< 1 Samuel 23 >

1 Wọ́n sì wí fún Dafidi pé, “Sá wò ó, àwọn ará Filistini ń bá ará Keila jagun, wọ́n sì ja àwọn ilẹ̀ ìpakà lólè.”
Na rĩrĩ, Daudi akĩĩrwo atĩrĩ, “Atĩrĩrĩ, Afilisti nĩmararũa na itũũra rĩa Keila, na magatunyana ngano ĩrĩa ĩrĩ mahuhĩro-inĩ.”
2 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa pé, “Ṣé kí èmi ó lọ kọlu àwọn ará Filistini wọ̀nyí bí?” Olúwa sì wí fún Dafidi pé, “Lọ kí o sì kọlu àwọn ará Filistini kí o sì gba Keila sílẹ̀.”
Nake agĩtuĩria ũhoro harĩ Jehova, akĩũria atĩrĩ, “Nĩnjagĩrĩirwo nĩgũthiĩ gũtharĩkĩra Afilisti acio?” Nake Jehova akĩmũcookeria atĩrĩ, “Thiĩ ũgatharĩkĩre Afilisti nĩguo ũhonokie Keila.”
3 Àwọn ọmọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Dafidi sì wí fún un pé, “Wò ó, àwa ń bẹ̀rù níhìn-ín yìí ní Juda; ǹjẹ́ yóò ti rí nígbà ti àwa bá dé Keila láti fi ojú ko ogun àwọn ara Filistini?”
No andũ a Daudi makĩmwĩra atĩrĩ, “Gũkũ Juda nĩtũretigĩra. Githĩ tũtigũgĩĩtigĩra makĩria twathiĩ Keila tũkarũe na mbũtũ cia Afilisti!”
4 Dafidi sì tún béèrè lọ́dọ̀ Olúwa. Olúwa sì dá a lóhùn, ó sì wí pé, “Dìde, kí o sọ̀kalẹ̀ lọ sí Keila, nítorí pé èmi ó fi àwọn ará Filistini náà lé ọ lọ́wọ́.”
O rĩngĩ Daudi agĩtuĩria ũhoro harĩ Jehova, nake Jehova akĩmũcookeria atĩrĩ, “Ikũrũka ũthiĩ Keila, nĩ ũndũ nĩngũneana Afilisti guoko-inĩ gwaku.”
5 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ sí Keila, wọ́n sì bá àwọn ará Filistini jà, wọ́n sì kó ohun ọ̀sìn wọn, wọ́n sì fi ìparun ńlá pa wọ́n. Dafidi sì gba àwọn ará Keila sílẹ̀.
Nĩ ũndũ ũcio Daudi na andũ ake magĩthiĩ Keila, makĩrũa na Afilisti, na makĩmataha mahiũ mao. Akĩrehera Afilisti hathara nene, na akĩhonokia andũ a Keila.
6 Ó sì ṣe, nígbà tí Abiatari ọmọ Ahimeleki fi sá tọ Dafidi lọ ní Keila, ó sọ̀kalẹ̀ òun pẹ̀lú efodu kan lọ́wọ́ rẹ̀.
(Na rĩrĩ, Abiatharu mũrũ wa Ahimeleku nĩokĩte akuuĩte ebodi rĩrĩa aikũrũkire, akĩũrĩra kũrĩ Daudi kũu Keila.)
7 A sì sọ fún Saulu pé Dafidi wá sí Keila. Saulu sì wí pé, “Ọlọ́run ti fi í lé mi lọ́wọ́; nítorí tí ó ti sé ara rẹ̀ mọ́ ní ti wíwá tí ó wá sí ìlú tí ó ní ìlẹ̀kùn àti kẹrẹ.”
Saũlũ akĩĩrwo atĩ Daudi nĩathiĩte Keila, nake akiuga atĩrĩ, “Ngai nĩamũneanĩte kũrĩ niĩ, nĩgũkorwo Daudi nĩehingĩrĩirie na ũndũ wa gũtoonya itũũra rĩrĩ na ihingo na mĩgĩĩko.”
8 Saulu sì pe gbogbo àwọn ènìyàn náà jọ sí ogun, láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí Keila, láti ká Dafidi mọ́ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀.
Nake Saũlũ agĩĩta mbũtũ ciake ciothe mathiĩ mbaara, nĩguo maikũrũke Keila makahingĩrĩrie Daudi na andũ ake.
9 Dafidi sì mọ̀ pé Saulu ti gbèrò búburú sí òun; ó sì wí fún Abiatari àlùfáà náà pé, “Mú efodu náà wá níhìn-ín yìí!”
Hĩndĩ ĩrĩa Daudi aamenyire atĩ Saũlũ nĩaciirĩire kũmwĩka ũũru-rĩ, akĩĩra Abiatharu mũthĩnjĩri-Ngai atĩrĩ, “Rehe ebodi ĩyo.”
10 Dafidi sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, lóòótọ́ ni ìránṣẹ́ rẹ ti gbọ́ pé Saulu ń wá ọ̀nà láti wá sí Keila, láti wá fọ́ ìlú náà nítorí mi.
Daudi akiuga atĩrĩ, “Wee Jehova, Ngai wa Isiraeli, ndungata yaku nĩ ĩiguĩte hatarĩ nganja atĩ Saũlũ nĩarooka Keila aniine itũũra rĩĩrĩ nĩ ũndũ wakwa.
11 Àwọn àgbà ìlú Keila yóò fi mí lé e lọ́wọ́ bí? Saulu yóò ha sọ̀kalẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ rẹ ti gbọ́ bí?” Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èmi bẹ̀ ọ́, wí fún ìránṣẹ́ rẹ. Olúwa sì wí pé, “Yóò sọ̀kalẹ̀ wá.”
Hihi aikari a Keila nĩmekũũneana kũrĩ we? Hihi Saũlũ nĩegũikũrũka gũkũ, ta ũrĩa ndungata yaku ĩiguĩte? Wee Jehova, Ngai wa Isiraeli, menyithia ndungata yaku ũhoro.” Nake Jehova akiuga atĩrĩ, “Nĩegũikũrũka.”
12 Dafidi sì wí pé, “Àwọn àgbà ìlú Keila yóò fi èmi àti àwọn ọmọkùnrin mi lé Saulu lọ́wọ́ bí?” Olúwa sì wí pé, “Wọn ó fi ọ́ lé wọn lọ́wọ́.”
O rĩngĩ Daudi akĩũria atĩrĩ, “Hihi aikari a Keila nĩmekũneana, niĩ na andũ akwa, kũrĩ Saũlũ?” Nake Jehova akiuga atĩrĩ, “Nĩmegũkũneana.”
13 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ tí wọ́n tó ẹgbẹ̀ta ènìyàn sì dìde, wọ́n lọ kúrò ní Keila, wọ́n sì lọ sí ibikíbi tí wọ́n lè rìn lọ. A sì wí fún Saulu pé, “Dafidi ti sá kúrò ní Keila; kò sì lọ sí Keila mọ́.”
Nĩ ũndũ ũcio Daudi na andũ ake, andũ ta magana matandatũ, makiuma Keila, na magĩikara magĩcangacangaga kũndũ na kũndũ. Rĩrĩa Saũlũ eerirwo atĩ Daudi nĩorĩte akoima Keila, agĩtiga gũthiĩ kuo.
14 Dafidi sì ń gbé ní aginjù, níbi tí ó ti sá pamọ́ sí, ó sì ń gbé níbi òkè ńlá kan ní aginjù Sifi. Saulu sì ń wá a lójoojúmọ́, ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò fi lé e lọ́wọ́.
Nake Daudi agĩikara ciĩhitho cia werũ-inĩ na irĩma-inĩ cia Werũ wa Zifu. O mũthenya Saũlũ nĩamũcaragia, no Ngai ndaaneanire Daudi moko-inĩ make.
15 Nígbà tí Dafidi wà ní Horeṣi ní aginjù Sifi, Dafidi sì rí i pé, Saulu ti jáde láti wá ẹ̀mí òun kiri.
Rĩrĩa Daudi aarĩ Horeshu kũu Werũ wa Zifu, akĩmenya atĩ Saũlũ okĩte nĩguo amũũrage.
16 Jonatani ọmọ Saulu sì dìde, ó sì tọ Dafidi lọ nínú igbó Horeṣi, ó sì gbà á ní ìyànjú nípa ti Ọlọ́run.
Nake Jonathani mũrũ wa Saũlũ agĩthiĩ kũrĩ Daudi kũu Horeshu na akĩmũteithia kwĩyũmĩrĩria thĩinĩ wa Ngai.
17 Òun sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù, nítorí tí ọwọ́ Saulu baba mi kì yóò tẹ̀ ọ́. Ìwọ ni yóò jẹ ọba lórí Israẹli, èmi ni yóò sì ṣe ibìkejì rẹ. Saulu baba mi mọ̀ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.”
Nake akĩmwĩra atĩrĩ, “Tiga gwĩtigĩra, Baba Saũlũ ndagakũhutia na guoko gwake. Wee nĩũgathamakĩra Isiraeli, na niĩ nduĩke mũnini waku. O na Baba Saũlũ, nĩoĩ ũguo.”
18 Àwọn méjèèjì sì ṣe àdéhùn níwájú Olúwa; Dafidi sì jókòó nínú igbó Horeṣi. Jonatani sì lọ sí ilé rẹ̀.
Nao eerĩ makĩgĩa kĩrĩkanĩro mbere ya Jehova. Thuutha ũcio Jonathani akĩinũka, no Daudi agĩtigwo kũu Horeshu.
19 Àwọn ará Sifi sì gòkè tọ Saulu wá sí Gibeah, wọ́n sì wí pé, “Ṣé Dafidi ti fi ara rẹ̀ pamọ́ sọ́dọ̀ wa ní ibi gíga ìsápamọ́sí ní Horeṣi, ní òkè Hakila, tí ó wà níhà gúúsù ti Jeṣimoni.
Nao andũ a Azifu makĩambata magĩthiĩ kũrĩ Saũlũ kũu Gibea makĩmwĩra atĩrĩ, “Githĩ Daudi ndehithĩte gatagatĩ-inĩ gaitũ ciĩhitho-inĩ cia gũkũ Horeshu, kĩrĩma-igũrũ kĩa Hakila, mwena wa gũthini wa Jeshimoni?
20 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ọba, sọ̀kalẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bi gbogbo ìfẹ́ tí ó wà ní ọkàn rẹ láti sọ̀kalẹ̀: ipa tí àwa ní láti fi lé ọba lọ́wọ́.”
Na rĩrĩ, wee mũthamaki, ikũrũka ũũke o rĩrĩa rĩothe ũngĩenda gũũka, na ithuĩ nĩ igũrũ riitũ kũmũneana kũrĩ mũthamaki.”
21 Saulu sì wí pé, “Alábùkún fún ni ẹ̀yin nípa Olúwa; nítorí pé ẹ̀yin ti káàánú fún mi.
Saũlũ akĩmacookeria atĩrĩ, “Jehova aromũrathima nĩ ũndũ wa kwĩĩnjiiria.
22 Lọ, èmi bẹ̀ yín, ẹ tún múra, kí ẹ sì mọ̀ ki ẹ si rí ibi tí ẹsẹ̀ rẹ̀ gbé wà, àti ẹni tí ó rí níbẹ̀: nítorí tí a ti sọ fún mi pé, ọgbọ́n ni ó ń lò jọjọ.
Thiĩi mũkehaarĩrie makĩria. Tuĩriai nĩ kũ Daudi amenyerete gũthiiaga, na nũũ ũmuonete kuo. Njĩrĩĩtwo atĩ nĩ mũndũ mwara mũno.
23 Ẹ sì wò, kí ẹ sì mọ ibi ìsápamọ́ tí ó máa ń sá pamọ́ sí, kí ẹ sì tún padà tọ̀ mí wá, kí èmi lè mọ̀ dájú; èmi ó sì bá yín lọ: yóò sì ṣe bí ó bá wà ní ilẹ̀ Israẹli, èmi ó sì wá a ní àwárí nínú gbogbo ẹgbẹ̀rún Juda!”
Tuĩriai ũhoro wa kũrĩa guothe ehithaga na mũndehere ũhoro mũkinyanĩru. Na niĩ nĩngũcooka thiĩ na inyuĩ; angĩkorwo arĩ kũndũ gũkũ-rĩ, nĩngamũcaria mĩhĩrĩga-inĩ yothe ya Juda.”
24 Wọ́n sì dìde, wọ́n sì ṣáájú Saulu lọ sí Sifi, ṣùgbọ́n Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ wà ní aginjù Maoni, ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ níhà gúúsù ti Jeṣimoni.
Nĩ ũndũ ũcio makiumagara magĩthiĩ kũu Zifu, magĩkinya mbere ya Saũlũ. Na rĩrĩ, Daudi na andũ ake maarĩ kũu Werũ-inĩ wa Maoni, kũu Araba mwena wa gũthini wa Jeshimoni.
25 Saulu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ ń wá a. Wọ́n sì sọ fún Dafidi: ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí ibi òkúta kan, ó sì jókòó ní aginjù ti Maoni. Saulu sì gbọ́, ó sì lépa Dafidi ní aginjù Maoni.
Nake Saũlũ na andũ ake makĩambĩrĩria kũmacaria, na rĩrĩa Daudi eerirwo ũhoro ũcio, agĩikũrũka agĩthiĩ rwaro-inĩ rwa ihiga, agĩikara kũu Werũ-inĩ wa Maoni. Rĩrĩa Saũlũ aiguire ũhoro ũcio-rĩ, o nake agĩthiĩ kũu Werũ-inĩ wa Maoni aingatithĩtie Daudi na ihenya.
26 Saulu sì ń rin apá kan òkè kan, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ní apá kejì òkè náà. Dafidi sì yára láti sá kúrò níwájú Saulu; nítorí pé Saulu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ti rọ̀gbà yí Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ká láti mú wọn.
Saũlũ aagerete mwena ũmwe wa kĩrĩma, nake Daudi na andũ ake makagerera mwena ũrĩa ũngĩ, mahiũhĩte nĩguo morĩre Saũlũ. Na rĩrĩa Saũlũ na thigari ciake maakuhagĩrĩria Daudi na andũ ake nĩguo mamanyiite-rĩ,
27 Ṣùgbọ́n oníṣẹ́ kan sì tọ Saulu wá ó sì wí pé, “Ìwọ yára kí o sì wá, nítorí tí àwọn Filistini ti gbé ogun ti ilẹ̀ wa.”
hagĩũka mũndũ watũmĩtwo kũrĩ Saũlũ, akĩmwĩra atĩrĩ, “Ũka na ihenya! Afilisti nĩmatharĩkĩire bũrũri.”
28 Saulu sì padà kúrò ní lílépa Dafidi, ó sì lọ pàdé àwọn Filistini nítorí náà ni wọ́n sì ṣe ń pe ibẹ̀ náà ní Selahamalekoti (èyí tí ó túmọ̀ sí “Òkúta Ìpinyà”).
Hĩndĩ ĩyo Saũlũ agĩtiga kũrũmĩrĩra Daudi, agĩthiĩ agacemanie na Afilisti. Nĩkĩo metaga handũ hau Sela-Hamalekothu.
29 Dafidi sì gòkè láti ibẹ̀ lọ, ó sì jókòó níbi tí ó sá pamọ́ sí ní En-Gedi.
Nake Daudi akĩambata akiuma kũu agĩthiĩ gũtũũra ciĩhitho-inĩ cia Eni-Gedi.

< 1 Samuel 23 >