< 1 Samuel 22 >

1 Dafidi sì kúrò níbẹ̀, ó sì sá sí ihò Adullamu; nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìdílé baba rẹ̀ sì gbọ́, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá níbẹ̀.
Na ka haere atu a Rawiri i reira, a rere ana ki te ana o Aturama. A ka rongo ona tuakana, me te whare katoa o tona papa, na ka haere ki reira, ki a ia.
2 Olúkúlùkù ẹni tí ó tí wà nínú ìpọ́njú, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ti jẹ gbèsè, àti olúkúlùkù ẹni tí ó wà nínú ìbànújẹ́, sì kó ara wọn jọ sọ́dọ̀ rẹ̀, òun sì jẹ́ olórí wọn; àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì tó ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin.
I huihui ano ki a ia nga tangata katoa e pehia ana e te aha, e te aha, me nga tangata i a ratou nei etahi taonga tarewa, me nga tangata katoa e mamae ana te ngakau: a ko ia hei rangatira mo ratou, tata tonu ki te wha rau nga tangata i piri ki a i a.
3 Dafidi sì ti ibẹ̀ náà lọ sí Mispa tí Moabu: ó sì wí fún ọba Moabu pé, “Jẹ́ kí baba àti ìyá mi, èmi bẹ̀ ọ́ wá bá ọ gbé, títí èmi yóò fi mọ ohun ti Ọlọ́run yóò ṣe fún mi.”
Na ka haere atu a Rawiri i reira ki Mihipa o Moapa, ka mea ki te kingi Moapa, Tukua toku papa me toku whaea kia haere mai ki a koutou, kia mohio ra ano ahau ki ta te Atua e mea ai ki ahau.
4 Ó sì mú wọn wá síwájú ọba Moabu; wọ́n sì bá á gbé ní gbogbo ọjọ́ tí Dafidi fi wà nínú ihò náà.
Na ka kawea raua e ia ki te aroaro o te kingi o Moapa, a noho ana kaua ki a ia i nga ra katoa i noho ai a Rawiri i te pourewa
5 Gadi wòlíì sí wí fún Dafidi pé, “Ma ṣe gbé inú ihò náà, yẹra, kí o sí lọ sí ilẹ̀ Juda.” Nígbà náà ni Dafidi sì yẹra, ó sì lọ sínú igbó Hereti.
Na ka mea a Kara poropiti ki a Rawiri, Kaua e noho ki te pourewa, whakatika, haere ki te whenua o hura. Na ka haere a Rawiri, a noho ana i te nehenehe i Harete
6 Saulu si gbọ́ pé a rí Dafidi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀; Saulu sì ń bẹ ní Gibeah lábẹ́ igi tamariski ní Rama; ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dúró tì í.
A, no te rongonga o Haora kua kitea a Rawiri ratou ko ona hoa, na i Kipea a Haora e noho ana, i raro i tetahi rakau, i Rama, me tana tao i tona ringa, me te tu ana tangata katoa i tona taha;
7 Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó dúró tì í, pé, “Ǹjẹ́ ẹ gbọ́ ẹ̀yin ará Benjamini, ọmọ Jese yóò ha fún olúkúlùkù yín ni oko ọgbà àjàrà bí? Kí ó sì sọ gbogbo yin dì olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún bí?
Ka mea a Haora ki ana tangata e tu ana i tona taha, Whakarongo mai ki ahau, e nga Pinemini; e homai ranei e te tama a Hehe he mara ki a koutou katoa, he kari waina, e meinga ranei koutou katoa e ia hei rangatira mano, hei rangatira rau;
8 Tí gbogbo yín di ìmọ̀lù sí mi, tí kò sì sí ẹnìkan tí ó sọ létí mi pé, ọmọ mi ti bá ọmọ Jese mulẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kó sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó ṣàánú mi, tí ó sì sọ ọ́ létí mi pé, ọmọ mi mú kí ìránṣẹ́ mi dìde sí mi láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
I whakatenetene mai ai koutou ki ahau; a kahore tetahi hei whakaatu ki ahau i te whakaritenga kawenata a taku tama raua ko te tama a Hehe: kahore tetahi o koutou e pouri moku, e whaki ranei ki ahau, na taku tama i whakatutehu taku tangata ki ahau, kia whanga puku, penei me tenei inaianei?
9 Doegi ará Edomu tí a fi jẹ olórí àwọn ìránṣẹ́ Saulu, sì dáhùn wí pé, “Èmi rí ọmọ Jese, ó wá sí Nobu, sọ́dọ̀ Ahimeleki ọmọ Ahitubu.
Katahi ka oho mai ko Roeke Eromi, he kaitohutohu no nga tangata a Haora, ka mea, I kite ahau i te tama a Hehe e haere ana ki Nopo, ki a Ahimereke tama a Ahitupu.
10 Òun sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa fún un, ó sì fún un ní oúnjẹ, ó sí fún un ni idà Goliati ará Filistini.”
Na uia ana e tera he tikanga mana i a Ihowa; i hoatu ano e ia he o mona; ko te hoari hoki a Koriata Pirihitini i hoatu ano e ia ki a ia.
11 Ọba sì ránṣẹ́ pe Ahimeleki àlùfáà, ọmọ Ahitubu àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀, àwọn àlùfáà tí ó wà ni Nobu: gbogbo wọn ni ó sì wá sọ́dọ̀ ọba.
Katahi te kingi ka unga tangata atu hei karanga i te tohunga, i a Ahimereke tama a Ahitupu ratou ko te whare katoa o tona papa, i nga tohunga e noho ana i Nopo, a ka haere katoa mai ratou ki te kingi.
12 Saulu sì wí pé, “Ǹjẹ́ gbọ́, ìwọ ọmọ Ahitubu.” Òun sì wí pé, “Èmi nìyìí olúwa mi.”
Na ka mea a Haora, Whakarongo mai, e te tama a Ahitupu. A ka mea tera, Tenei ahau, e toku ariki.
13 Saulu sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi ṣọ̀tẹ̀ sí mi, ìwọ àti ọmọ Jese, tí ìwọ fi fún un ní àkàrà, àti idà, àti ti ìwọ fi béèrè fún un lọ́dọ̀ Ọlọ́run kí òun lè dìde sí mi, láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
Ano ra ko Haora ki a ia, He aha korua ko te tama a Hehe i whakatenetene mai ai ki ahau, a hoatu ana e koe he taro mana, he hoari, uia ana ano e koe he tikanga mana i te Atua, kia whakatika mai ai ia ki ahau whanga ai; koia ano tenei inaianei?
14 Ahimeleki sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Ta ni ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ bí Dafidi, ẹni tí ó jẹ́ àna ọba, ẹni tí ó ń gbọ́ tìrẹ, tí ó sì ni ọlá ní ilé rẹ.
Na ka utu a Ahimereke ki te kingi, ka mea, Ha, ko wai o au tangata katoa hei rite mo Rawiri te pono? ko te hunaonga hoki ia a te kingi, e haere ana i tau ngare, e whakahonoretia ana hoki i roto i tou whare?
15 Òní lèmi ó ṣẹ̀ṣẹ̀ máa béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run fún un bí? Kí èyí jìnnà sí mi: kí ọba má ṣe ka nǹkan kan sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́rùn, tàbí sí gbogbo ìdílé baba mi: nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ̀ kò mọ̀kan nínú gbogbo nǹkan yìí, díẹ̀ tàbí púpọ̀.”
No tenei ra koia i timata ai ahau ki te ui mea mana i te Atua? kahore rapea! kaua tetahi mea e whakairia mai e te kingi ki tana pononga, ki tetahi ranei o te whare o toku papa: kahore hoki tau pononga i mohio ki tetahi aha o tenei, ahakoa iti, a hakoa rahi.
16 Ọba sì wí pé, “Ahimeleki, kíkú ni ìwọ yóò kú, ìwọ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀.”
Na ka mea te kingi, Ko te mate anake mou, e Ahimereke, mou, mo te whare katoa ano o tou papa.
17 Ọba sì wí fún àwọn aṣáájú ti máa ń sáré níwájú ọba, tí ó dúró tì í pé, “Yípadà kí ẹ sì pa àwọn àlùfáà Olúwa; nítorí pé ọwọ́ wọn wà pẹ̀lú Dafidi, àti nítorí pé wọ́n mọ ìgbà tí òun sá, wọn kò sì sọ ọ́ létí mi.” Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ ọba kò sì jẹ́ fi ọwọ́ wọn lé àwọn àlùfáà Olúwa láti pa wọ́n.
Na ka mea te kingi ki nga kaitiaki e tu ana i tona taha, Tahuri atu, whakamatea nga tohunga a Ihowa; he mea ko o ratou ringa ano kei a Rawiri; i mohio hoki ratou e rere ana ia, a kihai i whakaatu mai ki ahau. Otiia kihai i pai nga tangata a te k ingi kia totoro atu o ratou ringa, kia rere ki runga ki nga tohunga a Ihowa.
18 Ọba sì wí fún Doegi pé, “Ìwọ yípadà, kí o sì pa àwọn àlùfáà!” Doegi ará Edomu sì yípadà, ó sì kọlu àwọn àlùfáà, ó sì pa wọ́n ní ọjọ́ náà, àrùnlélọ́gọ́rin ènìyàn ti ń wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ efodu.
Na ka mea te kingi ki a Roeke, Tahuri atu, e rere ki runga ki nga tohunga. Na tahuri ana a Roeke, Eromi, a rere ana ki runga ki nga tohunga, a e waru tekau ma rima nga tangata i patua e ia i taua ra, he hunga kakahu i te epora rinena.
19 Ó sì fi ojú idà pa ara Nobu, ìlú àwọn àlùfáà náà àti ọkùnrin àti obìnrin, ọmọ wẹ́wẹ́, àti àwọn tí ó wà lẹ́nu ọmú, àti màlúù, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti àgùntàn.
I patua ano hoki e ia a Nopo, te pa o nga tohunga, ki te mata o te hoari, te tane, te wahine, nga tamariki, nga mea ngote u, nga kau, nga kaihe, nga hipi, ki te mata o te hoari.
20 Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Ahimeleki ọmọ Ahitubu tí a ń pè ní Abiatari sì bọ́; ó sì sá àsálà tọ Dafidi lọ.
Na i mawhiti tetahi o nga tama a Ahimereke tama a Ahitupu, tona ingoa ko Apiatara; a rere ana ki te whai i a Rawiri.
21 Abiatari sì fihan Dafidi pé Saulu pa àwọn àlùfáà Olúwa tán.
A na Apiatara i korero ki a Rawiri ta Haora patunga i nga tohunga a Ihowa.
22 Dafidi sì wí fún Abiatari pé, “Èmi ti mọ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Doegi ará Edomu ti wà níbẹ̀ pé, nítòótọ́ yóò sọ fún Saulu: nítorí mi ni a ṣe pa gbogbo ìdílé baba rẹ.
Na ka mea a Rawiri ki a Apiatara, I mohio ano ahau i taua ra i a Roeke Eromi i kona, ka whakaaturia e ia ki a Haora. Naku i mate ai nga tangata katoa o te whare o tou papa.
23 Ìwọ jókòó níhìn-ín lọ́dọ̀ mi, má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé ẹni ti ń wá ẹ̀mí mi, ó ń wá ẹ̀mí rẹ, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ mi ni ìwọ ó wà ní àìléwu.”
E noho koe ki ahau, kaua e wehi; ko te tangata hoki e whai ana i te mate moku, e whai ana i te mate mou: na kei ahau nei koe, ka tiakina koe.

< 1 Samuel 22 >