< 1 Samuel 3 >

1 Samuẹli ọmọkùnrin náà ṣe òjíṣẹ́ níwájú Olúwa ní abẹ́ Eli. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ọ̀rọ̀ Olúwa ṣọ̀wọ́n: kò sì sí ìran púpọ̀.
O SAMUELA, ke keiki, lawelawe aku la ia na Iehova imua o Eli. Kakaikahi ka olelo a Iehova ia manawa: aole he hoikeia'na i laha.
2 Ní alẹ́ ọjọ́ kan Eli ẹni tí ojú rẹ̀ ti bẹ̀rẹ̀ sí di aláìlágbára, tí kò sì ríran dáradára, ó dùbúlẹ̀ ní ipò rẹ̀ bi ti àtẹ̀yìnwá.
A ia mau la, ia Eli i moe ilalo ma kona wahi, ua powehiwehi kona maka, aole ia i ike;
3 Nígbà tí iná kò tí ì kú Samuẹli dùbúlẹ̀ nínú tẹmpili Olúwa, níbi tí àpótí Olúwa gbé wà.
Mamua o ke pio ana o ke kukui o ke Akua ma ka halelewa o Iehova, kahi i waiho ai ka pahu o ke Akua, a ua moe iho o Samuela;
4 Nígbà náà ni Olúwa pe Samuẹli. Samuẹli sì dáhùn, “Èmi nìyí.”
Hea mai la o Iehova ia Samuela, i aku la ia, Eia no wau.
5 Ó sì sáré lọ sí ọ̀dọ̀ Eli ó sì wí pé, “Èmi nìyí nítorí pé ìwọ pè mí.” Ṣùgbọ́n Eli wí fún un pé, “Èmi kò pè ọ́; padà lọ dùbúlẹ̀.” Nítorí náà ó lọ ó sì lọ dùbúlẹ̀.
A holo aku la ia io Eli la, i aku la, Eia no wau, no ka mea, ua kahea mai oe ia'u. I mai la ia, Aole au i kahea aku; e moe hou oe. A hele aku la ia, a moe iho la.
6 Olúwa sì tún pè é, “Samuẹli!” Samuẹli tún dìde ó tọ Eli lọ, ó sì wí pé, “Èmi nìyìí, nítorí tí ìwọ pè mí.” “Ọmọ mi, èmi kò pè ọ́, padà lọ dùbúlẹ̀.”
Kahea hou mai la o Iehova, E Samuela. A ala mai o Samuela, a hele io Eli la, i aku la, Eia no wau; no ka mea, ua kahea mai oe ia'u. I mai la ia, Aole au i kahea aku, e kuu keiki; e moe hou oe.
7 Ní àkókò yìí Samuẹli kò tí ì mọ̀ Olúwa: bẹ́ẹ̀ ni a kò sì tí ì fi ọ̀rọ̀ Olúwa hàn án.
A o Samuela, aole ia i ike ia Iehova ia wa, aole hoi i hoikeia ka olelo a Iehova ia ia.
8 Olúwa pe Samuẹli ní ìgbà kẹta, Samuẹli sì tún dìde, ó sì lọ sọ́dọ̀ Eli ó sì wí pé, “Èmi nìyìí; nítorí tí ìwọ pè mí.” Nígbà náà ni Eli wá mọ̀ pé Olúwa ni ó ń pe ọmọ náà.
Kahea hou mai la o Iehova ia Samuela, o ke kolu keia. Ala mai la ia, a hele aku la io Eli la, i aku la; Eia no wau; no ka mea, ua kahea mai oe ia'u. A ike iho la o Eli, ua kahea mai o Iehova i ke keiki.
9 Nítorí náà Eli sọ fún Samuẹli, “Lọ kí o lọ dùbúlẹ̀. Tí o bá sì pè ọ́, sọ wí pé, ‘Máa wí, Olúwa nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbọ́.’” Bẹ́ẹ̀ ni Samuẹli lọ, ó sì lọ dùbúlẹ̀ ní ààyè rẹ̀.
No ia mea, olelo aku la o Eli ia Samuela, O hoi oe e moe; a i kahea hou mai oia ia oe, e i aku oe, E Iehova, e olelo mai, no ka mea, ua lohe kau kauwa. A hoi aku la o Samuela, a moe iho la ma kona wahi.
10 Olúwa wá, ó sì dúró níbẹ̀, ó pè é bí ó ṣe pè é ní ìgbà tí ó kọjá, “Samuẹli! Samuẹli!” Nígbà náà ni Samuẹli dáhùn pé, “Máa wí nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbọ́.”
Hele mai la o Iehova, a hoike ia ia iho, a kahea mai la e like me na manawa mamua, E Samuela, e Samuela. I aku la o Samuela, E olelo mai, no ka mea, ua lohe kau kauwa.
11 Olúwa sọ fún Samuẹli pé, “Wò ó, èmi ṣetán láti ṣe ohun kan ní Israẹli tí yóò jẹ́ kí etí gbogbo ènìyàn tí ó gbọ́ ọ já gooro.
Olelo mai la o Iehova ia Samuela, Aia hoi, e hana auanei au i kekahi mea iloko o ka Iseraela, i mea e kani ai na pepeiao elua o na mea a pau i lohe.
12 Ní ìgbà náà ni èmi yóò mú ohun gbogbo tí mo ti sọ sí ilé Eli ṣẹ láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin.
Ia la no hooko aku au maluna o Eli i na mea a pau a'u i olelo ai no kona hale, o ka hoomaka ana, a me ka hoopau ana.
13 Nítorí èmi sọ fún un pé, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ fún ilé rẹ̀ títí láé nítorí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn tí òun mọ̀ nípa rẹ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ sọ ọ̀rọ̀-òdì, òun kò sì dá wọn lẹ́kun.
Ua hai aku au ia ia, e hoohewa mau loa ana au i kona hale, no ka hewa ana i ike ai: no ka mea, na kana mau keiki i lawe mai ai ka hewa maluna o laua iho, aole ia i kaohi aku ia laua.
14 Nítorí náà, mo búra sí ilé Eli, ‘Ìwà ẹ̀ṣẹ̀ ilé Eli ni a kì yóò fi ẹbọ tàbí ọrẹ mú kúrò láéláé.’”
No ia mea, ua hoohiki aku au no ko ka hale o Eli, aole e kalaia ka hewa o ko ka hale o Eli i ka mohai a i ka alana i ka manawa a pau.
15 Samuẹli dùbúlẹ̀ títí di òwúrọ̀ nígbà náà ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ilé Olúwa, ó sì bẹ̀rù láti sọ ìran náà fún Eli.
Moe iho la o Samuela a kakahiaka, a wehe ae la ia i na puka o ka hale o Iehova; a makau ino la o Samuela e hai aku ia Eli i ka mea i ikeia.
16 Ṣùgbọ́n Eli pè é, ó sì wí pé, “Samuẹli, ọmọ mi.” Samuẹli sì dáhùn pé, “Èmi nìyìí.”
Kahea aku la o Eli ia Samuela, i aku la, E Samuela, e kuu keiki. I mai la ia, Eia no wau.
17 Eli béèrè pé, “Kín ni ohun tí ó sọ fún ọ?” “Má ṣe fi pamọ́ fún mi. Kí Ọlọ́run mi ṣe bẹ́ẹ̀ sí ọ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí ìwọ bá fi ohunkóhun tí ó wí fún ọ pamọ́ fún mi.”
Ninau aku la ia, Heaha ka mea a Iehova i olelo mai ai ia oe? Ke noi aku nei au ia oe, mai huna ia'u; pela ke Akua e hana mai ai ia oe, a e haawi hou mai hoi, ke huna oe ia'u i kekahi o ka olelo a pau ana i olelo mai ai ia oe.
18 Samuẹli sọ gbogbo rẹ̀ fún un, kò sì fi ohun kankan pamọ́ fún un. Nígbà náà Eli wí pé, “Òun ni Olúwa; jẹ́ kí ó ṣe ohun tí ó dára ní ojú rẹ̀.”
Hai aku la o Samuela ia ia i na olelo a pau, aole i huna ia ia. I mai la ia, Oia no o Iehova; e hana mai ia i kana mea i makemake ai.
19 Olúwa wà pẹ̀lú Samuẹli bí ó ṣe ń dàgbà, kò sì jẹ́ kí ọ̀kan nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀ kùnà.
A nui ae la o Samuela, a me ia pu no o Iehova, aole loa ana olelo i hooko ole ia mai e ia.
20 Gbogbo Israẹli láti Dani títí dé Beerṣeba mọ̀ pé a ti fa Samuẹli kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí wòlíì Olúwa.
A ike ka Iseraela a pau, mai Dana a hiki i Beereseba, ua hookupaaia o Samuela i kaula no Iehova.
21 Olúwa sì bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ara hàn án ní Ṣilo, nítorí Olúwa ti fi ará hàn án fún Samuẹli ní Ṣilo nípa ọ̀rọ̀ Olúwa.
A hoike hou ia mai la o Iehova ma Silo: no ka mea, hoike mai la o Iehova ia ia iho ia Samuela ma Silo ma ka olelo a Iehova.

< 1 Samuel 3 >