< 1 Samuel 21 >

1 Dafidi sì wá sí Nobu sọ́dọ̀ Ahimeleki àlùfáà, Ahimeleki sì bẹ̀rù láti pàdé Dafidi, ó sì wí fún un pé, “Èéha ti rí tí o fi ṣe ìwọ nìkan, àti tí kò sì sí ọkùnrin kan tí ó pẹ̀lú rẹ?”
David se rendit à Nob auprès du sacrificateur Achimélec. Achimélec vint à la rencontre de David en tremblant, et lui dit: « Pourquoi es-tu seul, et n'y a-t-il personne avec toi? ».
2 Dafidi sì wí fún Ahimeleki àlùfáà pé, “Ọba pàṣẹ iṣẹ́ kan fún mi, ó sì wí fún mi pé, ‘Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan mọ ìdí iṣẹ́ náà ti mo rán ọ, àti èyí tí èmi ti pàṣẹ fún ọ.’ Èmi sì yan àwọn ìránṣẹ́ mi sí ibí báyìí.
David répondit au prêtre Achimélec: « Le roi m'a ordonné de faire quelque chose et m'a dit: « Que personne ne sache rien de l'affaire pour laquelle je t'envoie et de ce que je t'ai ordonné. J'ai envoyé les jeunes gens dans un certain lieu.
3 Ǹjẹ́ kín ni ó wà ní ọwọ́ rẹ̀? Fún mi ni ìṣù àkàrà márùn-ún tàbí ohunkóhun tí o bá rí.”
Maintenant, qu'est-ce qui est sous ta main? Donnez-moi, je vous prie, cinq pains en main, ou tout ce qui est disponible. »
4 Àlùfáà náà sí dá Dafidi lóhùn ó sì wí pé, “Kò sí àkàrà mìíràn lọ́wọ́ mi bí kò ṣe àkàrà mímọ́. Kìkì pé bi àwọn ọmọkùnrin bá ti pa ara wọn mọ́ kúrò lọ́dọ̀ obìnrin!”
Le prêtre répondit à David: « Je n'ai pas de pain ordinaire, mais il y a du pain saint, si seulement les jeunes gens se sont tenus à l'écart des femmes. »
5 Dafidi sì dá àlùfáà náà lóhùn, ó sì wí fún un pé, “Nítòótọ́ ni a tí ń pa ara wá mọ́ kúrò lọ́dọ̀ obìnrin láti ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́ta wá, tí èmí ti jáde. Gbogbo nǹkan àwọn ọmọkùnrin náà ni ó mọ́, àti àkàrà náà sì wá dàbí àkàrà mìíràn, pàápàá nígbà tí ó jẹ́ pé òmíràn wà tí a yà sí mímọ́ lónìí nínú ohun èlò náà!”
David prit la parole devant le prêtre et lui dit: « En vérité, les femmes ont été éloignées de nous comme d'habitude ces trois jours. Quand je suis sorti, les vases des jeunes gens étaient saints, bien que ce ne fût qu'un voyage ordinaire. Combien plus aujourd'hui leurs vases seront-ils saints? »
6 Bẹ́ẹ̀ ni àlùfáà náà sì fi àkàrà mímọ́ fún un; nítorí tí kò sí àkàrà mìíràn níbẹ̀ bí kò ṣe àkàrà ìfihàn tí a ti kó kúrò níwájú Olúwa, láti fi àkàrà gbígbóná síbẹ̀ ní ọjọ́ tí a kó o kúrò.
Et le prêtre lui donna des pains saints; car il n'y avait là que le pain de démonstration qui avait été enlevé devant l'Éternel, pour être remplacé par du pain chaud le jour où il avait été enlevé.
7 Ọkùnrin kan nínú àwọn ìránṣẹ́ Saulu sì ń bẹ níbẹ̀ lọ́jọ́ náà, tí a tí dádúró síwájú Olúwa; orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Doegi, ará Edomu olórí nínú àwọn darandaran Saulu.
Or un homme parmi les serviteurs de Saül était là ce jour-là, détenu devant l'Éternel; il s'appelait Doëg, l'Édomite, le meilleur des bergers qui appartenaient à Saül.
8 Dafidi sì tún wí fún Ahimeleki pé, “Kò sí ọ̀kọ̀ tàbí idà lọ́wọ́ rẹ níhìn-ín? Nítorí tí èmi kò mú idà mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mú nǹkan ìjà mi lọ́wọ́, nítorí pé iṣẹ́ ọba náà jẹ́ iṣẹ́ ìkánjú.”
David dit à Achimélec: « N'y a-t-il pas ici sous ta main une lance ou une épée? Car je n'ai pas apporté avec moi mon épée ou mes armes, parce que les affaires du roi exigeaient la hâte. »
9 Àlùfáà náà sì wí pé, “Idà Goliati ará Filistini tí ó pa ní àfonífojì Ela ní ń bẹ, wò ó, a fi aṣọ kan wé e lẹ́yìn efodu; bí ìwọ yóò bá mú èyí, mú un; kò sì sí òmíràn níhìn-ín mọ́ bí kò ṣe ọ̀kan náà.” Dafidi sì wí pé, “Kò sí èyí tí ó dàbí rẹ̀ fún mi.”
Le prêtre dit: « Voici l'épée de Goliath le Philistin, que tu as tué dans la vallée d'Elah, et qui est ici enveloppée dans un tissu derrière l'éphod. Si tu veux la prendre, prends-la, car il n'y en a pas d'autre ici que celle-là. » David a dit: « Il n'y en a pas de semblable. Donne-le moi. »
10 Dafidi sì dìde, o sì sá ni ọjọ́ náà níwájú Saulu, ó sì lọ sọ́dọ̀ Akiṣi, ọba Gati.
David se leva et s'enfuit ce jour-là par crainte de Saül, et il alla chez Akish, roi de Gath.
11 Àwọn ìránṣẹ́ Akiṣi sì wí fún un pé, “Èyí ha kọ́ ní Dafidi ọba ilẹ̀ náà? Ǹjẹ́ wọn kò ha ti dárin ti wọ́n sì gbe orin nítorí rẹ̀, tí wọ́n sì jó pé, “‘Saulu pa ẹgbẹ̀rún tirẹ̀. Dafidi sì pa ẹgbàárùn-ún tirẹ̀’?”
Les serviteurs d'Akish lui dirent: « Ce David n'est-il pas le roi du pays? Ne chantaient-ils pas l'un l'autre à son sujet dans les danses, en disant, « Saül a tué ses milliers d'hommes, et David ses dix mille? »
12 Dafidi sì pa ọ̀rọ̀ wọ̀nyí í mọ́ ni ọkàn rẹ̀, ó sì bẹ̀rù Akiṣi ọba Gati gidigidi.
David garda ces paroles dans son cœur, et il eut très peur d'Akish, roi de Gath.
13 Òun sì pa ìṣe rẹ̀ dà níwájú wọn, ó sì sọ ara rẹ̀ di aṣiwèrè ní ọwọ́ wọn, ó sì ń fi ọwọ́ rẹ̀ ha ìlẹ̀kùn ojú ọ̀nà, ó sì ń wá itọ́ sí irùngbọ̀n rẹ̀.
Il changea de comportement devant eux et fit semblant d'être fou entre leurs mains, il gribouilla sur les battants de la porte et laissa tomber ses crachats sur sa barbe.
14 Nígbà náà ni Akiṣi wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wó o, nítorí kín ni ẹ̀yin ṣe mú un tọ̀ mí wá.
Alors Akish dit à ses serviteurs: « Regardez, vous voyez que cet homme est fou. Pourquoi donc me l'amenez-vous?
15 Mo ha ni un fi aṣiwèrè ṣe? Tí ẹ̀yin fi mú èyí tọ̀ mí wá láti hu ìwà aṣiwèrè níwájú mi? Eléyìí yóò ha wọ inú ilé mi?”
Est-ce que je manque de fous, pour que vous ayez amené cet homme pour qu'il fasse le fou en ma présence? Cet homme devrait-il entrer dans ma maison? »

< 1 Samuel 21 >