< 1 Samuel 24 >

1 Nígbà tí Saulu padà kúrò lẹ́yìn àwọn Filistini a sì sọ fún un pé, “Wò ó, Dafidi ń bẹ́ ni aginjù En-Gedi.”
وقتی شائول از جنگ با فلسطینی‌ها مراجعت نمود، به او خبر دادند که داوود به صحرای عین جدی رفته است.
2 Saulu sì mú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta akọni ọkùnrin tí a yàn nínú gbogbo Israẹli ó sì lọ láti wá Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ lórí òkúta àwọn ewúrẹ́ igbó.
پس او با سه هزار نفر از بهترین سربازان خود به صحرای عین جدی رفت و در میان «صخره‌های بز کوهی» به جستجوی داوود و افرادش پرداخت.
3 Ó sì dé ibi àwọn agbo àgùntàn tí ó wà ní ọ̀nà, ihò kan sì wà níbẹ̀, Saulu sì wọ inú rẹ̀ lọ láti bo ẹsẹ̀ rẹ̀, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ń bẹ lẹ́bàá ihò náà.
بر سر راه به آغل گوسفندان رسید. در آنجا غاری بود. شائول وارد غار شد تا رفع حاجت نماید. اتفاقاً داوود و مردانش در انتهای غار مخفی شده بودند!
4 Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì wí fún un pé, “Wò ó, èyí ni ọjọ́ náà tí Olúwa wí fún ọ pé, ‘Wò ó, èmi fi ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́, ìwọ ó sì ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ lójú rẹ.’” Dafidi sì dìde, ó sì yọ́ lọ gé etí aṣọ Saulu.
افراد داوود آهسته در گوش او گفتند: «امروز همان روزی است که خداوند وعده داده دشمنت را به دست تو تسلیم نماید تا هر چه می‌خواهی با او بکنی!» پس داوود آهسته جلو رفت و گوشهٔ ردای شائول را برید.
5 Ó sì ṣe lẹ́yìn èyí, àyà já Dafidi nítorí tí ó gé etí aṣọ Saulu.
ولی بعد وجدانش ناراحت شد که این کار را کرده است
6 Òun sì wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Èèwọ̀ ni fún mi láti ọ̀dọ́ Olúwa wá bí èmi bá ṣe nǹkan yìí sí ẹni tí a ti fi àmì òróró Olúwa yàn, láti nawọ́ mi sí i, nítorí pé ẹni àmì òróró Olúwa ni.”
و به افراد خود گفت: «کار بدی کردم. وای بر من اگر کوچکترین آسیبی از طرف من به پادشاهم برسد، زیرا او برگزیدهٔ خداوند است.»
7 Dafidi sì fi ọ̀rọ̀ wọ̀nyí dá àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dúró, kò sì jẹ́ kí wọn dìde sí Saulu, Saulu sì dìde kúrò ní ihò náà, ó sì bá ọ̀nà rẹ̀ lọ.
داوود با این سخنان افرادش را سرزنش کرد و نگذاشت به شائول آسیبی برسانند. پس از اینکه شائول از غار خارج شد، داوود بیرون آمد و فریاد زد: «ای پادشاه من!» وقتی شائول برگشت، داوود او را تعظیم کرد
8 Dafidi sì dìde lẹ́yìn náà, ó sì jáde kúrò nínú ihò náà ó sì kọ sí Saulu pé, “Olúwa mi, ọba!” Saulu sì wo ẹ̀yìn rẹ̀. Dafidi sì dojú rẹ́ bo ilẹ̀ ó sì tẹríba fún un.
9 Dafidi sì wí fún Saulu pé, “Èéha ti ṣe tí ìwọ fi ń gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn pé, ‘Wò ó, Dafidi ń wa ẹ̀mí rẹ́’?
و گفت: «چرا به حرف مردم گوش می‌دهی که می‌گویند من قصد جان توا را دارم؟ امروز به تو ثابت شد که این سخن حقیقت ندارد. خداوند تو را در این غار به دست من تسلیم نمود و بعضی از افرادم گفتند که تو را بکشم، اما من این کار را نکردم. به آنها گفتم که او پادشاه برگزیدهٔ خداوند است و من هرگز به او آسیبی نخواهم رساند.
10 Wò ó, ojú rẹ́ rí i lónìí, bí Olúwa ti fi ìwọ lé mi lọ́wọ́ lónìí nínú ihò, àwọn kan ní kí èmi ó pa ọ, ṣùgbọ́n èmi dá ọ sí, ‘Èmi sì wí pé, èmi kì yóò nawọ́ mi sí olúwa mi, nítorí pé ẹni àmì òróró Olúwa ni òun jẹ́.’
11 Pẹ̀lúpẹ̀lú, baba mi, wò ó, àní wo etí aṣọ rẹ lọ́wọ́ mi; nítorí èmi gé etí aṣọ rẹ, èmi kò sì pa ọ́, sì wò ó, kí o sì mọ̀ pé kò sí ibi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ lọ́wọ́ mi, èmi kò sì ṣẹ̀ ọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ ń dọdẹ ẹ̀mí mi láti gbà á.
ببین ای پدر من، قسمتی از ردایت در دست من است. من آن را بریدم، ولی تو را نکشتم! آیا همین به تو ثابت نمی‌کند که من قصد آزار تو را ندارم و نسبت به تو گناه نکرده‌ام، هر چند تو در تعقیب من هستی تا مرا نابود کنی؟
12 Kí Olúwa ṣe ìdájọ́ láàrín èmi àti ìwọ, àti kí Olúwa ó gbẹ̀san mi lára rẹ; ṣùgbọ́n, ọwọ́ mi kì yóò sí lára rẹ.
خداوند در میان من و تو حکم کند و انتقام مرا خودش از تو بگیرد. ولی از طرف من هیچ بدی به تو نخواهد رسید. چنانکه مَثَلی قدیمی می‌گوید:”بدی از آدم بد صادر می‌شود.“پس مطمئن باش من به تو آسیبی نمی‌رسانم.
13 Gẹ́gẹ́ bí òwe ìgbà àtijọ́ ti wí, ìwà búburú a máa ti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn búburú jáde wá; ṣùgbọ́n ọwọ́ mi kì yóò sí lára rẹ.
14 “Nítorí ta ni ọba Israẹli fi jáde? Ta ni ìwọ ń lépa? Òkú ajá, tàbí eṣinṣin?
پادشاه اسرائیل در تعقیب چه کسی است؟ آیا حیف نیست که پادشاه وقتش را برای من که به اندازهٔ یک سگ مرده یا یک کک ارزش ندارم تلف نماید؟
15 Kí Olúwa ó ṣe onídàájọ́, kí ó sì dájọ́ láàrín èmi àti ìwọ, kí ó sì gbèjà mi, kí ó sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ rẹ.”
خداوند خودش بین ما داوری کند تا معلوم شود مقصر کیست. خداوند خودش از حق من دفاع کند و مرا از چنگ تو برهاند!»
16 Ó sì ṣe, nígbà tí Dafidi sì dákẹ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún Saulu, Saulu sì wí pé, “Ohùn rẹ ni èyí bí, Dafidi ọmọ mi?” Saulu sì gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sọkún.
وقتی داوود صحبت خود را تمام کرد، شائول گفت: «پسرم داوود، آیا این صدای توست؟» و گریه امانش نداد. او به داوود گفت: «تو از من بهتر هستی. چون تو در حق من خوبی کرده‌ای، ولی من نسبت به تو بدی کرده‌ام.
17 Ó sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ ṣe olódodo jù mí lọ; nítorí pé ìwọ ti fi ìre san án fún mi, èmi fi ibi san án fún ọ.
18 Ìwọ sì fi oore tí ìwọ ti ṣe fún mi hàn lónìí: nígbà tí ó jẹ́ pé, Olúwa ti fi ẹ̀mí mi lé ọ lọ́wọ́, ìwọ kò sì pa mí.
آری، تو امروز نشان دادی که نسبت به من مهربان هستی، زیرا خداوند مرا به تو تسلیم نمود، اما تو مرا نکشتی.
19 Nítorí pé bí ènìyàn bá rí ọ̀tá rẹ̀, ó lè jẹ́ kí ó lọ ní àlàáfíà bí? Olúwa yóò sì fi ìre san èyí ti ìwọ ṣe fún mi lónìí.
کیست که دشمن خود را در چنگ خویش بیابد، ولی او را نکشد؟ به خاطر این لطفی که تو امروز به من کردی، خداوند به تو پاداش خوبی بدهد.
20 Wò ó, èmi mọ̀ nísinsin yìí pé, nítòótọ́ ìwọ ó jẹ ọba, àti pé ìjọba Israẹli yóò sì fi ìdí múlẹ̀ ní ọwọ́ rẹ.
حال مطمئنم که تو پادشاه اسرائیل خواهی شد و حکومت خود را تثبیت خواهی کرد.
21 Sì búra fún mi nísinsin yìí ní orúkọ Olúwa, pé, ìwọ kì yóò gé irú-ọmọ mi kúrò lẹ́yìn mi, àti pé, ìwọ kì yóò pa orúkọ mi run kúrò ní ìdílé baba mi.”
به خداوند قسم بخور که وقتی به پادشاهی رسیدی، خاندان مرا از بین نبری و بگذاری اسم من باقی بماند.»
22 Dafidi sì búra fún Saulu. Saulu sì lọ sí ilé rẹ̀; ṣùgbọ́n Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì gòkè lọ sí ihò náà.
پس داوود برای او قسم خورد و شائول به خانهٔ خود رفت، ولی داوود و همراهانش به مخفیگاه خود برگشتند.

< 1 Samuel 24 >