< 1 Samuel 23 >

1 Wọ́n sì wí fún Dafidi pé, “Sá wò ó, àwọn ará Filistini ń bá ará Keila jagun, wọ́n sì ja àwọn ilẹ̀ ìpakà lólè.”
Und sie sagten dem David an und sprachen: Siehe, die Philister streiten wider Kegilah und plündern die Tennen.
2 Dafidi sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa pé, “Ṣé kí èmi ó lọ kọlu àwọn ará Filistini wọ̀nyí bí?” Olúwa sì wí fún Dafidi pé, “Lọ kí o sì kọlu àwọn ará Filistini kí o sì gba Keila sílẹ̀.”
Und David befragte Jehovah und sprach: Soll ich hingehen und diese Philister schlagen? Und Jehovah sprach zu David: Gehe und schlage die Philister und rette Kegilah.
3 Àwọn ọmọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ Dafidi sì wí fún un pé, “Wò ó, àwa ń bẹ̀rù níhìn-ín yìí ní Juda; ǹjẹ́ yóò ti rí nígbà ti àwa bá dé Keila láti fi ojú ko ogun àwọn ara Filistini?”
Und Davids Männer sprachen zu ihm: Siehe, wir sind hier in Judah in Furcht. Und wieviel mehr, wenn wir nach Kegilah wider die Schlachtreihen der Philister ziehen.
4 Dafidi sì tún béèrè lọ́dọ̀ Olúwa. Olúwa sì dá a lóhùn, ó sì wí pé, “Dìde, kí o sọ̀kalẹ̀ lọ sí Keila, nítorí pé èmi ó fi àwọn ará Filistini náà lé ọ lọ́wọ́.”
Und David befragte wiederum Jehovah, und Jehovah antwortete ihm und sprach: Mache dich auf und gehe hinab nach Kegilah; denn ich gebe die Philister in deine Hand.
5 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ sí Keila, wọ́n sì bá àwọn ará Filistini jà, wọ́n sì kó ohun ọ̀sìn wọn, wọ́n sì fi ìparun ńlá pa wọ́n. Dafidi sì gba àwọn ará Keila sílẹ̀.
Und David zog mit seinen Männern nach Kegilah und stritt gegen die Philister, und trieb ihre Viehherden davon und schlug sie mit großer Schlacht, und David rettete die Einwohner Kegilahs.
6 Ó sì ṣe, nígbà tí Abiatari ọmọ Ahimeleki fi sá tọ Dafidi lọ ní Keila, ó sọ̀kalẹ̀ òun pẹ̀lú efodu kan lọ́wọ́ rẹ̀.
Und es geschah, da Abjathar, Achimelechs Sohn, zu David nach Kegilah entwich, kam das Ephod in seiner Hand herab.
7 A sì sọ fún Saulu pé Dafidi wá sí Keila. Saulu sì wí pé, “Ọlọ́run ti fi í lé mi lọ́wọ́; nítorí tí ó ti sé ara rẹ̀ mọ́ ní ti wíwá tí ó wá sí ìlú tí ó ní ìlẹ̀kùn àti kẹrẹ.”
Und dem Saul ward angesagt, daß David nach Kegilah gekommen sei. Und Saul sprach: Gott hat ihn in meine Hand gegeben, da er sich eingeschlossen und in eine Stadt mit Türen und Riegeln gekommen ist.
8 Saulu sì pe gbogbo àwọn ènìyàn náà jọ sí ogun, láti sọ̀kalẹ̀ lọ sí Keila, láti ká Dafidi mọ́ àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀.
Und Saul ließ es das ganze Volk hören, daß es zum Streite hinabgehe nach Kegilah, um David und seine Männer dort zu belagern.
9 Dafidi sì mọ̀ pé Saulu ti gbèrò búburú sí òun; ó sì wí fún Abiatari àlùfáà náà pé, “Mú efodu náà wá níhìn-ín yìí!”
Und David wußte, daß Saul Böses wider ihn im Stillen sann, und sprach zu Abjathar, dem Priester: Bringe das Ephod herbei.
10 Dafidi sì wí pé, “Olúwa Ọlọ́run Israẹli, lóòótọ́ ni ìránṣẹ́ rẹ ti gbọ́ pé Saulu ń wá ọ̀nà láti wá sí Keila, láti wá fọ́ ìlú náà nítorí mi.
Und David sprach: Jehovah, Gott Israels, dein Knecht hat gehört, daß Saul trachte, nach Kegilah zu kommen, um die Stadt wegen meiner zu verderben.
11 Àwọn àgbà ìlú Keila yóò fi mí lé e lọ́wọ́ bí? Saulu yóò ha sọ̀kalẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìránṣẹ́ rẹ ti gbọ́ bí?” Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èmi bẹ̀ ọ́, wí fún ìránṣẹ́ rẹ. Olúwa sì wí pé, “Yóò sọ̀kalẹ̀ wá.”
Werden mich die Bürger von Kegilah in seine Hand überantworten? Wird Saul herabkommen, wie dein Knecht gehört hat? Jehovah, Gott Israels, sage es doch an deinem Knechte. Und Jehovah sprach: Er wird herabkommen.
12 Dafidi sì wí pé, “Àwọn àgbà ìlú Keila yóò fi èmi àti àwọn ọmọkùnrin mi lé Saulu lọ́wọ́ bí?” Olúwa sì wí pé, “Wọn ó fi ọ́ lé wọn lọ́wọ́.”
Und David sprach: Werden die Bürger von Kegilah mich und meine Männer in Sauls Hand überantworten? Und Jehovah sprach: Sie werden euch überantworten.
13 Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ tí wọ́n tó ẹgbẹ̀ta ènìyàn sì dìde, wọ́n lọ kúrò ní Keila, wọ́n sì lọ sí ibikíbi tí wọ́n lè rìn lọ. A sì wí fún Saulu pé, “Dafidi ti sá kúrò ní Keila; kò sì lọ sí Keila mọ́.”
Und David machte sich auf und seine Männer, bei sechshundert Mann, und sie zogen aus von Kegilah und gingen, wohin sie gehen konnten. Und es ward dem Saul angesagt, daß David aus Kegilah entronnen war; und er unterließ es, auszuziehen.
14 Dafidi sì ń gbé ní aginjù, níbi tí ó ti sá pamọ́ sí, ó sì ń gbé níbi òkè ńlá kan ní aginjù Sifi. Saulu sì ń wá a lójoojúmọ́, ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò fi lé e lọ́wọ́.
Und David wohnte in der Wüste in den Festen und blieb auf dem Gebirge in der Wüste Siph, und Saul suchte ihn alle Tage. Gott gab ihn aber nicht in seine Hand.
15 Nígbà tí Dafidi wà ní Horeṣi ní aginjù Sifi, Dafidi sì rí i pé, Saulu ti jáde láti wá ẹ̀mí òun kiri.
Und David sah, daß Saul ausgezogen war, ihm nach der Seele zu trachten. Aber David war in der Wüste Siph in dem Forste.
16 Jonatani ọmọ Saulu sì dìde, ó sì tọ Dafidi lọ nínú igbó Horeṣi, ó sì gbà á ní ìyànjú nípa ti Ọlọ́run.
Und Jonathan, Sauls Sohn, machte sich auf und ging zu David in den Forst und stärkte seine Hand in Gott;
17 Òun sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù, nítorí tí ọwọ́ Saulu baba mi kì yóò tẹ̀ ọ́. Ìwọ ni yóò jẹ ọba lórí Israẹli, èmi ni yóò sì ṣe ibìkejì rẹ. Saulu baba mi mọ̀ bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.”
Und sprach zu ihm: Fürchte dich nicht; denn die Hand meines Vaters Saul wird dich nicht finden, und du wirst König über Israel; ich aber will der Zweite nach dir sein, und auch mein Vater Saul weiß solches.
18 Àwọn méjèèjì sì ṣe àdéhùn níwájú Olúwa; Dafidi sì jókòó nínú igbó Horeṣi. Jonatani sì lọ sí ilé rẹ̀.
Und die zwei schlossen einen Bund vor Jehovah, und David blieb im Forst, Jonathan aber ging nach seinem Hause.
19 Àwọn ará Sifi sì gòkè tọ Saulu wá sí Gibeah, wọ́n sì wí pé, “Ṣé Dafidi ti fi ara rẹ̀ pamọ́ sọ́dọ̀ wa ní ibi gíga ìsápamọ́sí ní Horeṣi, ní òkè Hakila, tí ó wà níhà gúúsù ti Jeṣimoni.
Und die Siphiter gingen zu Saul hinauf nach Gibeah und sprachen: Hält David sich nicht bei uns verborgen in den Festen, in dem Forste, auf dem Hügel Chachilah, der rechts von dem Wüstenlande ist.
20 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ọba, sọ̀kalẹ̀ wá gẹ́gẹ́ bi gbogbo ìfẹ́ tí ó wà ní ọkàn rẹ láti sọ̀kalẹ̀: ipa tí àwa ní láti fi lé ọba lọ́wọ́.”
Und nun komme herab, wie es deine Seele gelüstet herabzukommen, o König, und an uns ist es, ihn in die Hand des Königs zu überantworten.
21 Saulu sì wí pé, “Alábùkún fún ni ẹ̀yin nípa Olúwa; nítorí pé ẹ̀yin ti káàánú fún mi.
Und Saul sprach: Gesegnet seid ihr von Jehovah, daß ihr mich bemitleidet.
22 Lọ, èmi bẹ̀ yín, ẹ tún múra, kí ẹ sì mọ̀ ki ẹ si rí ibi tí ẹsẹ̀ rẹ̀ gbé wà, àti ẹni tí ó rí níbẹ̀: nítorí tí a ti sọ fún mi pé, ọgbọ́n ni ó ń lò jọjọ.
Gehet doch, bereitet ferner, daß ihr wisset und sehet den Ort, da sein Fuß ist, wer ihn dort gesehen hat; denn man hat mir gesagt, daß er gar listig ist.
23 Ẹ sì wò, kí ẹ sì mọ ibi ìsápamọ́ tí ó máa ń sá pamọ́ sí, kí ẹ sì tún padà tọ̀ mí wá, kí èmi lè mọ̀ dájú; èmi ó sì bá yín lọ: yóò sì ṣe bí ó bá wà ní ilẹ̀ Israẹli, èmi ó sì wá a ní àwárí nínú gbogbo ẹgbẹ̀rún Juda!”
Und sehet und wisset alle die Verstecke, wohin er sich versteckt, und kommt zu mir zurück, wenn ihr gewiß seid, auf daß ich mit euch ziehe. Und es soll sein, so er im Lande ist, so will ich ihn ausforschen unter allen Tausenden Judahs.
24 Wọ́n sì dìde, wọ́n sì ṣáájú Saulu lọ sí Sifi, ṣùgbọ́n Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ wà ní aginjù Maoni, ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ níhà gúúsù ti Jeṣimoni.
Und sie machten sich auf und gingen nach Siph vor Saul her; und David und seine Männer waren in der Wüste Maon, in der Arabah, zur Rechten von dem Wüstenland.
25 Saulu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ sì lọ ń wá a. Wọ́n sì sọ fún Dafidi: ó sì sọ̀kalẹ̀ wá sí ibi òkúta kan, ó sì jókòó ní aginjù ti Maoni. Saulu sì gbọ́, ó sì lépa Dafidi ní aginjù Maoni.
Und Saul ging und seine Männer, um zu suchen, und sie sagten es dem David an, und er ging hinab in die Felsenklippe und blieb in der Wüste Maon. Und Saul hörte es und setzte hinter David nach in die Wüste Maon.
26 Saulu sì ń rin apá kan òkè kan, Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ní apá kejì òkè náà. Dafidi sì yára láti sá kúrò níwájú Saulu; nítorí pé Saulu àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ti rọ̀gbà yí Dafidi àti àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ ká láti mú wọn.
Und Saul zog auf der einen Seite des Berges, und David und seine Männer auf der anderen Seite des Berges, und David war in Hast, dem Saul zu entgehen. Saul aber und seine Männer umgaben David und seine Männer, damit er sie fasse.
27 Ṣùgbọ́n oníṣẹ́ kan sì tọ Saulu wá ó sì wí pé, “Ìwọ yára kí o sì wá, nítorí tí àwọn Filistini ti gbé ogun ti ilẹ̀ wa.”
Und es kam ein Bote zu Saul und sprach: Komm in Eile, denn die Philister sind in das Land eingefallen.
28 Saulu sì padà kúrò ní lílépa Dafidi, ó sì lọ pàdé àwọn Filistini nítorí náà ni wọ́n sì ṣe ń pe ibẹ̀ náà ní Selahamalekoti (èyí tí ó túmọ̀ sí “Òkúta Ìpinyà”).
Und Saul kehrte um von der Nachsetzung hinter David und zog den Philistern entgegen. Darum nennen sie den Ort Sela-Hammachlekoth.
29 Dafidi sì gòkè láti ibẹ̀ lọ, ó sì jókòó níbi tí ó sá pamọ́ sí ní En-Gedi.
Und David zog von dannen hinauf und blieb in den Festen En-Gedi.

< 1 Samuel 23 >