< 1 Samuel 25 >

1 Samuẹli sì kú; gbogbo ènìyàn Israẹli sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì sọkún rẹ̀ wọ́n sì sin ín nínú ilé rẹ̀ ní Rama. Dafidi sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ijù Parani.
W tem umarł Samuel. A zebrawszy się wszyscy Izraelczycy, płakali go, i pogrzebli go w domu jego w Ramacie. Tedy wstawszy Dawid, poszedł na puszczę Faran.
2 Ọkùnrin kan sì ń bẹ ní Maoni, ẹni tí iṣẹ́ rẹ̀ ń bẹ ní Karmeli; ọkùnrin náà sì ní ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ní ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún ewúrẹ́: ó sì ń rẹ irun àgùntàn rẹ̀ ní Karmeli.
A był niektóry mąż w Maon, który miał majętność na Karmelu; a on mąż był możny bardzo, mając owiec trzy tysiące, a tysiąc kóz; i trafiło się, że strzygł owce swoje na Karmelu.
3 Orúkọ ọkùnrin náà sì ń jẹ́ Nabali, orúkọ aya rẹ̀ ń jẹ́ Abigaili; òun sì jẹ́ olóye obìnrin, àti arẹwà ènìyàn; ṣùgbọ́n òǹrorò àti oníwà búburú ni ọkùnrin; ẹni ìdílé Kalebu ni òun jẹ́.
A było imię męża onego Nabal, a imię żony jego Abigail, która niewiasta była mądra, i piękna; ale mąż jej był nieużyty i złych postępków, a był narodu Kalebowego.
4 Dafidi sì gbọ́ ní aginjù pé Nabali ń rẹ́ irun àgùntàn rẹ̀.
A usłyszawszy Dawid na puszczy, iż Nabal strzygł owce swoje,
5 Dafidi sì rán ọmọkùnrin mẹ́wàá, Dafidi sì sọ fún àwọn ọ̀dọ́kùnrin náà pé, “Ẹ gòkè lọ sí Karmeli, kí ẹ sì tọ Nabali lọ, kí ẹ sì kí i ni orúkọ mi.
Posłał dziesięciu sług, i rzekł im: Idźcie do Karmelu, a przyszedłszy do Nabala, pozdrówcie go imieniem mojem spokojnie,
6 Báyìí ni ẹ ó sì wí fún ẹni tí ó wà ni ìrora pé, ‘Àlàáfíà fún ọ! Àlàáfíà fún ohun gbogbo tí ìwọ ní!
A mówcie tak: Żyj, a niech będzie tobie pokój, i domowi twemu pokój, i wszystkiemu, co masz, pokój!
7 “‘Ǹjẹ́ mo gbọ́ pé, àwọn olùrẹ́run ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ. Wò ó, àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ ti wà lọ́dọ̀ wa àwa kò sì pa wọ́n lára, wọn kò sì sọ ohunkóhun nù ní gbogbo ọjọ́ tí wọ́n wà ní Karmeli.
A teraz słyszałem, że masz te, coć owce strzygą; a pasterze twoi bywali z nami, niebyliśmy im przykrymi, i nic im nie zginęło po wszystkie dni, których byli w Karmelu;
8 Bi àwọn ọmọkùnrin rẹ léèrè, wọn ó sì sọ fún ọ. Nítorí náà, jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí rí ojúrere lọ́dọ̀ rẹ; nítorí pé àwa sá wá ní ọjọ́ àsè: èmi bẹ̀ ọ́ ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà, fi fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àti fún Dafidi ọmọ rẹ.’”
Spytaj sług twoich, a powiedząć. Przetoż niech znajdą słudzy łaskę w oczach twoich, gdyżeśmy w dobry dzień przyszli; daj proszę cokolwiek znajdzie ręka twoja, sługom twoim, i synowi twemu Dawidowi.
9 Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì lọ, wọ́n sì sọ fún Nabali gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní orúkọ Dafidi, wọ́n sì sinmi.
A tak przyszli słudzy Dawidowi, i mówili do Nabala wszystkie one słowa imieniem Dawidowem, i przestali.
10 Nabali sì dá àwọn ìránṣẹ́ Dafidi lóhùn pé, “Ta ni ń jẹ́ Dafidi? Tàbí ta ni sì ń jẹ́ ọmọ Jese? Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìránṣẹ́ ni ń bẹ ni ìsinsin yìí tí wọn sá olúkúlùkù kúrò lọ́dọ̀ olúwa rẹ̀.
A odpowiadając Nabal sługom Dawidowym, rzekł: Cóż jest Dawid? a co zacz syn Isajego? dziś się namnożyło sług, którzy uciekają od panów swoich.
11 Ǹjẹ́ ki èmi o mú oúnjẹ mi, àti omi mi, àti ẹran mi ti mo pa fún àwọn olùrẹ́run mi, ki èmi sì fi fún àwọn ọkùnrin ti èmi kò mọ̀ ibi wọ́n ti wá?”
I wezmęż ja chleb mój, i wodę moję, i mięsa bydła mego, którem pobił dla tych, którzy strzygą owce moje, a dam mężom, których nie znam, skąd są?
12 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n, wọ́n sì padà, wọ́n sì wá, wọn si rò fún un gẹ́gẹ́ bi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
A obróciwszy się słudzy Dawidowi w drogę swoję, wrócili się, i przyszli a powiedzieli mu wszystkie te słowa.
13 Dafidi sí wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Kí olúkúlùkù yín ó di idà rẹ́ mọ́ ìdí,” olúkúlùkù ọkùnrin sì di idà tirẹ̀ mọ́ ìdí; àti Dafidi pẹ̀lú sì di idà tirẹ̀; ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin si gòkè tọ Dafidi lẹ́yìn; igba si jókòó níbi ẹrù.
Tedy rzekł Dawid mężom swym: Przypaszcie każdy miecz swój; przypasał też i Dawid miecz swój, i szło za Dawidem około czterech set mężów, a dwieście zostało przy rzeczach.
14 Ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin Nabali si wí fún Abigaili aya rẹ̀ pé, “Wo o, Dafidi rán oníṣẹ́ láti aginjù wá láti kí olúwa wa; ó sì kanra mọ́ wọn.
Ale Abigaili, żonie Nabalowej, oznajmił to jeden czeladnik z sług Nabalowych, mówiąc: Oto przysłał Dawid posły z puszczy, aby błogosławili Panu naszemu, lecz on je sfukał.
15 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà ṣe oore fún wa gidigidi, wọn kò ṣe wá ní ibi kan, ohunkóhun kò nù ni ọwọ́ wa ni gbogbo ọjọ́ ti àwa bá wọn rìn nígbà ti àwa ń bẹ lóko.
A mężowie ci dobrzy nam byli bardzo, i nie przykrzyli się nam; nic nam nie zginęło po wszystkie dni, pókiśmy z nimi chodzili, będąc na polu;
16 Odi ni wọ́n sá à jásí fún wa lọ́sàn án, àti lóru, ni gbogbo ọjọ́ ti a fi bá wọn gbé, tí a n bojútó àwọn àgùntàn.
Miasto muru byli nam, tak w nocy jako we dnie, po wszystkie dni, pókiśmy przy nich trzody paśli.
17 Ǹjẹ́, rò ó wò, kí ìwọ sì mọ èyí ti ìwọ yóò ṣe; nítorí pé a ti gbèrò ibi sí olúwa wa, àti sí gbogbo ilé rẹ̀; òun sì jásí ọmọ Beliali tí a kò le sọ̀rọ̀ fún.”
Przetoż teraz obacz, a rozmyśl się, co masz czynić; boć już gotowe nieszczęście na pana naszego, i na wszystek dom jego; lecz on jest człowiekiem niezbożnym, że z nim trudno mówić.
18 Abigaili sì yára, ó sì mú igbá ìṣù àkàrà àti ìgò ọtí wáìnì méjì, àti àgùntàn márùn-ún, tí a ti ṣè, àti òsùwọ̀n àgbàdo yíyan márùn-ún, àti ọgọ́rùn-ún ìdì àjàrà, àti igba àkàrà èso ọ̀pọ̀tọ́, ó sì dìwọ́n ru kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Pospieszyła się tedy Abigail, i wzięła dwieście chleba, i dwie łagwi wina, i pięć owiec oprawnych, i pięć miar prażma, i sto wiązanek rodzynków, i dwieście funtów fig, a włożyła to na osły;
19 Òun sì wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Máa lọ níwájú mi; wò ó, èmi ń bọ̀ lẹ́yìn yín,” ṣùgbọ́n òun kò wí fún Nabali baálé rẹ̀.
I rzekła sługom swoim: Idźcie przedemną, a ja pojadę za wami; ale mężowi swemu Nabalowi nie oznajmiła.
20 Bí o ti gun orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó sì ń sọ̀kalẹ̀ sí ibi ìkọ̀kọ̀ òkè náà, wò ó, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì sọ̀kalẹ̀ níwájú rẹ̀; òun sì wá pàdé wọn.
I stało się, że jadąc na ośle, i zjeżdżając głębią góry, oto też Dawid i mężowie jego zjeżdżali przeciwko niej, i spotkała się z nimi.
21 Dafidi sì ti wí pé, “Ǹjẹ́ lásán ni èmi ti pa gbogbo èyí tí i ṣe ti eléyìí ní aginjù, ti ohunkóhun kò sì nù nínú gbogbo èyí ti í ṣe tirẹ̀: òun ni ó sì fi ibi san ìre fún mi yìí.
(A Dawid był rzekł: Zaprawdę darmom strzegł wszystkiego, co ten miał na puszczy, że nic nie zginęło ze wszystkiego, co ma; bo mi oddał złem za dobre.
22 Bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, ni ki Ọlọ́run ó ṣe sí àwọn ọ̀tá Dafidi, bi èmi bá fi ọkùnrin kan sílẹ̀ nínú gbogbo èyí tí i ṣe tirẹ̀ títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀.”
To niech uczyni Bóg nieprzyjaciołom Dawidowym, i to niech przyczyni, jeźli co do zarania zostawię ze wszystkiego co ma, aż do najmniejszego szczenięcia).
23 Abigaili sì rí Dafidi, ó sì yára, ó sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì dojúbolẹ̀ níwájú Dafidi, ó sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀.
Tedy ujrzawszy Abigail Dawida, pospieszyła się, i zsiadła z osła, i upadła przed Dawidem na oblicze swoje, i ukłoniła się aż do ziemi;
24 Ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó wí pé, “Olúwa mi, fi ẹ̀ṣẹ̀ yìí yá mi: kí ó sì jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, sọ̀rọ̀ létí rẹ, kí ó sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.
A upadłszy do nóg jego, mówiła: Niech będzie na mnie, panie mój, ta nieprawość, a niech mówi proszę służebnica twoja do uszu twoich, i posłuchaj słów służebnicy twojej.
25 Olúwa mi, èmi bẹ̀ ọ́ má ka ọkùnrin Beliali yìí sí, àní Nabali. Nítorí pé bí orúkọ rẹ̀ ti jẹ́ bẹ́ẹ̀ ni òun náà rí. Nabali ni orúkọ rẹ̀, àìmoye si wà pẹ̀lú rẹ̀; ṣùgbọ́n èmi ìránṣẹ́bìnrin rẹ kò ri àwọn ọmọkùnrin olúwa mi, ti ìwọ rán.
Niech się proszę nie obraża pan mój na mężą tego bezbożnego Nabala, gdyż według imienia swego takim jest. Nabal jest imię jego, i głupstwo jest przy nim; alemci ja służebnica twoja nie widziała sług pana mego, któreś był posłał.
26 Ǹjẹ́ olúwa mi, bi Olúwa ti wà láààyè, àti bí ẹ̀mí rẹ̀ si ti wà láààyè, bi Olúwa sì ti dá ọ dúró láti wá ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, àti láti fi ọwọ́ ara rẹ gba ẹ̀san; ǹjẹ́, kí àwọn ọ̀tá rẹ, àti àwọn ẹni tí ń gbèrò ibi sí olúwa mi rí bi i Nabali.
Przetoż teraz panie mój, jako żywy Pan, jako żywa i dusza twoja, że cię zawściągnął Pan, abyś nie szedł na rozlanie krwi, i żeby się nie mściła ręka twoja; a teraz niech będą jako Nabal nieprzyjaciele twoi, i którzy szukają złego panu memu.
27 Ǹjẹ́ èyí ni ẹ̀bùn tí ìránṣẹ́bìnrin rẹ mú wá fún olúwa mi, jẹ́ kí a sì fi fún àwọn ọmọkùnrin ti ń tọ olúwa mi lẹ́yìn.
Teraz tedy to błogosławieństwo, które przyniosła służebnica twoja panu swemu, niech będzie dane sługom, którzy chodzą za panem moim.
28 “Èmi bẹ̀ ọ́, fi ìrékọjá arábìnrin rẹ jìn ín, nítorí Olúwa yóò sá ṣe ilé òdodo fún olúwa mi, nítorí pé ó ja ogun Olúwa. Nítorí náà kí a má ri ibi kan ni ọwọ́ rẹ níwọ̀n ìgbà tí ó wà láààyè.
Przepuść proszę występek służebnicy twojej, gdyż zapewne uczyni Pan panu memu dom trwały, ponieważ walki Pańskie pan mój odprawuje, a złość nie jest znalezina w tobie aż dotąd.
29 Bí ọkùnrin kan bá sì dìde láti máa lépa rẹ, àti máa wá ẹ̀mí rẹ, a ó sì di ẹ̀mí olúwa mi nínú ìdì ìyè lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ; àti ẹ̀mí àwọn ọ̀tá rẹ ni a ó sì gbọ̀n sọnù gẹ́gẹ́ bí kànnàkànnà jáde.
A choćby powstał człowiek, coby cię prześladował, i szukał duszy twojej, tedy będzie dusza pana mego zachowana w wiązance żywiących u Pana, Boga twego; lecz duszę nieprzyjaciół twoich Bóg jako z procy wyrzuci.
30 Yóò sì ṣe, Olúwa yóò ṣe sí olúwa mi gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìre tí ó ti wí nípa tirẹ̀, yóò sì yàn ọ́ ni aláṣẹ lórí Israẹli.
A gdy uczyni Pan panu memu wszystko, co mówił dobrego o tobie, a zlecić, abyś był wodzem nad Izraelem:
31 Èyí kì yóò sì jásí ìbànújẹ́ fún ọ, tàbí ìbànújẹ́ ọkàn fún olúwa mi, nítorí pé ìwọ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, tàbí pé olúwa mi gba ẹ̀san fún ara rẹ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí Olúwa ba ṣe oore fún olúwa mi, ǹjẹ́ rántí ìránṣẹ́bìnrin rẹ!”
Tedyć nie będzie to ku zachwianiu, ani ku urazie serca pana mego, jako gdyby rozlał krew niewinną, i gdyby się sam pomścił pan mój. Gdy tedy dobrze uczyni Pan panu memu, wspomnisz na służebnicę twoję.
32 Dafidi sì wí fún Abigaili pé, “Alábùkún fún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ó rán ọ lónìí yìí láti pàdé mi.
I rzekł Dawid do Abigaili: Błogosławiony Pan, Bóg Izraelski, który cię dziś posłał przeciwko mnie.
33 Ìbùkún ni fún ọgbọ́n rẹ, alábùkún sì ni ìwọ, tí ó da mi dúró lónìí yìí láti wá ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, àti láti fi ọwọ́ mi gba ẹ̀san fún ara mi.
Błogosławiona wymowa twoja, i błogosławionaś ty, któraś mię zawściągnęła dzisiaj, żem nie szedł na rozlanie krwi, a żem się sam nie mścił krzywdy swojej.
34 Nítòótọ́, bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli tí ń bẹ, tí ó da mi dúró láti pa ọ́ lára bí kò ṣe pé bí ìwọ ti yára tí ó sì wá pàdé mi, nítòótọ́ kì bá tí kù fún Nabali di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ nínú àwọn ọkùnrin rẹ̀.”
A zaprawdę, jako żywy Pan, Bóg Izraelski, który mię zawściągnął, abym ci nic złego nie uczynił: bo gdybyś się była nie pospieszyła, a nie zajechała mi drogi, nie zostałoby było Nabalowi aż do świtania, i najmniejszego szczenięcia.
35 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gba nǹkan tí ó mú wá fún un lọ́wọ́ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Gòkè lọ ni àlàáfíà sí ilé rẹ, wò ó, èmi ti gbọ́ ohùn rẹ, inú mi sì dùn sí ọ.”
A tak przyjął Dawid z ręki jej, co mu była przyniosła, i rzekł do niej: Idź w pokoju do domu twego: otom usłuchał głosu twego, i przyjąłem cię łaskawie.
36 Abigaili sì tọ Nabali wá, sì wò ó, òun sì ṣe àsè ni ilé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àsè ọba: inú Nabali sì dùn nítorí pé, ó ti mú ọtí ni àmupara; òun kò si sọ nǹkan fún un, díẹ̀ tàbí púpọ̀: títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀
Tedy się wróciła Abigail do Nabala; a on miał ucztę w domu swoim, jako ucztę królewską, a serce Nabalowe było wesołe w nim, a był pijany bardzo; i nie oznajmiła mu najmniejszej rzeczy aż do poranku.
37 Ó sì ṣe; ni òwúrọ̀, nígbà ti ọtí náà si dá tán lójú Nabali, obìnrin rẹ̀ sì ro nǹkan wọ̀nyí fún un, ọkàn rẹ sì kú nínú rẹ̀, òun sì dàbí òkúta.
Ale nazajutrz, gdy wytrzeźwiał Nabal z wina, oznajmiła mu żona jego te rzeczy: i zmartwiało w nim serce jego, i stał się jako kamień
38 Ó sì ṣe lẹ́yìn ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́wàá, Olúwa lu Nabali, ó sì kú.
A gdy wyszło jakoby dziesięć dni, uderzył Pan Nabala, i umarł.
39 Dafidi sì gbọ́ pé Nabali kú, ó sì wí pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí o gbèjà gígàn mi láti ọwọ́ Nabali wá, tí ó sì dá ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró láti ṣe ibi: Olúwa sì yí ìkà Nabali sí orí òun tìkára rẹ̀.” Dafidi sì ránṣẹ́, ó sì ba Abigaili sọ̀rọ̀ láti mú un fi ṣe aya fún ara rẹ̀.
A usłyszawszy Dawid, iż umarł Nabal, rzekł: Błogosławiony Pan, który się pomścił pohańbienia mego nad Nabalem, a sługę swego zatrzymał od złego, a złość Nabalowę obrócił Pan na głowę jego. Tedy posłał Dawid wskazując do Abigaili, że ją sobie chce wziąć za żonę.
40 Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì lọ sọ́dọ̀ Abigaili ni Karmeli, wọn sì sọ fún un pé, “Dafidi rán wá si ọ láti mu ọ ṣe aya rẹ̀.”
I przyszli słudzy Dawidowi do Abigaili do Karmelu, i rzekli do niej, mówiąc: Dawid posłał nas do ciebie, aby cię sobie wziął za żonę.
41 Ó sì dìde, ó sì dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ ó jẹ́ ìránṣẹ́ kan láti máa wẹ ẹsẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi.”
Która wstawszy, pokłoniła się obliczem do ziemi, i rzekła: Oto, służebnica twoja niech będzie sługą, aby umywała nogi sług pana mego.
42 Abigaili sì yára, ó sì dìde, ó sì gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ márùn-ún sì tẹ̀lé e lẹ́yìn; òun sì tẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ Dafidi, o sì wá di aya rẹ̀.
Przetoż pospieszywszy się wstała Abigail, i wsiadła na osła z pięcioma panienkami swemi, które z nią chodziły; i tak jechała za posłami Dawidowymi, a była mu za żonę.
43 Dafidi sì mú Ahinoamu ará Jesreeli; àwọn méjèèjì sì jẹ́ aya rẹ̀.
Ale i Achinoamę wziął Dawid z Jezreel, i były mu te dwie za żony.
44 Ṣùgbọ́n Saulu ti fi Mikali ọmọ rẹ̀ obìnrin aya Dafidi, fún Palti ọmọ Laiṣi tí i ṣe ara Galimu.
Albowiem Saul dał był Michol, córkę swoję, żonę Dawidowę, Faltemu, synowi Laisowemu, który był z Gallim.

< 1 Samuel 25 >