< 1 Samuel 25 >

1 Samuẹli sì kú; gbogbo ènìyàn Israẹli sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì sọkún rẹ̀ wọ́n sì sin ín nínú ilé rẹ̀ ní Rama. Dafidi sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ijù Parani.
Meghalt Sámuel, és összegyűlt egész Izrael, gyászt tartottak fölötte és eltemették házában, Rámában. – Fölkelt Dávid és lement Párán pusztájába.
2 Ọkùnrin kan sì ń bẹ ní Maoni, ẹni tí iṣẹ́ rẹ̀ ń bẹ ní Karmeli; ọkùnrin náà sì ní ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ní ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún ewúrẹ́: ó sì ń rẹ irun àgùntàn rẹ̀ ní Karmeli.
Volt egy ember Máónban, gazdasága pedig Karmellben; ez ember igen nagy volt: volt ugyanis neki háromezer juha és ezer kecskéje. És ő Karmellben volt, mikor juhait nyírták.
3 Orúkọ ọkùnrin náà sì ń jẹ́ Nabali, orúkọ aya rẹ̀ ń jẹ́ Abigaili; òun sì jẹ́ olóye obìnrin, àti arẹwà ènìyàn; ṣùgbọ́n òǹrorò àti oníwà búburú ni ọkùnrin; ẹni ìdílé Kalebu ni òun jẹ́.
Az embernek neve Nábál s feleségének neve Abígájil; az asszony jó eszű és szép alakú volt, a férfi pedig durva volt és rossz cselekedetű – ő Kálébbeli volt.
4 Dafidi sì gbọ́ ní aginjù pé Nabali ń rẹ́ irun àgùntàn rẹ̀.
Hallotta Dávid a pusztában, hogy Nábál a juhait nyírja;
5 Dafidi sì rán ọmọkùnrin mẹ́wàá, Dafidi sì sọ fún àwọn ọ̀dọ́kùnrin náà pé, “Ẹ gòkè lọ sí Karmeli, kí ẹ sì tọ Nabali lọ, kí ẹ sì kí i ni orúkọ mi.
akkor küldött Dávid tíz legényt, és mondta Dávid a legényeknek: Menjetek föl Karmellbe és midőn Nábálhoz elértek, kérdezzétek meg nevemben békéjéről.
6 Báyìí ni ẹ ó sì wí fún ẹni tí ó wà ni ìrora pé, ‘Àlàáfíà fún ọ! Àlàáfíà fún ohun gbogbo tí ìwọ ní!
És mondjátok: ekképpen az életre! Te is békében, házad is békében, és minden, ami a tied, békében!
7 “‘Ǹjẹ́ mo gbọ́ pé, àwọn olùrẹ́run ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ. Wò ó, àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ ti wà lọ́dọ̀ wa àwa kò sì pa wọ́n lára, wọn kò sì sọ ohunkóhun nù ní gbogbo ọjọ́ tí wọ́n wà ní Karmeli.
Most pedig, hallottam hogy nyírnak nálad; tehát, a te pásztoraid velünk voltak, nem bántottuk meg őket és nem hiányzott nekik semmi mindama napokban, hogy Karmellben voltak;
8 Bi àwọn ọmọkùnrin rẹ léèrè, wọn ó sì sọ fún ọ. Nítorí náà, jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí rí ojúrere lọ́dọ̀ rẹ; nítorí pé àwa sá wá ní ọjọ́ àsè: èmi bẹ̀ ọ́ ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà, fi fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àti fún Dafidi ọmọ rẹ.’”
kérdezd meg legényeidet, majd megmondják neked – találjanak hát legényeim kegyet szemeidben, mert szerencsés napra jöttünk; add, kérlek, azt amit talál kezed, szolgáidnak és fiadnak Dávidnak.
9 Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì lọ, wọ́n sì sọ fún Nabali gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní orúkọ Dafidi, wọ́n sì sinmi.
Odajöttek Dávid legényei és beszéltek Nábálhoz mind e szavak szerint Dávid nevében, és megálltak.
10 Nabali sì dá àwọn ìránṣẹ́ Dafidi lóhùn pé, “Ta ni ń jẹ́ Dafidi? Tàbí ta ni sì ń jẹ́ ọmọ Jese? Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìránṣẹ́ ni ń bẹ ni ìsinsin yìí tí wọn sá olúkúlùkù kúrò lọ́dọ̀ olúwa rẹ̀.
Felelt Nábál Dávid szolgáinak és mondta: Kicsoda Dávid és kicsoda Jisáj fia? Manapság sokan vannak a szolgák, akik megugranak kiki ura. elől.
11 Ǹjẹ́ ki èmi o mú oúnjẹ mi, àti omi mi, àti ẹran mi ti mo pa fún àwọn olùrẹ́run mi, ki èmi sì fi fún àwọn ọkùnrin ti èmi kò mọ̀ ibi wọ́n ti wá?”
Majd veszem kenyeremet és vizemet és levágott marhámat, amit levágtam nyíróim számára, hogy odaadjam embereknek, kikről nem tudom, honnan valók.
12 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n, wọ́n sì padà, wọ́n sì wá, wọn si rò fún un gẹ́gẹ́ bi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
Erre elfordultak Dávid legényei útjukra; visszatértek, eljutottak és megmondták neki mind e szavak szerint.
13 Dafidi sí wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Kí olúkúlùkù yín ó di idà rẹ́ mọ́ ìdí,” olúkúlùkù ọkùnrin sì di idà tirẹ̀ mọ́ ìdí; àti Dafidi pẹ̀lú sì di idà tirẹ̀; ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin si gòkè tọ Dafidi lẹ́yìn; igba si jókòó níbi ẹrù.
Ekkor mondta Dávid az ő embereinek: Kössétek föl kiki az ő kardját! És felkötötték kiki a kardját, és felkötötte Dávid is a kardját; és fölmentek Dávid után mintegy négyszáz ember, kétszázan pedig maradtak a poggyász mellett.
14 Ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin Nabali si wí fún Abigaili aya rẹ̀ pé, “Wo o, Dafidi rán oníṣẹ́ láti aginjù wá láti kí olúwa wa; ó sì kanra mọ́ wọn.
De Abígájilnak, Nábál feleségének, tudtára adta egyik legény a legények közül, mondván: Íme, küldött Dávid követeket a pusztából, hogy üdvözöljék urunkat, ő pedig rájuk rontott.
15 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà ṣe oore fún wa gidigidi, wọn kò ṣe wá ní ibi kan, ohunkóhun kò nù ni ọwọ́ wa ni gbogbo ọjọ́ ti àwa bá wọn rìn nígbà ti àwa ń bẹ lóko.
Ez emberek pedig igen jók hozzánk, nem bántódtunk meg és nem hiányzott nekünk semmi mind ama napokban, hogy velük jártunk, amikor a mezőn voltunk;
16 Odi ni wọ́n sá à jásí fún wa lọ́sàn án, àti lóru, ni gbogbo ọjọ́ ti a fi bá wọn gbé, tí a n bojútó àwọn àgùntàn.
fal voltak körülöttünk éjjel is, nappal is, mind a napokban, hogy velük voltunk, legeltetve a juhokat.
17 Ǹjẹ́, rò ó wò, kí ìwọ sì mọ èyí ti ìwọ yóò ṣe; nítorí pé a ti gbèrò ibi sí olúwa wa, àti sí gbogbo ilé rẹ̀; òun sì jásí ọmọ Beliali tí a kò le sọ̀rọ̀ fún.”
Most tehát tudd meg és lásd, mit cselekedjél, mert el van határozva a veszedelem urunk ellen és egész háza ellen; ő pedig alávalóbb, semhogy beszélni lehetne hozzá.
18 Abigaili sì yára, ó sì mú igbá ìṣù àkàrà àti ìgò ọtí wáìnì méjì, àti àgùntàn márùn-ún, tí a ti ṣè, àti òsùwọ̀n àgbàdo yíyan márùn-ún, àti ọgọ́rùn-ún ìdì àjàrà, àti igba àkàrà èso ọ̀pọ̀tọ́, ó sì dìwọ́n ru kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Ekkor sietett Abígájil és vett kétszáz kenyeret, két tömlő bort, öt elkészített juhot, öt mérték pörkölt gabonaszemet, száz aszuszőlőlepényt és kétszáz fügelepényt, és rátette a szamarakra.
19 Òun sì wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Máa lọ níwájú mi; wò ó, èmi ń bọ̀ lẹ́yìn yín,” ṣùgbọ́n òun kò wí fún Nabali baálé rẹ̀.
És mondta legényeinek: Vonuljatok előttem, íme én utánatok megyek; férjének, Nábálnak pedig nem mondta meg.
20 Bí o ti gun orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó sì ń sọ̀kalẹ̀ sí ibi ìkọ̀kọ̀ òkè náà, wò ó, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì sọ̀kalẹ̀ níwájú rẹ̀; òun sì wá pàdé wọn.
Volt pedig, amint ül a szamáron és lemegy a hegy hasadékán, íme, Dávid és emberei lejönnek elejébe, és rájuk talált.
21 Dafidi sì ti wí pé, “Ǹjẹ́ lásán ni èmi ti pa gbogbo èyí tí i ṣe ti eléyìí ní aginjù, ti ohunkóhun kò sì nù nínú gbogbo èyí ti í ṣe tirẹ̀: òun ni ó sì fi ibi san ìre fún mi yìí.
Dávid pedig mondta volt: Bizony hiába óvtam meg mindent, ami ezé a pusztában, nem hiányzott semmi mindabból, ami az övé, de rosszal fizetett nekem jóért.
22 Bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, ni ki Ọlọ́run ó ṣe sí àwọn ọ̀tá Dafidi, bi èmi bá fi ọkùnrin kan sílẹ̀ nínú gbogbo èyí tí i ṣe tirẹ̀ títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀.”
Így cselekedjék Isten Dávid ellenségeivel és így folytassa: nem hagyok meg mindabból, ami az övé, a reggel virradtáig egy falra vizelőt.
23 Abigaili sì rí Dafidi, ó sì yára, ó sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì dojúbolẹ̀ níwájú Dafidi, ó sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀.
Midőn meglátta Abígájil Dávidot, sietett és leszállt a szamárról: levetette magát Dávid előtt arcára és leborult földig.
24 Ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó wí pé, “Olúwa mi, fi ẹ̀ṣẹ̀ yìí yá mi: kí ó sì jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, sọ̀rọ̀ létí rẹ, kí ó sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.
Levetette magát lábaihoz és mondta: Én rajtam, uram, a bűn; hadd beszéljen, kérlek, szolgálód előtted és halljad szolgálód szavait.
25 Olúwa mi, èmi bẹ̀ ọ́ má ka ọkùnrin Beliali yìí sí, àní Nabali. Nítorí pé bí orúkọ rẹ̀ ti jẹ́ bẹ́ẹ̀ ni òun náà rí. Nabali ni orúkọ rẹ̀, àìmoye si wà pẹ̀lú rẹ̀; ṣùgbọ́n èmi ìránṣẹ́bìnrin rẹ kò ri àwọn ọmọkùnrin olúwa mi, ti ìwọ rán.
Ne fordítsa uram, kérlek, a szívét erre az alávaló emberre, lábára, mert amilyen a neve, olyan ő maga: Nábál a neve és aljasság van vele; én pedig, szolgálód, nem láttam Uram legényeit, akiket küldtél.
26 Ǹjẹ́ olúwa mi, bi Olúwa ti wà láààyè, àti bí ẹ̀mí rẹ̀ si ti wà láààyè, bi Olúwa sì ti dá ọ dúró láti wá ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, àti láti fi ọwọ́ ara rẹ gba ẹ̀san; ǹjẹ́, kí àwọn ọ̀tá rẹ, àti àwọn ẹni tí ń gbèrò ibi sí olúwa mi rí bi i Nabali.
Most tehát, uram, él az Örökkévaló és lelked életére, miután visszatartott téged az Örökkévaló attól, hogy vérbűnbe essél és hogy tenkezed segítsen magadnak, most tehát legyenek mint Nábál az ellenségeid és akik rosszra törnek uram ellen;
27 Ǹjẹ́ èyí ni ẹ̀bùn tí ìránṣẹ́bìnrin rẹ mú wá fún olúwa mi, jẹ́ kí a sì fi fún àwọn ọmọkùnrin ti ń tọ olúwa mi lẹ́yìn.
most tehát ez az ajándék, melyet hozott szolgálód uramnak, adassék a legényeknek, akik uram nyomában járnak.
28 “Èmi bẹ̀ ọ́, fi ìrékọjá arábìnrin rẹ jìn ín, nítorí Olúwa yóò sá ṣe ilé òdodo fún olúwa mi, nítorí pé ó ja ogun Olúwa. Nítorí náà kí a má ri ibi kan ni ọwọ́ rẹ níwọ̀n ìgbà tí ó wà láààyè.
Bocsásd meg, kérlek, szolgálód vétkét, mert az Örökkévaló uramnak állandó házat fog alapítani, mert uram az Örökkévaló harcait harcolja, valami rossz tehát ne találtassék rajtad élteden át.
29 Bí ọkùnrin kan bá sì dìde láti máa lépa rẹ, àti máa wá ẹ̀mí rẹ, a ó sì di ẹ̀mí olúwa mi nínú ìdì ìyè lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ; àti ẹ̀mí àwọn ọ̀tá rẹ ni a ó sì gbọ̀n sọnù gẹ́gẹ́ bí kànnàkànnà jáde.
Fölkelt egy ember, hogy üldözzön téged és hogy lelkedre törjön; de be lesz kötve uram lelke az élők kötésében az Örökkévalónál, Istenednél; ellenségeid lelkét pedig parittyázza a parittya fenekében!
30 Yóò sì ṣe, Olúwa yóò ṣe sí olúwa mi gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìre tí ó ti wí nípa tirẹ̀, yóò sì yàn ọ́ ni aláṣẹ lórí Israẹli.
És lesz, midőn tesz az Örökkévaló urammal mind aszerint, ami jót beszélt felőled, és majd rendel téged fejedelmül Izrael fölé:
31 Èyí kì yóò sì jásí ìbànújẹ́ fún ọ, tàbí ìbànújẹ́ ọkàn fún olúwa mi, nítorí pé ìwọ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, tàbí pé olúwa mi gba ẹ̀san fún ara rẹ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí Olúwa ba ṣe oore fún olúwa mi, ǹjẹ́ rántí ìránṣẹ́bìnrin rẹ!”
akkor ne legyen ez neked megütközésül, se szívbotlásul uramnak, hogy vért ontottál ok nélkül és hogy uram önmagának segített; s midőn majd jól tesz az Örökkévaló urammal, emlékezzél meg szolgálódról.
32 Dafidi sì wí fún Abigaili pé, “Alábùkún fún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ó rán ọ lónìí yìí láti pàdé mi.
Mondta Dávid Abígájilnak: Áldva legyen az Örökkévaló, Izrael Istene, aki küldött téged e napon elémbe;
33 Ìbùkún ni fún ọgbọ́n rẹ, alábùkún sì ni ìwọ, tí ó da mi dúró lónìí yìí láti wá ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, àti láti fi ọwọ́ mi gba ẹ̀san fún ara mi.
és áldott legyen eszed és áldott légy te magad, hogy meggátoltál e napon, hogy ne essem vérbűnbe és ne kezem segítsen magamnak.
34 Nítòótọ́, bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli tí ń bẹ, tí ó da mi dúró láti pa ọ́ lára bí kò ṣe pé bí ìwọ ti yára tí ó sì wá pàdé mi, nítòótọ́ kì bá tí kù fún Nabali di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ nínú àwọn ọkùnrin rẹ̀.”
Azonban, él az Örökkévaló, Izrael Istene, aki visszatartott engem attól, hogy veled rosszul bánjak: bizony, ha nem siettél és nem jöttél volna elém, bizony nem maradt volna Nábálnak reggel virradtáig falra vizelője.
35 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gba nǹkan tí ó mú wá fún un lọ́wọ́ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Gòkè lọ ni àlàáfíà sí ilé rẹ, wò ó, èmi ti gbọ́ ohùn rẹ, inú mi sì dùn sí ọ.”
És elfogadta Dávid a kezéből amit hozott neki; őneki pedig mondta: Menj föl békében házadba, lásd, hallgattam szavadra és tekintetbe vettelek.
36 Abigaili sì tọ Nabali wá, sì wò ó, òun sì ṣe àsè ni ilé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àsè ọba: inú Nabali sì dùn nítorí pé, ó ti mú ọtí ni àmupara; òun kò si sọ nǹkan fún un, díẹ̀ tàbí púpọ̀: títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀
Eljutott Abígájíl Nábálhoz és íme, neki lakomája volt házában, mint a király lakomája, Nábálnak a szíve vidám volt és őfelette részeg volt; de nem mondott meg neki semmit, sem kicsinyt sem nagyot, reggel virradtáig.
37 Ó sì ṣe; ni òwúrọ̀, nígbà ti ọtí náà si dá tán lójú Nabali, obìnrin rẹ̀ sì ro nǹkan wọ̀nyí fún un, ọkàn rẹ sì kú nínú rẹ̀, òun sì dàbí òkúta.
Volt pedig reggel, mikor elszállt a bor Nábálból, megmondta neki felesége e dolgokat; erre elhalt benne a szíve, s ő maga kővé lett.
38 Ó sì ṣe lẹ́yìn ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́wàá, Olúwa lu Nabali, ó sì kú.
És történt mintegy tíz nap múlva, megverte az Örökkévaló Nábált, és meghalt.
39 Dafidi sì gbọ́ pé Nabali kú, ó sì wí pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí o gbèjà gígàn mi láti ọwọ́ Nabali wá, tí ó sì dá ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró láti ṣe ibi: Olúwa sì yí ìkà Nabali sí orí òun tìkára rẹ̀.” Dafidi sì ránṣẹ́, ó sì ba Abigaili sọ̀rọ̀ láti mú un fi ṣe aya fún ara rẹ̀.
Midőn hallotta Dávid, hogy Nábál meghalt, mondta: Áldva legyen az Örökkévaló, aki viselte gyalázásom ügyét Nábál ellenében, szolgáját pedig visszatartotta rossztól és Nábál rosszaságát visszatérítette az Örökkévaló az ő fejére. Erre küldött Dávid és megkérte Abígájilt, hogy magának feleségül vegye.
40 Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì lọ sọ́dọ̀ Abigaili ni Karmeli, wọn sì sọ fún un pé, “Dafidi rán wá si ọ láti mu ọ ṣe aya rẹ̀.”
Eljöttek Dávid szolgái Abígájilhoz Karmellbe és beszéltek hozzá, mondván: Dávid küldött bennünket hozzád, hogy téged magának feleségül vegyen.
41 Ó sì dìde, ó sì dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ ó jẹ́ ìránṣẹ́ kan láti máa wẹ ẹsẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi.”
Fölkelt, arccal földre borult és mondta: Itt a szolgálód rabnőül, hogy uram szolgáinak lábait mossa.
42 Abigaili sì yára, ó sì dìde, ó sì gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ márùn-ún sì tẹ̀lé e lẹ́yìn; òun sì tẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ Dafidi, o sì wá di aya rẹ̀.
Ekkor sietett és fölkelt Abígájil, felült a szamárra, meg öt leányzója, kik nyomában mentek; ment Dávid követei után és lett neki feleségül.
43 Dafidi sì mú Ahinoamu ará Jesreeli; àwọn méjèèjì sì jẹ́ aya rẹ̀.
Achínóamot pedig elvette volt Dávid Jizreélből, és voltak mindketten neki feleségül.
44 Ṣùgbọ́n Saulu ti fi Mikali ọmọ rẹ̀ obìnrin aya Dafidi, fún Palti ọmọ Laiṣi tí i ṣe ara Galimu.
Sául pedig adta volt Míkhál leányát, Dávid feleségét a Gallimból való Paltínak, Lájis fiának.

< 1 Samuel 25 >