< 1 Samuel 3 >

1 Samuẹli ọmọkùnrin náà ṣe òjíṣẹ́ níwájú Olúwa ní abẹ́ Eli. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ọ̀rọ̀ Olúwa ṣọ̀wọ́n: kò sì sí ìran púpọ̀.
A criança Samuel foi ministrada a Yahweh antes de Eli. A palavra de Yahweh era rara naqueles dias. Não havia muitas visões, então.
2 Ní alẹ́ ọjọ́ kan Eli ẹni tí ojú rẹ̀ ti bẹ̀rẹ̀ sí di aláìlágbára, tí kò sì ríran dáradára, ó dùbúlẹ̀ ní ipò rẹ̀ bi ti àtẹ̀yìnwá.
Naquele tempo, quando Eli estava deitado em seu lugar (agora seus olhos tinham começado a escurecer, de modo que ele não podia ver),
3 Nígbà tí iná kò tí ì kú Samuẹli dùbúlẹ̀ nínú tẹmpili Olúwa, níbi tí àpótí Olúwa gbé wà.
e a lâmpada de Deus ainda não tinha se apagado, e Samuel tinha se deitado no templo de Iavé onde estava a arca de Deus,
4 Nígbà náà ni Olúwa pe Samuẹli. Samuẹli sì dáhùn, “Èmi nìyí.”
Iavé chamou Samuel. Ele disse: “Aqui estou eu”.
5 Ó sì sáré lọ sí ọ̀dọ̀ Eli ó sì wí pé, “Èmi nìyí nítorí pé ìwọ pè mí.” Ṣùgbọ́n Eli wí fún un pé, “Èmi kò pè ọ́; padà lọ dùbúlẹ̀.” Nítorí náà ó lọ ó sì lọ dùbúlẹ̀.
Ele correu para Eli e disse: “Aqui estou; pois você me chamou”. Ele disse: “Eu não liguei”. Deite-se novamente”. Ele foi e se deitou.
6 Olúwa sì tún pè é, “Samuẹli!” Samuẹli tún dìde ó tọ Eli lọ, ó sì wí pé, “Èmi nìyìí, nítorí tí ìwọ pè mí.” “Ọmọ mi, èmi kò pè ọ́, padà lọ dùbúlẹ̀.”
Yahweh chamou mais uma vez, “Samuel!” Samuel levantou-se e foi ter com Eli e disse: “Aqui estou; pois você me chamou”. Ele respondeu: “Eu não liguei, meu filho”. Deite-se novamente”.
7 Ní àkókò yìí Samuẹli kò tí ì mọ̀ Olúwa: bẹ́ẹ̀ ni a kò sì tí ì fi ọ̀rọ̀ Olúwa hàn án.
Now Samuel ainda não conhecia Javé, nem a palavra de Javé lhe foi revelada ainda.
8 Olúwa pe Samuẹli ní ìgbà kẹta, Samuẹli sì tún dìde, ó sì lọ sọ́dọ̀ Eli ó sì wí pé, “Èmi nìyìí; nítorí tí ìwọ pè mí.” Nígbà náà ni Eli wá mọ̀ pé Olúwa ni ó ń pe ọmọ náà.
Yahweh ligou novamente para Samuel pela terceira vez. Ele se levantou e foi até Eli e disse: “Aqui estou eu; pois você me chamou”. Eli percebeu que Yahweh havia chamado a criança.
9 Nítorí náà Eli sọ fún Samuẹli, “Lọ kí o lọ dùbúlẹ̀. Tí o bá sì pè ọ́, sọ wí pé, ‘Máa wí, Olúwa nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbọ́.’” Bẹ́ẹ̀ ni Samuẹli lọ, ó sì lọ dùbúlẹ̀ ní ààyè rẹ̀.
Por isso Eli disse a Samuel: “Vai, deita-te”. Será, se ele te chamar, que você dirá: 'Fala, Javé; porque teu servo ouve'”. Então Samuel foi e deitou-se em seu lugar.
10 Olúwa wá, ó sì dúró níbẹ̀, ó pè é bí ó ṣe pè é ní ìgbà tí ó kọjá, “Samuẹli! Samuẹli!” Nígbà náà ni Samuẹli dáhùn pé, “Máa wí nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbọ́.”
Yahweh veio, e ficou de pé, e chamou como em outros tempos: “Samuel! Samuel!”. Então Samuel disse: “Fala; pois teu servo ouve”.
11 Olúwa sọ fún Samuẹli pé, “Wò ó, èmi ṣetán láti ṣe ohun kan ní Israẹli tí yóò jẹ́ kí etí gbogbo ènìyàn tí ó gbọ́ ọ já gooro.
Yahweh disse a Samuel: “Eis que farei em Israel uma coisa em que os ouvidos de todos os que a ouvirem formarão um formigueiro.
12 Ní ìgbà náà ni èmi yóò mú ohun gbogbo tí mo ti sọ sí ilé Eli ṣẹ láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin.
Naquele dia, vou fazer contra Eli tudo o que falei a respeito de sua casa, desde o início até o fim”.
13 Nítorí èmi sọ fún un pé, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ fún ilé rẹ̀ títí láé nítorí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn tí òun mọ̀ nípa rẹ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ sọ ọ̀rọ̀-òdì, òun kò sì dá wọn lẹ́kun.
Pois eu lhe disse que julgarei sua casa para sempre pela iniquidade que ele conhecia, porque seus filhos trouxeram uma maldição sobre si mesmos, e ele não os reprimiu.
14 Nítorí náà, mo búra sí ilé Eli, ‘Ìwà ẹ̀ṣẹ̀ ilé Eli ni a kì yóò fi ẹbọ tàbí ọrẹ mú kúrò láéláé.’”
Portanto, jurei à casa de Eli que a iniqüidade da casa de Eli não será removida com sacrifício ou oferta para sempre”.
15 Samuẹli dùbúlẹ̀ títí di òwúrọ̀ nígbà náà ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ilé Olúwa, ó sì bẹ̀rù láti sọ ìran náà fún Eli.
Samuel ficou deitado até a manhã, e abriu as portas da casa de Yahweh. Samuel tinha medo de mostrar a visão a Eli.
16 Ṣùgbọ́n Eli pè é, ó sì wí pé, “Samuẹli, ọmọ mi.” Samuẹli sì dáhùn pé, “Èmi nìyìí.”
Então Eli chamou Samuel e disse: “Samuel, meu filho!”. Ele disse: “Aqui estou eu”.
17 Eli béèrè pé, “Kín ni ohun tí ó sọ fún ọ?” “Má ṣe fi pamọ́ fún mi. Kí Ọlọ́run mi ṣe bẹ́ẹ̀ sí ọ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí ìwọ bá fi ohunkóhun tí ó wí fún ọ pamọ́ fún mi.”
Ele disse: “O que é que ele lhe disse? Por favor, não o esconda de mim. Deus o faça a você, e mais ainda, se você esconder de mim algo de todas as coisas que Ele falou com você”.
18 Samuẹli sọ gbogbo rẹ̀ fún un, kò sì fi ohun kankan pamọ́ fún un. Nígbà náà Eli wí pé, “Òun ni Olúwa; jẹ́ kí ó ṣe ohun tí ó dára ní ojú rẹ̀.”
Samuel lhe disse tudo, e não escondeu nada dele. Ele disse: “É Yahweh”. Deixe-o fazer o que lhe parece bom”.
19 Olúwa wà pẹ̀lú Samuẹli bí ó ṣe ń dàgbà, kò sì jẹ́ kí ọ̀kan nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀ kùnà.
Samuel cresceu, e Yahweh estava com ele e não deixou que nenhuma de suas palavras caísse no chão.
20 Gbogbo Israẹli láti Dani títí dé Beerṣeba mọ̀ pé a ti fa Samuẹli kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí wòlíì Olúwa.
Todo Israel de Dan até Beersheba sabia que Samuel foi estabelecido para ser um profeta de Javé.
21 Olúwa sì bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ara hàn án ní Ṣilo, nítorí Olúwa ti fi ará hàn án fún Samuẹli ní Ṣilo nípa ọ̀rọ̀ Olúwa.
Yahweh apareceu novamente em Shiloh; pois Yahweh revelou-se a Samuel em Shiloh pela palavra de Yahweh.

< 1 Samuel 3 >