< 1 Samuel 24 >

1 Nígbà tí Saulu padà kúrò lẹ́yìn àwọn Filistini a sì sọ fún un pé, “Wò ó, Dafidi ń bẹ́ ni aginjù En-Gedi.”
I stało się, gdy się wrócił Saul z pogoni za Filistynami, powiedziano mu, mówiąc: Oto, Dawid jest na puszczy Engaddy.
2 Saulu sì mú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta akọni ọkùnrin tí a yàn nínú gbogbo Israẹli ó sì lọ láti wá Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ lórí òkúta àwọn ewúrẹ́ igbó.
Wziąwszy tedy Saul trzy tysiące mężów przebranych z wszystkiego Izraela, poszedł szukać Dawida i mężów jego, po wierzchu skał kóz dzikich.
3 Ó sì dé ibi àwọn agbo àgùntàn tí ó wà ní ọ̀nà, ihò kan sì wà níbẹ̀, Saulu sì wọ inú rẹ̀ lọ láti bo ẹsẹ̀ rẹ̀, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ń bẹ lẹ́bàá ihò náà.
I przyszedł ku oborom owczym, które były podle drogi, kędy była jaskinia; do której wszedł Saul na potrzebę przyrodzoną, a Dawid i mężowie jego siedzieli po stronach jaskini.
4 Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì wí fún un pé, “Wò ó, èyí ni ọjọ́ náà tí Olúwa wí fún ọ pé, ‘Wò ó, èmi fi ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́, ìwọ ó sì ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ lójú rẹ.’” Dafidi sì dìde, ó sì yọ́ lọ gé etí aṣọ Saulu.
I rzekli mężowie Dawidowi do niego: Oto dzień, o którym ci powiedział Pan: Oto Ja dawam nieprzyjaciela twego w ręce twoje, a uczynisz mu, jako się będzie podobało w oczach twoich. Wstał tedy Dawid, i urznął po cichu kraj płaszcza Saulowego.
5 Ó sì ṣe lẹ́yìn èyí, àyà já Dafidi nítorí tí ó gé etí aṣọ Saulu.
I stało się, że uderzyło Dawida serce jego, przeto że urznął kraj płaszcza Saulowego.
6 Òun sì wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Èèwọ̀ ni fún mi láti ọ̀dọ́ Olúwa wá bí èmi bá ṣe nǹkan yìí sí ẹni tí a ti fi àmì òróró Olúwa yàn, láti nawọ́ mi sí i, nítorí pé ẹni àmì òróró Olúwa ni.”
I rzekł do mężów swoich: Uchowaj mię tego Panie, żebym to uczynić miał panu memu, pomazańcowi Pańskiemu, żebym miał ściągnąć nań rękę moję, ponieważ jest pomazańcem Pańskim.
7 Dafidi sì fi ọ̀rọ̀ wọ̀nyí dá àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dúró, kò sì jẹ́ kí wọn dìde sí Saulu, Saulu sì dìde kúrò ní ihò náà, ó sì bá ọ̀nà rẹ̀ lọ.
I przełomił Dawid męże swe słowy, a nie dopuścił im powstać przeciwko Saulowi; zatem Saul wstawszy z jaskini, poszedł w drogę.
8 Dafidi sì dìde lẹ́yìn náà, ó sì jáde kúrò nínú ihò náà ó sì kọ sí Saulu pé, “Olúwa mi, ọba!” Saulu sì wo ẹ̀yìn rẹ̀. Dafidi sì dojú rẹ́ bo ilẹ̀ ó sì tẹríba fún un.
Potem też Dawid wstał, i wyszedł z jaskini, a zawołał za Saulem, mówiąc: Królu, Panie mój! Tedy się obejrzał Saul nazad, a Dawid schyliwszy się twarzą ku ziemi, pokłonił się.
9 Dafidi sì wí fún Saulu pé, “Èéha ti ṣe tí ìwọ fi ń gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn pé, ‘Wò ó, Dafidi ń wa ẹ̀mí rẹ́’?
I rzekł Dawid do Saula: Czemuż słuchasz powieści ludzi mówiących: Otóż Dawid szuka twego złego:
10 Wò ó, ojú rẹ́ rí i lónìí, bí Olúwa ti fi ìwọ lé mi lọ́wọ́ lónìí nínú ihò, àwọn kan ní kí èmi ó pa ọ, ṣùgbọ́n èmi dá ọ sí, ‘Èmi sì wí pé, èmi kì yóò nawọ́ mi sí olúwa mi, nítorí pé ẹni àmì òróró Olúwa ni òun jẹ́.’
Oto, dnia tego widzą oczy twoje, że cię był podał Pan w ręce moje w jaskini, i mówiono mi, abym cię zabił; alem ci sfolgował, i rzekłem: Nie ściągnę ręki mojej na pana mego; bo jest pomazańcem Pańskim.
11 Pẹ̀lúpẹ̀lú, baba mi, wò ó, àní wo etí aṣọ rẹ lọ́wọ́ mi; nítorí èmi gé etí aṣọ rẹ, èmi kò sì pa ọ́, sì wò ó, kí o sì mọ̀ pé kò sí ibi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ lọ́wọ́ mi, èmi kò sì ṣẹ̀ ọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ ń dọdẹ ẹ̀mí mi láti gbà á.
Oto, ojcze mój, obacz a oglądaj kraj płaszcza twego w ręce mojej, że gdym urzynał kraj płaszcza twego, nie zabiłem cię. Poznaj a obacz, że niemasz w ręce mojej złości i nieprawości, anim zgrzeszył przeciwko tobie: a ty godzisz na duszę moję, abyś mi ją odjął.
12 Kí Olúwa ṣe ìdájọ́ láàrín èmi àti ìwọ, àti kí Olúwa ó gbẹ̀san mi lára rẹ; ṣùgbọ́n, ọwọ́ mi kì yóò sí lára rẹ.
Niech rozsądzi Pan między mną i między tobą, a niech się zemści Pan krzywdy mojej nad tobą; lecz ręka moja nie będzie na tobie.
13 Gẹ́gẹ́ bí òwe ìgbà àtijọ́ ti wí, ìwà búburú a máa ti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn búburú jáde wá; ṣùgbọ́n ọwọ́ mi kì yóò sí lára rẹ.
Jako mówi przypowieść starodawna: Od niezbożnych wynijdzie niezbożność; przetoż ręka moja nie będzie na tobie.
14 “Nítorí ta ni ọba Israẹli fi jáde? Ta ni ìwọ ń lépa? Òkú ajá, tàbí eṣinṣin?
Za kimże wżdy wyszedł król Izraelski? kogóż gonisz? psa zdechłego? pchłę jednę?
15 Kí Olúwa ó ṣe onídàájọ́, kí ó sì dájọ́ láàrín èmi àti ìwọ, kí ó sì gbèjà mi, kí ó sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ rẹ.”
Niechże będzie Pan sędzią, a niech rozsądzi między mną i między tobą, a niech obaczy i rozejmie przą moję, a niech mię wyswobodzi z ręki twojej.
16 Ó sì ṣe, nígbà tí Dafidi sì dákẹ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún Saulu, Saulu sì wí pé, “Ohùn rẹ ni èyí bí, Dafidi ọmọ mi?” Saulu sì gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sọkún.
A gdy przestał Dawid mówić słów tych do Saula, rzekł Saul: A twójże to głos, synu mój Dawidzie? I podniósłszy Saul głos swój, płakał.
17 Ó sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ ṣe olódodo jù mí lọ; nítorí pé ìwọ ti fi ìre san án fún mi, èmi fi ibi san án fún ọ.
I rzekł do Dawida: Sprawiedliwszyś ty niźli ja: bo tyś mnie oddał dobrem, a jam tobie oddał złem.
18 Ìwọ sì fi oore tí ìwọ ti ṣe fún mi hàn lónìí: nígbà tí ó jẹ́ pé, Olúwa ti fi ẹ̀mí mi lé ọ lọ́wọ́, ìwọ kò sì pa mí.
Tyś zaiste okazał dzisiaj, żeś mi uczynił dobre; bo choć mię podał Pan w rękę twoję, przecięś mię nie zabił.
19 Nítorí pé bí ènìyàn bá rí ọ̀tá rẹ̀, ó lè jẹ́ kí ó lọ ní àlàáfíà bí? Olúwa yóò sì fi ìre san èyí ti ìwọ ṣe fún mi lónìí.
Izaż znalazłszy kto nieprzyjaciela swego, wypuści go na drogę dobrą? niechajżeć Pan dobrem odda za to, coś mi dziś uczynił.
20 Wò ó, èmi mọ̀ nísinsin yìí pé, nítòótọ́ ìwọ ó jẹ ọba, àti pé ìjọba Israẹli yóò sì fi ìdí múlẹ̀ ní ọwọ́ rẹ.
A teraz oto wiem, że zapewne będziesz królował, a ostoi się w ręce twojej królestwo Izraelskie.
21 Sì búra fún mi nísinsin yìí ní orúkọ Olúwa, pé, ìwọ kì yóò gé irú-ọmọ mi kúrò lẹ́yìn mi, àti pé, ìwọ kì yóò pa orúkọ mi run kúrò ní ìdílé baba mi.”
Przetoż proszę, przysiąż mi przez Pana, że nie wygubisz nasienia mego po mnie, i nie wytracisz imienia mego z domu ojca mego.
22 Dafidi sì búra fún Saulu. Saulu sì lọ sí ilé rẹ̀; ṣùgbọ́n Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì gòkè lọ sí ihò náà.
A tak przysiągł Dawid Saulowi. I odszedł Saul do domu swego, a Dawid i mężowie jego poszli na miejsca obronne.

< 1 Samuel 24 >