< 1 Samuel 3 >

1 Samuẹli ọmọkùnrin náà ṣe òjíṣẹ́ níwájú Olúwa ní abẹ́ Eli. Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì ọ̀rọ̀ Olúwa ṣọ̀wọ́n: kò sì sí ìran púpọ̀.
Forsothe the child Samuel `mynystride to the Lord bifor Heli, and the word of the Lord was preciouse; in tho daies was noon opyn reuelacioun.
2 Ní alẹ́ ọjọ́ kan Eli ẹni tí ojú rẹ̀ ti bẹ̀rẹ̀ sí di aláìlágbára, tí kò sì ríran dáradára, ó dùbúlẹ̀ ní ipò rẹ̀ bi ti àtẹ̀yìnwá.
Therfor it was doon in a dai, Heli lay in his bed, and hise iyen dasewiden, and he myyte not se the lanterne of God, bifor that it was quenchid.
3 Nígbà tí iná kò tí ì kú Samuẹli dùbúlẹ̀ nínú tẹmpili Olúwa, níbi tí àpótí Olúwa gbé wà.
Forsothe Samuel slepte in the temple of the Lord, where the ark of God was.
4 Nígbà náà ni Olúwa pe Samuẹli. Samuẹli sì dáhùn, “Èmi nìyí.”
And the Lord clepide Samuel; and he answeride and seide, Lo!
5 Ó sì sáré lọ sí ọ̀dọ̀ Eli ó sì wí pé, “Èmi nìyí nítorí pé ìwọ pè mí.” Ṣùgbọ́n Eli wí fún un pé, “Èmi kò pè ọ́; padà lọ dùbúlẹ̀.” Nítorí náà ó lọ ó sì lọ dùbúlẹ̀.
Y. And he ran to Hely, and seide to hym, Lo! Y; for thou clepidist me. Which Hely seide, Y clepide not thee; turne thou ayen and slepe.
6 Olúwa sì tún pè é, “Samuẹli!” Samuẹli tún dìde ó tọ Eli lọ, ó sì wí pé, “Èmi nìyìí, nítorí tí ìwọ pè mí.” “Ọmọ mi, èmi kò pè ọ́, padà lọ dùbúlẹ̀.”
And he yede and slepte. And the Lord addide eft to clepe Samuel; and Samuel roos, and yede to Hely, and seide, Lo! Y; for thou clepidist me. And Heli answeride, Y clepide not thee, my sone; turne thou ayen and slepe.
7 Ní àkókò yìí Samuẹli kò tí ì mọ̀ Olúwa: bẹ́ẹ̀ ni a kò sì tí ì fi ọ̀rọ̀ Olúwa hàn án.
Forsothe Samuel knew not yit the Lord, nether the `word of the Lord was shewid to hym.
8 Olúwa pe Samuẹli ní ìgbà kẹta, Samuẹli sì tún dìde, ó sì lọ sọ́dọ̀ Eli ó sì wí pé, “Èmi nìyìí; nítorí tí ìwọ pè mí.” Nígbà náà ni Eli wá mọ̀ pé Olúwa ni ó ń pe ọmọ náà.
And the Lord addide, and clepide yit Samuel the thridde tyme; `which Samuel roos and yede to Heli,
9 Nítorí náà Eli sọ fún Samuẹli, “Lọ kí o lọ dùbúlẹ̀. Tí o bá sì pè ọ́, sọ wí pé, ‘Máa wí, Olúwa nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbọ́.’” Bẹ́ẹ̀ ni Samuẹli lọ, ó sì lọ dùbúlẹ̀ ní ààyè rẹ̀.
and seide, Lo! Y; for thou clepidist me. Therfor Heli vndirstood, that the Lord clepide the child; and Heli seide to Samuel, Go and slepe; and if he clepith thee aftirward, thou schalt seie, Speke thou, Lord, for thi seruaunt herith. Therfor Samuel yede and slepte in his place.
10 Olúwa wá, ó sì dúró níbẹ̀, ó pè é bí ó ṣe pè é ní ìgbà tí ó kọjá, “Samuẹli! Samuẹli!” Nígbà náà ni Samuẹli dáhùn pé, “Máa wí nítorí tí ìránṣẹ́ rẹ ń gbọ́.”
And the Lord cam, and stood, and clepide as he hadde clepid the secunde tyme, Samuel, Samuel. And Samuel seide, Speke thou, Lord, for thi seruaunt herith.
11 Olúwa sọ fún Samuẹli pé, “Wò ó, èmi ṣetán láti ṣe ohun kan ní Israẹli tí yóò jẹ́ kí etí gbogbo ènìyàn tí ó gbọ́ ọ já gooro.
And the Lord seide to Samuel, Lo! Y make a word in Israel, which word who euer schal here, bothe hise eeris schulen rynge.
12 Ní ìgbà náà ni èmi yóò mú ohun gbogbo tí mo ti sọ sí ilé Eli ṣẹ láti ìbẹ̀rẹ̀ dé òpin.
In that dai Y schal reise ayens Heli alle thingis, whiche Y spak on his hows; Y schal bigynne, and Y schal ende.
13 Nítorí èmi sọ fún un pé, Èmi yóò ṣe ìdájọ́ fún ilé rẹ̀ títí láé nítorí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn tí òun mọ̀ nípa rẹ̀ nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ sọ ọ̀rọ̀-òdì, òun kò sì dá wọn lẹ́kun.
For Y biforseide to hym, that Y schulde deme his hows with outen ende for wickidnesse; for he knew, that hise sones diden vnworthili, and he chastiside not hem.
14 Nítorí náà, mo búra sí ilé Eli, ‘Ìwà ẹ̀ṣẹ̀ ilé Eli ni a kì yóò fi ẹbọ tàbí ọrẹ mú kúrò láéláé.’”
Therfor Y swoor to the hows of Heli, that the wickidnesse of his hows schal not be clensid bi sacrifices and yiftis til in to with outen ende.
15 Samuẹli dùbúlẹ̀ títí di òwúrọ̀ nígbà náà ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ilé Olúwa, ó sì bẹ̀rù láti sọ ìran náà fún Eli.
Forsothe Samuel slepte til the morewtid, and he openyde the doris of the hows of the Lord; and Samuel dredde to schewe the reuelacioun to Heli.
16 Ṣùgbọ́n Eli pè é, ó sì wí pé, “Samuẹli, ọmọ mi.” Samuẹli sì dáhùn pé, “Èmi nìyìí.”
Therfor Heli clepide Samuel, and seide, Samuel, my sone. And he answeride and seide, Y am redi.
17 Eli béèrè pé, “Kín ni ohun tí ó sọ fún ọ?” “Má ṣe fi pamọ́ fún mi. Kí Ọlọ́run mi ṣe bẹ́ẹ̀ sí ọ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ pẹ̀lú, bí ìwọ bá fi ohunkóhun tí ó wí fún ọ pamọ́ fún mi.”
And Heli axide hym, What is the word which the Lord spak to thee? Y preye thee, hide thou not fro me; God do to thee `these thingis, and encreesse these thingis, if thou hidist fro me a word of alle wordis that ben seid to thee.
18 Samuẹli sọ gbogbo rẹ̀ fún un, kò sì fi ohun kankan pamọ́ fún un. Nígbà náà Eli wí pé, “Òun ni Olúwa; jẹ́ kí ó ṣe ohun tí ó dára ní ojú rẹ̀.”
And Samuel schewide to hym alle the wordis, and `hidde not fro hym. And Heli answeride, He is the Lord; do he that, that is good in hise iyen.
19 Olúwa wà pẹ̀lú Samuẹli bí ó ṣe ń dàgbà, kò sì jẹ́ kí ọ̀kan nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀ kùnà.
Forsothe Samuel encreeside, and the Lord was with hym, and noon of alle hise wordis felde in to erthe.
20 Gbogbo Israẹli láti Dani títí dé Beerṣeba mọ̀ pé a ti fa Samuẹli kalẹ̀ gẹ́gẹ́ bí wòlíì Olúwa.
And al Israel fro Dan to Bersabee knew, that feithful Samuel was a profete of the Lord.
21 Olúwa sì bẹ̀rẹ̀ sí ní fi ara hàn án ní Ṣilo, nítorí Olúwa ti fi ará hàn án fún Samuẹli ní Ṣilo nípa ọ̀rọ̀ Olúwa.
And the Lord addide `that he schulde appere in Silo, for the Lord was schewid to Samuel in Silo bi the `word of the Lord; and the word of Samuel cam to al Israel.

< 1 Samuel 3 >