< 1 Samuel 25 >

1 Samuẹli sì kú; gbogbo ènìyàn Israẹli sì kó ara wọn jọ, wọ́n sì sọkún rẹ̀ wọ́n sì sin ín nínú ilé rẹ̀ ní Rama. Dafidi sì dìde, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ijù Parani.
Samuel mourut. Tout Israël se rassembla, prit le deuil et l'enterra dans sa maison à Rama. David se leva et descendit dans le désert de Paran.
2 Ọkùnrin kan sì ń bẹ ní Maoni, ẹni tí iṣẹ́ rẹ̀ ń bẹ ní Karmeli; ọkùnrin náà sì ní ọrọ̀ púpọ̀, ó sì ní ẹgbẹ̀rún mẹ́ta àgùntàn, àti ẹgbẹ̀rún ewúrẹ́: ó sì ń rẹ irun àgùntàn rẹ̀ ní Karmeli.
Il y avait à Maon un homme dont les biens étaient au Carmel, et cet homme était très grand. Il avait trois mille brebis et mille chèvres, et il tondait ses brebis au Carmel.
3 Orúkọ ọkùnrin náà sì ń jẹ́ Nabali, orúkọ aya rẹ̀ ń jẹ́ Abigaili; òun sì jẹ́ olóye obìnrin, àti arẹwà ènìyàn; ṣùgbọ́n òǹrorò àti oníwà búburú ni ọkùnrin; ẹni ìdílé Kalebu ni òun jẹ́.
Or le nom de cet homme était Nabal, et le nom de sa femme Abigaïl. Cette femme était intelligente et avait un beau visage; mais l'homme était hargneux et méchant dans ses actions. Il était de la maison de Caleb.
4 Dafidi sì gbọ́ ní aginjù pé Nabali ń rẹ́ irun àgùntàn rẹ̀.
David apprit dans le désert que Nabal tondait ses brebis.
5 Dafidi sì rán ọmọkùnrin mẹ́wàá, Dafidi sì sọ fún àwọn ọ̀dọ́kùnrin náà pé, “Ẹ gòkè lọ sí Karmeli, kí ẹ sì tọ Nabali lọ, kí ẹ sì kí i ni orúkọ mi.
David envoya dix jeunes gens. Il leur dit: « Montez au Carmel, allez vers Nabal, et saluez-le en mon nom.
6 Báyìí ni ẹ ó sì wí fún ẹni tí ó wà ni ìrora pé, ‘Àlàáfíà fún ọ! Àlàáfíà fún ohun gbogbo tí ìwọ ní!
Dites-lui: « Longue vie à toi! Que la paix soit avec toi! Que la paix soit avec ta maison! Que la paix soit avec tout ce qui t'appartient!
7 “‘Ǹjẹ́ mo gbọ́ pé, àwọn olùrẹ́run ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ. Wò ó, àwọn olùṣọ́-àgùntàn rẹ ti wà lọ́dọ̀ wa àwa kò sì pa wọ́n lára, wọn kò sì sọ ohunkóhun nù ní gbogbo ọjọ́ tí wọ́n wà ní Karmeli.
J'ai appris que tu as des tondeurs. Vos bergers ont maintenant été avec nous, et nous ne leur avons fait aucun mal. Rien n'a manqué d'eux pendant tout le temps qu'ils ont été au Carmel.
8 Bi àwọn ọmọkùnrin rẹ léèrè, wọn ó sì sọ fún ọ. Nítorí náà, jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí rí ojúrere lọ́dọ̀ rẹ; nítorí pé àwa sá wá ní ọjọ́ àsè: èmi bẹ̀ ọ́ ohunkóhun tí ọwọ́ rẹ bá bà, fi fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ, àti fún Dafidi ọmọ rẹ.’”
Interrogez vos jeunes gens, et ils vous le diront. Que les jeunes gens trouvent grâce à tes yeux, car nous venons en un jour favorable. Donne, je te prie, tout ce qui te tombe sous la main à tes serviteurs et à ton fils David.'"
9 Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì lọ, wọ́n sì sọ fún Nabali gẹ́gẹ́ bí gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ní orúkọ Dafidi, wọ́n sì sinmi.
Lorsque les jeunes gens de David arrivèrent, ils dirent à Nabal toutes ces paroles au nom de David, et ils attendirent.
10 Nabali sì dá àwọn ìránṣẹ́ Dafidi lóhùn pé, “Ta ni ń jẹ́ Dafidi? Tàbí ta ni sì ń jẹ́ ọmọ Jese? Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìránṣẹ́ ni ń bẹ ni ìsinsin yìí tí wọn sá olúkúlùkù kúrò lọ́dọ̀ olúwa rẹ̀.
Nabal répondit aux serviteurs de David et dit: « Qui est David? Qui est le fils de Jessé? Il y a beaucoup de serviteurs qui se séparent de leurs maîtres ces jours-ci.
11 Ǹjẹ́ ki èmi o mú oúnjẹ mi, àti omi mi, àti ẹran mi ti mo pa fún àwọn olùrẹ́run mi, ki èmi sì fi fún àwọn ọkùnrin ti èmi kò mọ̀ ibi wọ́n ti wá?”
Dois-je donc prendre mon pain, mon eau et la viande que j'ai tuée pour mes tondeurs, et les donner à des hommes dont j'ignore l'origine? ».
12 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì mú ọ̀nà wọn pọ̀n, wọ́n sì padà, wọ́n sì wá, wọn si rò fún un gẹ́gẹ́ bi gbogbo ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.
Et les jeunes gens de David s'en retournèrent sur leur chemin, et vinrent lui rapporter toutes ces paroles.
13 Dafidi sí wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Kí olúkúlùkù yín ó di idà rẹ́ mọ́ ìdí,” olúkúlùkù ọkùnrin sì di idà tirẹ̀ mọ́ ìdí; àti Dafidi pẹ̀lú sì di idà tirẹ̀; ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin si gòkè tọ Dafidi lẹ́yìn; igba si jókòó níbi ẹrù.
David dit à ses hommes: « Que chacun mette son épée! » Chaque homme a mis son épée. David mit aussi son épée. Environ quatre cents hommes suivirent David, et deux cents restèrent près des bagages.
14 Ọ̀kan nínú àwọn ọmọkùnrin Nabali si wí fún Abigaili aya rẹ̀ pé, “Wo o, Dafidi rán oníṣẹ́ láti aginjù wá láti kí olúwa wa; ó sì kanra mọ́ wọn.
Mais l'un des jeunes gens dit à Abigaïl, la femme de Nabal: « Voici, David a envoyé des messagers du désert pour saluer notre maître, et il les a insultés.
15 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà ṣe oore fún wa gidigidi, wọn kò ṣe wá ní ibi kan, ohunkóhun kò nù ni ọwọ́ wa ni gbogbo ọjọ́ ti àwa bá wọn rìn nígbà ti àwa ń bẹ lóko.
Mais ces hommes ont été très bons avec nous, et nous n'avons pas été blessés, et nous n'avons rien manqué tant que nous avons été avec eux, quand nous étions dans les champs.
16 Odi ni wọ́n sá à jásí fún wa lọ́sàn án, àti lóru, ni gbogbo ọjọ́ ti a fi bá wọn gbé, tí a n bojútó àwọn àgùntàn.
Ils étaient pour nous une muraille, de nuit comme de jour, pendant tout le temps que nous étions avec eux à garder les brebis.
17 Ǹjẹ́, rò ó wò, kí ìwọ sì mọ èyí ti ìwọ yóò ṣe; nítorí pé a ti gbèrò ibi sí olúwa wa, àti sí gbogbo ilé rẹ̀; òun sì jásí ọmọ Beliali tí a kò le sọ̀rọ̀ fún.”
Maintenant donc, sachez et réfléchissez à ce que vous ferez, car le mal est décidé contre notre maître et contre toute sa maison, car il est si inutile qu'on ne peut pas lui parler. »
18 Abigaili sì yára, ó sì mú igbá ìṣù àkàrà àti ìgò ọtí wáìnì méjì, àti àgùntàn márùn-ún, tí a ti ṣè, àti òsùwọ̀n àgbàdo yíyan márùn-ún, àti ọgọ́rùn-ún ìdì àjàrà, àti igba àkàrà èso ọ̀pọ̀tọ́, ó sì dìwọ́n ru kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
Alors Abigaïl se hâta de prendre deux cents pains, deux récipients de vin, cinq moutons apprêtés, cinq seahs de grains secs, cent grappes de raisins secs et deux cents gâteaux de figues, et les fit monter sur des ânes.
19 Òun sì wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Máa lọ níwájú mi; wò ó, èmi ń bọ̀ lẹ́yìn yín,” ṣùgbọ́n òun kò wí fún Nabali baálé rẹ̀.
Elle dit à ses jeunes gens: « Passez devant moi. Voici que je viens après vous. » Mais elle ne le dit pas à son mari, Nabal.
20 Bí o ti gun orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó sì ń sọ̀kalẹ̀ sí ibi ìkọ̀kọ̀ òkè náà, wò ó, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì sọ̀kalẹ̀ níwájú rẹ̀; òun sì wá pàdé wọn.
Comme elle montait sur son âne et descendait cachée par la montagne, voici que David et ses hommes descendaient vers elle, et elle les rencontra.
21 Dafidi sì ti wí pé, “Ǹjẹ́ lásán ni èmi ti pa gbogbo èyí tí i ṣe ti eléyìí ní aginjù, ti ohunkóhun kò sì nù nínú gbogbo èyí ti í ṣe tirẹ̀: òun ni ó sì fi ibi san ìre fún mi yìí.
Or David avait dit: « C'est en vain que j'ai gardé tout ce que cet homme a dans le désert, de sorte que rien n'a manqué de tout ce qui lui appartenait. Il m'a rendu le mal pour le bien.
22 Bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ, ni ki Ọlọ́run ó ṣe sí àwọn ọ̀tá Dafidi, bi èmi bá fi ọkùnrin kan sílẹ̀ nínú gbogbo èyí tí i ṣe tirẹ̀ títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀.”
Que Dieu fasse ainsi aux ennemis de David, et plus encore, si je laisse de tout ce qui lui appartient à la lumière du matin autant que quelqu'un qui urine sur un mur. »
23 Abigaili sì rí Dafidi, ó sì yára, ó sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì dojúbolẹ̀ níwájú Dafidi, ó sì rẹ ara rẹ̀ sílẹ̀.
Lorsqu'Abigaïl vit David, elle se précipita, descendit de son âne, tomba devant David sur sa face et se prosterna à terre.
24 Ó sì wólẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ̀, ó wí pé, “Olúwa mi, fi ẹ̀ṣẹ̀ yìí yá mi: kí ó sì jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ, èmi bẹ̀ ọ́, sọ̀rọ̀ létí rẹ, kí ó sì gbọ́ ọ̀rọ̀ ìránṣẹ́bìnrin rẹ.
Elle tomba à ses pieds et dit: « C'est à moi, mon seigneur, que revient la faute! Laisse ton serviteur parler à tes oreilles. Écoute les paroles de ta servante.
25 Olúwa mi, èmi bẹ̀ ọ́ má ka ọkùnrin Beliali yìí sí, àní Nabali. Nítorí pé bí orúkọ rẹ̀ ti jẹ́ bẹ́ẹ̀ ni òun náà rí. Nabali ni orúkọ rẹ̀, àìmoye si wà pẹ̀lú rẹ̀; ṣùgbọ́n èmi ìránṣẹ́bìnrin rẹ kò ri àwọn ọmọkùnrin olúwa mi, ti ìwọ rán.
Ne permets pas à mon seigneur d'être attentif à ce bon à rien de Nabal, car il est comme son nom. Nabal est son nom, et la folie est avec lui; mais moi, ton serviteur, je n'ai pas vu les jeunes gens de mon seigneur que tu as envoyés.
26 Ǹjẹ́ olúwa mi, bi Olúwa ti wà láààyè, àti bí ẹ̀mí rẹ̀ si ti wà láààyè, bi Olúwa sì ti dá ọ dúró láti wá ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, àti láti fi ọwọ́ ara rẹ gba ẹ̀san; ǹjẹ́, kí àwọn ọ̀tá rẹ, àti àwọn ẹni tí ń gbèrò ibi sí olúwa mi rí bi i Nabali.
Maintenant, mon seigneur, comme l'Éternel est vivant et comme ton âme est vivante, puisque l'Éternel t'a empêché de te rendre coupable par le sang et de te venger de ta propre main, maintenant, que tes ennemis et ceux qui cherchent à nuire à mon seigneur soient comme Nabal.
27 Ǹjẹ́ èyí ni ẹ̀bùn tí ìránṣẹ́bìnrin rẹ mú wá fún olúwa mi, jẹ́ kí a sì fi fún àwọn ọmọkùnrin ti ń tọ olúwa mi lẹ́yìn.
Maintenant, ce présent que ton serviteur a apporté à mon seigneur, qu'il soit donné aux jeunes gens qui suivent mon seigneur.
28 “Èmi bẹ̀ ọ́, fi ìrékọjá arábìnrin rẹ jìn ín, nítorí Olúwa yóò sá ṣe ilé òdodo fún olúwa mi, nítorí pé ó ja ogun Olúwa. Nítorí náà kí a má ri ibi kan ni ọwọ́ rẹ níwọ̀n ìgbà tí ó wà láààyè.
Je te prie de pardonner la faute de ton serviteur. Car l'Éternel fera de mon seigneur une maison sûre, parce que mon seigneur mène les combats de l'Éternel. Le mal ne se trouvera pas chez toi tous tes jours.
29 Bí ọkùnrin kan bá sì dìde láti máa lépa rẹ, àti máa wá ẹ̀mí rẹ, a ó sì di ẹ̀mí olúwa mi nínú ìdì ìyè lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run rẹ; àti ẹ̀mí àwọn ọ̀tá rẹ ni a ó sì gbọ̀n sọnù gẹ́gẹ́ bí kànnàkànnà jáde.
Si des hommes se lèvent pour te poursuivre et chercher ton âme, l'âme de mon seigneur sera liée dans le faisceau de vie de Yahvé ton Dieu. Il fera sortir les âmes de tes ennemis comme de la poche d'une fronde.
30 Yóò sì ṣe, Olúwa yóò ṣe sí olúwa mi gẹ́gẹ́ bí gbogbo ìre tí ó ti wí nípa tirẹ̀, yóò sì yàn ọ́ ni aláṣẹ lórí Israẹli.
Lorsque l'Éternel aura fait à mon seigneur tout le bien qu'il a dit de toi et qu'il t'aura établi chef d'Israël,
31 Èyí kì yóò sì jásí ìbànújẹ́ fún ọ, tàbí ìbànújẹ́ ọkàn fún olúwa mi, nítorí pé ìwọ ta ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sílẹ̀, tàbí pé olúwa mi gba ẹ̀san fún ara rẹ̀, ṣùgbọ́n nígbà tí Olúwa ba ṣe oore fún olúwa mi, ǹjẹ́ rántí ìránṣẹ́bìnrin rẹ!”
tu ne seras pas affligé, et mon seigneur ne sera pas offensé, soit que tu aies versé du sang sans raison, soit que mon seigneur se soit vengé. Quand Yahvé aura fait du bien à mon seigneur, souviens-toi de ton serviteur. »
32 Dafidi sì wí fún Abigaili pé, “Alábùkún fún ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ó rán ọ lónìí yìí láti pàdé mi.
David dit à Abigaïl: « Béni soit Yahvé, le Dieu d'Israël, qui t'a envoyée aujourd'hui à ma rencontre!
33 Ìbùkún ni fún ọgbọ́n rẹ, alábùkún sì ni ìwọ, tí ó da mi dúró lónìí yìí láti wá ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, àti láti fi ọwọ́ mi gba ẹ̀san fún ara mi.
Béni soit ta discrétion, et bénie sois-tu, qui m'a empêché aujourd'hui de me rendre coupable de sang, et de me venger de ma propre main.
34 Nítòótọ́, bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli tí ń bẹ, tí ó da mi dúró láti pa ọ́ lára bí kò ṣe pé bí ìwọ ti yára tí ó sì wá pàdé mi, nítòótọ́ kì bá tí kù fún Nabali di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ nínú àwọn ọkùnrin rẹ̀.”
En effet, comme vit Yahvé, le Dieu d'Israël, qui m'a empêché de te faire du mal, si tu ne t'étais pas empressé de venir à ma rencontre, il ne serait pas resté à Nabal, à la lumière du matin, plus qu'un homme qui urine sur un mur. »
35 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sì gba nǹkan tí ó mú wá fún un lọ́wọ́ rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Gòkè lọ ni àlàáfíà sí ilé rẹ, wò ó, èmi ti gbọ́ ohùn rẹ, inú mi sì dùn sí ọ.”
Et David reçut de sa main ce qu'elle lui avait apporté. Puis il lui dit: « Monte en paix dans ta maison. Voici que j'ai écouté ta voix et que j'ai exaucé ta demande. »
36 Abigaili sì tọ Nabali wá, sì wò ó, òun sì ṣe àsè ni ilé rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àsè ọba: inú Nabali sì dùn nítorí pé, ó ti mú ọtí ni àmupara; òun kò si sọ nǹkan fún un, díẹ̀ tàbí púpọ̀: títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀
Abigaïl se rendit auprès de Nabal; et voici qu'il donnait dans sa maison un festin comme celui d'un roi. Le cœur de Nabal était joyeux au-dedans de lui, car il était très ivre. Aussi ne lui dit-elle rien jusqu'à la lumière du matin.
37 Ó sì ṣe; ni òwúrọ̀, nígbà ti ọtí náà si dá tán lójú Nabali, obìnrin rẹ̀ sì ro nǹkan wọ̀nyí fún un, ọkàn rẹ sì kú nínú rẹ̀, òun sì dàbí òkúta.
Le matin, quand le vin eut disparu de Nabal, sa femme lui raconta ces choses; son cœur mourut au dedans de lui, et il devint comme une pierre.
38 Ó sì ṣe lẹ́yìn ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́wàá, Olúwa lu Nabali, ó sì kú.
Environ dix jours plus tard, l'Éternel frappa Nabal, de sorte qu'il mourut.
39 Dafidi sì gbọ́ pé Nabali kú, ó sì wí pé, “Ìyìn ni fún Olúwa tí o gbèjà gígàn mi láti ọwọ́ Nabali wá, tí ó sì dá ìránṣẹ́ rẹ̀ dúró láti ṣe ibi: Olúwa sì yí ìkà Nabali sí orí òun tìkára rẹ̀.” Dafidi sì ránṣẹ́, ó sì ba Abigaili sọ̀rọ̀ láti mú un fi ṣe aya fún ara rẹ̀.
Lorsque David apprit que Nabal était mort, il dit: « Béni soit Yahvé, qui a défendu ma cause de la main de Nabal et qui a préservé son serviteur du mal. Yahvé a fait retomber la méchanceté de Nabal sur sa propre tête. » David envoya et parla au sujet d'Abigaïl, pour la prendre pour femme.
40 Àwọn ìránṣẹ́ Dafidi sì lọ sọ́dọ̀ Abigaili ni Karmeli, wọn sì sọ fún un pé, “Dafidi rán wá si ọ láti mu ọ ṣe aya rẹ̀.”
Lorsque les serviteurs de David furent arrivés auprès d'Abigaïl au Carmel, ils lui parlèrent ainsi: « David nous a envoyés vers toi, pour te prendre pour femme. »
41 Ó sì dìde, ó sì dojúbolẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, jẹ́ kí ìránṣẹ́bìnrin rẹ ó jẹ́ ìránṣẹ́ kan láti máa wẹ ẹsẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ olúwa mi.”
Elle se leva, se prosterna, le visage contre terre, et dit: « Voici que ta servante est une servante pour laver les pieds des serviteurs de mon seigneur. »
42 Abigaili sì yára, ó sì dìde, ó sì gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ márùn-ún sì tẹ̀lé e lẹ́yìn; òun sì tẹ̀lé àwọn ìránṣẹ́ Dafidi, o sì wá di aya rẹ̀.
Abigaïl se leva précipitamment et monta sur un âne avec ses cinq servantes qui la suivaient; elle suivit les messagers de David et devint sa femme.
43 Dafidi sì mú Ahinoamu ará Jesreeli; àwọn méjèèjì sì jẹ́ aya rẹ̀.
David prit aussi Ahinoam, de Jizreel, et toutes deux devinrent ses femmes.
44 Ṣùgbọ́n Saulu ti fi Mikali ọmọ rẹ̀ obìnrin aya Dafidi, fún Palti ọmọ Laiṣi tí i ṣe ara Galimu.
Or Saül avait donné Mical, sa fille, la femme de David, à Palti, fils de Laïsh, qui était de Gallim.

< 1 Samuel 25 >