< 1 Samuel 22 >
1 Dafidi sì kúrò níbẹ̀, ó sì sá sí ihò Adullamu; nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìdílé baba rẹ̀ sì gbọ́, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá níbẹ̀.
HELE o Davida mai laila aku, a holo aku la ma ke ana o Adulama: a lohe ae la kona mau hoahanau a me na mea a pau o ka hale o kona makuakane, hele lakou io na la ilaila.
2 Olúkúlùkù ẹni tí ó tí wà nínú ìpọ́njú, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ti jẹ gbèsè, àti olúkúlùkù ẹni tí ó wà nínú ìbànújẹ́, sì kó ara wọn jọ sọ́dọ̀ rẹ̀, òun sì jẹ́ olórí wọn; àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì tó ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin.
O na kanaka a pau i popilikia, a me na kanaka aie a pau, a me na kanaka a pau i eha ma ka naau, hoakoakoa ae la lakou io na la: a lilo ia i luna no lakou: eha haneri kanaka paha me ia.
3 Dafidi sì ti ibẹ̀ náà lọ sí Mispa tí Moabu: ó sì wí fún ọba Moabu pé, “Jẹ́ kí baba àti ìyá mi, èmi bẹ̀ ọ́ wá bá ọ gbé, títí èmi yóò fi mọ ohun ti Ọlọ́run yóò ṣe fún mi.”
A hele o Davida mai laila aku a Mizepa ma Moaba: i aku la ia i ke alii o Moaba, Ke noi aku nei au, e ae mai oe i ko'u makuakane a me ko'u makuwahine e hele mai e noho me oe, a ike au i ka mea a ke Akua e hana mai ai no'u.
4 Ó sì mú wọn wá síwájú ọba Moabu; wọ́n sì bá á gbé ní gbogbo ọjọ́ tí Dafidi fi wà nínú ihò náà.
A lawe mai oia ia laua i ke alii o Moaba, a noho laua me ia i na la a pau a Davida i noho ai maluna o ka puukaua.
5 Gadi wòlíì sí wí fún Dafidi pé, “Ma ṣe gbé inú ihò náà, yẹra, kí o sí lọ sí ilẹ̀ Juda.” Nígbà náà ni Dafidi sì yẹra, ó sì lọ sínú igbó Hereti.
Olelo aku la ke kaula a Gada ia Davida, Mai noho oe ma ka puukaua; e hele aku, a hiki oe ma ka aina o ka Iuda. A hele aku la o Davida a hiki ma ka ululaau o Hareta.
6 Saulu si gbọ́ pé a rí Dafidi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀; Saulu sì ń bẹ ní Gibeah lábẹ́ igi tamariski ní Rama; ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dúró tì í.
A lohe ae la o Saula, ua ikeia o Davida, a me na kanaka me ia, (e noho ana o Saula ma Gibea malalo o ka laau ma kahi kiekie, a ma kona lima kana ihe, a ua hoonohoia kana mau kauwa a puni ona; )
7 Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó dúró tì í, pé, “Ǹjẹ́ ẹ gbọ́ ẹ̀yin ará Benjamini, ọmọ Jese yóò ha fún olúkúlùkù yín ni oko ọgbà àjàrà bí? Kí ó sì sọ gbogbo yin dì olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún bí?
Olelo aku la o Saula i kana poe kauwa e ku ana a puni ona, E hoolohe ano, e na Beniamina; e haawi anei ke keiki a Iese i na mahinaai, a me na pawaina na oukou a pau, a e hoolilo ia oukou a pau i luna tausani, a i luna haneri;
8 Tí gbogbo yín di ìmọ̀lù sí mi, tí kò sì sí ẹnìkan tí ó sọ létí mi pé, ọmọ mi ti bá ọmọ Jese mulẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kó sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó ṣàánú mi, tí ó sì sọ ọ́ létí mi pé, ọmọ mi mú kí ìránṣẹ́ mi dìde sí mi láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
I kipi ai oukou a pau ia'u, aohe mea e hoike mai ia'u, ua hana ka'u keiki me ke keiki a Iese i kuikahi, aole kekahi o oukou e manao mai ia'u, aole hoi e hoike mai ia'u, ua hoala ka'u keiki i ka'u kauwa e ku e ia'u, e hoohalua, e like me ia i keia la?
9 Doegi ará Edomu tí a fi jẹ olórí àwọn ìránṣẹ́ Saulu, sì dáhùn wí pé, “Èmi rí ọmọ Jese, ó wá sí Nobu, sọ́dọ̀ Ahimeleki ọmọ Ahitubu.
Alaila olelo mai o Doega no Edoma, oia ka luna o na kauwa a Saula, i mai la, Ua ike au i ke keiki a Iese e hele ana ma Noba io Ahimeleka la ke keiki a Ahituba.
10 Òun sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa fún un, ó sì fún un ní oúnjẹ, ó sí fún un ni idà Goliati ará Filistini.”
A ua ninau aku oia ia Iehova nona, a haawi aku i ka ai nana, a haawi aku hoi ia ia i ka pahikaua a Golia ke kanaka no ko Pilisetia.
11 Ọba sì ránṣẹ́ pe Ahimeleki àlùfáà, ọmọ Ahitubu àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀, àwọn àlùfáà tí ó wà ni Nobu: gbogbo wọn ni ó sì wá sọ́dọ̀ ọba.
Alaila hoouna aku ke alii e hea ia Ahimeleka, ke kahuna, ke keiki a Ahituba, a me ko ka hale a pau o kona makuakane, na kahuna ma Noba; a hele mai lakou a pau i ke alii.
12 Saulu sì wí pé, “Ǹjẹ́ gbọ́, ìwọ ọmọ Ahitubu.” Òun sì wí pé, “Èmi nìyìí olúwa mi.”
I aku la o Saula, Ano e hoolohe mai oe, e ke keiki a Ahituba. I mai la kela, Eia wau, e kuu haku.
13 Saulu sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi ṣọ̀tẹ̀ sí mi, ìwọ àti ọmọ Jese, tí ìwọ fi fún un ní àkàrà, àti idà, àti ti ìwọ fi béèrè fún un lọ́dọ̀ Ọlọ́run kí òun lè dìde sí mi, láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
I aku la o Saula ia ia, No ke aha la i kipi ai olua ia'u o oe a me ke keiki a Iese, i kou haawi ana ia ia i ka berena, a me ka pahikaua, a ua ninau oe i ke Akua nona, i ku e mai ia ia'u e halua, e like me ia i keia la.
14 Ahimeleki sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Ta ni ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ bí Dafidi, ẹni tí ó jẹ́ àna ọba, ẹni tí ó ń gbọ́ tìrẹ, tí ó sì ni ọlá ní ilé rẹ.
Olelo mai la o Ahimeleka i ke alii, i mai la, Owai la ka mea o kau poe kauwa i malama pono e like me Davida, ka hunonakane a ke alii, a ua hele ia i kau i ana aku, a ua manao nui ia ma kou hale?
15 Òní lèmi ó ṣẹ̀ṣẹ̀ máa béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run fún un bí? Kí èyí jìnnà sí mi: kí ọba má ṣe ka nǹkan kan sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́rùn, tàbí sí gbogbo ìdílé baba mi: nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ̀ kò mọ̀kan nínú gbogbo nǹkan yìí, díẹ̀ tàbí púpọ̀.”
O kuu hoomaka no anei ia e ninau aku i ke Akua nona? Aole ia'u ia mea: mai hooili ke alii ia mea maluna o kana kauwa, maluna hoi o ko ka hale a pau o ko'u makuakane; no ka mea, aole i ike kau kauwa i ka mea uuku, aole hoi i ka mea nui o keia mea.
16 Ọba sì wí pé, “Ahimeleki, kíkú ni ìwọ yóò kú, ìwọ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀.”
I aku la ke alii, E make io auanei oe, e Ahimeleka, o oe a me ko ka hale a pau o kou makuakane.
17 Ọba sì wí fún àwọn aṣáájú ti máa ń sáré níwájú ọba, tí ó dúró tì í pé, “Yípadà kí ẹ sì pa àwọn àlùfáà Olúwa; nítorí pé ọwọ́ wọn wà pẹ̀lú Dafidi, àti nítorí pé wọ́n mọ ìgbà tí òun sá, wọn kò sì sọ ọ́ létí mi.” Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ ọba kò sì jẹ́ fi ọwọ́ wọn lé àwọn àlùfáà Olúwa láti pa wọ́n.
Olelo aku la ke alii i ka poe kiai e ku ana a puni ona, E huli ae oukou a e pepehi i na kahuna no Iehova; no ka mea, ua hui pu ko lakou lima me Davida, a ua ike lakou i kona mahuka ana, aole hoi i hoike mai ia'u Aka, aole makemake na kauwa a ke alii e kau aku i ko lakou lima e lele maluna o na kahuna no Iehova.
18 Ọba sì wí fún Doegi pé, “Ìwọ yípadà, kí o sì pa àwọn àlùfáà!” Doegi ará Edomu sì yípadà, ó sì kọlu àwọn àlùfáà, ó sì pa wọ́n ní ọjọ́ náà, àrùnlélọ́gọ́rin ènìyàn ti ń wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ efodu.
I aku la ke alii ia Doega, E huli ae oe, a lele maluna o ua kahuna. A huli ae la o Doega, ka Edoma, a lele maluna o na kahuna, a pepehi iho la ia la i na kanaka he kanawalukumamalima i pulikiia i ka epoda olona.
19 Ó sì fi ojú idà pa ara Nobu, ìlú àwọn àlùfáà náà àti ọkùnrin àti obìnrin, ọmọ wẹ́wẹ́, àti àwọn tí ó wà lẹ́nu ọmú, àti màlúù, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti àgùntàn.
A luku aku la oia ia Noba ke kulanakauhale o na kahuna me ka maka o ka pahikaua; o na kanaka, o na wahine, o na kamalii, o na mea omo waiu, o na bipi, o na hoki, a me na hipa, me ka maka o ka pahikaua.
20 Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Ahimeleki ọmọ Ahitubu tí a ń pè ní Abiatari sì bọ́; ó sì sá àsálà tọ Dafidi lọ.
A o kekahi o na keiki a Ahimeleka, ke keiki a Ahituba, o Abiatara kona inoa, pakele aku la ia, a holo aku mahope o Davida.
21 Abiatari sì fihan Dafidi pé Saulu pa àwọn àlùfáà Olúwa tán.
A hoike aku la o Abiatara ia Davida i ka Saula pepehi ana i na kahuna o Iehova.
22 Dafidi sì wí fún Abiatari pé, “Èmi ti mọ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Doegi ará Edomu ti wà níbẹ̀ pé, nítòótọ́ yóò sọ fún Saulu: nítorí mi ni a ṣe pa gbogbo ìdílé baba rẹ.
I mai la o Davida i Abiatara, Ia la, i ka noho ana o Doega ka Edoma malaila, ike no wau, e hai aku ia ia Saula: owau no ka mea i make ai o na mea a pau o ka hale o kou makuakane.
23 Ìwọ jókòó níhìn-ín lọ́dọ̀ mi, má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé ẹni ti ń wá ẹ̀mí mi, ó ń wá ẹ̀mí rẹ, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ mi ni ìwọ ó wà ní àìléwu.”
E noho pu oe me au, mai makau: no ka mea, o ka mea nana e imi mai i kuu ola, oia ke imi mai i kou ola: aka, me a'u e maluhia oe.