< 1 Samuel 26 >

1 Nígbà náà ni àwọn ará Sifi tọ Saulu wá sí Gibeah, wọn wí pé, “Dafidi kò ha fi ara rẹ̀ pamọ́ níbi òkè Hakila, èyí tí ó wà níwájú Jeṣimoni?”
And Zipheis camen to Saul in to Gabaa, and seiden, Lo! Dauid is hidde in the hille of Achille, which is `euene ayens the wildirnesse.
2 Saulu sì dìde ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ijù Sifi ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àṣàyàn ènìyàn ni Israẹli sì pẹ̀lú rẹ̀ láti wá Dafidi ni ijù Sifi.
And Saul roos, and yede doun in to deseert of Ziph, and with hym thre thousynde of men of the chosun of Israel, that he schulde seke Dauid in the desert of Ziph.
3 Saulu sì pàgọ́ rẹ̀ ní ibi òkè Hakila tí o wà níwájú Jeṣimoni lójú ọ̀nà, Dafidi sì jókòó ni ibi ijù náà, ó sì rí pé Saulu ń tẹ̀lé òun ni ijù náà.
And Saul settide tentis in Gabaa of Achille, that was euen ayens the wildirnesse in the weie. Sotheli Dauid dwellide in deseert. Forsothe Dauid siy that Saul hadde come aftir hym in to deseert;
4 Dafidi sì rán ayọ́lẹ̀wò jáde, ó sì mọ nítòótọ́ pé Saulu ń bọ̀.
and Dauid sente aspieris, and lernede moost certeynli, that Saul hadde come thidur.
5 Dafidi sì dìde, ó sì wá sí ibi ti Saulu pàgọ́ sí: Dafidi rí ibi tí Saulu gbé dùbúlẹ̀ sí, àti Abneri ọmọ Neri, olórí ogun rẹ̀: Saulu sì dùbúlẹ̀ láàrín àwọn kẹ̀kẹ́, àwọn ènìyàn náà sì pàgọ́ wọn yí i ká.
And Dauid roos priueli, and cam to the place where Saul was. And whanne Dauid hadde seyn the place, wher ynne Saul slepte, and Abner, the sone of Ner, the prince of his chyualrye, and Saul slepynge in the tente, and the tother comyn puple bi his cumpas, Dauid seide to Achymelech,
6 Dafidi sì dáhùn, ó sì wí fún Ahimeleki, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Hiti, àti fún Abiṣai ọmọ Seruiah ẹ̀gbọ́n Joabu, pé, “Ta ni yóò ba mi sọ̀kalẹ̀ lọ sọ́dọ̀ Saulu ni ibùdó?” Abiṣai sì wí pé, “Èmi yóò ba ọ sọ̀kalẹ̀ lọ.”
Ethey, and to Abisai, sone of Saruye, the brother of Joab, `and seide, Who schal go doun with me to Saul in to `the castels? And Abisai seide, Y schal go doun with thee.
7 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti Abiṣai sì tọ àwọn ènìyàn náà wá lóru: sì wò ó, Saulu dùbúlẹ̀ ó sì ń sùn láàrín kẹ̀kẹ́, a sì fi ọ̀kọ̀ rẹ̀ gúnlẹ̀ ni ibi tìmùtìmù rẹ̀: Abneri àti àwọn ènìyàn náà sì dùbúlẹ̀ yí i ká.
Therfor Dauid and Abisai camen to the puple in the nyyt, and thei founden Saul lyggynge and slepynge in `the tente, and a spere sette faste in the erthe at his heed; `forsothe thei founden Abner and the puple slepynge in his cumpas.
8 Abiṣai sì wí fún Dafidi pé, “Ọlọ́run ti fi ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́ lónìí: ǹjẹ́ èmi bẹ̀ ọ́, sá à jẹ́ kí èmi o fi ọ̀kọ̀ gún un mọ́lẹ̀ lẹ́ẹ̀kan, èmi kì yóò gun un lẹ́ẹ̀méjì.”
And Abisay seide to Dauid, God hath closid to dai thin enemy in to thin hondis; now therfor Y schal peerse hym with a spere onys in the erthe, and `no nede schal be the secounde tyme.
9 Dafidi sì wí fún Abiṣai pé, “Má ṣe pa á nítorí pé ta ni lè na ọwọ́ rẹ̀ sí ẹni àmì òróró Olúwa kí ó sì wà láìjẹ̀bi?”
And Dauid seide to Abysai, Sle thou not hym, for who schal holde forth his hond into the crist of the Lord, and schal be innocent?
10 Dafidi sì wí pé, “Bí Olúwa tí ń bẹ Olúwa yóò pa á, tàbí ọjọ́ rẹ̀ yóò sì pé tí yóò kú, tàbí òun ó sọ̀kalẹ̀ lọ sí ibi ìjà yóò sì ṣègbé níbẹ̀.
And Dauid seide, The Lord lyueth, for no but the Lord smyte hym, ether his dai come that he die, ether he go doun in to batel and perische;
11 Olúwa má jẹ́ kí èmi na ọwọ́ mi sí ẹni àmì òróró Olúwa. Ǹjẹ́ èmi bẹ̀ ọ́, mú ọ̀kọ̀ náà tí ń bẹ níbi tìmùtìmù rẹ̀, àti ìgò omi kí a sì máa lọ.”
the Lord be merciful to me, that Y holde not forth myn hond in to the crist of the Lord; now therfor take thou the spere, which is at his heed, and `take thou the cuppe of watir, and go we awei.
12 Dafidi sì mú ọ̀kọ̀ náà àti ìgò omi náà kúrò níbi tìmùtìmù Saulu: wọ́n sì bá tiwọn lọ, kò sì sí ẹnìkan tí ó rí i, tàbí tí ó mọ̀: kò sì sí ẹnìkan tí ó jí; gbogbo wọn sì sùn; nítorí pé oorun èjìká láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá ti ṣubú lù wọ́n.
Dauid took the spere, and the cuppe of watir, that was at the heed of Saul, and thei yeden forth, and no man was that siy, and vndirstood, and wakide, but alle men slepten; for the sleep of the Lord `hadde feld on hem.
13 Dafidi sì rékọjá sí ìhà kejì, ó sì dúró lórí òkè kan tí ó jìnnà réré; àlàfo kan sì wà láàrín méjì wọn.
And whanne Dauid hadde passid euene ayens, and hadde stonde on the cop of the hil afer, and a greet space was bitwixe hem,
14 Dafidi sì kọ sí àwọn ènìyàn náà àti sí Abneri ọmọ Neri wí pé, “Ìwọ kò dáhùn, Abneri?” Nígbà náà ni Abneri sì dáhùn wí pé, “Ìwọ ta ni ń pe ọba?”
Dauid criede to the puple, and to Abner, the sone of Ner, and seide, Abner, whether thou schalt not answere? And Abner answeride, and seide, Who art thou, that criest, and disesist the kyng?
15 Dafidi sì wí fún Abneri pé, “Alágbára ọkùnrin kọ́ ni ìwọ bí? Ta ni ó sì dàbí ìwọ ni Israẹli? Ǹjẹ́ èéṣe tí ìwọ kò tọ́jú ọba Olúwa rẹ? Nítorí ẹnìkan nínú àwọn ènìyàn náà ti wọlé wá láti pa ọba olúwa rẹ.
And Dauith seide to Abner, Whether thou art not a man, and what other man is lijk thee in Israel? whi therfor `kepist thou not thi lord the kyng? `For o man of the cumpanye entride, that he schulde sle thi lord the kyng;
16 Nǹkan tí ìwọ ṣe yìí kò dára. Bí Olúwa ti ń bẹ, o tọ́ kí ẹ̀yin ó kú, nítorí pé ẹ̀yin kò pa olúwa yín mọ́, ẹni àmì òróró Olúwa. Ǹjẹ́ sì wo ibi tí ọ̀kọ̀ ọba gbé wà, àti ìgò omi tí ó ti wà níbi tìmùtìmù rẹ̀.”
this that thou hast doon, is not good; the Lord lyueth, for ye ben sones of deeth, that kepten not youre lord, the crist of the Lord. Now therfor se thou, where is the spere of the kyng, and where is the cuppe of watir, that weren at his heed.
17 Saulu sì mọ ohùn Dafidi, ó sì wí pé, “Ohùn rẹ ni èyí bí Dafidi ọmọ mi?” Dafidi sì wí pé, “Ohùn mi ni, olúwa mi, ọba.”
Forsothe Saul knew the vois of Dauid, and seide, Whether this vois is thin, my sone Dauid? And Dauid seide, My lord the kyng, it is my vois.
18 Òun sì wí pé, “Nítorí kín ni olúwa mi ṣe ń lépa ìránṣẹ́ rẹ̀? Kín ni èmi ṣe? Tàbí ìwà búburú wo ni ó wà lọ́wọ́ mi.
And Dauid seide, For what cause pursueth my lord his seruaunt? What haue Y do, ether what yuel is in myn hond? Now therfor,
19 Ǹjẹ́ èmi bẹ̀ ọ́, ọba, olúwa mi, gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́ rẹ. Bí ó bá ṣe Olúwa bá ti rú ọ sókè sí mi, jẹ́ kí òun o gba ẹbọ; ṣùgbọ́n bí o bá sì ṣe pé ọmọ ènìyàn ni, ìfibú ni kí wọn ó jásí níwájú Olúwa; nítorí tí wọn lé mi jáde lónìí kí èmi má ba à ní ìpín nínú ilẹ̀ ìní Olúwa, wí pé, ‘Lọ sin àwọn ọlọ́run mìíràn.’
my lord the kyng, Y preye, here the wordis of thi seruaunt; if the Lord stirith thee ayens me, the sacrifice be smellid; forsothe if sones of men stiren thee, thei ben cursid in the siyt of the Lord, whiche han cast me out `to dai, that Y dwelle not in the erytage of the Lord, and seien, Go thou, serue thou alien goddis.
20 Ǹjẹ́ má ṣe jẹ́ kí ẹ̀jẹ̀ mi ó sàn sílẹ̀ níwájú Olúwa; nítorí ọba Israẹli jáde láti wá ẹ̀mí mi bi ẹni ń dọdẹ àparò lórí òkè ńlá.”
And now my blood be not sched out in the erthe bifor the Lord; for the kyng of Israel yede out, that he seke a quike fle, as a partrich is pursuede in hillis.
21 Saulu sì wí pé, “Èmi ti dẹ́ṣẹ̀: yípadà, Dafidi ọmọ mi: nítorí pé èmi kì yóò wa ibi rẹ mọ́, nítorí tí ẹ̀mí mi sì ti ṣe iyebíye lójú rẹ lónìí: wò ó, èmi ti ń hùwà òmùgọ̀, mo sì ti ṣìnà jọjọ.”
And Saul seide, Y synnede; turne ayen, my sone Dauid, for Y schal no more do yuel to thee, for my lijf was precious to day in thin iyen; for it semeth, that Y dide folili, and Y vnknew ful many thingis.
22 Dafidi sì dáhùn, ó sì wí pé, “Wò ó, ọ̀kọ̀ ọba! Kí ó sì jẹ́ kí ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin rékọjá wá gbà á.
And Dauid answeride and seide, Lo! the spere of the kyng, oon of the `children of the kyng passe, and take it; forsothe the Lord schal yelde to ech man bi his riytfulnesse and feith;
23 Kí Olúwa o san án fún olúkúlùkù bí òdodo rẹ̀ àti bí òtítọ́ rẹ̀: nítorí pé Olúwa tí fi ọ lé mi lọ́wọ́ lónìí, ṣùgbọ́n èmi kò fẹ́ nawọ́ mi sí ẹni àmì òróró Olúwa.
for the Lord bitook thee to dai in to myn hond, and Y nolde holde forth myn hond in to the crist of the Lord;
24 Sì wò ó, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀mí rẹ ti tóbi lónìí lójú mi, bẹ́ẹ̀ ni ki ẹ̀mí mi ó tóbi lójú Olúwa, kí ó sì gbà mí lọ́wọ́ ibi gbogbo.”
and as thi lijf is magnified to dai in myn iyen, so my lijf be magnyfied in the iyen of the Lord, and delyuere he me fro al angwisch.
25 Saulu sì wí fún Dafidi pé, “Alábùkún fún ni ìwọ, Dafidi ọmọ mi: nítòótọ́ ìwọ yóò sì ṣe nǹkan ńlá, nítòótọ́ ìwọ yóò sì borí.” Dafidi sì bá ọ̀nà rẹ̀ lọ, Saulu sì yípadà sí ibùgbé rẹ̀.
Therfor Saul seide to Dauid, Blessid be thou, my sone Dauid; and sotheli thou doynge schalt do, and thou myyti schalt be myyti. Therfor Dauid yede in to his weie, and Saul turnede ayen in to his place.

< 1 Samuel 26 >