< 1 Samuel 28 >

1 Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, àwọn Filistini sì kó àwọn ogun wọn jọ, láti bá Israẹli jà. Akiṣi sì wí fún Dafidi pé, “Mọ̀ dájúdájú pé, ìwọ yóò bá mi jáde lọ sí ibi ìjà, ìwọ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ.”
En ces jours-là, les Philistins rassemblèrent leurs armées pour faire la guerre, afin de combattre Israël. Akish dit à David: « Sache que tu partiras avec moi dans l'armée, toi et tes hommes. »
2 Dafidi sì wí fún Akiṣi pé, “Nítòótọ́ ìwọ ó sì mọ ohun tí ìránṣẹ́ rẹ lè ṣe.” Akiṣi sì wí fún Dafidi pé, “Nítorí náà ni èmi ó ṣe fi ìwọ ṣe olùṣọ́ orí mi ni gbogbo ọjọ́.”
David dit à Akish: « Tu sauras donc ce que ton serviteur peut faire. » Achille dit à David: « Je ferai de toi mon garde du corps pour toujours. »
3 Samuẹli sì ti kú, gbogbo Israẹli sì sọkún rẹ̀, wọ́n sì sin ín ní Rama ní ìlú rẹ̀. Saulu sì ti mú àwọn abókùúsọ̀rọ̀ ọkùnrin, àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀ obìnrin kúrò ní ilẹ̀ náà.
Or Samuel était mort, et tout Israël avait porté son deuil et l'avait enterré à Rama, dans sa propre ville. Saül avait chassé du pays ceux qui avaient des esprits familiers et les sorciers.
4 Àwọn Filistini sì kó ara wọn jọ, wọ́n wá, wọ́n sì dó sí Ṣunemu: Saulu sì kó gbogbo Israẹli jọ, wọ́n sì tẹ̀dó ní Gilboa.
Les Philistins se rassemblèrent, et vinrent camper à Sunem. Saül rassembla tout Israël, et ils campèrent à Guilboa.
5 Nígbà tí Saulu sì rí ogun àwọn Filistini náà òun sì bẹ̀rù, àyà rẹ̀ sì wárìrì gidigidi.
Lorsque Saül vit l'armée des Philistins, il eut peur, et son cœur trembla beaucoup.
6 Nígbà tí Saulu sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, Olúwa kò dá a lóhùn nípa àlá, nípa Urimu tàbí nípa àwọn wòlíì.
Saül consulta Yahvé, et Yahvé ne lui répondit ni par des songes, ni par l'urim, ni par des prophètes.
7 Saulu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ bá mi wá obìnrin kan tí ó ní ẹ̀mí abókùúsọ̀rọ̀ èmi yóò sì tọ̀ ọ́ lọ, èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ̀!” Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Wò ó, obìnrin kan wà ní Endori tí ó ní ẹ̀mí abókùúsọ̀rọ̀.”
Alors Saül dit à ses serviteurs: « Cherche-moi une femme qui a un esprit familier, afin que j'aille la voir et que je la consulte. » Ses serviteurs lui dirent: « Voici une femme qui a un esprit familier à Endor. »
8 Saulu sì pa ara dà, ó sì mú aṣọ mìíràn wọ̀, ó sì lọ, àwọn ọmọkùnrin méjì sì pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ obìnrin náà lóru: òun sì wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, fi ẹ̀mí abókùúsọ̀rọ̀ wo nǹkan fún mi, kí o sì mú ẹni tí èmí ó dárúkọ rẹ̀ fún ọ wá sókè fún mi.”
Saül se déguisa, mit d'autres vêtements et partit, lui et deux hommes avec lui, et ils arrivèrent de nuit chez la femme. Il dit: « Je te prie de consulter pour moi l'esprit familier, et de me faire monter celui que je te nommerai. »
9 Obìnrin náà sì dá a lóhùn pé, “Wò ó, ìwọ sá à mọ ohun tí Saulu ṣe, bí òun ti gé àwọn abókùúsọ̀rọ̀ obìnrin, àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀ ọkùnrin kúrò ní ilẹ̀ náà; ǹjẹ́ èéha ṣe tí ìwọ dẹkùn fún ẹ̀mí mi, láti mú kí wọ́n pa mí.”
La femme lui dit: « Voici, tu sais ce que Saül a fait, comment il a exterminé du pays ceux qui ont des esprits familiers et les sorciers. Pourquoi donc tends-tu un piège à ma vie, pour me faire mourir? »
10 Saulu sì búra fún un nípa Olúwa pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ìyà kan kì yóò jẹ́ ọ́ nítorí nǹkan yìí.”
Saül lui jura par l'Éternel: « L'Éternel est vivant! Tu ne seras pas punie pour cette affaire. »
11 Obìnrin náà sì bi í pé, “Ta ni ẹ̀mí ó mú wá sókè fún ọ?” Òun sì wí pé, “Mú Samuẹli gòkè wá fún mi.”
Alors la femme dit: « Qui dois-je te faire monter? » Il a dit: « Faites monter Samuel pour moi. »
12 Nígbà tí obìnrin náà sì rí Samuẹli, ó kígbe lóhùn rara: obìnrin náà sì bá Saulu sọ̀rọ̀ pè, “Èéṣe tí ìwọ fi tàn mí jẹ? Nítorí pé Saulu ni ìwọ jẹ́.”
Lorsque la femme vit Samuel, elle poussa un grand cri. La femme s'adressa à Saül en disant: « Pourquoi m'as-tu trompée? Car tu es Saül! »
13 Ọba sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù; kín ni ìwọ rí?” Obìnrin náà sì wí fún Saulu pé, “Èmi rí ọlọ́run kan tí ń ti ilẹ̀ wá.”
Le roi lui dit: « N'aie pas peur! Que vois-tu? » La femme dit à Saul: « Je vois un dieu qui sort de la terre. »
14 Ó sì bi í pé, “Báwo ni ó ti rí i sí.” Ó sì wí pé, “Ọkùnrin arúgbó kan ni ó ń bọ; ó sì fi agbádá bora.” Saulu sì mọ̀ pé, Samuẹli ni; ó sì tẹríba, ó sì wólẹ̀.
Il lui dit: « A quoi ressemble-t-il? » Elle dit: « Un vieil homme arrive. Il est couvert d'une robe. » Saül comprit qu'il s'agissait de Samuel, et il s'inclina, le visage contre terre, en signe de respect.
15 Samuẹli sì i wí fún Saulu pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń yọ mí lẹ́nu láti mú mi wá sókè?” Saulu sì dáhùn ó sì wí pé, “Ìpọ́njú ńlá bá mi; nítorí tí àwọn Filistini ń bá mi jagun, Ọlọ́run sì kọ̀ mí sílẹ̀, kò sì dá mi lóhùn mọ́, nípa ọwọ́ àwọn wòlíì, tàbí nípa àlá; nítorí náà ni èmi ṣe pè ọ́, kí ìwọ lè fi ohun tí èmi yóò ṣe hàn mi.”
Samuel dit à Saül: « Pourquoi m'as-tu dérangé, pour me faire monter? » Saül répondit: « Je suis très angoissé, car les Philistins me font la guerre, et Dieu s'est éloigné de moi, il ne me répond plus, ni par des prophètes, ni par des songes. C'est pourquoi je t'ai appelé, afin que tu me fasses connaître ce que je dois faire. »
16 Samuẹli sì wí pé, “Ó ti ṣe ń bi mí léèrè nígbà tí ó jẹ́ pé, Olúwa ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, o sì di ọ̀tá rẹ̀.
Samuel répondit: « Pourquoi donc m'interroges-tu, puisque l'Éternel s'est éloigné de toi et qu'il est devenu ton adversaire?
17 Olúwa sì ṣe fún ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ti ipa ọwọ́ mi sọ: Olúwa sì yá ìjọba náà kúrò ní ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi fún aládùúgbò rẹ́, àní Dafidi.
L'Éternel t'a fait ce qu'il avait dit par moi. Yahvé a arraché le royaume de ta main et l'a donné à ton prochain, à David.
18 Nítorí pé ìwọ kò gbọ́ ohùn Olúwa ìwọ kò sì ṣe iṣẹ́ ìbínú rẹ̀ sí Amaleki nítorí náà ni Olúwa sì ṣe nǹkan yìí sí ọ lónìí yìí.
C'est parce que tu n'as pas écouté la voix de l'Éternel et que tu n'as pas exécuté son ardente colère contre Amalek, que l'Éternel t'a fait cela aujourd'hui.
19 Olúwa yóò sì fi Israẹli pẹ̀lú ìwọ lé àwọn Filistini lọ́wọ́, ní ọ̀la ni ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin yóò pẹ̀lú mi: Olúwa yóò sì fi ogun Israẹli lé àwọn Filistini lọ́wọ́.”
De plus, l'Éternel livrera Israël avec toi entre les mains des Philistins, et demain, toi et tes fils serez avec moi. L'Éternel livrera aussi l'armée d'Israël entre les mains des Philistins. »
20 Lójúkan náà ni Saulu ṣubú lulẹ̀ gbalaja níbí ó ṣe gùn tó, ẹ̀rù sì bà á gidigidi nítorí ọ̀rọ̀ Samuẹli; agbára kò sí fún un; nítorí pé kò jẹun ní ọjọ́ náà tọ̀sán tòru.
Et Saül tomba immédiatement de tout son long sur la terre et fut terrifié, à cause des paroles de Samuel. Il n'avait plus de force en lui, car il n'avait mangé aucun pain de tout le jour ni de toute la nuit.
21 Obìnrin náà sì tọ Saulu wá, ó sì rí i pé ó wà nínú ìbànújẹ́ púpọ̀, ó sì wí fún un pé, “Wò ó, ìránṣẹ́bìnrin rẹ́ ti gbọ́ ohun rẹ̀, èmi sì ti fi ẹ̀mí mi sí ọwọ́ mi, èmi sì ti gbọ́ ọ̀rọ̀ ti ìwọ sọ fún mi.
La femme s'approcha de Saül, vit qu'il était très troublé et lui dit: « Voici que ton serviteur a écouté ta voix, et moi, j'ai mis ma vie en jeu, et j'ai écouté les paroles que tu m'as dites.
22 Ǹjẹ́, nísinsin yìí èmi bẹ̀ ọ́, gbọ́ ohùn ìránṣẹ́bìnrin rẹ, èmi yóò sì fi oúnjẹ díẹ̀ síwájú rẹ̀; sì jẹun, ìwọ yóò sì lágbára, nígbà tí ìwọ bá ń lọ lọ́nà.”
Maintenant, écoute aussi la voix de ton serviteur, et laisse-moi mettre devant toi un morceau de pain. Mange, afin que tu aies des forces pour poursuivre ton chemin. »
23 Ṣùgbọ́n ó kọ̀, ó sì wí pé, “Èmi kì yóò jẹun.” Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rọ̀ ọ́. Ó sì dìde kúrò ni ilẹ̀, ó sì jókòó lórí àkéte.
Mais il refusa, et dit: « Je ne mangerai pas. » Mais ses serviteurs, avec la femme, le contraignirent, et il écouta leur voix. Il se leva de terre et s'assit sur le lit.
24 Obìnrin náà sì ni ẹgbọrọ màlúù kan ti ó sanra ni ilé, ó sì yára, ó pa á, ó sì mú ìyẹ̀fun, ó sì pò ó, ó sì fi ṣe àkàrà àìwú.
La femme avait dans la maison un veau gras. Elle se hâta de l'égorger; elle prit de la farine, la pétrit et en fit des pains sans levain.
25 Ó sì mú un wá síwájú Saulu, àti síwájú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀; wọ́n sì jẹun. Wọ́n sì dìde, wọ́n lọ ní òru náà.
Elle l'apporta devant Saül et devant ses serviteurs, et ils mangèrent. Puis ils se levèrent et partirent cette nuit-là.

< 1 Samuel 28 >