< 1 Samuel 22 >
1 Dafidi sì kúrò níbẹ̀, ó sì sá sí ihò Adullamu; nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìdílé baba rẹ̀ sì gbọ́, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá níbẹ̀.
Potem wyszedł Dawid stamtąd, i uszedł do jaskini Adullam. Co gdy usłyszeli bracia jego i wszystek dom jego, przyszli tam do niego.
2 Olúkúlùkù ẹni tí ó tí wà nínú ìpọ́njú, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ti jẹ gbèsè, àti olúkúlùkù ẹni tí ó wà nínú ìbànújẹ́, sì kó ara wọn jọ sọ́dọ̀ rẹ̀, òun sì jẹ́ olórí wọn; àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì tó ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin.
I zebrali się do niego wszyscy, którzy byli utrapieni, i wszyscy, którzy byli dłużni, i wszyscy, którzykolwiek byli w gorzkości serca, i był nad nimi książęciem, a było z nim około czterech set mężów.
3 Dafidi sì ti ibẹ̀ náà lọ sí Mispa tí Moabu: ó sì wí fún ọba Moabu pé, “Jẹ́ kí baba àti ìyá mi, èmi bẹ̀ ọ́ wá bá ọ gbé, títí èmi yóò fi mọ ohun ti Ọlọ́run yóò ṣe fún mi.”
I poszedł Dawid stamtąd do Masfa Moabskiego, i rzekł do króla Moabskiego: Niech się przeprowadzi proszę ojciec mój, i matka moja, aby mieszkali z wami, aż się dowiem co uczyni Bóg ze mną.
4 Ó sì mú wọn wá síwájú ọba Moabu; wọ́n sì bá á gbé ní gbogbo ọjọ́ tí Dafidi fi wà nínú ihò náà.
A tak przywiódł je przed króla Moabskiego; i mieszkali z nim po wszystkie dni, których był Dawid na onym zamku.
5 Gadi wòlíì sí wí fún Dafidi pé, “Ma ṣe gbé inú ihò náà, yẹra, kí o sí lọ sí ilẹ̀ Juda.” Nígbà náà ni Dafidi sì yẹra, ó sì lọ sínú igbó Hereti.
Rzekł potem Gad prorok do Dawida: Nie mieszkaj więcej na tym zamku; idź, a wróć się do ziemi Judzkiej. Tedy poszedł Dawid, a przyszedł do lasu Haret.
6 Saulu si gbọ́ pé a rí Dafidi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀; Saulu sì ń bẹ ní Gibeah lábẹ́ igi tamariski ní Rama; ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dúró tì í.
A usłyszawszy Saul, że się pojawił Dawid, i mężowie, którzy byli z nim, (bo Saul mieszkał w Gabaa pod gajem w Ramacie, mając włócznią swoję w rękach swych, a wszyscy słudzy jego stali przed nim).
7 Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó dúró tì í, pé, “Ǹjẹ́ ẹ gbọ́ ẹ̀yin ará Benjamini, ọmọ Jese yóò ha fún olúkúlùkù yín ni oko ọgbà àjàrà bí? Kí ó sì sọ gbogbo yin dì olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún bí?
Rzekł tedy Saul do sług swych, którzy stali przed nim: Słuchajcie proszę synowie Jemini: Izaż wam wszystkim da syn Isajego role i winnice, a wszystkich was poczyni półkownikami i rotmistrzami.
8 Tí gbogbo yín di ìmọ̀lù sí mi, tí kò sì sí ẹnìkan tí ó sọ létí mi pé, ọmọ mi ti bá ọmọ Jese mulẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kó sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó ṣàánú mi, tí ó sì sọ ọ́ létí mi pé, ọmọ mi mú kí ìránṣẹ́ mi dìde sí mi láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
Żeście się sprzysięgli wy wszyscy przeciwko mnie, a niemasz ktoby mi objawił? gdyż się zbuntował i syn mój z synem Isajego, a niemasz ktoby się mnie użalił między wami, a oznajmił mi, iż podburzył syn mój sługę mego przeciwko mnie, aby czyhał na mię, jako się to dziś okazuje.
9 Doegi ará Edomu tí a fi jẹ olórí àwọn ìránṣẹ́ Saulu, sì dáhùn wí pé, “Èmi rí ọmọ Jese, ó wá sí Nobu, sọ́dọ̀ Ahimeleki ọmọ Ahitubu.
Tedy odpowiedział Doeg Edomczyk, który też stał z sługami Saulowymi, i rzekł: Widziałem syna Isajego, gdy przyszedł do Noby, do Achimelecha, syna Achitobowego.
10 Òun sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa fún un, ó sì fún un ní oúnjẹ, ó sí fún un ni idà Goliati ará Filistini.”
Który się oń radził Pana, i dał mu żywności, dał mu też i miecz Golijata Filistyńczyka.
11 Ọba sì ránṣẹ́ pe Ahimeleki àlùfáà, ọmọ Ahitubu àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀, àwọn àlùfáà tí ó wà ni Nobu: gbogbo wọn ni ó sì wá sọ́dọ̀ ọba.
A tak posłał król, aby przyzwano Achimelecha, syna Achitobowego, kapłana, i wszystkiego domu ojca jego kapłanów, którzy byli w Nobe. I przyszli oni wszyscy do króla.
12 Saulu sì wí pé, “Ǹjẹ́ gbọ́, ìwọ ọmọ Ahitubu.” Òun sì wí pé, “Èmi nìyìí olúwa mi.”
Tedy rzekł Saul: Słuchaj teraz synu Achitoba; a on rzekł: Owom ja panie mój.
13 Saulu sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi ṣọ̀tẹ̀ sí mi, ìwọ àti ọmọ Jese, tí ìwọ fi fún un ní àkàrà, àti idà, àti ti ìwọ fi béèrè fún un lọ́dọ̀ Ọlọ́run kí òun lè dìde sí mi, láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
I rzekł do niego Saul: Czemuście się sprzysięgli przeciwko mnie, ty i syn Isajego, gdyś mu dał chleb i miecz, a radziłeś się oń Boga, aby powstał przeciwko mnie, czyhając na mię, jako się to dziś okazuje?
14 Ahimeleki sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Ta ni ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ bí Dafidi, ẹni tí ó jẹ́ àna ọba, ẹni tí ó ń gbọ́ tìrẹ, tí ó sì ni ọlá ní ilé rẹ.
I odpowiedział Achimelech królowi, a rzekł: I któż jest tak wierny między wszystkimi sługami twoimi, jako Dawid, który jest i zięciem królewskim i idzie za rozkazaniem twojem, a jest zacnym w domu twoim?
15 Òní lèmi ó ṣẹ̀ṣẹ̀ máa béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run fún un bí? Kí èyí jìnnà sí mi: kí ọba má ṣe ka nǹkan kan sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́rùn, tàbí sí gbogbo ìdílé baba mi: nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ̀ kò mọ̀kan nínú gbogbo nǹkan yìí, díẹ̀ tàbí púpọ̀.”
Azaż dziś począłem się oń radzić Boga? Uchowaj mię Boże! Niech nie wkłada król na sługę twego nic takiego, ani na wszystek dom ojca mego; bo nie wiedział sługa twój o tem wszystkiem najmniejszej rzeczy.
16 Ọba sì wí pé, “Ahimeleki, kíkú ni ìwọ yóò kú, ìwọ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀.”
I rzekł król: Śmiercią umrzesz Achimelechu, ty i wszystek dom ojca twego.
17 Ọba sì wí fún àwọn aṣáájú ti máa ń sáré níwájú ọba, tí ó dúró tì í pé, “Yípadà kí ẹ sì pa àwọn àlùfáà Olúwa; nítorí pé ọwọ́ wọn wà pẹ̀lú Dafidi, àti nítorí pé wọ́n mọ ìgbà tí òun sá, wọn kò sì sọ ọ́ létí mi.” Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ ọba kò sì jẹ́ fi ọwọ́ wọn lé àwọn àlùfáà Olúwa láti pa wọ́n.
Przytem rzekł król sługom, którzy stali przed nim: Obróćcie się, a pobijcie kapłany Pańskie; bo też ręka ich jest z Dawidem, gdyż wiedząc, że on uciekał, nie oznajmili mi. Ale słudzy królewscy nie chcieli podnieść ręki swej, ani się rzucić na kapłany Pańskie.
18 Ọba sì wí fún Doegi pé, “Ìwọ yípadà, kí o sì pa àwọn àlùfáà!” Doegi ará Edomu sì yípadà, ó sì kọlu àwọn àlùfáà, ó sì pa wọ́n ní ọjọ́ náà, àrùnlélọ́gọ́rin ènìyàn ti ń wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ efodu.
Przetoż rzekł król do Doega: Obróć się ty, a rzuć się na kapłany. A tak obróciwszy się Doeg Edomczyk, rzucił się na kapłany, i zabił onegoż dnia ośmdziesiąt i pięć mężów, którzy nosili efod lniane.
19 Ó sì fi ojú idà pa ara Nobu, ìlú àwọn àlùfáà náà àti ọkùnrin àti obìnrin, ọmọ wẹ́wẹ́, àti àwọn tí ó wà lẹ́nu ọmú, àti màlúù, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti àgùntàn.
Nobe też miasto kapłańskie wysiekł ostrzem miecza, od męża aż do niewiasty, od małego aż do ssącego, i woły, i osły, i owce wysiekł ostrzem miecza.
20 Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Ahimeleki ọmọ Ahitubu tí a ń pè ní Abiatari sì bọ́; ó sì sá àsálà tọ Dafidi lọ.
Uszedł tylko syn jeden Achimelecha, syna Achitobowego; a imię jego Abijatar; i uciekł do Dawida.
21 Abiatari sì fihan Dafidi pé Saulu pa àwọn àlùfáà Olúwa tán.
Tedy oznajmił Abijatar Dawidowi, że pobił Saul kapłany Pańskie.
22 Dafidi sì wí fún Abiatari pé, “Èmi ti mọ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Doegi ará Edomu ti wà níbẹ̀ pé, nítòótọ́ yóò sọ fún Saulu: nítorí mi ni a ṣe pa gbogbo ìdílé baba rẹ.
I rzekł Dawid do Abijatara: Wiedziałem onegoż dnia, gdyż tam był Doeg Edomczyk, że pewnie oznajmić miał Saulowi: Jam jest przyczyną śmierci wszystkich dusz domu ojca twego.
23 Ìwọ jókòó níhìn-ín lọ́dọ̀ mi, má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé ẹni ti ń wá ẹ̀mí mi, ó ń wá ẹ̀mí rẹ, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ mi ni ìwọ ó wà ní àìléwu.”
Zostańże przy mnie, nie bój się; bo ktoby szukał duszy mojej, będzie szukał duszy twojej; ale ty będziesz schroniony przy mnie.