< 1 Samuel 22 >

1 Dafidi sì kúrò níbẹ̀, ó sì sá sí ihò Adullamu; nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìdílé baba rẹ̀ sì gbọ́, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá níbẹ̀.
De aceea David a plecat de acolo și a scăpat în peștera Adulam; și când frații săi și toată casa tatălui său au auzit, au coborât acolo la el.
2 Olúkúlùkù ẹni tí ó tí wà nínú ìpọ́njú, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ti jẹ gbèsè, àti olúkúlùkù ẹni tí ó wà nínú ìbànújẹ́, sì kó ara wọn jọ sọ́dọ̀ rẹ̀, òun sì jẹ́ olórí wọn; àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì tó ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin.
Și toți cei strâmtorați și toți datornicii și toți nemulțumiții s-au adunat la el; și el a devenit căpetenie peste ei; și erau cu el cam patru sute de bărbați.
3 Dafidi sì ti ibẹ̀ náà lọ sí Mispa tí Moabu: ó sì wí fún ọba Moabu pé, “Jẹ́ kí baba àti ìyá mi, èmi bẹ̀ ọ́ wá bá ọ gbé, títí èmi yóò fi mọ ohun ti Ọlọ́run yóò ṣe fún mi.”
Și David a plecat de acolo la Mițpa, în Moab; și a spus împăratului Moabului: Lasă pe tatăl meu și pe mama mea, te rog, să vină și să stea cu voi, până când voi ști ce va face Dumnezeu pentru mine.
4 Ó sì mú wọn wá síwájú ọba Moabu; wọ́n sì bá á gbé ní gbogbo ọjọ́ tí Dafidi fi wà nínú ihò náà.
Și i-a adus înaintea împăratului Moabului; și ei au locuit cu el cât timp a fost David în fortăreață.
5 Gadi wòlíì sí wí fún Dafidi pé, “Ma ṣe gbé inú ihò náà, yẹra, kí o sí lọ sí ilẹ̀ Juda.” Nígbà náà ni Dafidi sì yẹra, ó sì lọ sínú igbó Hereti.
Și profetul Gad i-a spus lui David: Nu rămâne în fortăreață; depărtează-te și du-te în țara lui Iuda. Atunci David s-a depărtat și a intrat în pădurea Heret.
6 Saulu si gbọ́ pé a rí Dafidi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀; Saulu sì ń bẹ ní Gibeah lábẹ́ igi tamariski ní Rama; ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dúró tì í.
Când Saul a auzit că David a fost descoperit, el și oamenii care erau cu el (acum, Saul stătea în Ghibea sub un copac în Rama, având sulița sa în mână și toți servitorii săi stăteau în picioare lângă el).
7 Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó dúró tì í, pé, “Ǹjẹ́ ẹ gbọ́ ẹ̀yin ará Benjamini, ọmọ Jese yóò ha fún olúkúlùkù yín ni oko ọgbà àjàrà bí? Kí ó sì sọ gbogbo yin dì olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún bí?
Atunci Saul a spus servitorilor săi care stăteau în picioare lângă el: Ascultați acum, voi beniamiților; vă va da fiul lui Isai fiecăruia dintre voi câmpuri și vii și vă va face el căpetenii peste mii și căpetenii peste sute,
8 Tí gbogbo yín di ìmọ̀lù sí mi, tí kò sì sí ẹnìkan tí ó sọ létí mi pé, ọmọ mi ti bá ọmọ Jese mulẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kó sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó ṣàánú mi, tí ó sì sọ ọ́ létí mi pé, ọmọ mi mú kí ìránṣẹ́ mi dìde sí mi láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
Încât ați uneltit toți împotriva mea și nu este nimeni care să îmi arate că fiul meu a făcut o alianță cu fiul lui Isai și nu este nimeni dintre voi căruia să îi pară rău pentru mine, sau să îmi arate că fiul meu a stârnit pe servitorul meu împotriva mea, ca să pândească împotriva mea, ca în această zi?
9 Doegi ará Edomu tí a fi jẹ olórí àwọn ìránṣẹ́ Saulu, sì dáhùn wí pé, “Èmi rí ọmọ Jese, ó wá sí Nobu, sọ́dọ̀ Ahimeleki ọmọ Ahitubu.
Atunci a răspuns Doeg edomitul, care era pus peste servitorii lui Saul și a spus: Am văzut pe fiul lui Isai venind la Nob, la Ahimelec, fiul lui Ahitub.
10 Òun sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa fún un, ó sì fún un ní oúnjẹ, ó sí fún un ni idà Goliati ará Filistini.”
Și acesta a întrebat pe DOMNUL pentru el și i-a dat merinde și i-a dat sabia lui Goliat, filisteanul.
11 Ọba sì ránṣẹ́ pe Ahimeleki àlùfáà, ọmọ Ahitubu àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀, àwọn àlùfáà tí ó wà ni Nobu: gbogbo wọn ni ó sì wá sọ́dọ̀ ọba.
Atunci împăratul a trimis să îl cheme pe preotul Ahimelec, fiul lui Ahitub, și pe toată casa tatălui său, pe preoții care erau în Nob; și ei au venit toți la împărat.
12 Saulu sì wí pé, “Ǹjẹ́ gbọ́, ìwọ ọmọ Ahitubu.” Òun sì wí pé, “Èmi nìyìí olúwa mi.”
Și Saul a spus: Ascultă acum, tu, fiu al lui Ahitub. Și el a răspuns: Iată-mă, domnul meu.
13 Saulu sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi ṣọ̀tẹ̀ sí mi, ìwọ àti ọmọ Jese, tí ìwọ fi fún un ní àkàrà, àti idà, àti ti ìwọ fi béèrè fún un lọ́dọ̀ Ọlọ́run kí òun lè dìde sí mi, láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
Și Saul i-a spus: De ce ați uneltit împotriva mea, tu și fiul lui Isai, în aceea că i-ai dat pâine și o sabie și ai întrebat pe Dumnezeu pentru el, ca să se ridice împotriva mea, ca să pândească împotriva mea, ca în această zi?
14 Ahimeleki sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Ta ni ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ bí Dafidi, ẹni tí ó jẹ́ àna ọba, ẹni tí ó ń gbọ́ tìrẹ, tí ó sì ni ọlá ní ilé rẹ.
Atunci Ahimelec a răspuns împăratului și a zis: Și cine este atât de credincios printre toți servitorii tăi ca David, care este ginerele împăratului și merge la chemarea ta și este demn de cinste în casa ta?
15 Òní lèmi ó ṣẹ̀ṣẹ̀ máa béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run fún un bí? Kí èyí jìnnà sí mi: kí ọba má ṣe ka nǹkan kan sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́rùn, tàbí sí gbogbo ìdílé baba mi: nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ̀ kò mọ̀kan nínú gbogbo nǹkan yìí, díẹ̀ tàbí púpọ̀.”
Am început eu atunci să întreb pe Dumnezeu pentru el? Departe de mine; să nu impute împăratul vreun lucru servitorului său, nici întregii case a tatălui meu, fiindcă servitorul tău nu a știut nimic din toate acestea, mic sau mare.
16 Ọba sì wí pé, “Ahimeleki, kíkú ni ìwọ yóò kú, ìwọ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀.”
Și împăratul i-a spus: Vei muri negreșit, Ahimelec, tu și toată casa tatălui tău.
17 Ọba sì wí fún àwọn aṣáájú ti máa ń sáré níwájú ọba, tí ó dúró tì í pé, “Yípadà kí ẹ sì pa àwọn àlùfáà Olúwa; nítorí pé ọwọ́ wọn wà pẹ̀lú Dafidi, àti nítorí pé wọ́n mọ ìgbà tí òun sá, wọn kò sì sọ ọ́ létí mi.” Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ ọba kò sì jẹ́ fi ọwọ́ wọn lé àwọn àlùfáà Olúwa láti pa wọ́n.
Și împăratul a spus alergătorilor care stăteau în picioare lângă el: Întoarceți-vă și ucideți pe preoții DOMNULUI, pentru că și mâna lor este cu David și pentru că au știut când a fugit și nu mi-au arătat aceasta. Dar servitorii împăratului au refuzat să întindă mâna ca să cadă asupra preoților DOMNULUI.
18 Ọba sì wí fún Doegi pé, “Ìwọ yípadà, kí o sì pa àwọn àlùfáà!” Doegi ará Edomu sì yípadà, ó sì kọlu àwọn àlùfáà, ó sì pa wọ́n ní ọjọ́ náà, àrùnlélọ́gọ́rin ènìyàn ti ń wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ efodu.
Și împăratul i-a spus lui Doeg: Întoarce-te și aruncă-te asupra preoților. Și Doeg edomitul s-a întors și s-a aruncat asupra preoților și a ucis în acea zi optzeci și cinci de persoane care purtau un efod de in.
19 Ó sì fi ojú idà pa ara Nobu, ìlú àwọn àlùfáà náà àti ọkùnrin àti obìnrin, ọmọ wẹ́wẹ́, àti àwọn tí ó wà lẹ́nu ọmú, àti màlúù, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti àgùntàn.
Și Saul a lovit Nob, cetatea preoților, cu ascuțișul sabiei, deopotrivă bărbați și femei, copii și sugari și boi și măgari și oi, cu ascuțișul sabiei.
20 Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Ahimeleki ọmọ Ahitubu tí a ń pè ní Abiatari sì bọ́; ó sì sá àsálà tọ Dafidi lọ.
Și unul dintre fiii lui Ahimelec, fiul lui Ahitub, numit Abiatar, a scăpat și a fugit după David.
21 Abiatari sì fihan Dafidi pé Saulu pa àwọn àlùfáà Olúwa tán.
Și Abiatar i-a arătat lui David că Saul a ucis pe preoții DOMNULUI.
22 Dafidi sì wí fún Abiatari pé, “Èmi ti mọ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Doegi ará Edomu ti wà níbẹ̀ pé, nítòótọ́ yóò sọ fún Saulu: nítorí mi ni a ṣe pa gbogbo ìdílé baba rẹ.
Și David i-a spus lui Abiatar: Am știut aceasta în acea zi, când Doeg edomitul era acolo, că va spune cu siguranță lui Saul; eu am cauzat moartea tuturor persoanelor din casa tatălui tău.
23 Ìwọ jókòó níhìn-ín lọ́dọ̀ mi, má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé ẹni ti ń wá ẹ̀mí mi, ó ń wá ẹ̀mí rẹ, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ mi ni ìwọ ó wà ní àìléwu.”
Rămâi cu mine, nu te teme, pentru că cel care caută viața mea caută și viața ta; dar cu mine vei fi în siguranță.

< 1 Samuel 22 >