< 1 Samuel 26 >

1 Nígbà náà ni àwọn ará Sifi tọ Saulu wá sí Gibeah, wọn wí pé, “Dafidi kò ha fi ara rẹ̀ pamọ́ níbi òkè Hakila, èyí tí ó wà níwájú Jeṣimoni?”
I przyszli Zyfejczycy do Saula do Gabaa, a mówili: Izali się nie kryje Dawid na pagórku Hachila, przeciw Jesymon?
2 Saulu sì dìde ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ijù Sifi ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àṣàyàn ènìyàn ni Israẹli sì pẹ̀lú rẹ̀ láti wá Dafidi ni ijù Sifi.
Ruszył się tedy Saul, i ciągnął na puszczą Zyf, a z nim trzy tysiące mężów przebranych z Izraela, aby szukał Dawida na puszczy Zyf.
3 Saulu sì pàgọ́ rẹ̀ ní ibi òkè Hakila tí o wà níwájú Jeṣimoni lójú ọ̀nà, Dafidi sì jókòó ni ibi ijù náà, ó sì rí pé Saulu ń tẹ̀lé òun ni ijù náà.
I położył się Saul obozem na pagórku Hachila, które jest przeciw Jesymon podle drogi; a Dawid mieszkał na puszczy, i dowiedział się, że przyciągnął Saul za nim na puszczą,
4 Dafidi sì rán ayọ́lẹ̀wò jáde, ó sì mọ nítòótọ́ pé Saulu ń bọ̀.
Bo posławszy Dawid szpiegi dowiedział się, że przyciągnął Saul zapewne.
5 Dafidi sì dìde, ó sì wá sí ibi ti Saulu pàgọ́ sí: Dafidi rí ibi tí Saulu gbé dùbúlẹ̀ sí, àti Abneri ọmọ Neri, olórí ogun rẹ̀: Saulu sì dùbúlẹ̀ láàrín àwọn kẹ̀kẹ́, àwọn ènìyàn náà sì pàgọ́ wọn yí i ká.
Przetoż wstał Dawid, i przyszedł aż ku miejscu, gdzie się położył obozem Saul; i upatrzył Dawid miejsce, gdzie spał Saul, i Abner, syn Nera, hetman wojska jego; bo Saul spał w obozie, a lud leżał około niego.
6 Dafidi sì dáhùn, ó sì wí fún Ahimeleki, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Hiti, àti fún Abiṣai ọmọ Seruiah ẹ̀gbọ́n Joabu, pé, “Ta ni yóò ba mi sọ̀kalẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Saulu ni ibùdó?” Abiṣai sì wí pé, “Èmi yóò ba ọ sọ̀kalẹ̀ lọ.”
I odpowiedział Dawid, a rzekł do Achimelecha Hetejczyka, i do Abisajego, syna Sarwii, brata Joabowego, mówiąc: Któż pójdzie ze mną do Saula do obozu? Odpowiedział Abisaj: Ja z tobą pójdę.
7 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti Abiṣai sì tọ àwọn ènìyàn náà wá lóru: sì wò ó, Saulu dùbúlẹ̀ ó sì ń sùn láàrín kẹ̀kẹ́, a sì fi ọ̀kọ̀ rẹ̀ gúnlẹ̀ ni ibi tìmùtìmù rẹ̀: Abneri àti àwọn ènìyàn náà sì dùbúlẹ̀ yí i ká.
A tak przyszedł Dawid i Abisaj do ludu w nocy, a oto, Saul leżąc spał w obozie, a włócznia jego była utkniona w ziemi u głowy jego; Abner też z ludem leżeli około niego.
8 Abiṣai sì wí fún Dafidi pé, “Ọlọ́run ti fi ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́ lónìí: ǹjẹ́ èmi bẹ̀ ọ́, sá à jẹ́ kí èmi o fi ọ̀kọ̀ gún un mọ́lẹ̀ lẹ́ẹ̀kan, èmi kì yóò gun un lẹ́ẹ̀méjì.”
Tedy rzekł Abisaj do Dawida: Zamknął dziś Bóg nieprzyjaciela twego w ręce twoje, a teraz niech go przebije proszę włócznią ku ziemi raz, a więcej nie powtórzę.
9 Dafidi sì wí fún Abiṣai pé, “Má ṣe pa á nítorí pé ta ni lè na ọwọ́ rẹ̀ sí ẹni àmì òróró Olúwa kí ó sì wà láìjẹ̀bi?”
Ale rzekł Dawid do Abisajego: Nie zabijaj go; bo któż ściągnąwszy rękę swą na pomazańca Pańskiego, niewinnym będzie?
10 Dafidi sì wí pé, “Bí Olúwa tí ń bẹ Olúwa yóò pa á, tàbí ọjọ́ rẹ̀ yóò sì pé tí yóò kú, tàbí òun ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibi ìjà yóò sì ṣègbé níbẹ̀.
Nadto rzekł Dawid: Jako żyje Pan, że jeźli go Pan nie zabije, albo dzień jego nie przyjdzie, aby umarł, albo na wojnę wyjechawszy, nie zginie,
11 Olúwa má jẹ́ kí èmi na ọwọ́ mi sí ẹni àmì òróró Olúwa. Ǹjẹ́ èmi bẹ̀ ọ́, mú ọ̀kọ̀ náà tí ń bẹ níbi tìmùtìmù rẹ̀, àti ìgò omi kí a sì máa lọ.”
Tedy uchowaj mię Panie, abym miał ściągnąć rękę moję na pomazańca Pańskiego; ale weźmij proszę włócznią, która jest u głów jego, i kubek od wody, a odejdźmy.
12 Dafidi sì mú ọ̀kọ̀ náà àti ìgò omi náà kúrò níbi tìmùtìmù Saulu: wọ́n sì bá tiwọn lọ, kò sì sí ẹnìkan tí ó rí i, tàbí tí ó mọ̀: kò sì sí ẹnìkan tí ó jí; gbogbo wọn sì sùn; nítorí pé oorun èjìká láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá ti ṣubú lù wọ́n.
Tedy wziął Dawid włócznią, i kubek od wody, który był u głów Saulowych, i odeszli, a nie był, ktoby widział, ani ktoby wiedział, ani ktoby się ocucił, ale wszyscy spali; bo sen twardy od Pana przypadł był na nie.
13 Dafidi sì rékọjá sí ìhà kejì, ó sì dúró lórí òkè kan tí ó jìnnà réré; àlàfo kan sì wà láàrín méjì wọn.
I przyszedł Dawid na drugą stronę, i stanął na wierzchu góry z daleka, a był plac wielki między nimi.
14 Dafidi sì kọ sí àwọn ènìyàn náà àti sí Abneri ọmọ Neri wí pé, “Ìwọ kò dáhùn, Abneri?” Nígbà náà ni Abneri sì dáhùn wí pé, “Ìwọ ta ni ń pe ọba?”
I zawołał Dawid na lud, i na Abnera, syna Nerowego, mówiąc: Nie ozwieszże się Abnerze? I odpowiadając Abner, rzekł: Któżeś ty, co wołasz na króla?
15 Dafidi sì wí fún Abneri pé, “Alágbára ọkùnrin kọ́ ni ìwọ bí? Ta ni ó sì dàbí ìwọ ni Israẹli? Ǹjẹ́ èéṣe tí ìwọ kò tọ́jú ọba Olúwa rẹ? Nítorí ẹnìkan nínú àwọn ènìyàn náà ti wọlé wá láti pa ọba olúwa rẹ.
I rzekł Dawid do Abnera: Azaż ty nie mąż? A któż jakoś ty w Izraelu? przeczżeś tedy nie strzegł króla, pana twego? bo przyszedł jeden z ludu, chcąc zabić króla, pana twego.
16 Nǹkan tí ìwọ ṣe yìí kò dára. Bí Olúwa ti ń bẹ, o tọ́ kí ẹ̀yin ó kú, nítorí pé ẹ̀yin kò pa olúwa yín mọ́, ẹni àmì òróró Olúwa. Ǹjẹ́ sì wo ibi tí ọ̀kọ̀ ọba gbé wà, àti ìgò omi tí ó ti wà níbi tìmùtìmù rẹ̀.”
Nie dobra to, coś uczynił. Jako żywy Pan, żeście winni śmierci, którzyście nie strzegli pana waszego, pomazańca Pańskiego. A teraz, patrz, kędy jest włócznia królewska, i kubek od wody, co był w głowach jego?
17 Saulu sì mọ ohùn Dafidi, ó sì wí pé, “Ohùn rẹ ni èyí bí Dafidi ọmọ mi?” Dafidi sì wí pé, “Ohùn mi ni, olúwa mi, ọba.”
Poznał tedy Saul głos Dawida, i rzekł: Twójże to głos, synu mój Dawidzie? Odpowiedział Dawid: Głos to mój, królu, panie mój.
18 Òun sì wí pé, “Nítorí kín ni olúwa mi ṣe ń lépa ìránṣẹ́ rẹ̀? Kín ni èmi ṣe? Tàbí ìwà búburú wo ni ó wà lọ́wọ́ mi.
Nadto rzekł: Czemuż pan mój prześladuje sługę swego? bo cóżem uczynił? a co jest złego w ręce mojej?
19 Ǹjẹ́ èmi bẹ̀ ọ́, ọba, olúwa mi, gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ. Bí ó bá ṣe Olúwa bá ti rú ọ sókè sí mi, jẹ́ kí òun o gba ẹbọ; ṣùgbọ́n bí o bá sì ṣe pé ọmọ ènìyàn ni, ìfibú ni kí wọn ó jásí níwájú Olúwa; nítorí tí wọn lé mi jáde lónìí kí èmi má ba à ní ìpín nínú ilẹ̀ ìní Olúwa, wí pé, ‘Lọ sin àwọn ọlọ́run mìíràn.’
Przetoż teraz niech posłucha proszę król, pan mój, słów sługi swego; jeźli cię Pan pobudził przeciwko mnie, niech powonia ofiary; ale jeźli synowie Judzcy, przeklęci są przed Panem, którzy mię dziś wygnali, abym nie mieszkał w dziedzictwie Pańskiem, jakoby rzekli: Idź, służ bogom cudzym.
20 Ǹjẹ́ má ṣe jẹ́ kí ẹ̀jẹ̀ mi ó sàn sílẹ̀ níwájú Olúwa; nítorí ọba Israẹli jáde láti wá ẹ̀mí mi bi ẹni ń dọdẹ àparò lórí òkè ńlá.”
A teraz niech nie będzie wylana krew moja na ziemię przed obliczem Pańskiem; bo wyszedł król Izraelski szukać pchły jednej, jakoby też kto gonił kuropatwę po górach.
21 Saulu sì wí pé, “Èmi ti dẹ́ṣẹ̀: yípadà, Dafidi ọmọ mi: nítorí pé èmi kì yóò wa ibi rẹ mọ́, nítorí tí ẹ̀mí mi sì ti ṣe iyebíye lójú rẹ lónìí: wò ó, èmi ti ń hùwà òmùgọ̀, mo sì ti ṣìnà jọjọ.”
Tedy rzekł Saul: Zgrzeszyłem. Wróćże się, synu mój Dawidzie, boć już nic złego nie uczynię więcej, ponieważ droga była dusza moja w oczach twoich dnia tego; otom głupio uczynił, i zbłądziłem nader bardzo.
22 Dafidi sì dáhùn, ó sì wí pé, “Wò ó, ọ̀kọ̀ ọba! Kí ó sì jẹ́ kí ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin rékọjá wá gbà á.
A odpowiadając Dawid rzekł: Oto włócznia królewska; niech sam przyjdzie kto z sług, a weźmie ją.
23 Kí Olúwa o san án fún olúkúlùkù bí òdodo rẹ̀ àti bí òtítọ́ rẹ̀: nítorí pé Olúwa tí fi ọ lé mi lọ́wọ́ lónìí, ṣùgbọ́n èmi kò fẹ́ nawọ́ mi sí ẹni àmì òróró Olúwa.
A Pan niech odda każdemu sprawiedliwość jego, i wiarę jego. Albowiem podał cię był Pan dziś w ręce moje; alem nie chciał ściągnąć ręki mojej na pomazańca Pańskiego.
24 Sì wò ó, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀mí rẹ ti tóbi lónìí lójú mi, bẹ́ẹ̀ ni ki ẹ̀mí mi ó tóbi lójú Olúwa, kí ó sì gbà mí lọ́wọ́ ibi gbogbo.”
Przetoż jako dziś poważona była dusza twoja w oczach moich, tak niech będzie poważona dusza moja w oczach Pańskich, a niech mię wyrwie Pan ze wszego ucisku.
25 Saulu sì wí fún Dafidi pé, “Alábùkún fún ni ìwọ, Dafidi ọmọ mi: nítòótọ́ ìwọ yóò sì ṣe nǹkan ńlá, nítòótọ́ ìwọ yóò sì borí.” Dafidi sì bá ọ̀nà rẹ̀ lọ, Saulu sì yípadà sí ibùgbé rẹ̀.
I rzekł Saul do Dawida: Błogosławionyś ty, synu mój Dawidzie; tak czyniąc dokażesz, a tak się wzmacniając, mocnym będziesz. Odszedł potem Dawid w drogę swą, a Saul się wrócił na miejsce swoje,

< 1 Samuel 26 >