< 1 Samuel 25 >

1 Samuẹli sì kú; gbogbo ènìyàn Israẹli sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì sọkún rẹ̀ wọ́n sì sin ín nínú ilé rẹ̀ ní Rama. Dafidi sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ijù Parani.
Un Samuēls nomira un viss Israēls sapulcējās un žēlojās par to un to apraka viņa namā Rāmatā.
2 Ọkùnrin kan sì ń bẹ ní Maoni, ẹni tí iṣẹ́ rẹ̀ ń bẹ ní Karmeli; ọkùnrin náà sì ní ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ní ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún ewúrẹ́: ó sì ń rẹ irun àgùntàn rẹ̀ ní Karmeli.
Tad Dāvids nogāja uz Pārana tuksnesi. Un viens vīrs bija Maonā, kam saimniecība bija Karmelī; un tas vīrs bija ļoti bagāts, un tam bija trīstūkstoš avis un tūkstoš kazas. Un tas bija Karmelī, savas avis cirpt.
3 Orúkọ ọkùnrin náà sì ń jẹ́ Nabali, orúkọ aya rẹ̀ ń jẹ́ Abigaili; òun sì jẹ́ olóye obìnrin, àti arẹwà ènìyàn; ṣùgbọ́n òǹrorò àti oníwà búburú ni ọkùnrin; ẹni ìdílé Kalebu ni òun jẹ́.
Un tam vīram bija vārds Nābals, un viņa sievai bija vārds Abigaīle, un tā sieva bija ļoti gudra padomā un skaista augumā. Bet tas vīrs bija pikts un ļauns savos darbos un no Kāleba bērniem.
4 Dafidi sì gbọ́ ní aginjù pé Nabali ń rẹ́ irun àgùntàn rẹ̀.
Kad nu Dāvids tuksnesī dzirdēja, ka Nābals savas avis cirpa,
5 Dafidi sì rán ọmọkùnrin mẹ́wàá, Dafidi sì sọ fún àwọn ọ̀dọ́kùnrin náà pé, “Ẹ gòkè lọ sí Karmeli, kí ẹ sì tọ Nabali lọ, kí ẹ sì kí i ni orúkọ mi.
Tad viņš sūtīja desmit puišus un sacīja tiem puišiem: ejat uz Karmeli un ejat pie Nābala un sveicinājiet viņu no manas puses,
6 Báyìí ni ẹ ó sì wí fún ẹni tí ó wà ni ìrora pé, ‘Àlàáfíà fún ọ! Àlàáfíà fún ohun gbogbo tí ìwọ ní!
Un sakāt: Dievs palīdz, miers lai ir ar tevi un miers ar tavu namu un miers ar visu, kas tev pieder!
7 “‘Ǹjẹ́ mo gbọ́ pé, àwọn olùrẹ́run ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ. Wò ó, àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ ti wà lọ́dọ̀ wa àwa kò sì pa wọ́n lára, wọn kò sì sọ ohunkóhun nù ní gbogbo ọjọ́ tí wọ́n wà ní Karmeli.
Un nu es esmu dzirdējis, ka tev ir avju cirpēji. Tad nu tavi gani pie mums ir bijuši, mēs tiem nekā ļauna neesam darījuši, tiem arī nekas nav zudis visu to laiku, kamēr tie Karmelī bijuši.
8 Bi àwọn ọmọkùnrin rẹ léèrè, wọn ó sì sọ fún ọ. Nítorí náà, jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí rí ojúrere lọ́dọ̀ rẹ; nítorí pé àwa sá wá ní ọjọ́ àsè: èmi bẹ̀ ọ́ ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà, fi fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àti fún Dafidi ọmọ rẹ.’”
Vaicā savus puišus, tad tie tev to sacīs. Lai tad tie jaunekļi žēlastību atrod priekš tavām acīm, jo mēs labā dienā esam atnākuši. Dod jel saviem kalpiem un savam dēlam Dāvidam, kas tev pie rokas.
9 Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì lọ, wọ́n sì sọ fún Nabali gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní orúkọ Dafidi, wọ́n sì sinmi.
Kad nu Dāvida puiši bija nākuši un šos vārdus uz Nābalu no Dāvida puses runājuši, tad tie palika klusu.
10 Nabali sì dá àwọn ìránṣẹ́ Dafidi lóhùn pé, “Ta ni ń jẹ́ Dafidi? Tàbí ta ni sì ń jẹ́ ọmọ Jese? Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìránṣẹ́ ni ń bẹ ni ìsinsin yìí tí wọn sá olúkúlùkù kúrò lọ́dọ̀ olúwa rẹ̀.
Bet Nābals atbildēja Dāvida kalpiem un sacīja: kas tas tāds Dāvids un kas tas tāds Isajus dēls? Šinī laikā ir daudz kalpu, kas no saviem kungiem aizbēg.
11 Ǹjẹ́ ki èmi o mú oúnjẹ mi, àti omi mi, àti ẹran mi ti mo pa fún àwọn olùrẹ́run mi, ki èmi sì fi fún àwọn ọkùnrin ti èmi kò mọ̀ ibi wọ́n ti wá?”
Vai tad es savu maizi un ūdeni un savus lopus ņemšu, ko es priekš saviem cirpējiem esmu kāvis, un došu vīriem, ko es nepazīstu, no kurienes tie ir?
12 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n, wọ́n sì padà, wọ́n sì wá, wọn si rò fún un gẹ́gẹ́ bi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
Tad Dāvida puiši griezās atpakaļ uz savu ceļu un gāja atpakaļ un nāca un atsacīja viņam visus šos vārdus.
13 Dafidi sí wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Kí olúkúlùkù yín ó di idà rẹ́ mọ́ ìdí,” olúkúlùkù ọkùnrin sì di idà tirẹ̀ mọ́ ìdí; àti Dafidi pẹ̀lú sì di idà tirẹ̀; ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin si gòkè tọ Dafidi lẹ́yìn; igba si jókòó níbi ẹrù.
Tad Dāvids sacīja uz saviem vīriem: apjoziet ikviens savu zobenu. Tad ikviens apjoza savu zobenu. Un Dāvids apjoza arīdzan savu zobenu, un tie devās uz augšu Dāvidam pakaļ pie četrsimt vīru, un divsimt palika pie rīkiem.
14 Ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin Nabali si wí fún Abigaili aya rẹ̀ pé, “Wo o, Dafidi rán oníṣẹ́ láti aginjù wá láti kí olúwa wa; ó sì kanra mọ́ wọn.
Bet Abigaīlei, Nābala sievai, viens no tiem puišiem to stāstīja un sacīja: redzi, Dāvids ir vēstnešus sūtījis no tuksneša un mūsu kungu licis sveicināt, bet viņš tos izbāra.
15 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà ṣe oore fún wa gidigidi, wọn kò ṣe wá ní ibi kan, ohunkóhun kò nù ni ọwọ́ wa ni gbogbo ọjọ́ ti àwa bá wọn rìn nígbà ti àwa ń bẹ lóko.
Bet tie vīri mums ir bijuši ļoti labi, un mums nekā ļauna nav darījuši un mums nekas nav zudis visu to laiku, kad mēs pie tiem mituši, kad bijām laukā.
16 Odi ni wọ́n sá à jásí fún wa lọ́sàn án, àti lóru, ni gbogbo ọjọ́ ti a fi bá wọn gbé, tí a n bojútó àwọn àgùntàn.
Tie mums bijuši par mūri gan naktīm, gan dienām, visu to laiku, kad mēs pie tiem bijuši, avis ganīdami.
17 Ǹjẹ́, rò ó wò, kí ìwọ sì mọ èyí ti ìwọ yóò ṣe; nítorí pé a ti gbèrò ibi sí olúwa wa, àti sí gbogbo ilé rẹ̀; òun sì jásí ọmọ Beliali tí a kò le sọ̀rọ̀ fún.”
Un nu ņem vērā un raugi, ko tu dari, jo nelaime būs gatava pret mūsu kungu un pret visu viņa namu, un tas ir netikls vīrs, ka viņam nekā nevar sacīt.
18 Abigaili sì yára, ó sì mú igbá ìṣù àkàrà àti ìgò ọtí wáìnì méjì, àti àgùntàn márùn-ún, tí a ti ṣè, àti òsùwọ̀n àgbàdo yíyan márùn-ún, àti ọgọ́rùn-ún ìdì àjàrà, àti igba àkàrà èso ọ̀pọ̀tọ́, ó sì dìwọ́n ru kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Tad Abigaīle steidzās un ņēma divsimt maizes un divus ādas traukus ar vīnu un piecas kautas avis un piecus pūrus miltu un simts rozīņu raušu un divsimt vīģu raušu, un to krāva uz ēzeļiem.
19 Òun sì wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Máa lọ níwájú mi; wò ó, èmi ń bọ̀ lẹ́yìn yín,” ṣùgbọ́n òun kò wí fún Nabali baálé rẹ̀.
Un tā sacīja uz saviem puišiem: noejat manā priekšā, redzi, es būšu aiz jums. Bet savam vīram Nābalam, viņa par to tam nedeva ziņas.
20 Bí o ti gun orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó sì ń sọ̀kalẹ̀ sí ibi ìkọ̀kọ̀ òkè náà, wò ó, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì sọ̀kalẹ̀ níwájú rẹ̀; òun sì wá pàdé wọn.
Kad nu viņa uz ēzeļa jādama nonāca pakalnā, meža ēnā, redzi, tad Dāvids ar saviem vīriem nonāca viņai pretī, un viņa tos sastapa.
21 Dafidi sì ti wí pé, “Ǹjẹ́ lásán ni èmi ti pa gbogbo èyí tí i ṣe ti eléyìí ní aginjù, ti ohunkóhun kò sì nù nínú gbogbo èyí ti í ṣe tirẹ̀: òun ni ó sì fi ibi san ìre fún mi yìí.
Bet Dāvids bija sacījis: tiešām, es esmu velti sargājis visu, kas šim pieder tuksnesī, un tam nekas nav zudis no tā, kas viņam bija, bet viņš man maksā ļaunu par labu.
22 Bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, ni ki Ọlọ́run ó ṣe sí àwọn ọ̀tá Dafidi, bi èmi bá fi ọkùnrin kan sílẹ̀ nínú gbogbo èyí tí i ṣe tirẹ̀ títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀.”
Lai Dievs Dāvida ienaidniekiem šā un tā dara, ja es no visa, kas viņam pieder, līdz rītam vienu atlicināju, kas mīž pie sienas.
23 Abigaili sì rí Dafidi, ó sì yára, ó sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì dojúbolẹ̀ níwájú Dafidi, ó sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀.
Kad nu Abigaīle Dāvidu redzēja, tad viņa steidzās un nokāpa no ēzeļa un Dāvida priekšā krita uz savu vaigu un metās pie zemes.
24 Ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó wí pé, “Olúwa mi, fi ẹ̀ṣẹ̀ yìí yá mi: kí ó sì jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, sọ̀rọ̀ létí rẹ, kí ó sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.
Un tā krita viņam pie kājām un sacīja: ak mans kungs, pielīdzini man, man to noziegumu, un lai jel tava kalpone priekš tavām ausīm runā, un klausi tavas kalpones vārdus!
25 Olúwa mi, èmi bẹ̀ ọ́ má ka ọkùnrin Beliali yìí sí, àní Nabali. Nítorí pé bí orúkọ rẹ̀ ti jẹ́ bẹ́ẹ̀ ni òun náà rí. Nabali ni orúkọ rẹ̀, àìmoye si wà pẹ̀lú rẹ̀; ṣùgbọ́n èmi ìránṣẹ́bìnrin rẹ kò ri àwọn ọmọkùnrin olúwa mi, ti ìwọ rán.
Mans kungs, nedusmojies, lūdzams, par šo netiklo vīru, par Nābalu, jo viņš ir tāds, kā viņa vārds skan; Nābals (ģeķis) viņa vārds un ģeķība ir pie viņa, un es, tava kalpone, sava kunga puišus neesmu redzējusi, ko tu esi sūtījis.
26 Ǹjẹ́ olúwa mi, bi Olúwa ti wà láààyè, àti bí ẹ̀mí rẹ̀ si ti wà láààyè, bi Olúwa sì ti dá ọ dúró láti wá ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, àti láti fi ọwọ́ ara rẹ gba ẹ̀san; ǹjẹ́, kí àwọn ọ̀tá rẹ, àti àwọn ẹni tí ń gbèrò ibi sí olúwa mi rí bi i Nabali.
Nu tad, mans kungs, tik tiešām kā Tas Kungs dzīvs un tava dvēsele dzīva, Tas Kungs tevi ir noturējis, ka tu neesi nācis asinsgrēkā un neesi atriebies ar savu roku, un nu, kā Nābals, tā lai top tavi ienaidnieki un tie, kas pret manu kungu ļaunu domā.
27 Ǹjẹ́ èyí ni ẹ̀bùn tí ìránṣẹ́bìnrin rẹ mú wá fún olúwa mi, jẹ́ kí a sì fi fún àwọn ọmọkùnrin ti ń tọ olúwa mi lẹ́yìn.
Un šī nu ir tā svētība, ko tava kalpone savam kungam ir atnesusi; lai to dod tiem puišiem, kas manam kungam staigā pakaļ.
28 “Èmi bẹ̀ ọ́, fi ìrékọjá arábìnrin rẹ jìn ín, nítorí Olúwa yóò sá ṣe ilé òdodo fún olúwa mi, nítorí pé ó ja ogun Olúwa. Nítorí náà kí a má ri ibi kan ni ọwọ́ rẹ níwọ̀n ìgbà tí ó wà láààyè.
Piedod, lūdzams, tavai kalponei to pārkāpumu; jo Tas Kungs tiešām manam kungam dos pastāvīgu namu, tāpēc ka mans kungs karo Tā Kunga karu, un nekāds ļaunums tevi neaizņems ne mūžam.
29 Bí ọkùnrin kan bá sì dìde láti máa lépa rẹ, àti máa wá ẹ̀mí rẹ, a ó sì di ẹ̀mí olúwa mi nínú ìdì ìyè lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ; àti ẹ̀mí àwọn ọ̀tá rẹ ni a ó sì gbọ̀n sọnù gẹ́gẹ́ bí kànnàkànnà jáde.
Un kad kāds cilvēks pret tevi celsies, tevi vajāt un tavu dvēseli meklēt, tad mana kunga dvēsele būs iesieta tai dzīvo (dvēseļu) kūlītī pie Tā Kunga, tava Dieva, bet tavu ienaidnieku dvēsele taps kā no lingas izlingota.
30 Yóò sì ṣe, Olúwa yóò ṣe sí olúwa mi gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìre tí ó ti wí nípa tirẹ̀, yóò sì yàn ọ́ ni aláṣẹ lórí Israẹli.
Kad nu Tas Kungs manam kungam visu to labu darīs, ko Viņš par tevi runājis, un tevi cels par valdnieku pār Israēli,
31 Èyí kì yóò sì jásí ìbànújẹ́ fún ọ, tàbí ìbànújẹ́ ọkàn fún olúwa mi, nítorí pé ìwọ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, tàbí pé olúwa mi gba ẹ̀san fún ara rẹ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí Olúwa ba ṣe oore fún olúwa mi, ǹjẹ́ rántí ìránṣẹ́bìnrin rẹ!”
Tad manam kungam nebūs šis grēks un šis sirds grūtums, ka tu velti būtu asinis izlējis, un ka mans kungs pats sev būtu palīdzējies; un kad Tas Kungs manam kungam labu darīs, tad tu pieminēsi savu kalponi.
32 Dafidi sì wí fún Abigaili pé, “Alábùkún fún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ó rán ọ lónìí yìí láti pàdé mi.
Tad Dāvids sacīja uz Abigaīli: slavēts lai ir Tas Kungs, Israēla Dievs, kas tevi šodien man pretī sūtījis.
33 Ìbùkún ni fún ọgbọ́n rẹ, alábùkún sì ni ìwọ, tí ó da mi dúró lónìí yìí láti wá ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, àti láti fi ọwọ́ mi gba ẹ̀san fún ara mi.
Un slavēts lai ir tavs padoms, un svētīta esi tu pati, ka tu man šodien noturējusi, ka neesmu nācis asinsgrēkā, un ka ar savu roku neesmu atriebies.
34 Nítòótọ́, bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli tí ń bẹ, tí ó da mi dúró láti pa ọ́ lára bí kò ṣe pé bí ìwọ ti yára tí ó sì wá pàdé mi, nítòótọ́ kì bá tí kù fún Nabali di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ nínú àwọn ọkùnrin rẹ̀.”
Jo patiesi, tik tiešām kā Tas Kungs, Israēla Dievs, dzīvs, kas mani noturējis tev ļaunu darīt; ja tu nebūtu steigusies un man pretī nākusi, tad Nābalam nebūtu atlicis līdz rīta gaismai neviens, kas mīž pie sienas.
35 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gba nǹkan tí ó mú wá fún un lọ́wọ́ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Gòkè lọ ni àlàáfíà sí ilé rẹ, wò ó, èmi ti gbọ́ ohùn rẹ, inú mi sì dùn sí ọ.”
Tad Dāvids ņēma no viņas rokas, ko viņa tam bija atvedusi, un uz to sacīja: ej ar mieru atkal savās mājās! Redz, es tavu balsi esmu klausījis un tavu lūgšanu pieņēmis.
36 Abigaili sì tọ Nabali wá, sì wò ó, òun sì ṣe àsè ni ilé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àsè ọba: inú Nabali sì dùn nítorí pé, ó ti mú ọtí ni àmupara; òun kò si sọ nǹkan fún un, díẹ̀ tàbí púpọ̀: títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀
Kad nu Abigaīle pie Nābala nāca, redzi, tad tam bija dzīres savā namā, tāpat kā ķēniņa dzīres, un Nābala sirds priecājās pie sevis, un viņš bija ļoti piedzēries. Bet viņa tam ne vārda nesacīja, ne maza, ne liela, līdz rīta gaismai.
37 Ó sì ṣe; ni òwúrọ̀, nígbà ti ọtí náà si dá tán lójú Nabali, obìnrin rẹ̀ sì ro nǹkan wọ̀nyí fún un, ọkàn rẹ sì kú nínú rẹ̀, òun sì dàbí òkúta.
Un notikās rītā, kad vīns no Nābala bija izgājis, tad viņa sieva tam visu to stāstīja. Tad viņa sirds iekš viņa pamira, un viņš kļuva kā akmens.
38 Ó sì ṣe lẹ́yìn ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́wàá, Olúwa lu Nabali, ó sì kú.
Un pēc kādām desmit dienām Tas Kungs sita Nābalu, ka tas nomira.
39 Dafidi sì gbọ́ pé Nabali kú, ó sì wí pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí o gbèjà gígàn mi láti ọwọ́ Nabali wá, tí ó sì dá ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró láti ṣe ibi: Olúwa sì yí ìkà Nabali sí orí òun tìkára rẹ̀.” Dafidi sì ránṣẹ́, ó sì ba Abigaili sọ̀rọ̀ láti mú un fi ṣe aya fún ara rẹ̀.
Kad Dāvids dzirdēja, Nābalu esam mirušu, tad viņš sacīja: slavēts ir Tas Kungs, kas manu apsmieklu pie Nābala atriebis un Savu kalpu noturējis no ļauna, un ka Tas Kungs Nābalam to ļaunu uz viņa galvu maksājis. Un Dāvids nosūtīja un runāja uz Abigaīli, ka viņš to ņemtu par sievu.
40 Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì lọ sọ́dọ̀ Abigaili ni Karmeli, wọn sì sọ fún un pé, “Dafidi rán wá si ọ láti mu ọ ṣe aya rẹ̀.”
Tad Dāvida kalpi nāca pie Abigaīles uz Karmeli un runāja uz to un sacīja: Dāvids mūs pie tevis ir sūtījis, ka viņš tevi ņemtu sev par sievu.
41 Ó sì dìde, ó sì dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ ó jẹ́ ìránṣẹ́ kan láti máa wẹ ẹsẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi.”
Tad viņa cēlās un metās uz savu vaigu pie zemes un sacīja: redzi, še ir tava kalpone, ka tā kalpo un mazgā sava kunga kalpu kājas.
42 Abigaili sì yára, ó sì dìde, ó sì gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ márùn-ún sì tẹ̀lé e lẹ́yìn; òun sì tẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ Dafidi, o sì wá di aya rẹ̀.
Un Abigaīle steidzās un cēlās un jāja uz ēzeļa ar savām piecām jaunām meitām, kas viņai staigāja pakaļ, un tā gāja Dāvida vēstnešiem pakaļ un viņam palika par sievu.
43 Dafidi sì mú Ahinoamu ará Jesreeli; àwọn méjèèjì sì jẹ́ aya rẹ̀.
Un Dāvids ņēma arī Aķinoamu no Jezreēles, un tā šās abas viņam bija par sievām.
44 Ṣùgbọ́n Saulu ti fi Mikali ọmọ rẹ̀ obìnrin aya Dafidi, fún Palti ọmọ Laiṣi tí i ṣe ara Galimu.
Jo Sauls savu meitu Mikali, Dāvida sievu, bija devis Paltam, Laīsa dēlam, kas bija no Gallim.

< 1 Samuel 25 >