< 1 Samuel 28 >

1 Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, àwọn Filistini sì kó àwọn ogun wọn jọ, láti bá Israẹli jà. Akiṣi sì wí fún Dafidi pé, “Mọ̀ dájúdájú pé, ìwọ yóò bá mi jáde lọ sí ibi ìjà, ìwọ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ.”
I stalo se za dnů těch, že Filistinští sebrali vojska svá k boji, aby bojovali s Izraelem. I řekl Achis Davidovi: Věz nepochybně, že potáhneš se mnou na vojnu, ty i muži tvoji.
2 Dafidi sì wí fún Akiṣi pé, “Nítòótọ́ ìwọ ó sì mọ ohun tí ìránṣẹ́ rẹ lè ṣe.” Akiṣi sì wí fún Dafidi pé, “Nítorí náà ni èmi ó ṣe fi ìwọ ṣe olùṣọ́ orí mi ni gbogbo ọjọ́.”
Odpověděl David Achisovi: Teprv ty poznáš, co učiní služebník tvůj. I řekl Achis Davidovi: Touť příčinou strážným života svého tě ustanovím po všecky dny.
3 Samuẹli sì ti kú, gbogbo Israẹli sì sọkún rẹ̀, wọ́n sì sin ín ní Rama ní ìlú rẹ̀. Saulu sì ti mú àwọn abókùúsọ̀rọ̀ ọkùnrin, àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀ obìnrin kúrò ní ilẹ̀ náà.
(Samuel pak již byl umřel; pročež plakal ho všecken Izrael, a pochovali jej v Ráma, totiž v městě jeho. A Saul byl vyplénil věšťce a hadače z země.)
4 Àwọn Filistini sì kó ara wọn jọ, wọ́n wá, wọ́n sì dó sí Ṣunemu: Saulu sì kó gbogbo Israẹli jọ, wọ́n sì tẹ̀dó ní Gilboa.
Tedy shromáždivše se Filistinští, přitáhli a položili se u Sunem. Shromáždil i Saul všeho Izraele, a položili se v Gelboe.
5 Nígbà tí Saulu sì rí ogun àwọn Filistini náà òun sì bẹ̀rù, àyà rẹ̀ sì wárìrì gidigidi.
Vida pak Saul vojsko Filistinské, bál se, a uleklo se srdce jeho velmi.
6 Nígbà tí Saulu sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, Olúwa kò dá a lóhùn nípa àlá, nípa Urimu tàbí nípa àwọn wòlíì.
I dotazoval se Saul Hospodina, ale Hospodin neodpovídal jemu ani skrze sny, ani skrze urim, ani skrze proroky.
7 Saulu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ bá mi wá obìnrin kan tí ó ní ẹ̀mí abókùúsọ̀rọ̀ èmi yóò sì tọ̀ ọ́ lọ, èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ̀!” Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Wò ó, obìnrin kan wà ní Endori tí ó ní ẹ̀mí abókùúsọ̀rọ̀.”
Protož řekl Saul služebníkům svým: Pohledejte mi ženy mající ducha věštího, i půjdu k ní a poradím se skrze ni. Jemuž odpověděli služebníci jeho: Aj, žena mající ducha věštího v Endor.
8 Saulu sì pa ara dà, ó sì mú aṣọ mìíràn wọ̀, ó sì lọ, àwọn ọmọkùnrin méjì sì pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ obìnrin náà lóru: òun sì wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, fi ẹ̀mí abókùúsọ̀rọ̀ wo nǹkan fún mi, kí o sì mú ẹni tí èmí ó dárúkọ rẹ̀ fún ọ wá sókè fún mi.”
Tedy změniv Saul oděv, oblékl se v roucho jiné, a šel sám a dva muži s ním, a přišli k ženě té v noci. I řekl: Medle hádej mi skrze ducha věštího, a způsob to, ať ke mně vyjde ten, kohož bych jmenoval tobě.
9 Obìnrin náà sì dá a lóhùn pé, “Wò ó, ìwọ sá à mọ ohun tí Saulu ṣe, bí òun ti gé àwọn abókùúsọ̀rọ̀ obìnrin, àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀ ọkùnrin kúrò ní ilẹ̀ náà; ǹjẹ́ èéha ṣe tí ìwọ dẹkùn fún ẹ̀mí mi, láti mú kí wọ́n pa mí.”
Ale žena řekla jemu: Aj, ty víš, co učinil Saul, kterak vyhladil věšťce a hadače z země. Pročež tedy ty pokládáš osídlo duši mé, abys mne o hrdlo připravil?
10 Saulu sì búra fún un nípa Olúwa pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ìyà kan kì yóò jẹ́ ọ́ nítorí nǹkan yìí.”
I přisáhl jí Saul skrze Hospodina, řka: Živť jest Hospodin, že nepřijde na tě trestání pro tu věc.
11 Obìnrin náà sì bi í pé, “Ta ni ẹ̀mí ó mú wá sókè fún ọ?” Òun sì wí pé, “Mú Samuẹli gòkè wá fún mi.”
Tedy řekla žena: Kohožť mám vyvésti? Kterýž řekl: Samuele mi vyveď.
12 Nígbà tí obìnrin náà sì rí Samuẹli, ó kígbe lóhùn rara: obìnrin náà sì bá Saulu sọ̀rọ̀ pè, “Èéṣe tí ìwọ fi tàn mí jẹ? Nítorí pé Saulu ni ìwọ jẹ́.”
A když uzřela žena Samuele, zkřikla hlasem velikým, a řekla žena Saulovi takto: Pročež jsi mne oklamal! Nebo ty jsi Saul.
13 Ọba sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù; kín ni ìwọ rí?” Obìnrin náà sì wí fún Saulu pé, “Èmi rí ọlọ́run kan tí ń ti ilẹ̀ wá.”
I řekl jí král: Neboj se. Což jsi pak viděla? Odpověděla žena Saulovi: Bohy jsem viděla vystupující z země.
14 Ó sì bi í pé, “Báwo ni ó ti rí i sí.” Ó sì wí pé, “Ọkùnrin arúgbó kan ni ó ń bọ; ó sì fi agbádá bora.” Saulu sì mọ̀ pé, Samuẹli ni; ó sì tẹríba, ó sì wólẹ̀.
Řekl jí opět: Jaký jest způsob jeho? Odpověděla jemu: Muž starý vystupuje a jest oděný pláštěm. Tedy srozuměl Saul, že by Samuel byl, a sehnuv se tváří k zemi, poklonil se jemu.
15 Samuẹli sì i wí fún Saulu pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń yọ mí lẹ́nu láti mú mi wá sókè?” Saulu sì dáhùn ó sì wí pé, “Ìpọ́njú ńlá bá mi; nítorí tí àwọn Filistini ń bá mi jagun, Ọlọ́run sì kọ̀ mí sílẹ̀, kò sì dá mi lóhùn mọ́, nípa ọwọ́ àwọn wòlíì, tàbí nípa àlá; nítorí náà ni èmi ṣe pè ọ́, kí ìwọ lè fi ohun tí èmi yóò ṣe hàn mi.”
I řekl Samuel Saulovi: Proč mne nepokojíš, že jsi mne zavolati rozkázal? Odpověděl Saul: Úzkostmi sevřín jsem velice; nebo Filistinští bojují proti mně, a Bůh odstoupil ode mne, a neodpovídá mi více, ani skrze proroky, ani skrze sny. Protož povolal jsem tě, abys mi oznámil, co bych měl činiti.
16 Samuẹli sì wí pé, “Ó ti ṣe ń bi mí léèrè nígbà tí ó jẹ́ pé, Olúwa ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, o sì di ọ̀tá rẹ̀.
I řekl Samuel: Proč tedy se mne dotazuješ, poněvadž Hospodin odstoupil od tebe, a jest s nepřítelem tvým?
17 Olúwa sì ṣe fún ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ti ipa ọwọ́ mi sọ: Olúwa sì yá ìjọba náà kúrò ní ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi fún aládùúgbò rẹ́, àní Dafidi.
Učiniltě zajisté jemu Hospodin, jakož mluvil skrze mne, a odtrhl Hospodin království od ruky tvé, a dal je bližnímu tvému, Davidovi.
18 Nítorí pé ìwọ kò gbọ́ ohùn Olúwa ìwọ kò sì ṣe iṣẹ́ ìbínú rẹ̀ sí Amaleki nítorí náà ni Olúwa sì ṣe nǹkan yìí sí ọ lónìí yìí.
Nebo že jsi neuposlechl hlasu Hospodinova, a nevykonals hněvu prchlivosti jeho nad Amalechem, protož učinil tobě to dnes Hospodin.
19 Olúwa yóò sì fi Israẹli pẹ̀lú ìwọ lé àwọn Filistini lọ́wọ́, ní ọ̀la ni ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin yóò pẹ̀lú mi: Olúwa yóò sì fi ogun Israẹli lé àwọn Filistini lọ́wọ́.”
Nadto vydá Hospodin i Izraele s tebou v ruku Filistinských, a zítra budeš ty i synové tvoji se mnou. I vojska Izraelská vydá Hospodin v ruku Filistinských.
20 Lójúkan náà ni Saulu ṣubú lulẹ̀ gbalaja níbí ó ṣe gùn tó, ẹ̀rù sì bà á gidigidi nítorí ọ̀rọ̀ Samuẹli; agbára kò sí fún un; nítorí pé kò jẹun ní ọjọ́ náà tọ̀sán tòru.
I padl Saul náhle tak, jak dlouhý byl, na zem, nebo se byl ulekl náramně slov Samuelových. K tomu ani síly v něm nebylo, nebo nic nejedl celý ten den a celou tu noc.
21 Obìnrin náà sì tọ Saulu wá, ó sì rí i pé ó wà nínú ìbànújẹ́ púpọ̀, ó sì wí fún un pé, “Wò ó, ìránṣẹ́bìnrin rẹ́ ti gbọ́ ohun rẹ̀, èmi sì ti fi ẹ̀mí mi sí ọwọ́ mi, èmi sì ti gbọ́ ọ̀rọ̀ ti ìwọ sọ fún mi.
Přistoupivši pak ta žena k Saulovi a uzřevši, že jest předěšen náramně, řekla jemu: Aj, uposlechla děvka tvá hlasu tvého, a opovážila jsem se života svého, že jsem uposlechla slov tvých, kteráž jsi mluvil ke mně.
22 Ǹjẹ́, nísinsin yìí èmi bẹ̀ ọ́, gbọ́ ohùn ìránṣẹ́bìnrin rẹ, èmi yóò sì fi oúnjẹ díẹ̀ síwájú rẹ̀; sì jẹun, ìwọ yóò sì lágbára, nígbà tí ìwọ bá ń lọ lọ́nà.”
Nyní tedy uposlechni i ty, prosím, hlasu děvky své, a položím před tebe kousek chleba, abys jedl a posilil se, a tak jíti mohl cestou svou.
23 Ṣùgbọ́n ó kọ̀, ó sì wí pé, “Èmi kì yóò jẹun.” Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rọ̀ ọ́. Ó sì dìde kúrò ni ilẹ̀, ó sì jókòó lórí àkéte.
Kterýž odepřel a řekl: Nebuduť jísti. I přinutili ho služebníci jeho, ano i ta žena, tak že uposlechl hlasu jejich, a vstav s země, sedl na lůžko.
24 Obìnrin náà sì ni ẹgbọrọ màlúù kan ti ó sanra ni ilé, ó sì yára, ó pa á, ó sì mú ìyẹ̀fun, ó sì pò ó, ó sì fi ṣe àkàrà àìwú.
Měla pak ta žena tele tučné v domě, kteréž spěšně zabila, a vzavši mouky, zadělala, a napekla z ní chlebů přesných.
25 Ó sì mú un wá síwájú Saulu, àti síwájú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀; wọ́n sì jẹun. Wọ́n sì dìde, wọ́n lọ ní òru náà.
Potom přinesla před Saule a služebníky jeho, kteříž jedli, a vstavše v touž noc, odešli.

< 1 Samuel 28 >