< 1 Samuel 3 >
1 Samuẹli ọmọkùnrin náà ṣe òjíṣẹ́ níwájú Olúwa ní abẹ́ Eli. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ọ̀rọ̀ Olúwa ṣọ̀wọ́n: kò sì sí ìran púpọ̀.
A pacholę Samuel służył Panu przed Heli, a słowo Pańskie było drogie w one dni, bo nie bywało widzenia jawnego.
2 Ní alẹ́ ọjọ́ kan Eli ẹni tí ojú rẹ̀ ti bẹ̀rẹ̀ sí di aláìlágbára, tí kò sì ríran dáradára, ó dùbúlẹ̀ ní ipò rẹ̀ bi ti àtẹ̀yìnwá.
I stało się dnia onego, gdy Heli leżał na miejscu swojem, (a oczy jego już się były poczęły zaciemniać, i nie mógł dojrzeć.)
3 Nígbà tí iná kò tí ì kú Samuẹli dùbúlẹ̀ nínú tẹmpili Olúwa, níbi tí àpótí Olúwa gbé wà.
A lampa Boża jeszcze nie była zagaszona, Samuel też spał w kościele Pańskim, gdzie była skrzynia Boża,
4 Nígbà náà ni Olúwa pe Samuẹli. Samuẹli sì dáhùn, “Èmi nìyí.”
Że zawołał Pan na Samuela, a on się ozwał: Owom ja.
5 Ó sì sáré lọ sí ọ̀dọ̀ Eli ó sì wí pé, “Èmi nìyí nítorí pé ìwọ pè mí.” Ṣùgbọ́n Eli wí fún un pé, “Èmi kò pè ọ́; padà lọ dùbúlẹ̀.” Nítorí náà ó lọ ó sì lọ dùbúlẹ̀.
I przybieżał do Heliego i rzekł: Owom ja, gdyżeś mię wołał. A on rzekł: Nie wołałem, wróć się, śpij; i poszedł a spał.
6 Olúwa sì tún pè é, “Samuẹli!” Samuẹli tún dìde ó tọ Eli lọ, ó sì wí pé, “Èmi nìyìí, nítorí tí ìwọ pè mí.” “Ọmọ mi, èmi kò pè ọ́, padà lọ dùbúlẹ̀.”
Powtóre Pan jeszcze zawołał Samuela; i wstał Samuel, a poszedł do Heliego, i rzekł: Owom ja, gdyżeś mię wołał; któremu on rzekł: nie wołałem, synu mój, wróć się a śpij.
7 Ní àkókò yìí Samuẹli kò tí ì mọ̀ Olúwa: bẹ́ẹ̀ ni a kò sì tí ì fi ọ̀rọ̀ Olúwa hàn án.
A Samuel jeszcze nie znał Pana, i jeszcze mu nie było objawione słowo Pańskie.
8 Olúwa pe Samuẹli ní ìgbà kẹta, Samuẹli sì tún dìde, ó sì lọ sọ́dọ̀ Eli ó sì wí pé, “Èmi nìyìí; nítorí tí ìwọ pè mí.” Nígbà náà ni Eli wá mọ̀ pé Olúwa ni ó ń pe ọmọ náà.
Nadto jeszcze Pan zawołał Samuela po trzecie; a on wstawszy szedł do Heliego i rzekł: Owom ja, gdyżeś mię wołał. Tedy zrozumiał Heli, że Pan wołał pacholęcia.
9 Nítorí náà Eli sọ fún Samuẹli, “Lọ kí o lọ dùbúlẹ̀. Tí o bá sì pè ọ́, sọ wí pé, ‘Máa wí, Olúwa nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbọ́.’” Bẹ́ẹ̀ ni Samuẹli lọ, ó sì lọ dùbúlẹ̀ ní ààyè rẹ̀.
I rzekł Heli do Samuela: Idź, śpij, a jeźli cię kto zawoła, rzeczesz: Mów Panie, bo słyszy sługa twój. A tak Samuel szedł i spał na miejscu swojem.
10 Olúwa wá, ó sì dúró níbẹ̀, ó pè é bí ó ṣe pè é ní ìgbà tí ó kọjá, “Samuẹli! Samuẹli!” Nígbà náà ni Samuẹli dáhùn pé, “Máa wí nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbọ́.”
Potem przyszedł Pan, i stanął a zawołał jako i pierwszy i drugi raz: Samuelu, Samuelu! I rzekł Samuel: Mów Panie, bo sługa twój słucha.
11 Olúwa sọ fún Samuẹli pé, “Wò ó, èmi ṣetán láti ṣe ohun kan ní Israẹli tí yóò jẹ́ kí etí gbogbo ènìyàn tí ó gbọ́ ọ já gooro.
Tedy rzekł Pan do Samuela: Oto, Ja uczynię rzecz w Izraelu, którą ktokolwiek usłyszy, zabrzmi mu w obu uszach jego.
12 Ní ìgbà náà ni èmi yóò mú ohun gbogbo tí mo ti sọ sí ilé Eli ṣẹ láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin.
Dnia onego wzbudzę przeciw Heliemu wszystko, com mówił przeciwko domowi jego; pocznę i dokonam.
13 Nítorí èmi sọ fún un pé, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ fún ilé rẹ̀ títí láé nítorí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn tí òun mọ̀ nípa rẹ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ sọ ọ̀rọ̀-òdì, òun kò sì dá wọn lẹ́kun.
I okażę mu, iż Ja sądzę dom jego aż na wieki dla nieprawości, o której wiedział; bo wiedząc, że na się przekleństwo przywodzili synowie jego, wszakże nie bronił im tego.
14 Nítorí náà, mo búra sí ilé Eli, ‘Ìwà ẹ̀ṣẹ̀ ilé Eli ni a kì yóò fi ẹbọ tàbí ọrẹ mú kúrò láéláé.’”
A przetoż przysiągłem domowi Heli, że nie będzie oczyszczona nieprawość domu Heliego żadną ofiarą, ani ofiarą śniedną, aż na wieki.
15 Samuẹli dùbúlẹ̀ títí di òwúrọ̀ nígbà náà ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ilé Olúwa, ó sì bẹ̀rù láti sọ ìran náà fún Eli.
I spał Samuel aż do poranku, i otworzył drzwi domu Pańskiego. A Samuel bał się oznajmić widzenia tego Heliemu.
16 Ṣùgbọ́n Eli pè é, ó sì wí pé, “Samuẹli, ọmọ mi.” Samuẹli sì dáhùn pé, “Èmi nìyìí.”
Tedy zawołał Heli Samuela, i rzekł: Samuelu, synu mój; który odpowiedział: Otom ja.
17 Eli béèrè pé, “Kín ni ohun tí ó sọ fún ọ?” “Má ṣe fi pamọ́ fún mi. Kí Ọlọ́run mi ṣe bẹ́ẹ̀ sí ọ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí ìwọ bá fi ohunkóhun tí ó wí fún ọ pamọ́ fún mi.”
I rzekł: Cóż to za słowa, któreć Pan powiedział? proszę nie taj przedemną; to a toć Bóg niechaj uczyni, jeźliże co zataisz przedemną ze wszystkich słów, które mówił do ciebie.
18 Samuẹli sọ gbogbo rẹ̀ fún un, kò sì fi ohun kankan pamọ́ fún un. Nígbà náà Eli wí pé, “Òun ni Olúwa; jẹ́ kí ó ṣe ohun tí ó dára ní ojú rẹ̀.”
I oznajmił mu Samuel wszystkie słowa, a nie zataił nic przed nim. A on rzekł: Pan jest; co dobrego w oczach jego, niech czyni.
19 Olúwa wà pẹ̀lú Samuẹli bí ó ṣe ń dàgbà, kò sì jẹ́ kí ọ̀kan nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀ kùnà.
I rósł Samuel, a Pan był z nim, i nie dopuścił upaść żadnemu ze wszystkich sług jego na ziemię.
20 Gbogbo Israẹli láti Dani títí dé Beerṣeba mọ̀ pé a ti fa Samuẹli kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí wòlíì Olúwa.
Poznał tedy wszystek Izrael od Dan aż do Beerseba, iż Samuel był wiernym prorokiem Panu.
21 Olúwa sì bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ara hàn án ní Ṣilo, nítorí Olúwa ti fi ará hàn án fún Samuẹli ní Ṣilo nípa ọ̀rọ̀ Olúwa.
Bo i napotem ukazywał się Pan Samuelowi w Sylo, tak jako mu się przedtem objawił Pan w Sylo przez słowo swoje.