< 1 Samuel 25 >
1 Samuẹli sì kú; gbogbo ènìyàn Israẹli sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì sọkún rẹ̀ wọ́n sì sin ín nínú ilé rẹ̀ ní Rama. Dafidi sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ijù Parani.
Et Samuel mourut; et tout Israël se rassembla pour pleurer sur lui, et on l'inhuma dans la ville d'Armathem. Cependant David s'en retourna au désert de Maon.
2 Ọkùnrin kan sì ń bẹ ní Maoni, ẹni tí iṣẹ́ rẹ̀ ń bẹ ní Karmeli; ọkùnrin náà sì ní ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ní ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún ewúrẹ́: ó sì ń rẹ irun àgùntàn rẹ̀ ní Karmeli.
Il y avait alors en Maon un homme d'une très grande taille, et ses troupeaux étaient sur le mont Carmel; il possédait trois mille brebis et mille chèvres; or, il était à tondre ses brebis sur le Carmel.
3 Orúkọ ọkùnrin náà sì ń jẹ́ Nabali, orúkọ aya rẹ̀ ń jẹ́ Abigaili; òun sì jẹ́ olóye obìnrin, àti arẹwà ènìyàn; ṣùgbọ́n òǹrorò àti oníwà búburú ni ọkùnrin; ẹni ìdílé Kalebu ni òun jẹ́.
L'homme s'appelait Nabal, et sa femme Abigaïl, femme excellente par l'intelligence, et très belle de visage; mais l'homme était dur, méchant dans ses habitudes; c'était un homme grossier.
4 Dafidi sì gbọ́ ní aginjù pé Nabali ń rẹ́ irun àgùntàn rẹ̀.
David apprit dans le désert que Nabal, du Carmel, tondait ses brebis.
5 Dafidi sì rán ọmọkùnrin mẹ́wàá, Dafidi sì sọ fún àwọn ọ̀dọ́kùnrin náà pé, “Ẹ gòkè lọ sí Karmeli, kí ẹ sì tọ Nabali lọ, kí ẹ sì kí i ni orúkọ mi.
Et il envoya dix jeunes serviteurs, leur disant: Montez sur le Carmel, allez trouver Nabal et saluez-le en mon nom.
6 Báyìí ni ẹ ó sì wí fún ẹni tí ó wà ni ìrora pé, ‘Àlàáfíà fún ọ! Àlàáfíà fún ohun gbogbo tí ìwọ ní!
Voici ce que vous lui direz: Bonne santé à toi pour toujours, prospérité à ta maison et à tout ce que tu possèdes.
7 “‘Ǹjẹ́ mo gbọ́ pé, àwọn olùrẹ́run ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ. Wò ó, àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ ti wà lọ́dọ̀ wa àwa kò sì pa wọ́n lára, wọn kò sì sọ ohunkóhun nù ní gbogbo ọjọ́ tí wọ́n wà ní Karmeli.
Or, voici que je viens d'apprendre que tes bergers faisaient la tonte; ce sont ceux qui étaient avec nous dans le désert; nous ne leur avons jamais fait obstacle. Nous n'avons rien exigé d'eux, aussi longtemps qu'ils ont demeuré sur le Carmel.
8 Bi àwọn ọmọkùnrin rẹ léèrè, wọn ó sì sọ fún ọ. Nítorí náà, jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí rí ojúrere lọ́dọ̀ rẹ; nítorí pé àwa sá wá ní ọjọ́ àsè: èmi bẹ̀ ọ́ ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà, fi fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àti fún Dafidi ọmọ rẹ.’”
Interroge tes serviteurs, et ils te le déclareront; pour nous, tes serviteurs aussi, puissions-nous trouver grâce à tes yeux, car nous sommes venus en un jour heureux. Donne donc à ton fils David quelque chose que tu aies sous la main.
9 Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì lọ, wọ́n sì sọ fún Nabali gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní orúkọ Dafidi, wọ́n sì sinmi.
Les serviteurs partent; ils répètent à Nabal, au nom de David, toutes les paroles que celui-ci leur a dites. Mais Nabal fit un bond en arrière,
10 Nabali sì dá àwọn ìránṣẹ́ Dafidi lóhùn pé, “Ta ni ń jẹ́ Dafidi? Tàbí ta ni sì ń jẹ́ ọmọ Jese? Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìránṣẹ́ ni ń bẹ ni ìsinsin yìí tí wọn sá olúkúlùkù kúrò lọ́dọ̀ olúwa rẹ̀.
Et répondant aux serviteurs de David, il dit: Qu'est-ce que David? Qu'est-ce que le fils de Jessé? Le monde est plein aujourd'hui de serviteurs qui s'échappent de la maison de leur maître.
11 Ǹjẹ́ ki èmi o mú oúnjẹ mi, àti omi mi, àti ẹran mi ti mo pa fún àwọn olùrẹ́run mi, ki èmi sì fi fún àwọn ọkùnrin ti èmi kò mọ̀ ibi wọ́n ti wá?”
Oui, je vais prendre mon pain, mon vin, les victimes que j'ai sacrifiées pour mes tondeurs, et je vais les donner à des hommes qui viennent je ne sais d'où!
12 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n, wọ́n sì padà, wọ́n sì wá, wọn si rò fún un gẹ́gẹ́ bi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
Les serviteurs reprirent donc le chemin par lequel ils étaient venus, et ils arrivèrent, et ils rapportèrent cette réponse à David.
13 Dafidi sí wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Kí olúkúlùkù yín ó di idà rẹ́ mọ́ ìdí,” olúkúlùkù ọkùnrin sì di idà tirẹ̀ mọ́ ìdí; àti Dafidi pẹ̀lú sì di idà tirẹ̀; ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin si gòkè tọ Dafidi lẹ́yìn; igba si jókòó níbi ẹrù.
Alors, David dit à ses gens: Que chacun de vous ceigne son épée. Et environ quatre cents hommes s'en allèrent avec David; il en resta deux cents auprès des bagages.
14 Ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin Nabali si wí fún Abigaili aya rẹ̀ pé, “Wo o, Dafidi rán oníṣẹ́ láti aginjù wá láti kí olúwa wa; ó sì kanra mọ́ wọn.
Et l'un des serviteurs de Nabal parla à sa femme Abigaïl, disant: Voilà que David a envoyé du désert des messagers pour bénir notre maître, et il leur a tourné le dos.
15 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà ṣe oore fún wa gidigidi, wọn kò ṣe wá ní ibi kan, ohunkóhun kò nù ni ọwọ́ wa ni gbogbo ọjọ́ ti àwa bá wọn rìn nígbà ti àwa ń bẹ lóko.
Ce sont des hommes très bienveillants pour nous; ils ne nous ont point fait obstacle, ils n'ont rien exigé de nous, durant tout le temps que nous avons passé près d'eux.
16 Odi ni wọ́n sá à jásí fún wa lọ́sàn án, àti lóru, ni gbogbo ọjọ́ ti a fi bá wọn gbé, tí a n bojútó àwọn àgùntàn.
Et, tandis que nous étions aux champs, ils étaient pour nous comme un retranchement, nuit et jour, durant tout le temps que nous avons été près d'eux paissant nos troupeaux.
17 Ǹjẹ́, rò ó wò, kí ìwọ sì mọ èyí ti ìwọ yóò ṣe; nítorí pé a ti gbèrò ibi sí olúwa wa, àti sí gbogbo ilé rẹ̀; òun sì jásí ọmọ Beliali tí a kò le sọ̀rọ̀ fún.”
Et maintenant réfléchis, vois ce que tu as à faire; car le malheur fond sur notre maître et sa maison; lui-même est un fils de pestilence, et il n'y a pas à lui parler.
18 Abigaili sì yára, ó sì mú igbá ìṣù àkàrà àti ìgò ọtí wáìnì méjì, àti àgùntàn márùn-ún, tí a ti ṣè, àti òsùwọ̀n àgbàdo yíyan márùn-ún, àti ọgọ́rùn-ún ìdì àjàrà, àti igba àkàrà èso ọ̀pọ̀tọ́, ó sì dìwọ́n ru kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Et Abigaïl se hâta; elle prit deux cents pains, deux vases pleins de vin, cinq brebis apprêtées, cinq éphi de fleur de farine, un gomor de raisins secs, deux cents cabas de figues, et elle les chargea sur des ânes.
19 Òun sì wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Máa lọ níwájú mi; wò ó, èmi ń bọ̀ lẹ́yìn yín,” ṣùgbọ́n òun kò wí fún Nabali baálé rẹ̀.
Puis, elle dit à ses serviteurs: Partez devant moi; voilà que je vous suis. Mais elle ne dit rien à son mari.
20 Bí o ti gun orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó sì ń sọ̀kalẹ̀ sí ibi ìkọ̀kọ̀ òkè náà, wò ó, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì sọ̀kalẹ̀ níwájú rẹ̀; òun sì wá pàdé wọn.
Or, tandis qu'elle cheminait sur son ânesse et qu'elle descendait cachée par les plis de la montagne, David et ses gens montaient par le même chemin, de sorte qu'elle les rencontra.
21 Dafidi sì ti wí pé, “Ǹjẹ́ lásán ni èmi ti pa gbogbo èyí tí i ṣe ti eléyìí ní aginjù, ti ohunkóhun kò sì nù nínú gbogbo èyí ti í ṣe tirẹ̀: òun ni ó sì fi ibi san ìre fún mi yìí.
Et David disait: J'ai gardé équitablement dans le désert un homme injuste et tout ce qui lui appartenait, je n'ai jamais ordonné qu'on lui en prît la moindre chose, et il m'a rendu le mal pour le bien.
22 Bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, ni ki Ọlọ́run ó ṣe sí àwọn ọ̀tá Dafidi, bi èmi bá fi ọkùnrin kan sílẹ̀ nínú gbogbo èyí tí i ṣe tirẹ̀ títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀.”
Que le Seigneur punisse David et le punisse encore, si de tout ce qui est à Nabal je laisse jusqu'à demain matin quelque chose en vie, ne fût-ce qu'un chien.
23 Abigaili sì rí Dafidi, ó sì yára, ó sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì dojúbolẹ̀ níwájú Dafidi, ó sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀.
Et Abigaïl vit David; aussitôt, elle sauta de son ânesse, elle tomba devant David la face contre terre, et resta prosternée
24 Ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó wí pé, “Olúwa mi, fi ẹ̀ṣẹ̀ yìí yá mi: kí ó sì jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, sọ̀rọ̀ létí rẹ, kí ó sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.
A ses pieds, disant: Ne fais retomber sur moi que ma propre iniquité, seigneur; que ta servante te parle; écoute les paroles de ta servante;
25 Olúwa mi, èmi bẹ̀ ọ́ má ka ọkùnrin Beliali yìí sí, àní Nabali. Nítorí pé bí orúkọ rẹ̀ ti jẹ́ bẹ́ẹ̀ ni òun náà rí. Nabali ni orúkọ rẹ̀, àìmoye si wà pẹ̀lú rẹ̀; ṣùgbọ́n èmi ìránṣẹ́bìnrin rẹ kò ri àwọn ọmọkùnrin olúwa mi, ti ìwọ rán.
Que mon seigneur ne fasse pas attention à cet homme de pestilence; car il est bien ce que son nom indique; il se nomme Nabal (fou), et la folie est avec lui. Mais moi, ta servante, je n'ai point vu les serviteurs de mon seigneur, que tu avais envoyés.
26 Ǹjẹ́ olúwa mi, bi Olúwa ti wà láààyè, àti bí ẹ̀mí rẹ̀ si ti wà láààyè, bi Olúwa sì ti dá ọ dúró láti wá ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, àti láti fi ọwọ́ ara rẹ gba ẹ̀san; ǹjẹ́, kí àwọn ọ̀tá rẹ, àti àwọn ẹni tí ń gbèrò ibi sí olúwa mi rí bi i Nabali.
Maintenant, mon seigneur, vive le Seigneur et vive ton âme! D'autant plus que ton Seigneur t'a empêché de verser le sang innocent et de te venger par ta main. Puissent ressembler à Nabal tes ennemis et ceux qui veulent nuire à mon seigneur.
27 Ǹjẹ́ èyí ni ẹ̀bùn tí ìránṣẹ́bìnrin rẹ mú wá fún olúwa mi, jẹ́ kí a sì fi fún àwọn ọmọkùnrin ti ń tọ olúwa mi lẹ́yìn.
Accepte donc cette bénédiction que ta servante a apportée à mon seigneur; tu la distribueras aux serviteurs qui accompagnent mon seigneur.
28 “Èmi bẹ̀ ọ́, fi ìrékọjá arábìnrin rẹ jìn ín, nítorí Olúwa yóò sá ṣe ilé òdodo fún olúwa mi, nítorí pé ó ja ogun Olúwa. Nítorí náà kí a má ri ibi kan ni ọwọ́ rẹ níwọ̀n ìgbà tí ó wà láààyè.
Détourne de ta servante la peine de l'iniquité, car le Seigneur, pour mon seigneur, édifiera certainement une maison sûre; le Seigneur combat pour mon seigneur en toutes ses batailles, et jamais le malheur ne se trouvera avec toi.
29 Bí ọkùnrin kan bá sì dìde láti máa lépa rẹ, àti máa wá ẹ̀mí rẹ, a ó sì di ẹ̀mí olúwa mi nínú ìdì ìyè lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ; àti ẹ̀mí àwọn ọ̀tá rẹ ni a ó sì gbọ̀n sọnù gẹ́gẹ́ bí kànnàkànnà jáde.
Et si un homme s'élève qui te poursuive, et en veuille à ta vie, l'âme de mon seigneur sera maintenue dans les liens de la vie par la volonté du Seigneur Dieu, et tu feras tournoyer la vie de tes adversaires, comme au milieu d'une fronde.
30 Yóò sì ṣe, Olúwa yóò ṣe sí olúwa mi gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìre tí ó ti wí nípa tirẹ̀, yóò sì yàn ọ́ ni aláṣẹ lórí Israẹli.
Et lorsque le Seigneur aura fait à mon seigneur tout le bien qu'il lui a promis, il te donnera la mission de régner sur Israël.
31 Èyí kì yóò sì jásí ìbànújẹ́ fún ọ, tàbí ìbànújẹ́ ọkàn fún olúwa mi, nítorí pé ìwọ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, tàbí pé olúwa mi gba ẹ̀san fún ara rẹ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí Olúwa ba ṣe oore fún olúwa mi, ǹjẹ́ rántí ìránṣẹ́bìnrin rẹ!”
Et mon seigneur n'aura point commis le péché et l'abomination de verser, sans cause, le sang innocent ni de se venger par sa main; et le Seigneur sera bienveillant pour mon seigneur; et tu te souviendras de ta servante, tu seras bienveillant pour elle.
32 Dafidi sì wí fún Abigaili pé, “Alábùkún fún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ó rán ọ lónìí yìí láti pàdé mi.
Et David dit à Abigaïl: Béni soit le Seigneur Dieu d'Israël, qui t'a envoyée aujourd'hui au-devant de moi.
33 Ìbùkún ni fún ọgbọ́n rẹ, alábùkún sì ni ìwọ, tí ó da mi dúró lónìí yìí láti wá ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, àti láti fi ọwọ́ mi gba ẹ̀san fún ara mi.
Bénie sois ta résolution; bénie sois-tu toi-même, qui m'as empêché aujourd'hui de verser le sang innocent et de me venger par ma main.
34 Nítòótọ́, bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli tí ń bẹ, tí ó da mi dúró láti pa ọ́ lára bí kò ṣe pé bí ìwọ ti yára tí ó sì wá pàdé mi, nítòótọ́ kì bá tí kù fún Nabali di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ nínú àwọn ọkùnrin rẹ̀.”
Mais, vive le Seigneur Dieu; vivant d'Israël, qui m'empêche aujourd'hui de te maltraiter! sans ton empressement à venir à ma rencontre, j'avais dit: de ne laisserai rien en vie chez Nabal jusqu'à demain matin.
35 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gba nǹkan tí ó mú wá fún un lọ́wọ́ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Gòkè lọ ni àlàáfíà sí ilé rẹ, wò ó, èmi ti gbọ́ ohùn rẹ, inú mi sì dùn sí ọ.”
David prit de ses mains tout ce qu'elle lui avait apporté, et il lui dit: Retourne en paix à ta demeure. Vois, je t'ai accordé ce que tu m'as demandé, et je me suis réjoui de ta présence.
36 Abigaili sì tọ Nabali wá, sì wò ó, òun sì ṣe àsè ni ilé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àsè ọba: inú Nabali sì dùn nítorí pé, ó ti mú ọtí ni àmupara; òun kò si sọ nǹkan fún un, díẹ̀ tàbí púpọ̀: títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀
Abigaïl rentra donc chez Nabal, et il y avait en sa maison un festin comme un festin de roi; Nabal montrait la joie de son cœur; il était complètement ivre. Jusqu'aux lueurs du matin, sa femme ne lui dit aucune chose, grande ni petite.
37 Ó sì ṣe; ni òwúrọ̀, nígbà ti ọtí náà si dá tán lójú Nabali, obìnrin rẹ̀ sì ro nǹkan wọ̀nyí fún un, ọkàn rẹ sì kú nínú rẹ̀, òun sì dàbí òkúta.
Le jour parut; comme Nabal avait cuvé son vin, elle lui raconta tout; aussitôt le cœur lui manqua et lui-même fut comme une pierre.
38 Ó sì ṣe lẹ́yìn ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́wàá, Olúwa lu Nabali, ó sì kú.
Il passa en cet état dix jours; puis, le Seigneur l'ayant frappé, il expira.
39 Dafidi sì gbọ́ pé Nabali kú, ó sì wí pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí o gbèjà gígàn mi láti ọwọ́ Nabali wá, tí ó sì dá ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró láti ṣe ibi: Olúwa sì yí ìkà Nabali sí orí òun tìkára rẹ̀.” Dafidi sì ránṣẹ́, ó sì ba Abigaili sọ̀rọ̀ láti mú un fi ṣe aya fún ara rẹ̀.
David l'apprit, et il dit: Béni soit le Seigneur, qui a jugé l'outrage que j'avais reçu de Nabal, et qui a sauvé son serviteur des mains des méchants, et qui a fait retomber l'iniquité de Nabal sur sa tête. Ensuite, David envoya chez Abigaïl, et lui fit parler pour la prendre en mariage.
40 Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì lọ sọ́dọ̀ Abigaili ni Karmeli, wọn sì sọ fún un pé, “Dafidi rán wá si ọ láti mu ọ ṣe aya rẹ̀.”
Les serviteurs de David arrivèrent au Carmel chez Abigaïl, et ils lui parlèrent, disant: David nous a envoyés vers toi afin de te prendre pour sa femme.
41 Ó sì dìde, ó sì dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ ó jẹ́ ìránṣẹ́ kan láti máa wẹ ẹsẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi.”
A ces mots, elle se leva et elle se prosterna la face contre terre, et elle dit: Voici ta servante, emploie-la comme une esclave à laver les pieds de tes serviteurs.
42 Abigaili sì yára, ó sì dìde, ó sì gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ márùn-ún sì tẹ̀lé e lẹ́yìn; òun sì tẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ Dafidi, o sì wá di aya rẹ̀.
Abigaïl se releva, elle monta sur une ânesse, cinq jeunes filles l'accompagnèrent; elle suivit les serviteurs de David, et elle fut sa femme.
43 Dafidi sì mú Ahinoamu ará Jesreeli; àwọn méjèèjì sì jẹ́ aya rẹ̀.
David avait déjà épousé Achinaam de Jezraël; toutes les deux étaient ses femmes;
44 Ṣùgbọ́n Saulu ti fi Mikali ọmọ rẹ̀ obìnrin aya Dafidi, fún Palti ọmọ Laiṣi tí i ṣe ara Galimu.
Et Saül avait donné sa fille Michol, la femme de David, à Phalti, fils d'Amis de Rhomma.