< 1 Samuel 24 >

1 Nígbà tí Saulu padà kúrò lẹ́yìn àwọn Filistini a sì sọ fún un pé, “Wò ó, Dafidi ń bẹ́ ni aginjù En-Gedi.”
A gdy Saul wrócił z pościgu za Filistynami, doniesiono mu: Oto Dawid przebywa na pustyni En-Gedi.
2 Saulu sì mú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta akọni ọkùnrin tí a yàn nínú gbogbo Israẹli ó sì lọ láti wá Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ lórí òkúta àwọn ewúrẹ́ igbó.
Saul wziął więc trzy tysiące doborowych mężczyzn spośród całego Izraela i wyruszył na poszukiwanie Dawida i jego ludzi po skałach dzikich kóz.
3 Ó sì dé ibi àwọn agbo àgùntàn tí ó wà ní ọ̀nà, ihò kan sì wà níbẹ̀, Saulu sì wọ inú rẹ̀ lọ láti bo ẹsẹ̀ rẹ̀, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ń bẹ lẹ́bàá ihò náà.
I przybył do owczych zagród przy drodze, gdzie była jaskinia. Wszedł do niej Saul, by zakryć sobie nogi. Dawid zaś i jego ludzie siedzieli w głębi jaskini.
4 Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì wí fún un pé, “Wò ó, èyí ni ọjọ́ náà tí Olúwa wí fún ọ pé, ‘Wò ó, èmi fi ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́, ìwọ ó sì ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ lójú rẹ.’” Dafidi sì dìde, ó sì yọ́ lọ gé etí aṣọ Saulu.
Ludzie Dawida powiedzieli do niego: Oto dzień, o którym PAN ci powiedział: Oto wydam twego wroga w twoje ręce, abyś z nim uczynił to, co wyda ci się słuszne. Dawid wstał więc i po cichu odciął skraj płaszcza Saula.
5 Ó sì ṣe lẹ́yìn èyí, àyà já Dafidi nítorí tí ó gé etí aṣọ Saulu.
Potem jednak serce Dawida zadrżało z tego powodu, że odciął skraj płaszcza Saula.
6 Òun sì wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Èèwọ̀ ni fún mi láti ọ̀dọ́ Olúwa wá bí èmi bá ṣe nǹkan yìí sí ẹni tí a ti fi àmì òróró Olúwa yàn, láti nawọ́ mi sí i, nítorí pé ẹni àmì òróró Olúwa ni.”
I zwrócił się do swoich ludzi: Nie daj Boże, żebym miał to uczynić memu panu, pomazańcowi PANA, bym miał wyciągnąć swoją rękę na niego, ponieważ jest pomazańcem PANA.
7 Dafidi sì fi ọ̀rọ̀ wọ̀nyí dá àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dúró, kò sì jẹ́ kí wọn dìde sí Saulu, Saulu sì dìde kúrò ní ihò náà, ó sì bá ọ̀nà rẹ̀ lọ.
Tymi słowami Dawid powstrzymał swych ludzi i nie pozwolił im powstać przeciw Saulowi. Saul zaś wyszedł z jaskini i poszedł swoją drogą.
8 Dafidi sì dìde lẹ́yìn náà, ó sì jáde kúrò nínú ihò náà ó sì kọ sí Saulu pé, “Olúwa mi, ọba!” Saulu sì wo ẹ̀yìn rẹ̀. Dafidi sì dojú rẹ́ bo ilẹ̀ ó sì tẹríba fún un.
Potem Dawid również wstał, wyszedł z jaskini i zawołał za Saulem: Mój panie, królu! Kiedy Saul obejrzał się za siebie, Dawid schylił się twarzą ku ziemi i pokłonił się.
9 Dafidi sì wí fún Saulu pé, “Èéha ti ṣe tí ìwọ fi ń gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn pé, ‘Wò ó, Dafidi ń wa ẹ̀mí rẹ́’?
Następnie Dawid powiedział do Saula: Dlaczego słuchasz opowieści ludzi, którzy mówią: Oto Dawid pragnie twojej zguby?
10 Wò ó, ojú rẹ́ rí i lónìí, bí Olúwa ti fi ìwọ lé mi lọ́wọ́ lónìí nínú ihò, àwọn kan ní kí èmi ó pa ọ, ṣùgbọ́n èmi dá ọ sí, ‘Èmi sì wí pé, èmi kì yóò nawọ́ mi sí olúwa mi, nítorí pé ẹni àmì òróró Olúwa ni òun jẹ́.’
Oto dziś twoje oczy widzą, że PAN wydał cię w jaskini w moje ręce. I namawiano [mnie], bym cię zabił, lecz oszczędziłem cię i powiedziałem: Nie wyciągnę swojej ręki na mego pana, bo jest pomazańcem PANA.
11 Pẹ̀lúpẹ̀lú, baba mi, wò ó, àní wo etí aṣọ rẹ lọ́wọ́ mi; nítorí èmi gé etí aṣọ rẹ, èmi kò sì pa ọ́, sì wò ó, kí o sì mọ̀ pé kò sí ibi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ lọ́wọ́ mi, èmi kò sì ṣẹ̀ ọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ ń dọdẹ ẹ̀mí mi láti gbà á.
Zobacz, mój ojcze, zobacz skraj swego płaszcza w mojej ręce. Odcinając ci bowiem skraj twego płaszcza, nie zabiłem cię. Wiedz i zobacz, że nie ma w mojej ręce złości ani nieprawości, ani też nie zgrzeszyłem przeciwko tobie. A ty czyhasz na moje życie, by [mi] je odebrać.
12 Kí Olúwa ṣe ìdájọ́ láàrín èmi àti ìwọ, àti kí Olúwa ó gbẹ̀san mi lára rẹ; ṣùgbọ́n, ọwọ́ mi kì yóò sí lára rẹ.
Niech PAN rozsądzi między mną a tobą i niech PAN za mnie zemści się na tobie. Lecz nie podniosę swojej ręki na ciebie.
13 Gẹ́gẹ́ bí òwe ìgbà àtijọ́ ti wí, ìwà búburú a máa ti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn búburú jáde wá; ṣùgbọ́n ọwọ́ mi kì yóò sí lára rẹ.
Jak mówi starodawne przysłowie: Od niegodziwych pochodzi niegodziwość, ale nie podniosę swojej ręki na ciebie.
14 “Nítorí ta ni ọba Israẹli fi jáde? Ta ni ìwọ ń lépa? Òkú ajá, tàbí eṣinṣin?
Za kim wyruszył król Izraela? Kogo gonisz? Zdechłego psa? Jedną pchłę?
15 Kí Olúwa ó ṣe onídàájọ́, kí ó sì dájọ́ láàrín èmi àti ìwọ, kí ó sì gbèjà mi, kí ó sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ rẹ.”
Niech PAN będzie sędzią i niech rozsądzi między mną a tobą, niech zobaczy i ujmie się w mojej sprawie, i niech mnie wyzwoli z twojej ręki.
16 Ó sì ṣe, nígbà tí Dafidi sì dákẹ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún Saulu, Saulu sì wí pé, “Ohùn rẹ ni èyí bí, Dafidi ọmọ mi?” Saulu sì gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sọkún.
I kiedy Dawid przestał mówić te słowa do Saula, Saul zawołał: Czy to jest twój głos, synu mój, Dawidzie? I Saul podniósł swój głos, i zapłakał.
17 Ó sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ ṣe olódodo jù mí lọ; nítorí pé ìwọ ti fi ìre san án fún mi, èmi fi ibi san án fún ọ.
Potem powiedział do Dawida: Jesteś sprawiedliwszy ode mnie, bo oddałeś mi dobrem, a ja tobie oddałem złem.
18 Ìwọ sì fi oore tí ìwọ ti ṣe fún mi hàn lónìí: nígbà tí ó jẹ́ pé, Olúwa ti fi ẹ̀mí mi lé ọ lọ́wọ́, ìwọ kò sì pa mí.
Dziś pokazałeś, że świadczysz mi dobro. Choć bowiem PAN wydał mnie w twoje ręce, nie zabiłeś mnie.
19 Nítorí pé bí ènìyàn bá rí ọ̀tá rẹ̀, ó lè jẹ́ kí ó lọ ní àlàáfíà bí? Olúwa yóò sì fi ìre san èyí ti ìwọ ṣe fún mi lónìí.
Gdy ktoś spotka swego wroga, to czy wypuści go na dobrą drogę? Niech PAN odpłaci ci dobrem za to, co mi dziś uczyniłeś.
20 Wò ó, èmi mọ̀ nísinsin yìí pé, nítòótọ́ ìwọ ó jẹ ọba, àti pé ìjọba Israẹli yóò sì fi ìdí múlẹ̀ ní ọwọ́ rẹ.
A teraz oto wiem, że z pewnością będziesz królem i że królestwo Izraela ostoi się w twojej ręce.
21 Sì búra fún mi nísinsin yìí ní orúkọ Olúwa, pé, ìwọ kì yóò gé irú-ọmọ mi kúrò lẹ́yìn mi, àti pé, ìwọ kì yóò pa orúkọ mi run kúrò ní ìdílé baba mi.”
Przysięgnij mi więc na PANA, że nie wytępisz mojego potomstwa po mnie i nie wytracisz mojego imienia z domu mego ojca.
22 Dafidi sì búra fún Saulu. Saulu sì lọ sí ilé rẹ̀; ṣùgbọ́n Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì gòkè lọ sí ihò náà.
I Dawid przysiągł Saulowi. Potem Saul wrócił do swego domu, a Dawid i jego ludzie udali się do miejsca obronnego.

< 1 Samuel 24 >