< 1 Samuel 24 >

1 Nígbà tí Saulu padà kúrò lẹ́yìn àwọn Filistini a sì sọ fún un pé, “Wò ó, Dafidi ń bẹ́ ni aginjù En-Gedi.”
And it cometh to pass when Saul hath turned back from after the Philistines, that they declare to him, saying, 'Lo, David [is] in the wilderness of En-gedi.'
2 Saulu sì mú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta akọni ọkùnrin tí a yàn nínú gbogbo Israẹli ó sì lọ láti wá Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ lórí òkúta àwọn ewúrẹ́ igbó.
And Saul taketh three thousand chosen men out of all Israel, and goeth to seek David and his men, on the front of the rocks of the wild goats,
3 Ó sì dé ibi àwọn agbo àgùntàn tí ó wà ní ọ̀nà, ihò kan sì wà níbẹ̀, Saulu sì wọ inú rẹ̀ lọ láti bo ẹsẹ̀ rẹ̀, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ń bẹ lẹ́bàá ihò náà.
and he cometh in unto folds of the flock, on the way, and there [is] a cave, and Saul goeth in to cover his feet; and David and his men in the sides of the cave are abiding.
4 Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì wí fún un pé, “Wò ó, èyí ni ọjọ́ náà tí Olúwa wí fún ọ pé, ‘Wò ó, èmi fi ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́, ìwọ ó sì ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ lójú rẹ.’” Dafidi sì dìde, ó sì yọ́ lọ gé etí aṣọ Saulu.
And the men of David say unto him, 'Lo, the day of which Jehovah said unto thee, Lo, I am giving thine enemy into thy hand, and thou hast done to him as it is good in thine eyes;' and David riseth and cutteth off the skirt of the upper robe which [is] on Saul — gently.
5 Ó sì ṣe lẹ́yìn èyí, àyà já Dafidi nítorí tí ó gé etí aṣọ Saulu.
And it cometh to pass afterwards that the heart of David smiteth him, because that he hath cut off the skirt which [is] on Saul,
6 Òun sì wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Èèwọ̀ ni fún mi láti ọ̀dọ́ Olúwa wá bí èmi bá ṣe nǹkan yìí sí ẹni tí a ti fi àmì òróró Olúwa yàn, láti nawọ́ mi sí i, nítorí pé ẹni àmì òróró Olúwa ni.”
and he saith to his men, 'Far be it from me, by Jehovah; I do not do this thing to my lord — to the anointed of Jehovah — to put forth my hand against him, for the anointed of Jehovah he [is].'
7 Dafidi sì fi ọ̀rọ̀ wọ̀nyí dá àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dúró, kò sì jẹ́ kí wọn dìde sí Saulu, Saulu sì dìde kúrò ní ihò náà, ó sì bá ọ̀nà rẹ̀ lọ.
And David subdueth his men by words, and hath not permitted them to rise against Saul; and Saul hath risen from the cave, and goeth on the way;
8 Dafidi sì dìde lẹ́yìn náà, ó sì jáde kúrò nínú ihò náà ó sì kọ sí Saulu pé, “Olúwa mi, ọba!” Saulu sì wo ẹ̀yìn rẹ̀. Dafidi sì dojú rẹ́ bo ilẹ̀ ó sì tẹríba fún un.
and David riseth afterwards, and goeth out from the cave, and calleth after Saul, saying, 'My lord, O king!' And Saul looketh attentively behind him, and David boweth — face to the earth — and doth obeisance.
9 Dafidi sì wí fún Saulu pé, “Èéha ti ṣe tí ìwọ fi ń gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn pé, ‘Wò ó, Dafidi ń wa ẹ̀mí rẹ́’?
And David saith to Saul, 'Why dost thou hear the words of man, saying, Lo, David is seeking thine evil?
10 Wò ó, ojú rẹ́ rí i lónìí, bí Olúwa ti fi ìwọ lé mi lọ́wọ́ lónìí nínú ihò, àwọn kan ní kí èmi ó pa ọ, ṣùgbọ́n èmi dá ọ sí, ‘Èmi sì wí pé, èmi kì yóò nawọ́ mi sí olúwa mi, nítorí pé ẹni àmì òróró Olúwa ni òun jẹ́.’
Lo, this day have thine eyes seen how that Jehovah hath given thee to-day into my hand in the cave; and [one] said to slay thee, and [mine eye] hath pity on thee, and I say, I do not put forth my hand against my lord, for the anointed of Jehovah he [is].
11 Pẹ̀lúpẹ̀lú, baba mi, wò ó, àní wo etí aṣọ rẹ lọ́wọ́ mi; nítorí èmi gé etí aṣọ rẹ, èmi kò sì pa ọ́, sì wò ó, kí o sì mọ̀ pé kò sí ibi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ lọ́wọ́ mi, èmi kò sì ṣẹ̀ ọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ ń dọdẹ ẹ̀mí mi láti gbà á.
'And, my father, see, yea see the skirt of thine upper robe in my hand; for by cutting off the skirt of thy upper robe, and I have not slain thee, know and see that there is not in my hand evil and transgression, and I have not sinned against thee, and thou art hunting my soul to take it!
12 Kí Olúwa ṣe ìdájọ́ láàrín èmi àti ìwọ, àti kí Olúwa ó gbẹ̀san mi lára rẹ; ṣùgbọ́n, ọwọ́ mi kì yóò sí lára rẹ.
'Jehovah doth judge between me and thee, and Jehovah hath avenged me of thee, and my hand is not on thee;
13 Gẹ́gẹ́ bí òwe ìgbà àtijọ́ ti wí, ìwà búburú a máa ti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn búburú jáde wá; ṣùgbọ́n ọwọ́ mi kì yóò sí lára rẹ.
as saith the simile of the ancients, From the wicked goeth out wickedness, and my hand is not on thee.
14 “Nítorí ta ni ọba Israẹli fi jáde? Ta ni ìwọ ń lépa? Òkú ajá, tàbí eṣinṣin?
'After whom hath the king of Israel come out? after whom art thou pursuing? — after a dead dog! after one flea!
15 Kí Olúwa ó ṣe onídàájọ́, kí ó sì dájọ́ láàrín èmi àti ìwọ, kí ó sì gbèjà mi, kí ó sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ rẹ.”
And Jehovah hath been for judge, and hath judged between me and thee, yea, he seeth and pleadeth my cause, and doth deliver me out of thy hand.'
16 Ó sì ṣe, nígbà tí Dafidi sì dákẹ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún Saulu, Saulu sì wí pé, “Ohùn rẹ ni èyí bí, Dafidi ọmọ mi?” Saulu sì gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sọkún.
And it cometh to pass, when David completeth to speak these words unto Saul, that Saul saith, 'Is this thy voice, my son David?' and Saul lifteth up his voice, and weepeth.
17 Ó sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ ṣe olódodo jù mí lọ; nítorí pé ìwọ ti fi ìre san án fún mi, èmi fi ibi san án fún ọ.
And he saith unto David, 'More righteous thou [art] than I; for thou hast done me good, and I have done thee evil;
18 Ìwọ sì fi oore tí ìwọ ti ṣe fún mi hàn lónìí: nígbà tí ó jẹ́ pé, Olúwa ti fi ẹ̀mí mi lé ọ lọ́wọ́, ìwọ kò sì pa mí.
and thou hast declared to-day how that thou hast done good with me, how that Jehovah shut me up into thy hand, and thou didst not slay me,
19 Nítorí pé bí ènìyàn bá rí ọ̀tá rẹ̀, ó lè jẹ́ kí ó lọ ní àlàáfíà bí? Olúwa yóò sì fi ìre san èyí ti ìwọ ṣe fún mi lónìí.
and that a man doth find his enemy, and hath sent him away in a good manner; and Jehovah doth repay thee good for that which thou didst to me this day.
20 Wò ó, èmi mọ̀ nísinsin yìí pé, nítòótọ́ ìwọ ó jẹ ọba, àti pé ìjọba Israẹli yóò sì fi ìdí múlẹ̀ ní ọwọ́ rẹ.
'And, now, lo, I have known that thou dost certainly reign, and the kingdom of Israel hath stood in thy hand;
21 Sì búra fún mi nísinsin yìí ní orúkọ Olúwa, pé, ìwọ kì yóò gé irú-ọmọ mi kúrò lẹ́yìn mi, àti pé, ìwọ kì yóò pa orúkọ mi run kúrò ní ìdílé baba mi.”
and, now, swear to me by Jehovah — thou dost not cut off my seed after me, nor dost thou destroy my name from the house of my father.'
22 Dafidi sì búra fún Saulu. Saulu sì lọ sí ilé rẹ̀; ṣùgbọ́n Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì gòkè lọ sí ihò náà.
And David sweareth to Saul, and Saul goeth unto his house, and David and his men have gone up unto the fortress.

< 1 Samuel 24 >