< 1 Samuel 22 >

1 Dafidi sì kúrò níbẹ̀, ó sì sá sí ihò Adullamu; nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìdílé baba rẹ̀ sì gbọ́, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá níbẹ̀.
A tak odšel odtud David, skryl se v jeskyni Adulam. To když uslyšeli bratří jeho i všecken dům otce jeho, sešli se tam k němu.
2 Olúkúlùkù ẹni tí ó tí wà nínú ìpọ́njú, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ti jẹ gbèsè, àti olúkúlùkù ẹni tí ó wà nínú ìbànújẹ́, sì kó ara wọn jọ sọ́dọ̀ rẹ̀, òun sì jẹ́ olórí wọn; àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì tó ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin.
A shromáždili se k němu, kteřížkoli byli v ssoužení, a kteřížkoli byli zadlužilí, a kteřížkoli byli v hořkosti ducha, a byl nad nimi knížetem, tak že jich bylo s ním okolo čtyř set mužů.
3 Dafidi sì ti ibẹ̀ náà lọ sí Mispa tí Moabu: ó sì wí fún ọba Moabu pé, “Jẹ́ kí baba àti ìyá mi, èmi bẹ̀ ọ́ wá bá ọ gbé, títí èmi yóò fi mọ ohun ti Ọlọ́run yóò ṣe fún mi.”
Potom odšel odtud David do Masfa Moábského a řekl králi Moábskému: Prosím, nechť vcházejí k vám i vycházejí otec můj a matka má, dokudž nezvím, co se mnou učiní Bůh.
4 Ó sì mú wọn wá síwájú ọba Moabu; wọ́n sì bá á gbé ní gbogbo ọjọ́ tí Dafidi fi wà nínú ihò náà.
I přivedl je před krále Moábského, a bydlili s ním po všecky dny, v nichž zůstával David na tom hradě.
5 Gadi wòlíì sí wí fún Dafidi pé, “Ma ṣe gbé inú ihò náà, yẹra, kí o sí lọ sí ilẹ̀ Juda.” Nígbà náà ni Dafidi sì yẹra, ó sì lọ sínú igbó Hereti.
Ale prorok Gád řekl Davidovi: Nebývejž déle na tom hradě, jdi, navrať se do země Judské. I odšel David, a přišel do lesa Haret.
6 Saulu si gbọ́ pé a rí Dafidi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀; Saulu sì ń bẹ ní Gibeah lábẹ́ igi tamariski ní Rama; ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dúró tì í.
V tom uslyšel Saul, že by se zjevil David i muži, kteříž byli s ním. Saul pak bydlil v Gabaa pod hájem v Ráma, maje kopí své v rukou svých, a všickni služebníci jeho stáli před ním.
7 Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó dúró tì í, pé, “Ǹjẹ́ ẹ gbọ́ ẹ̀yin ará Benjamini, ọmọ Jese yóò ha fún olúkúlùkù yín ni oko ọgbà àjàrà bí? Kí ó sì sọ gbogbo yin dì olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún bí?
I řekl Saul služebníkům svým, kteříž stáli před ním: Slyšte medle, synové Jemini: Všechněm-li vám dá syn Izai pole a vinice? Všecky-li vás postaví za správce nad tisíci a sty,
8 Tí gbogbo yín di ìmọ̀lù sí mi, tí kò sì sí ẹnìkan tí ó sọ létí mi pé, ọmọ mi ti bá ọmọ Jese mulẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kó sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó ṣàánú mi, tí ó sì sọ ọ́ létí mi pé, ọmọ mi mú kí ìránṣẹ́ mi dìde sí mi láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
Že jste se všickni spikli proti mně, aniž jest, kdo by mi oznámil? Již i syn můj učinil smlouvu s synem Izai, a však žádný z vás nelituje mne, aniž mi kdo oznámí, že pozdvihl syn můj služebníka mého proti mně, aby mi zálohy strojil, jakož se to již děje.
9 Doegi ará Edomu tí a fi jẹ olórí àwọn ìránṣẹ́ Saulu, sì dáhùn wí pé, “Èmi rí ọmọ Jese, ó wá sí Nobu, sọ́dọ̀ Ahimeleki ọmọ Ahitubu.
Odpověděl pak Doeg Idumejský, kterýž též stál s služebníky Saulovými, a řekl: Viděl jsem syna Izai, an přišel do Nobe k Achimelechovi synu Achitobovu.
10 Òun sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa fún un, ó sì fún un ní oúnjẹ, ó sí fún un ni idà Goliati ará Filistini.”
Kterýž radil se o něho s Hospodinem a dal jemu potravy, také i meč Goliáše Filistinského dal jemu.
11 Ọba sì ránṣẹ́ pe Ahimeleki àlùfáà, ọmọ Ahitubu àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀, àwọn àlùfáà tí ó wà ni Nobu: gbogbo wọn ni ó sì wá sọ́dọ̀ ọba.
I poslal král, aby zavolali Achimelecha syna Achitobova, kněze, i vší čeledi otce jeho, totiž kněží, kteříž byli v Nobe. I přišli všickni před krále.
12 Saulu sì wí pé, “Ǹjẹ́ gbọ́, ìwọ ọmọ Ahitubu.” Òun sì wí pé, “Èmi nìyìí olúwa mi.”
Tedy řekl Saul: Slyš nyní, synu Achitobův. Kterýž odpověděl: Ej, pane můj.
13 Saulu sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi ṣọ̀tẹ̀ sí mi, ìwọ àti ọmọ Jese, tí ìwọ fi fún un ní àkàrà, àti idà, àti ti ìwọ fi béèrè fún un lọ́dọ̀ Ọlọ́run kí òun lè dìde sí mi, láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
I dí k němu Saul: Proč jste se spikli proti mně, ty a syn Izai, když jsi jemu dal chléb a meč, a radils se s Bohem o něj, aby povstal proti mně k strojení mi záloh, jakož se to již děje?
14 Ahimeleki sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Ta ni ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ bí Dafidi, ẹni tí ó jẹ́ àna ọba, ẹni tí ó ń gbọ́ tìrẹ, tí ó sì ni ọlá ní ilé rẹ.
Odpovídaje Achimelech králi, řekl: A kdo jest tak věrný ze všech služebníků tvých jako David, kterýž i zetěm královým jest, kterýž kráčí v poslušenství tvém, a vzácný jest v domě tvém?
15 Òní lèmi ó ṣẹ̀ṣẹ̀ máa béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run fún un bí? Kí èyí jìnnà sí mi: kí ọba má ṣe ka nǹkan kan sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́rùn, tàbí sí gbogbo ìdílé baba mi: nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ̀ kò mọ̀kan nínú gbogbo nǹkan yìí, díẹ̀ tàbí púpọ̀.”
Zdaliž jsem se nyní počal tázati Boha o něj? Odstup to ode mne. Nesčítejž král takové věci na služebníka svého, ani na koho z čeledi otce mého, neboť neví služebník tvůj o ničemž o tom ani nejmenší věci.
16 Ọba sì wí pé, “Ahimeleki, kíkú ni ìwọ yóò kú, ìwọ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀.”
Ale král řekl: Smrtí umřeš Achimelechu, ty i všecken dům otce tvého.
17 Ọba sì wí fún àwọn aṣáájú ti máa ń sáré níwájú ọba, tí ó dúró tì í pé, “Yípadà kí ẹ sì pa àwọn àlùfáà Olúwa; nítorí pé ọwọ́ wọn wà pẹ̀lú Dafidi, àti nítorí pé wọ́n mọ ìgbà tí òun sá, wọn kò sì sọ ọ́ létí mi.” Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ ọba kò sì jẹ́ fi ọwọ́ wọn lé àwọn àlùfáà Olúwa láti pa wọ́n.
I řekl král drabantům, kteříž stáli před ním: Obraťte se a zbíte kněží Hospodinovy, nebo i jejich ruka jest s Davidem; přes to vědouce, že utíká, nedali mi znáti. Služebníci však královští nechtěli vztáhnouti rukou svých, ani se obořiti na kněží Hospodinovy.
18 Ọba sì wí fún Doegi pé, “Ìwọ yípadà, kí o sì pa àwọn àlùfáà!” Doegi ará Edomu sì yípadà, ó sì kọlu àwọn àlùfáà, ó sì pa wọ́n ní ọjọ́ náà, àrùnlélọ́gọ́rin ènìyàn ti ń wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ efodu.
A protož řekl král Doegovi: Obrať ty se, a pobí ty kněží. Takž Doeg Idumejský obrátiv se, obořil se na kněží, a zbil toho dne osmdesáte a pět mužů, kteříž nosili efod lněný.
19 Ó sì fi ojú idà pa ara Nobu, ìlú àwọn àlùfáà náà àti ọkùnrin àti obìnrin, ọmọ wẹ́wẹ́, àti àwọn tí ó wà lẹ́nu ọmú, àti màlúù, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti àgùntàn.
Nobe také město kněžské vyhubil ostrostí meče, od muže až do ženy, od malého až do požívajícího prsí, voly i osly, i dobytky pobil ostrostí meče.
20 Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Ahimeleki ọmọ Ahitubu tí a ń pè ní Abiatari sì bọ́; ó sì sá àsálà tọ Dafidi lọ.
Jediný toliko syn Achimelechův, syna Achitobova, jehož jméno bylo Abiatar, ušel a utekl k Davidovi.
21 Abiatari sì fihan Dafidi pé Saulu pa àwọn àlùfáà Olúwa tán.
Tedy oznámil Abiatar Davidovi, že Saul zmordoval kněží Hospodinovy.
22 Dafidi sì wí fún Abiatari pé, “Èmi ti mọ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Doegi ará Edomu ti wà níbẹ̀ pé, nítòótọ́ yóò sọ fún Saulu: nítorí mi ni a ṣe pa gbogbo ìdílé baba rẹ.
I řekl David Abiatarovi: Vědělť jsem toho dne, když tam byl Doeg Idumejský, že jistotně oznámí Saulovi; jáť jsem přičinu dal k zhubení všech duší domu otce tvého.
23 Ìwọ jókòó níhìn-ín lọ́dọ̀ mi, má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé ẹni ti ń wá ẹ̀mí mi, ó ń wá ẹ̀mí rẹ, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ mi ni ìwọ ó wà ní àìléwu.”
Zůstaň u mne, neboj se; nebo kdož hledati bude bezživotí mého, hledati bude bezživotí tvého, ale ochráněn budeš u mne.

< 1 Samuel 22 >