawk tih a tawn doela David hnuk ah cet uh. Amih tah Besor soklong ah a om sak tih David doe ham neh anih taengkah pilnam te doe hamla ha pawk uh. Te dongah David te pilnam taengla thoeih tih amih te sading la a voek.
22 Gbogbo àwọn ènìyàn búburú àti àwọn ọmọ Beliali nínú àwọn tí o bá Dafidi lọ sì dáhùn, wọ́n sì wí pé, “Bí wọn kò ti bá wa lọ, àwa ki yóò fi nǹkan kan fún wọn nínú ìkógun ti àwa rí gbà bí kò ṣe obìnrin olúkúlùkù wọn, àti ọmọ wọn; ki wọn sì mú wọn, ki wọn sì máa lọ.”
Tedae David hnuk aka vai hlang rhoek khuikah boethae neh aka muen hlang boeih loh a doo uh vaengah, “Kai taengah aka pongpa pawt tah kutbuem n'lat he amih taengla pae boel saeh. A yuu a ca rhoek te tah rhip hmaithawn uh saeh lamtah cet uh saeh,” a ti uh.
23 Dafidi sì wí pé, “Ẹ má ṣe bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin ara mi: Olúwa ni ó fi nǹkan yìí fún wa, òun ni ó sì pa wá mọ́, òun ni ó sì fi ẹgbẹ́ ogun ti ó dìde sí wa lé wa lọ́wọ́.
Tedae David loh, “Ka manuca rhoek, te tlam te saii uh boeh. BOEIPA loh mamih taengla m'paek coeng te tah mamih loh ngaithuen sih. Te dongah ni mamih aka cuuk thil caem te mamih kut ah m'paek.
24 Ta ni yóò gbọ́ tiyín nínú ọ̀ràn yìí? Ṣùgbọ́n bi ìpín ẹni tí ó sọ̀kalẹ̀ lọ si ìjà ti rí, bẹ́ẹ̀ ni ìpín ẹni ti ó dúró ti ẹrù; wọn ó sì pín in bákan náà.”
Caemtloek la aka suntla rhoek kah hamsum la na ti ol te u long a hnatun eh? Te dongah hnopai taengah aka om rhoek khaw hamsum la yen tael uh thae saeh,” a ti nah.
25 Láti ọjọ́ náà lọ, ó sì pàṣẹ, ó sì sọ ọ di òfin fún Israẹli títí di òní yìí.
Te dongah te khohnin lamkah a so hang ah tah tekah ol te oltlueh neh laitloeknah la a saii tih tihnin due Israel ham a om pah.
26 Dafidi sì padà sí Siklagi, ó sì rán nínú ìkógun náà si àwọn àgbàgbà Juda, àti sí àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ni ẹ̀bùn fún un yín, láti inú ìkógun àwọn ọ̀tá Olúwa wa.”
David te Ziklag la a pha vaengah kutbuem te Judah kah a hamca rhoek taeng neh a hui rhoek taengla a pat tih, “BOEIPA thunkha rhoek kah kutbuem khui lamkah nangmih ham yoethennah ni he ne,” a ti nah.
27 Ó sì rán an sí àwọn tí ó wà ni Beteli àti sí àwọn tí ó wà ní gúúsù tí Ramoti, àti sí àwọn tí ó wà ní Jattiri.
Te rhoek te Bethel ah, tuithim Ramoth neh Jattir ah,
28 Àti sí àwọn tí ó wà ní Aroeri, àti sí àwọn tí ó wà ní Sifimoti, àti sí àwọn tí ó wà ni Eṣitemoa.
Aroer ah, Siphmoth ah, Eshtmoa ah,
29 Àti si àwọn tí ó wà ni Rakeli, àti sí àwọn tí ó wà ní ìlú àwọn Jerahmeeli, àti sí àwọn tí ó wà ni ìlú àwọn ará Keni,
Rakal ah khaw, Jerahmeli khopuei rhoek ah khaw, Keni kah khopuei rhoek ah khaw,
30 àti sí àwọn tí ó wà ni Horma, àti sí àwọn ti ó wà ní Bori-Aṣani, àti sí àwọn tí ó wà ni Ataki.
Hormah ah khaw, Khorashan ah khaw, Athach ah khaw,
31 Àti àwọn tí ó wà ni Hebroni, àti sí gbogbo àwọn ìlú ti Dafidi tìkára rẹ̀ àti tí àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ máa ń rìn ká.
Hebron neh David amah neh a hlang rhoek kah pongpa nah hmuen boeih taengah a tael.

< 1 Samuel 30 >