< 1 Samuel 28 >

1 Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, àwọn Filistini sì kó àwọn ogun wọn jọ, láti bá Israẹli jà. Akiṣi sì wí fún Dafidi pé, “Mọ̀ dájúdájú pé, ìwọ yóò bá mi jáde lọ sí ibi ìjà, ìwọ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ.”
Hate tueng dawk Filistinnaw ni a ransanaw hah Isarelnaw tuk hanelah a pâkhueng. Akhish ni Devit koevah nama hoi na taminaw hah ransanaw koe cei van han tie hah kamcengcalah panuek atipouh.
2 Dafidi sì wí fún Akiṣi pé, “Nítòótọ́ ìwọ ó sì mọ ohun tí ìránṣẹ́ rẹ lè ṣe.” Akiṣi sì wí fún Dafidi pé, “Nítorí náà ni èmi ó ṣe fi ìwọ ṣe olùṣọ́ orí mi ni gbogbo ọjọ́.”
Devit ni Akhish koevah a san ni bangmaw a sak thai tie hah panuek atipouh. Akhish ni Devit koevah, hatdawkvah ka tengo lah na ta han atipouh.
3 Samuẹli sì ti kú, gbogbo Israẹli sì sọkún rẹ̀, wọ́n sì sin ín ní Rama ní ìlú rẹ̀. Saulu sì ti mú àwọn abókùúsọ̀rọ̀ ọkùnrin, àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀ obìnrin kúrò ní ilẹ̀ náà.
Samuel teh a due toung dawkvah, Isarelnaw pueng ni a khuika awh teh, amae kho Ramah vah a pakawp awh toe. Sawl ni khueyue hoi tonghmanaw pueng hai a ram thung hoi koung a pâlei toe.
4 Àwọn Filistini sì kó ara wọn jọ, wọ́n wá, wọ́n sì dó sí Ṣunemu: Saulu sì kó gbogbo Israẹli jọ, wọ́n sì tẹ̀dó ní Gilboa.
Filistinnaw teh a kamkhueng awh teh Shunem kho vah a tungpup awh. Sawl ni Isarelnaw a pâkhueng teh Gilboa khovah a tungpup awh.
5 Nígbà tí Saulu sì rí ogun àwọn Filistini náà òun sì bẹ̀rù, àyà rẹ̀ sì wárìrì gidigidi.
Sawl ni Filistin ransanaw a hmu toteh a taki dawkvah, puenghoi a lung thung a pâyaw.
6 Nígbà tí Saulu sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, Olúwa kò dá a lóhùn nípa àlá, nípa Urimu tàbí nípa àwọn wòlíì.
Sawl ni BAWIPA a pacei navah, BAWIPA ni a mang hoi hai, Urim hoi hai, profet hoi hai pato hoeh toe.
7 Saulu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ bá mi wá obìnrin kan tí ó ní ẹ̀mí abókùúsọ̀rọ̀ èmi yóò sì tọ̀ ọ́ lọ, èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ̀!” Àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Wò ó, obìnrin kan wà ní Endori tí ó ní ẹ̀mí abókùúsọ̀rọ̀.”
Sawl ni a sannaw koe khueyue koe pouknae kahei thai nahanlah na tawng pouh awh atipouh. A sannaw ni khenhaw! Endor kho vah khueyue napui buet touh ao kaima atipouh awh.
8 Saulu sì pa ara dà, ó sì mú aṣọ mìíràn wọ̀, ó sì lọ, àwọn ọmọkùnrin méjì sì pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ obìnrin náà lóru: òun sì wí pé, “Èmi bẹ̀ ọ́, fi ẹ̀mí abókùúsọ̀rọ̀ wo nǹkan fún mi, kí o sì mú ẹni tí èmí ó dárúkọ rẹ̀ fún ọ wá sókè fún mi.”
Sawl teh a mei loukcalah a kamthoup teh, khohna alouke a kho teh alouke tami kahni touh hoi tangminlah hote napui koe a cei teh, na kamyawngkhai e kahrai kângue lahoi kai ni ka dei hane tami hah na kaw pouh haw atipouh.
9 Obìnrin náà sì dá a lóhùn pé, “Wò ó, ìwọ sá à mọ ohun tí Saulu ṣe, bí òun ti gé àwọn abókùúsọ̀rọ̀ obìnrin, àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀ ọkùnrin kúrò ní ilẹ̀ náà; ǹjẹ́ èéha ṣe tí ìwọ dẹkùn fún ẹ̀mí mi, láti mú kí wọ́n pa mí.”
Napui ni khenhaw. Sawl ni a sak e na panue. A ram thung e khueyue hoi tonghma pueng hah koung a raphoe toe. Bangkongmaw ka due nahanelah kahringnae karap na patung atipouh.
10 Saulu sì búra fún un nípa Olúwa pé, “Bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ìyà kan kì yóò jẹ́ ọ́ nítorí nǹkan yìí.”
Sawl ni BAWIPA min thoebo laihoi, BAWIPA a hring e patetlah hete hno kecu dawk maw nang dawk reknae phat mahoeh telah ahni koe lawk a kam.
11 Obìnrin náà sì bi í pé, “Ta ni ẹ̀mí ó mú wá sókè fún ọ?” Òun sì wí pé, “Mú Samuẹli gòkè wá fún mi.”
Napui ni apimaw na kaw pouh han telah a pacei. Ahni ni Samuel na kaw pouh haw atipouh.
12 Nígbà tí obìnrin náà sì rí Samuẹli, ó kígbe lóhùn rara: obìnrin náà sì bá Saulu sọ̀rọ̀ pè, “Èéṣe tí ìwọ fi tàn mí jẹ? Nítorí pé Saulu ni ìwọ jẹ́.”
Napui ni Samuel a hmu navah kacaipounglah a hram. Napui ni Sawl koe bangkongmaw na dum. Nang teh Sawl nahoehmaw atipouh.
13 Ọba sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù; kín ni ìwọ rí?” Obìnrin náà sì wí fún Saulu pé, “Èmi rí ọlọ́run kan tí ń ti ilẹ̀ wá.”
Siangpahrang ni napui koevah, taket hanh, bangmaw na hmu atipouh. Napui ni talai thung hoi muitha buet touh a tâco e ka hmu atipouh.
14 Ó sì bi í pé, “Báwo ni ó ti rí i sí.” Ó sì wí pé, “Ọkùnrin arúgbó kan ni ó ń bọ; ó sì fi agbádá bora.” Saulu sì mọ̀ pé, Samuẹli ni; ó sì tẹríba, ó sì wólẹ̀.
Ahni ni napui koevah Bangpatete a meilam lah maw ao atipouh. Napui ni tongpa matawng poung e a tâco teh angkidung a kho atipouh. Sawl ni Samuel doeh tie a panue teh talai dawk a tabo.
15 Samuẹli sì i wí fún Saulu pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń yọ mí lẹ́nu láti mú mi wá sókè?” Saulu sì dáhùn ó sì wí pé, “Ìpọ́njú ńlá bá mi; nítorí tí àwọn Filistini ń bá mi jagun, Ọlọ́run sì kọ̀ mí sílẹ̀, kò sì dá mi lóhùn mọ́, nípa ọwọ́ àwọn wòlíì, tàbí nípa àlá; nítorí náà ni èmi ṣe pè ọ́, kí ìwọ lè fi ohun tí èmi yóò ṣe hàn mi.”
Hahoi Samuel ni Sawl koevah, bang kecu dawk maw kai hah runae na poe atipouh. Sawl ni ka kângai hroung a ru dawk doeh. Bangkongtetpawiteh, Filistinnaw ni na tuk teh Cathut ni na ceitakhai toe. Profet lahoi hai mang lahoi hai na pato hoeh toe. Hatdawkvah, ka tawk hane na ka dei pouh hanelah, na kaw e doeh atipouh.
16 Samuẹli sì wí pé, “Ó ti ṣe ń bi mí léèrè nígbà tí ó jẹ́ pé, Olúwa ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀, o sì di ọ̀tá rẹ̀.
Samuel ni BAWIPA ni hnamthun takhai teh na taran lah a coung toe tie hah na panue nalaihoi bangkongmaw lawk na pacei.
17 Olúwa sì ṣe fún ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ti ipa ọwọ́ mi sọ: Olúwa sì yá ìjọba náà kúrò ní ọwọ́ rẹ̀, ó sì fi fún aládùúgbò rẹ́, àní Dafidi.
Kai hno lahoi lawk ouk a dei e patetlah BAWIPA ni nang dawkvah a sak toe. Uknaeram teh BAWIPA ni na kut dawk e na lawp teh na imri Devit koe roeroe a poe toe.
18 Nítorí pé ìwọ kò gbọ́ ohùn Olúwa ìwọ kò sì ṣe iṣẹ́ ìbínú rẹ̀ sí Amaleki nítorí náà ni Olúwa sì ṣe nǹkan yìí sí ọ lónìí yìí.
BAWIPA e lawk na ngâi hoeh dawkvah, Amaleknaw dawk puenghoi a lungkhuek e patetlah na sak hoeh kecu dawk atu nang dawk hete hno heh a pha toe.
19 Olúwa yóò sì fi Israẹli pẹ̀lú ìwọ lé àwọn Filistini lọ́wọ́, ní ọ̀la ni ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin yóò pẹ̀lú mi: Olúwa yóò sì fi ogun Israẹli lé àwọn Filistini lọ́wọ́.”
Hathloilah, BAWIPA ni nang hoi Isarelnaw hai Filistinnaw e kut dawk na poe awh han. Hahoi tangtho vah nama hoi na capa teh kai koe na o roi han. BAWIPA ni Isarel ransanaw hai Filistinnaw e kut dawk a poe awh han atipouh.
20 Lójúkan náà ni Saulu ṣubú lulẹ̀ gbalaja níbí ó ṣe gùn tó, ẹ̀rù sì bà á gidigidi nítorí ọ̀rọ̀ Samuẹli; agbára kò sí fún un; nítorí pé kò jẹun ní ọjọ́ náà tọ̀sán tòru.
Hottelah Samuel ni a dei e lawk hah Sawl ni a takipoung teh, talai dawk a rawp, a thayung khoeroe awm hoeh, karum khodai banghai catnet hoeh.
21 Obìnrin náà sì tọ Saulu wá, ó sì rí i pé ó wà nínú ìbànújẹ́ púpọ̀, ó sì wí fún un pé, “Wò ó, ìránṣẹ́bìnrin rẹ́ ti gbọ́ ohun rẹ̀, èmi sì ti fi ẹ̀mí mi sí ọwọ́ mi, èmi sì ti gbọ́ ọ̀rọ̀ ti ìwọ sọ fún mi.
Napui teh Sawl koe a cei teh, kângai hroung ka ru poung lah ao e hah a panue dawkvah, khenhaw! na san ni na dei e hah ka yuem teh due hai due tihoi kai koe na dei e hah ka tarawi toe.
22 Ǹjẹ́, nísinsin yìí èmi bẹ̀ ọ́, gbọ́ ohùn ìránṣẹ́bìnrin rẹ, èmi yóò sì fi oúnjẹ díẹ̀ síwájú rẹ̀; sì jẹun, ìwọ yóò sì lágbára, nígbà tí ìwọ bá ń lọ lọ́nà.”
Hatdawkvah, nang ni hai na sannu ni a dei e hah tarawi van haw, bu youn touh na poe han, na ban navah na thayung bet ao nahanelah na ca han atipouh.
23 Ṣùgbọ́n ó kọ̀, ó sì wí pé, “Èmi kì yóò jẹun.” Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pẹ̀lú rọ̀ ọ́. Ó sì dìde kúrò ni ilẹ̀, ó sì jókòó lórí àkéte.
Hateiteh, ka cat mahoeh ati. A sannaw ni napui hoi ngangngang a pasawt awh teh ahnimae lawk hah a tarawi pouh dawkvah a thaw teh ikhun dawk a tahung.
24 Obìnrin náà sì ni ẹgbọrọ màlúù kan ti ó sanra ni ilé, ó sì yára, ó pa á, ó sì mú ìyẹ̀fun, ó sì pò ó, ó sì fi ṣe àkàrà àìwú.
Hahoi napui ni maitotan ka thaw poung e a tawn e hah karanglah a thei pouh teh, tavai hoi kanawk e tawn phuen hoeh e vaiyei a sak.
25 Ó sì mú un wá síwájú Saulu, àti síwájú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀; wọ́n sì jẹun. Wọ́n sì dìde, wọ́n lọ ní òru náà.
Hottelah Sawl hoi a sannaw e a hmalah a pâtoum pouh teh a ca awh. Hahoi a thaw awh teh tangminlah a cei awh.

< 1 Samuel 28 >