< 1 Samuel 24 >

1 Nígbà tí Saulu padà kúrò lẹ́yìn àwọn Filistini a sì sọ fún un pé, “Wò ó, Dafidi ń bẹ́ ni aginjù En-Gedi.”
And whanne Saul turnede ayen, aftir that he pursuede Filisteis, thei telden to hym, and seiden, Lo! Dauid is in the deseert of Engaddi.
2 Saulu sì mú ẹgbẹ̀rún mẹ́ta akọni ọkùnrin tí a yàn nínú gbogbo Israẹli ó sì lọ láti wá Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ lórí òkúta àwọn ewúrẹ́ igbó.
Therfor Saul took three thousinde of chosun men of al Israel, and yede to seke Dauid and hise men, yhe on moost brokun rochis, that ben `able to weie to wield geet aloone.
3 Ó sì dé ibi àwọn agbo àgùntàn tí ó wà ní ọ̀nà, ihò kan sì wà níbẹ̀, Saulu sì wọ inú rẹ̀ lọ láti bo ẹsẹ̀ rẹ̀, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì ń bẹ lẹ́bàá ihò náà.
And he cam to the fooldis of scheep, that offriden hem silf to the wei goere. And there was a denne, in to which denne Saul entride, that he schulde purge the wombe; forsothe Dauid and hise men weren hid in the ynnere part of the denne.
4 Àwọn ọmọkùnrin Dafidi sì wí fún un pé, “Wò ó, èyí ni ọjọ́ náà tí Olúwa wí fún ọ pé, ‘Wò ó, èmi fi ọ̀tá rẹ lé ọ lọ́wọ́, ìwọ ó sì ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti tọ́ lójú rẹ.’” Dafidi sì dìde, ó sì yọ́ lọ gé etí aṣọ Saulu.
And the seruauntis of Dauid seiden to hym, Lo! the dai of which the Lord spak to the, Y schal bitake to thee thin enemy, that thou do to hym as it plesith in thin iyen. Therfor Dauid roos, and kittide the hemme of the mentil of Saul priuely.
5 Ó sì ṣe lẹ́yìn èyí, àyà já Dafidi nítorí tí ó gé etí aṣọ Saulu.
Aftir these thingis Dauid smoot his herte, for he hadde kit awei the hemme of the mentil of Saul.
6 Òun sì wí fún àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ pé, “Èèwọ̀ ni fún mi láti ọ̀dọ́ Olúwa wá bí èmi bá ṣe nǹkan yìí sí ẹni tí a ti fi àmì òróró Olúwa yàn, láti nawọ́ mi sí i, nítorí pé ẹni àmì òróró Olúwa ni.”
And Dauid seide to hise men, The Lord be merciful to me, lest Y do this thing to my lord, the crist of the Lord, that Y sende myn hond `in to hym, for he is the crist of the Lord. The Lord lyueth, for no but the Lord smyte hym, ether his dai come, that he die, ether he go doun in to batel and perische, the Lord be merciful to me, that Y sende not myn hond in to the crist of the Lord.
7 Dafidi sì fi ọ̀rọ̀ wọ̀nyí dá àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ dúró, kò sì jẹ́ kí wọn dìde sí Saulu, Saulu sì dìde kúrò ní ihò náà, ó sì bá ọ̀nà rẹ̀ lọ.
Forsothe Saul roos out of the denne, and yede in the weie bigunnun.
8 Dafidi sì dìde lẹ́yìn náà, ó sì jáde kúrò nínú ihò náà ó sì kọ sí Saulu pé, “Olúwa mi, ọba!” Saulu sì wo ẹ̀yìn rẹ̀. Dafidi sì dojú rẹ́ bo ilẹ̀ ó sì tẹríba fún un.
Sotheli Dauid roos aftir hym, and he yede out of the denne, and criede aftir the bak of Saul, and seide, My lord, the kyng! And Saul bihelde bihinde him silf; and Dauid bowide hym silf lowe to the erthe, and worschipide.
9 Dafidi sì wí fún Saulu pé, “Èéha ti ṣe tí ìwọ fi ń gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ènìyàn pé, ‘Wò ó, Dafidi ń wa ẹ̀mí rẹ́’?
And he seide to Saul, Whi herist thou the wordis of men spekynge, Dauid sekith yuel ayens thee?
10 Wò ó, ojú rẹ́ rí i lónìí, bí Olúwa ti fi ìwọ lé mi lọ́wọ́ lónìí nínú ihò, àwọn kan ní kí èmi ó pa ọ, ṣùgbọ́n èmi dá ọ sí, ‘Èmi sì wí pé, èmi kì yóò nawọ́ mi sí olúwa mi, nítorí pé ẹni àmì òróró Olúwa ni òun jẹ́.’
Lo! to dai thin iyen siyen, that the Lord bitook thee in myn hond in the denne, and Y thouyte that Y wolde sle thee, but myn iye sparide thee; for Y seide, Y schal not holde forth myn hond in to my lord, which is the crist, `that is, anoyntid, of the Lord.
11 Pẹ̀lúpẹ̀lú, baba mi, wò ó, àní wo etí aṣọ rẹ lọ́wọ́ mi; nítorí èmi gé etí aṣọ rẹ, èmi kò sì pa ọ́, sì wò ó, kí o sì mọ̀ pé kò sí ibi tàbí ẹ̀ṣẹ̀ lọ́wọ́ mi, èmi kò sì ṣẹ̀ ọ̀, ṣùgbọ́n ìwọ ń dọdẹ ẹ̀mí mi láti gbà á.
But rathere, my fadir, se thou, and knowe the hemme of thi mentil in myn hond, for whanne Y kittide aweie the hemme of thi mentil, Y nolde holde forth myn hond in thee; perseyue thou, and see, for nether yuel nether wickidnesse is in myn hond, nether Y synnede ayens thee; but thou aspiest my lijf, that thou do it awei.
12 Kí Olúwa ṣe ìdájọ́ láàrín èmi àti ìwọ, àti kí Olúwa ó gbẹ̀san mi lára rẹ; ṣùgbọ́n, ọwọ́ mi kì yóò sí lára rẹ.
The Lord deme bitwixe me and thee, and the Lord venge me of thee; but myn hond be not in thee,
13 Gẹ́gẹ́ bí òwe ìgbà àtijọ́ ti wí, ìwà búburú a máa ti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn búburú jáde wá; ṣùgbọ́n ọwọ́ mi kì yóò sí lára rẹ.
as it is seid also in eld prouerbe, Wickidnesse schal go out of wickid men; therfor myn hond be not in thee.
14 “Nítorí ta ni ọba Israẹli fi jáde? Ta ni ìwọ ń lépa? Òkú ajá, tàbí eṣinṣin?
`Whom pursuest thou, kyng of Israel, whom pursuest thou? Thou pursuest a deed hound, and a quyk fle.
15 Kí Olúwa ó ṣe onídàájọ́, kí ó sì dájọ́ láàrín èmi àti ìwọ, kí ó sì gbèjà mi, kí ó sì gbà mí kúrò lọ́wọ́ rẹ.”
The Lord be iuge, and the Lord deme bitwixe me and thee, and se, and deme my cause, and delyuere me fro thin hond.
16 Ó sì ṣe, nígbà tí Dafidi sì dákẹ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí fún Saulu, Saulu sì wí pé, “Ohùn rẹ ni èyí bí, Dafidi ọmọ mi?” Saulu sì gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sọkún.
Sotheli whanne Dauid hadde fillid spekynge siche wordis to Saul, Saul seide, Whether this is thi vois, my sone Dauid? And Saul reiside his vois, and wepte.
17 Ó sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ ṣe olódodo jù mí lọ; nítorí pé ìwọ ti fi ìre san án fún mi, èmi fi ibi san án fún ọ.
And he seide to Dauid, Thou art more iust than Y; for thou yauest goodis to me; forsothe Y yeldide yuelis to thee.
18 Ìwọ sì fi oore tí ìwọ ti ṣe fún mi hàn lónìí: nígbà tí ó jẹ́ pé, Olúwa ti fi ẹ̀mí mi lé ọ lọ́wọ́, ìwọ kò sì pa mí.
And thou schewidist to me to dai, what goodis thou hast do to me, how the Lord bitook me in thin hond, and thou killidist not me.
19 Nítorí pé bí ènìyàn bá rí ọ̀tá rẹ̀, ó lè jẹ́ kí ó lọ ní àlàáfíà bí? Olúwa yóò sì fi ìre san èyí ti ìwọ ṣe fún mi lónìí.
For who, `whanne he fyndith his enemy, schal delyuere hym in good weie? But the Lord yelde to thee this while, for that, that thou wrouytist to dai in me.
20 Wò ó, èmi mọ̀ nísinsin yìí pé, nítòótọ́ ìwọ ó jẹ ọba, àti pé ìjọba Israẹli yóò sì fi ìdí múlẹ̀ ní ọwọ́ rẹ.
And now, for Y woot, that thou schalt regne moost certeynli, and schalt haue in thin hond the rewme of Israel, swere thou to me in the Lord,
21 Sì búra fún mi nísinsin yìí ní orúkọ Olúwa, pé, ìwọ kì yóò gé irú-ọmọ mi kúrò lẹ́yìn mi, àti pé, ìwọ kì yóò pa orúkọ mi run kúrò ní ìdílé baba mi.”
that thou do not a wei my seed aftir me, nether take a wey my name fro the hows of my fadir.
22 Dafidi sì búra fún Saulu. Saulu sì lọ sí ilé rẹ̀; ṣùgbọ́n Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì gòkè lọ sí ihò náà.
And Dauid swoor to Saul. Therfor Saul yede in to his hows, and Dauid and hise men stieden to sikire placis.

< 1 Samuel 24 >