< 1 Samuel 21 >

1 Dafidi sì wá sí Nobu sọ́dọ̀ Ahimeleki àlùfáà, Ahimeleki sì bẹ̀rù láti pàdé Dafidi, ó sì wí fún un pé, “Èéha ti rí tí o fi ṣe ìwọ nìkan, àti tí kò sì sí ọkùnrin kan tí ó pẹ̀lú rẹ?”
Tedy přišel David do Nobe k Achimelechovi knězi. I ulek se Achimelech, vyšel vstříc Davidovi a řekl jemu: Cože to, že jsi sám, a není žádného s tebou?
2 Dafidi sì wí fún Ahimeleki àlùfáà pé, “Ọba pàṣẹ iṣẹ́ kan fún mi, ó sì wí fún mi pé, ‘Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan mọ ìdí iṣẹ́ náà ti mo rán ọ, àti èyí tí èmi ti pàṣẹ fún ọ.’ Èmi sì yan àwọn ìránṣẹ́ mi sí ibí báyìí.
Odpověděl David Achimelechovi knězi: Král mi poručil nějakou věc, a řekl mi: Ať žádný nezvídá toho, proč tě posílám, a coť jsem poručil. Služebníkům pak uložil jsem jisté místo.
3 Ǹjẹ́ kín ni ó wà ní ọwọ́ rẹ̀? Fún mi ni ìṣù àkàrà márùn-ún tàbí ohunkóhun tí o bá rí.”
Protož nyní, co máš tu před rukama, dej v ruku mou, asi pět chlebů, aneb což na hotově máš.
4 Àlùfáà náà sí dá Dafidi lóhùn ó sì wí pé, “Kò sí àkàrà mìíràn lọ́wọ́ mi bí kò ṣe àkàrà mímọ́. Kìkì pé bi àwọn ọmọkùnrin bá ti pa ara wọn mọ́ kúrò lọ́dọ̀ obìnrin!”
Odpověděl kněz Davidovi a řekl: Nemámť chleba obecného před rukama, než toliko chléb svatý, však jestliže se toliko od žen zdrželi služebníci.
5 Dafidi sì dá àlùfáà náà lóhùn, ó sì wí fún un pé, “Nítòótọ́ ni a tí ń pa ara wá mọ́ kúrò lọ́dọ̀ obìnrin láti ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́ta wá, tí èmí ti jáde. Gbogbo nǹkan àwọn ọmọkùnrin náà ni ó mọ́, àti àkàrà náà sì wá dàbí àkàrà mìíràn, pàápàá nígbà tí ó jẹ́ pé òmíràn wà tí a yà sí mímọ́ lónìí nínú ohun èlò náà!”
Odpověděl David knězi a řekl: Jistě ženy vzdáleny byly od nás, jakož včera tak i před včerejškem, když jsem vyšel; protož těla služebníků svatá jsou. Ač pak toto předsevzetí jest proti slušnosti, však i to dnes posvěceno bude pro tělo.
6 Bẹ́ẹ̀ ni àlùfáà náà sì fi àkàrà mímọ́ fún un; nítorí tí kò sí àkàrà mìíràn níbẹ̀ bí kò ṣe àkàrà ìfihàn tí a ti kó kúrò níwájú Olúwa, láti fi àkàrà gbígbóná síbẹ̀ ní ọjọ́ tí a kó o kúrò.
A tak dal jemu kněz chleby svaté; nebo nebylo tam chleba, jediné chlebové předložení, kteříž odloženi byli od tváři Hospodinovy, aby položeni byli chlebové teplí toho dne, když ti vzati byli.
7 Ọkùnrin kan nínú àwọn ìránṣẹ́ Saulu sì ń bẹ níbẹ̀ lọ́jọ́ náà, tí a tí dádúró síwájú Olúwa; orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Doegi, ará Edomu olórí nínú àwọn darandaran Saulu.
(Byl pak tu jeden z služebníků Saulových v týž den, kterýž se tam pozadržel před Hospodinem, jehož jméno bylo Doeg Idumejský, nejpřednější mezi pastýři Saulovými.)
8 Dafidi sì tún wí fún Ahimeleki pé, “Kò sí ọ̀kọ̀ tàbí idà lọ́wọ́ rẹ níhìn-ín? Nítorí tí èmi kò mú idà mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mú nǹkan ìjà mi lọ́wọ́, nítorí pé iṣẹ́ ọba náà jẹ́ iṣẹ́ ìkánjú.”
I řekl David Achimelechovi: Nemáš-liž zde kopí aneb meče? Nebo ani meče svého ani braně své nevzal jsem v ruku svou, proto že rozkaz královský dotíral.
9 Àlùfáà náà sì wí pé, “Idà Goliati ará Filistini tí ó pa ní àfonífojì Ela ní ń bẹ, wò ó, a fi aṣọ kan wé e lẹ́yìn efodu; bí ìwọ yóò bá mú èyí, mú un; kò sì sí òmíràn níhìn-ín mọ́ bí kò ṣe ọ̀kan náà.” Dafidi sì wí pé, “Kò sí èyí tí ó dàbí rẹ̀ fún mi.”
Jemuž řekl kněz: Meč Goliáše Filistinského, kteréhož jsi zabil v údolí Elah, aj, ten jest zde obvinutý v roucho za efodem. Jestliže jej chceš sobě vzíti, vezmi, nebo zde jiného není kromě toho. I řekl David: Neníť přes ten, dejž mi jej.
10 Dafidi sì dìde, o sì sá ni ọjọ́ náà níwájú Saulu, ó sì lọ sọ́dọ̀ Akiṣi, ọba Gati.
Tedy vstal David, a utekl toho dne před Saulem, a přišel k Achisovi králi Gát.
11 Àwọn ìránṣẹ́ Akiṣi sì wí fún un pé, “Èyí ha kọ́ ní Dafidi ọba ilẹ̀ náà? Ǹjẹ́ wọn kò ha ti dárin ti wọ́n sì gbe orin nítorí rẹ̀, tí wọ́n sì jó pé, “‘Saulu pa ẹgbẹ̀rún tirẹ̀. Dafidi sì pa ẹgbàárùn-ún tirẹ̀’?”
Služebníci pak Achisovi řekli jemu: Zdaliž tento není David, král země? Zdaliž neprozpěvovali tomuto po houfích, řkouce: Porazil Saul svůj tisíc, David pak svých deset tisíců.
12 Dafidi sì pa ọ̀rọ̀ wọ̀nyí í mọ́ ni ọkàn rẹ̀, ó sì bẹ̀rù Akiṣi ọba Gati gidigidi.
I složil David ta slova v srdci svém, a bál se velmi Achisa krále Gát.
13 Òun sì pa ìṣe rẹ̀ dà níwájú wọn, ó sì sọ ara rẹ̀ di aṣiwèrè ní ọwọ́ wọn, ó sì ń fi ọwọ́ rẹ̀ ha ìlẹ̀kùn ojú ọ̀nà, ó sì ń wá itọ́ sí irùngbọ̀n rẹ̀.
Protož změnil způsob svůj před očima jejich, a bláznem se dělal, jsa v rukou jejich; psal také po vratech u brány, a pouštěl sliny po bradě své.
14 Nígbà náà ni Akiṣi wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wó o, nítorí kín ni ẹ̀yin ṣe mú un tọ̀ mí wá.
Tedy řekl Achis služebníkům svým: Hle, viděvše člověka blázna, pročež jste ho ke mně přivedli?
15 Mo ha ni un fi aṣiwèrè ṣe? Tí ẹ̀yin fi mú èyí tọ̀ mí wá láti hu ìwà aṣiwèrè níwájú mi? Eléyìí yóò ha wọ inú ilé mi?”
Nedostává-liž se mi bláznů, že jste uvedli tohoto, aby bláznil přede mnou? Ten-liž má vjíti do mého domu?

< 1 Samuel 21 >