< 1 Samuel 21 >

1 Dafidi sì wá sí Nobu sọ́dọ̀ Ahimeleki àlùfáà, Ahimeleki sì bẹ̀rù láti pàdé Dafidi, ó sì wí fún un pé, “Èéha ti rí tí o fi ṣe ìwọ nìkan, àti tí kò sì sí ọkùnrin kan tí ó pẹ̀lú rẹ?”
David te hlah uh tih a caeh vanneh Jonathan khaw amah kho la bal. David tah Nob kah khosoih Ahimelek taengla pawk. Tedae David doe ham te Ahimelek te lakueng tih, “Nang he balae tih hlang neh na puei uh kolla namah bueng na pawk,” a ti nah.
2 Dafidi sì wí fún Ahimeleki àlùfáà pé, “Ọba pàṣẹ iṣẹ́ kan fún mi, ó sì wí fún mi pé, ‘Má ṣe jẹ́ kí ẹnìkan mọ ìdí iṣẹ́ náà ti mo rán ọ, àti èyí tí èmi ti pàṣẹ fún ọ.’ Èmi sì yan àwọn ìránṣẹ́ mi sí ibí báyìí.
David loh khosoih Ahimelek te, “Manghai loh ol ng'uen tih, ‘Kai loh nang kan tueih te khaw, nang kang uen te khaw, olka he hlang pakhat long khaw ming boel saeh, tongmang hmuen pakhat kah camoe rhoek te ka ming sak coeng,’ a ti.
3 Ǹjẹ́ kín ni ó wà ní ọwọ́ rẹ̀? Fún mi ni ìṣù àkàrà márùn-ún tàbí ohunkóhun tí o bá rí.”
Na kut dongah vaidam panga tah om aya? Na hmuh duen khaw ka kut dongah m'pae laeh,” a ti nah.
4 Àlùfáà náà sí dá Dafidi lóhùn ó sì wí pé, “Kò sí àkàrà mìíràn lọ́wọ́ mi bí kò ṣe àkàrà mímọ́. Kìkì pé bi àwọn ọmọkùnrin bá ti pa ara wọn mọ́ kúrò lọ́dọ̀ obìnrin!”
Khosoih loh David te a doo tih, “Ka kut dongah rhaengpuei buh tah om pawt dae, camoe rhoek ni huta taeng lamloh a cue uh atah buh cim om,” a ti nah.
5 Dafidi sì dá àlùfáà náà lóhùn, ó sì wí fún un pé, “Nítòótọ́ ni a tí ń pa ara wá mọ́ kúrò lọ́dọ̀ obìnrin láti ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́ta wá, tí èmí ti jáde. Gbogbo nǹkan àwọn ọmọkùnrin náà ni ó mọ́, àti àkàrà náà sì wá dàbí àkàrà mìíràn, pàápàá nígbà tí ó jẹ́ pé òmíràn wà tí a yà sí mímọ́ lónìí nínú ohun èlò náà!”
Te vaengah David loh khosoih te a doo tih amah taengah, “Huta khaw hlaem hlavai kah ka caeh bangla kaimih lamloh cue uh. Te dongah camoe rhoek kah hnopai tah cimcaihnah neh om. Amah te rhongingnah longpuei ah cet sitoe cakhaw hnopai dongah tahae khohnin duela cim uh ngai bal pueng,” a ti nah.
6 Bẹ́ẹ̀ ni àlùfáà náà sì fi àkàrà mímọ́ fún un; nítorí tí kò sí àkàrà mìíràn níbẹ̀ bí kò ṣe àkàrà ìfihàn tí a ti kó kúrò níwájú Olúwa, láti fi àkàrà gbígbóná síbẹ̀ ní ọjọ́ tí a kó o kúrò.
Te vaengah buh a om pawt dongah BOEIPA mikhmuh lamkah a rhoe a hmai buh cim te khosoih loh David a paek. Te khohnin ah buh bae neh a tho ham koi te vik a loh coeng.
7 Ọkùnrin kan nínú àwọn ìránṣẹ́ Saulu sì ń bẹ níbẹ̀ lọ́jọ́ náà, tí a tí dádúró síwájú Olúwa; orúkọ rẹ̀ sì ń jẹ́ Doegi, ará Edomu olórí nínú àwọn darandaran Saulu.
Tekah khohnin ah Saul sal rhoek khui lamkah hlang pakhat, Saul kah tudawn boei, a ming ah Edom hoel Doeg khaw BOEIPA mikhmuh ah cue uh.
8 Dafidi sì tún wí fún Ahimeleki pé, “Kò sí ọ̀kọ̀ tàbí idà lọ́wọ́ rẹ níhìn-ín? Nítorí tí èmi kò mú idà mi, bẹ́ẹ̀ ni èmi kò mú nǹkan ìjà mi lọ́wọ́, nítorí pé iṣẹ́ ọba náà jẹ́ iṣẹ́ ìkánjú.”
Te phoeiah Ahimelek te David loh, “Na kut ah caai neh cunghang mai khaw a om moenih a he, manghai ol he tokrhat la a om dongah ka kut dongah ka cunghang khaw, kamah kah hnopai khaw ka loh moenih,” a ti nah.
9 Àlùfáà náà sì wí pé, “Idà Goliati ará Filistini tí ó pa ní àfonífojì Ela ní ń bẹ, wò ó, a fi aṣọ kan wé e lẹ́yìn efodu; bí ìwọ yóò bá mú èyí, mú un; kò sì sí òmíràn níhìn-ín mọ́ bí kò ṣe ọ̀kan náà.” Dafidi sì wí pé, “Kò sí èyí tí ó dàbí rẹ̀ fún mi.”
Khosoih loh, “Elah ah na ngawn Philisti Goliath kah cunghang tah hnisui hlip ah himbai neh ka cun, te te na loh atah namah ham lo, he phoeiah tah he ah he a tloe om pawh,” a ti nah. Te dongah David loh, “Te bang te a om moenih, te te kamah taengla m'pae,” a ti nah.
10 Dafidi sì dìde, o sì sá ni ọjọ́ náà níwájú Saulu, ó sì lọ sọ́dọ̀ Akiṣi, ọba Gati.
Tekah khohnin ah David te hlah uh tih Saul mikhmuh lamloh aka yong te Gath manghai Akhish taengla pawk.
11 Àwọn ìránṣẹ́ Akiṣi sì wí fún un pé, “Èyí ha kọ́ ní Dafidi ọba ilẹ̀ náà? Ǹjẹ́ wọn kò ha ti dárin ti wọ́n sì gbe orin nítorí rẹ̀, tí wọ́n sì jó pé, “‘Saulu pa ẹgbẹ̀rún tirẹ̀. Dafidi sì pa ẹgbàárùn-ún tirẹ̀’?”
Tedae anih te Akhish kah sal rhoek loh, “Khohmuen manghai David pawt nim he? lamnah neh a doo uh tih, ‘Saul loh a thawng, a thawng hil, David loh a thawngrha, a thawngrha hil a ngawn,’ a ti uh te anih ham pawt nim?” a ti uh.
12 Dafidi sì pa ọ̀rọ̀ wọ̀nyí í mọ́ ni ọkàn rẹ̀, ó sì bẹ̀rù Akiṣi ọba Gati gidigidi.
Tekah olka te David loh a thinko ah a khueh tih Gath manghai Akhish mikhmuh ah mat a rhih.
13 Òun sì pa ìṣe rẹ̀ dà níwájú wọn, ó sì sọ ara rẹ̀ di aṣiwèrè ní ọwọ́ wọn, ó sì ń fi ọwọ́ rẹ̀ ha ìlẹ̀kùn ojú ọ̀nà, ó sì ń wá itọ́ sí irùngbọ̀n rẹ̀.
Te dongah amih mikhmuh ah a om a ih te a thovael tih amih kut dongah yan uh. Vongka thohkhaih dongah a khoeih a khoeih tih a tamkai te a hmuimul dongla a tlak sak.
14 Nígbà náà ni Akiṣi wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Wó o, nítorí kín ni ẹ̀yin ṣe mú un tọ̀ mí wá.
Te dongah Akhish loh a sal rhoek taengah, “So uh lah, kekah hlang ke pavai ni ke, ba ham nim anih te kai taengla nan khuen uh?
15 Mo ha ni un fi aṣiwèrè ṣe? Tí ẹ̀yin fi mú èyí tọ̀ mí wá láti hu ìwà aṣiwèrè níwájú mi? Eléyìí yóò ha wọ inú ilé mi?”
Pavai ka nai tih nim pavai he kai taengla nang khuen uh? Kai im khuila kun saeh a he?” a ti nah.

< 1 Samuel 21 >