< 1 Samuel 22 >

1 Dafidi sì kúrò níbẹ̀, ó sì sá sí ihò Adullamu; nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìdílé baba rẹ̀ sì gbọ́, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá níbẹ̀.
Potem Dawid odszedł stamtąd i uciekł do jaskini Adullam. Kiedy jego bracia i cała rodzina jego ojca usłyszeli o tym, przyszli tam do niego.
2 Olúkúlùkù ẹni tí ó tí wà nínú ìpọ́njú, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ti jẹ gbèsè, àti olúkúlùkù ẹni tí ó wà nínú ìbànújẹ́, sì kó ara wọn jọ sọ́dọ̀ rẹ̀, òun sì jẹ́ olórí wọn; àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì tó ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin.
I zebrali się wokół niego wszyscy, którzy byli uciśnieni, wszyscy, którzy byli zadłużeni, oraz wszyscy, którzy byli rozgoryczeni, a on stał się ich przywódcą. I było przy nim około czterystu mężczyzn.
3 Dafidi sì ti ibẹ̀ náà lọ sí Mispa tí Moabu: ó sì wí fún ọba Moabu pé, “Jẹ́ kí baba àti ìyá mi, èmi bẹ̀ ọ́ wá bá ọ gbé, títí èmi yóò fi mọ ohun ti Ọlọ́run yóò ṣe fún mi.”
Stamtąd Dawid poszedł do Mispy w Moabie i powiedział do króla Moabu: Pozwól, proszę, by mój ojciec i moja matka przyszli i [mieszkali] z wami, aż się dowiem, co Bóg ze mną uczyni.
4 Ó sì mú wọn wá síwájú ọba Moabu; wọ́n sì bá á gbé ní gbogbo ọjọ́ tí Dafidi fi wà nínú ihò náà.
Przyprowadził ich więc przed króla Moabu i mieszkali u niego przez wszystkie dni, kiedy Dawid przebywał w warowni.
5 Gadi wòlíì sí wí fún Dafidi pé, “Ma ṣe gbé inú ihò náà, yẹra, kí o sí lọ sí ilẹ̀ Juda.” Nígbà náà ni Dafidi sì yẹra, ó sì lọ sínú igbó Hereti.
Potem prorok Gad powiedział do Dawida: Nie pozostawaj w warowni. Wyrusz i wróć do ziemi judzkiej. Dawid wyruszył więc i przybył do lasu Cheret.
6 Saulu si gbọ́ pé a rí Dafidi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀; Saulu sì ń bẹ ní Gibeah lábẹ́ igi tamariski ní Rama; ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dúró tì í.
W czasie gdy Saul usłyszał, że pojawił się Dawid oraz ludzie, którzy z nim byli, Saul przebywał w Gibea pod drzewem w Rama, z włócznią w ręku, a wszyscy jego słudzy stali przy nim.
7 Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó dúró tì í, pé, “Ǹjẹ́ ẹ gbọ́ ẹ̀yin ará Benjamini, ọmọ Jese yóò ha fún olúkúlùkù yín ni oko ọgbà àjàrà bí? Kí ó sì sọ gbogbo yin dì olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún bí?
Saul powiedział więc do swych sług, którzy stali przy nim: Słuchajcie, Beniaminici: Czy syn Jessego da wam wszystkim pola i winnice i czy wszystkich was ustanowi tysiącznikami i setnikami?
8 Tí gbogbo yín di ìmọ̀lù sí mi, tí kò sì sí ẹnìkan tí ó sọ létí mi pé, ọmọ mi ti bá ọmọ Jese mulẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kó sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó ṣàánú mi, tí ó sì sọ ọ́ létí mi pé, ọmọ mi mú kí ìránṣẹ́ mi dìde sí mi láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
Czy dlatego sprzysięgliście się wszyscy przeciwko mnie i nie ma nikogo, kto by mi wyjawił, że mój syn zawarł przymierze z synem Jessego, i nie ma nikogo wśród was, kto by mi współczuł i powiadomił mnie, że mój syn podburzył mego sługę przeciwko mnie, aby czyhał na mnie, jak to [jest] dzisiaj?
9 Doegi ará Edomu tí a fi jẹ olórí àwọn ìránṣẹ́ Saulu, sì dáhùn wí pé, “Èmi rí ọmọ Jese, ó wá sí Nobu, sọ́dọ̀ Ahimeleki ọmọ Ahitubu.
Wtedy Doeg Edomita, przełożony sług Saula, odpowiedział: Widziałem syna Jessego, gdy przyszedł do Nob, do Achimeleka, syna Achituba.
10 Òun sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa fún un, ó sì fún un ní oúnjẹ, ó sí fún un ni idà Goliati ará Filistini.”
Ten radził się PANA w jego sprawie i dał mu żywność, dał mu też miecz Goliata Filistyna.
11 Ọba sì ránṣẹ́ pe Ahimeleki àlùfáà, ọmọ Ahitubu àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀, àwọn àlùfáà tí ó wà ni Nobu: gbogbo wọn ni ó sì wá sọ́dọ̀ ọba.
Wtedy król posłał, by wezwać kapłana Achimeleka, syna Achituba, i cały dom jego ojca, czyli kapłanów, którzy [byli] w Nob. I wszyscy oni przyszli do króla.
12 Saulu sì wí pé, “Ǹjẹ́ gbọ́, ìwọ ọmọ Ahitubu.” Òun sì wí pé, “Èmi nìyìí olúwa mi.”
Saul powiedział: Słuchaj teraz, synu Achituba. A ten odpowiedział: Oto jestem, mój panie.
13 Saulu sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi ṣọ̀tẹ̀ sí mi, ìwọ àti ọmọ Jese, tí ìwọ fi fún un ní àkàrà, àti idà, àti ti ìwọ fi béèrè fún un lọ́dọ̀ Ọlọ́run kí òun lè dìde sí mi, láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
Saul zapytał go: Dlaczego sprzysięgliście się przeciwko mnie, ty i syn Jessego, że dałeś mu chleb i miecz i radziłeś się Boga w jego sprawie, by powstał przeciwko mnie, czyhając na mnie, jak to [jest] dzisiaj?
14 Ahimeleki sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Ta ni ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ bí Dafidi, ẹni tí ó jẹ́ àna ọba, ẹni tí ó ń gbọ́ tìrẹ, tí ó sì ni ọlá ní ilé rẹ.
Achimelek odpowiedział królowi: I któż spośród wszystkich twoich sług jest tak wierny jak Dawid, zięć króla, który wyrusza na twój rozkaz i jest szanowany w twoim domu?
15 Òní lèmi ó ṣẹ̀ṣẹ̀ máa béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run fún un bí? Kí èyí jìnnà sí mi: kí ọba má ṣe ka nǹkan kan sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́rùn, tàbí sí gbogbo ìdílé baba mi: nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ̀ kò mọ̀kan nínú gbogbo nǹkan yìí, díẹ̀ tàbí púpọ̀.”
Czyż dopiero dziś zacząłem radzić się Boga w jego sprawie? Dalekie to ode mnie! Niech król nie obciąża swego sługi ani całego domu mego ojca o nic takiego. Twój sługa bowiem nie miał o tym wszystkim najmniejszego pojęcia.
16 Ọba sì wí pé, “Ahimeleki, kíkú ni ìwọ yóò kú, ìwọ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀.”
Król powiedział: Musisz umrzeć, Achimeleku, ty i cały dom twego ojca.
17 Ọba sì wí fún àwọn aṣáájú ti máa ń sáré níwájú ọba, tí ó dúró tì í pé, “Yípadà kí ẹ sì pa àwọn àlùfáà Olúwa; nítorí pé ọwọ́ wọn wà pẹ̀lú Dafidi, àti nítorí pé wọ́n mọ ìgbà tí òun sá, wọn kò sì sọ ọ́ létí mi.” Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ ọba kò sì jẹ́ fi ọwọ́ wọn lé àwọn àlùfáà Olúwa láti pa wọ́n.
Potem król nakazał sługom, którzy stali przy nim: Odwróćcie się i zabijcie kapłanów PANA, gdyż ich ręka także [jest] z Dawidem, a chociaż wiedzieli, że on uciekł, nie powiadomili mnie. Lecz słudzy króla nie chcieli podnieść ręki na kapłanów PANA i rzucić się [na nich].
18 Ọba sì wí fún Doegi pé, “Ìwọ yípadà, kí o sì pa àwọn àlùfáà!” Doegi ará Edomu sì yípadà, ó sì kọlu àwọn àlùfáà, ó sì pa wọ́n ní ọjọ́ náà, àrùnlélọ́gọ́rin ènìyàn ti ń wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ efodu.
Wtedy król powiedział do Doega: Odwróć się i rzuć na kapłanów. I Doeg Edomita odwrócił się i rzucił na kapłanów, i zabił w tym dniu osiemdziesięciu pięciu mężczyzn noszących lniany efod.
19 Ó sì fi ojú idà pa ara Nobu, ìlú àwọn àlùfáà náà àti ọkùnrin àti obìnrin, ọmọ wẹ́wẹ́, àti àwọn tí ó wà lẹ́nu ọmú, àti màlúù, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti àgùntàn.
Również Nob, miasto kapłanów, wybił ostrzem miecza: mężczyzn i kobiety, dzieci i niemowlęta, woły, osły i owce – [wszystko to] ostrzem miecza.
20 Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Ahimeleki ọmọ Ahitubu tí a ń pè ní Abiatari sì bọ́; ó sì sá àsálà tọ Dafidi lọ.
Uszedł tylko jeden syn Achimeleka, syna Achituba, imieniem Abiatar, uciekł on do Dawida.
21 Abiatari sì fihan Dafidi pé Saulu pa àwọn àlùfáà Olúwa tán.
Abiatar zawiadomił Dawida, że Saul zabił kapłanów PANA.
22 Dafidi sì wí fún Abiatari pé, “Èmi ti mọ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Doegi ará Edomu ti wà níbẹ̀ pé, nítòótọ́ yóò sọ fún Saulu: nítorí mi ni a ṣe pa gbogbo ìdílé baba rẹ.
I Dawid powiedział do Abiatara: Wiedziałem już tego dnia, gdy był tam Doeg Edomita, że z pewnością doniesie o tym Saulowi. To ja spowodowałem [śmierć] wszystkich osób domu twego ojca.
23 Ìwọ jókòó níhìn-ín lọ́dọ̀ mi, má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé ẹni ti ń wá ẹ̀mí mi, ó ń wá ẹ̀mí rẹ, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ mi ni ìwọ ó wà ní àìléwu.”
Zostań ze mną, nie bój się. Kto bowiem czyha na moje życie, czyha też na twoje życie. Lecz u mnie będziesz bezpieczny.

< 1 Samuel 22 >