< 1 Samuel 20 >

1 Nígbà náà ni Dafidi sá kúrò ní Naioti ti Rama ó sì lọ sọ́dọ̀ Jonatani ó sì béèrè pé, “Kí ni mo ṣe? Kí ni ẹ̀ṣẹ̀ mi? Báwo ni mo ṣe ṣẹ baba rẹ, tí ó sì ń wá ọ̀nà láti gba ẹ̀mí mi?”
Nitriban-day boake Naiote e Ramà añe t’i Davide vaho nivo­trak’ am’ Ionatane, le nanoa’e ty hoe: Ino ze o nanoeko zao? Ino o hakeokoo? naho ino ty tahiko añatrefan-drae’o, ie mipay ty fiaiko?
2 Jonatani dáhùn pé, “Kí a má rí i! Ìwọ kò ní kú! Wò ó baba mi kì í ṣe ohunkóhun tí ó tóbi tàbí tí ó kéré, láìfi lọ̀ mí. Èéṣe tí yóò fi fi èyí pamọ́ fún mi? Kò rí bẹ́ẹ̀.”
Le hoe re tama’e: Sondo’e; tsy hihomake irehe; oniño te tsy manao ndra kede ndra bey ty raeko naho tsy aboa’e amako heike; aa vaho ino ty hampikafiran-draeko amako o raha zao? Tsy to izay.
3 Ṣùgbọ́n Dafidi tún búra, ó sì wí pé, “Baba rẹ mọ̀ dáradára pé mo rí ojúrere ní ojú rẹ, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, ‘Jonatani kò gbọdọ̀ mọ èyí yóò sì bà á nínú jẹ́.’ Síbẹ̀ nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè àti gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti wà láààyè, ìgbésẹ̀ kan ni ó wà láàrín ìyè àti ikú.”
Mbore nititike t’i Davide nanao ty hoe: Toe fohin-drae’o t’ie nahaoni-pañisohañe am-pihaino’o, le hoe ty atao’e, Ko ampahafohineñe Ionatane zao hera hihontoke; fe kanao veloñe t’Iehovà naho veloñe ty fiai’o le toe lika raike ty añivoko naho ty fikenkañañe.
4 Jonatani wí fún Dafidi pé, “Ohunkóhun tí ìwọ bá ń fẹ́ kí èmi kí ó ṣe, èmi yóò ṣe é fún ọ.”
Le hoe t’Ionatane amy Davide; Ino ty salalan-tro’o hanoeko ama’o?
5 Dafidi sì wí fún Jonatani pé, “Wò ó, ọ̀la ni oṣù tuntun, mo sì gbọdọ̀ bá ọba jẹun, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó lọ láti fi ara pamọ́ lórí pápá títí di àṣálẹ́ ọjọ́ kẹta.
Le hoe t’i Davide am’ Ionatane: Inao te pea-bolañe ty hamaray, le tsy ho napoko ty hitoboke hitrao-pikama amy mpanjakay; aa le angao homb’eo iraho hietak’ an-kivok’ ao ampara’ te haleñe amy andro faha teloy.
6 Bí ó bá sì ṣe pé baba rẹ bá fẹ́ mi kù, kí o sì wí fún un pé, ‘Dafidi fi tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ béèrè ààyè láti sáré lọ sí Bẹtilẹhẹmu ìlú rẹ̀ nítorí wọ́n ń ṣe ẹbọ ọdọọdún ní ibẹ̀ fún gbogbo ìdílé rẹ̀.’
Aa naho mipay ahy ndra kede ty rae’o, le anò ty hoe: Nimane halaly amako t’i Davide ty hihitrifa’e mb’e Betlekheme rova’e; fa tondroke i soron-tsavereña’e boa-taoñey.
7 Tí o bá wí pé, ‘Àlàáfíà ni,’ nígbà náà, ìránṣẹ́ rẹ wà láìléwu. Ṣùgbọ́n tí ó bá bínú gidigidi, ìwọ yóò mọ̀ dájú pé ó pinnu láti ṣe ìpalára mi.
Aa naho manao ty hoe re: Soa izay. Le hanintsiñe ty mpitoro’o; f’ie viñetse, le fohino te ikinia’e raty.
8 Ṣùgbọ́n ní tìrẹ ìwọ, fi ojúrere wo ìránṣẹ́ rẹ; nítorí tí ìwọ ti bá a dá májẹ̀mú pẹ̀lú rẹ níwájú Olúwa. Tí mo bá jẹ̀bi, pa mí fún ara rẹ! Èéṣe tí ìwọ yóò fi fi mí lé baba rẹ lọ́wọ́?”
Aa le isoho o mpitoro’oo; amy fañina’ Iehovà nanoe’ i mpitoro’oy ama’oy; f’ie aman-kakeo le vonò; fa ino ty hanesea’o ahy mb’aman-drae’o mb’eo?
9 Jonatani wí pé, “Kí a má rí i! Ti mo bá ti gbọ́ tí baba mi ti pinnu láti pa ọ́ lára, ṣé èmi kò ní sọ fún ọ?”
Le hoe t’Ionatane: Atòtse ama’o izay fa naho vata’e napotako te nikililien-draeko raty, tsy ho nampandrendreheko hao?
10 Nígbà náà ni Dafidi sì wí fún Jonatani pé, “Ta ni yóò sọ fún mi tí baba rẹ̀ bá dá ọ lóhùn ní ohùn líle?”
Aa le hoe t’i Davide am’ Ionatane, Ia ty hita­lily amako te nanoiñe azo an-keloke ty rae’o?
11 Jonatani wí fún Dafidi pé, “Wá, jẹ́ kí a jáde lọ sórí pápá.” Nígbà náà wọ́n sì jáde lọ.
Le hoe t’Ionatane amy Davide: Antao homb’ an-kivoke ey. Le nimb’an-kivoke ey iereon-dro-roe.
12 Nígbà náà ni Jonatani wí fún Dafidi pé, “Mo fi Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli búra pé, èmi yóò rí i dájú pé mo gbọ́ ti ẹnu baba mi ní ìwòyí ọ̀la tàbí ní ọ̀túnla! Bí ó bá sì ní inú dídùn sí ọ, èmi yóò ránṣẹ́ sí ọ, èmi yóò sì jẹ́ kí o mọ̀?
Aa hoe t’Ionatane amy Davide: aolo’ Iehovà Andrianañahare’ Israele: Izaho hitsok’ an-draeko amo ora zao te maray, ndra herone, le inao, naho fañisohañe amy Davide ty ao, lehe tsy hahitriko ama’o, vaho hitalily azo,
13 Ṣùgbọ́n tí baba mi bá fẹ́ pa ọ́ lára, kí Olúwa kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ sí Jonatani; tí èmi kò bá jẹ́ kí o mọ̀, kí n sì jẹ́ kí o lọ ní àlàáfíà. Kí Olúwa kí ó wà pẹ̀lú rẹ gẹ́gẹ́ bí ó ti wà pẹ̀lú baba mi.
le ee te hanoe’ Iehovà am’ Ionatane naho mandikoatse; fa naho mahafale an-draeko ty mañoho-doza ama’o, le hitaliliako, hañirahako azo homb’eo, hañaveloa’o am-panin­tsiñañe; vaho hindre ama’o t’Iehovà manahake ty nindreza’e aman-draeko.
14 Ṣùgbọ́n fi àìkùnà inú rere hàn mí bí inú rere Olúwa, níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè kí wọ́n má ba à pa mí.
Aa naho mbe velon-draho tsy haboa’o amako hao ty fiferenaiña’ Iehovà, tsy hihomahako?
15 Má ṣe ké àánú rẹ kúrò lórí ìdílé mi títí láé. Bí Olúwa tilẹ̀ ké gbogbo ọ̀tá Dafidi kúrò lórí ilẹ̀.”
Le tsy hapitso’o an-trañoko nainai’e ty fañisoha’o; ndra te naitoa’ Iehovà o rafelahi’ i Davideo, fonga finao’e an-tane atoy.
16 Nígbà náà ni Jonatani bá ilé Dafidi dá májẹ̀mú wí pé, “Olúwa yóò pe àwọn àti Dafidi láti ṣírò.”
Aa le nifañina ami’ty anjomba’ i Davide t’Ionatane, t’ie ho paia’ Iehovà am-pità’ o rafelahi’ i Davideo.
17 Jonatani mú kí Dafidi tún ìbúra ṣe nítorí ìfẹ́ tí ó ní sí i, nítorí tí ó fẹ́ ẹ gẹ́gẹ́ bí ó ti fẹ́ràn ara rẹ̀.
Le nampifantà’ Ionatane indraike t’i Davide, ami’ty fikokoa’e; amy te nikokoa’e manahake ty nikokoa’e ty vata’e.
18 Nígbà náà ni Jonatani wí fún Dafidi pé, “Lọ́la ní ibi àsè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun, a yóò fẹ́ ọ kù, nítorí ààyè rẹ yóò ṣófo.
Le hoe t’Ionatane ama’e: Hiri-bolañe te maray: le ho paian-drehe; amy te ho kòake i fiambesa’oy.
19 Ní ọ̀túnla lọ́wọ́ alẹ́ lọ sí ibi tí o sá pamọ́ sí nígbà tí ìṣòro yìí bẹ̀rẹ̀, kí o sì dúró níbi òkúta Eselu.
Aa le mietaha soa irehe te herone, le miheova mb’amy fikafira’o amy androm-pitoloñañey le ey avao irehe marine ty vato’ i Ezele.
20 Èmi yóò ta ọfà mẹ́ta sí ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀, gẹ́gẹ́ bí i pé mo ta á sí àmì ibìkan.
Hahiririko ty ana-pale telo añ’ila’e eo, hoe mañohatse fanolarañe.
21 Èmi yóò rán ọmọdékùnrin kan èmi yóò wí fún un wí pé, ‘Lọ, kí o lọ wá ọfà náà.’ Tí mo bá sọ fún un wí pé, ‘Wò ó, ọfà wọ̀nyí wà ní ibi báyìí ní ẹ̀gbẹ́ ẹ̀ rẹ; kó wọn wá síbí,’ kí o sì wá, nítorí pé, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti wà ní ààyè, o wà ní àlàáfíà; kò sí ewu.
Ie amy zao, hañitrifako ajalahy: Akia paiao o ana-paleo. Aa naho ataoko ty hoe: Ingo, añ’ila’o atoy o ana-paleo, rambeso vaho mb’etoa; le fañanintsiñe ty ho ama’o fa tsy joy, kanao veloñe t’Iehovà.
22 Ṣùgbọ́n tí mo bá sọ fún ọmọdékùnrin náà pé, ‘Wò ó, àwọn ọfà náà ń bẹ níwájú rẹ,’ ǹjẹ́ máa bá tìrẹ lọ, nítorí Olúwa ni ó rán ọ lọ.
F’ie ataoko ty hoe i ajalahiy: Inge, mbe aolo’o añe o ana-paleo; le akia, fa nirahe’ Iehovà mb’eo.
23 Nípa ọ̀rọ̀ tí èmi àti ìwọ jọ sọ, rántí Olúwa jẹ́ ẹlẹ́rìí láàrín ìwọ àti èmi títí láéláé.”
Aa i nisaontsien-tikañey, Inao! añivon-tikañe nainai’e t’Iehovà.
24 Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi sá pamọ́ sínú pápá. Nígbà tí àsè ìbẹ̀rẹ̀ oṣù tuntun sì dé, ọba sì jókòó láti jẹun.
Le nietak’ an-kivok’ ao t’i Davide; aa ie nipea-bolañe, niam­besatse hikama i mpanjakay.
25 Ọba sì jókòó gẹ́gẹ́ bí ipò o rẹ̀ ní ibi tí ó máa ń jókòó lórí ìjókòó tí ó wà lẹ́gbẹ̀ẹ́ ògiri, ní òdìkejì Jonatani, Abneri sì jókòó ti Saulu, ṣùgbọ́n ààyè Dafidi sì ṣófo.
Niambesatse amy fiambesa’ey i mpanjakay, manahake ty lili’e, amy fiambesatse mioza amy rindriñeiy; nijohañe t’Ionatane, vaho niambesatse añ’ila’ i Saole eo ty Abnere; fe nikòake ty fiambesa’ i Davide.
26 Saulu kò sọ nǹkan kan ní ọjọ́ náà, nítorí ó rò pé, “Nǹkan kan ti ṣẹlẹ̀ sí Dafidi láti jẹ́ kí ó di aláìmọ́ lóòtítọ́ ó jẹ́ aláìmọ́.”
Tsy nisaontsy ndra inoñ’ inoñe amy andro zay t’i Saole, fa hoe ty natao’e: Va’e nifetsahan-draha; he t’ie maleotse; tsy malio.
27 Ṣùgbọ́n ní ọjọ́ kejì, ní ọjọ́ kejì oṣù, ààyè Dafidi sì tún ṣófo. Nígbà náà ni Saulu wí fún ọmọ rẹ̀ Jonatani pé, “Kí ni ó dé tí ọmọ Jese kò fi wá sí ibi oúnjẹ, lánàá àti lónìí?”
Ie amy loak’ andro manonjohy i pea-bolañeiy, i andro faharoey, naho nikoake ty fiambesa’ i Davide; le hoe t’i Saole am’ Ionatane ana’e: Akore te tsy nimb’ am-pikamàñe mb’etoa i ana’ Iisay, ndra omale ndra androany?
28 Jonatani sì dáhùn pé, “Dafidi bẹ̀ mí tọ̀wọ̀tọ̀wọ̀ fún ààyè láti lọ sí Bẹtilẹhẹmu.
Le hoe ty natoi’ Ionatane amy Saole: Nihalalia’ i Davide t’ie hienga mb’e Betlekheme mb’eo;
29 Ó wí pé, ‘Jẹ́ kí n lọ, nítorí pé ìdílé wa ń ṣe ìrúbọ ní ìlú, àwọn ẹ̀gbọ́n ọ̀n mi sì ti pàṣẹ fún mi láti wà níbẹ̀; tí èmi bá rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí n lọ láti lọ rí àwọn ẹ̀gbọ́n mi.’ Ìdí nìyìí tí kò fi wá sí orí tábìlì oúnjẹ ọba.”
ami’ty hoe: Ehe, angao hiavotse iraho, fa misoroñe an-drova ao o longokoo vaho nañambara’ ty rahalahiko hiatreke; aa naho nahatendreke fañisohañe am-pihaino’o le adono hihitrike mb’eo handrendreke an-drolongoko. Aa le tsy niheo mb’ am-pandambaña’ i mpanjakay atoa re.
30 Ìbínú Saulu sì ru sí Jonatani ó sì wí fún un pé, “Ìwọ ọmọ aláìgbọ́ràn àti ọlọ̀tẹ̀ búburú yìí, ṣé èmi kò ti mọ̀ pé, ìwọ ti yan ọmọ Jese fún ìtìjú ti ara rẹ àti fún ìtìjú màmá rẹ tí ó bí ọ?
Nisolebotse am’ Ionatane ty haviñera’ i Saole, ami’ty hoe: Ty anan-drakemba-piola mengoke tia, tsy apotako hao te jinobo’o ho an-kasalara’o naho ho ami’ty fimeñaram-piboridañan-drene’o i ana’ Iisaiiy?
31 Níwọ́n ìgbà tí ọmọ Jese bá wà láààyè lórí ilẹ̀ ayé, a kì yóò fi ẹsẹ̀ ìwọ tàbí ti ìjọba rẹ múlẹ̀. Nísinsin yìí ránṣẹ́ kí o sì lọ mú un wá fún mi, nítorí ó gbọdọ̀ kú!”
Fa naho mbe veloñe ambone tane atoy i ana’ Iisaiiy, le tsy horizan-drehe, ndra ty fifehea’o. Aa le ahitrifo mb’ amako mb’etoa re, fa mañeva ho mate.
32 Jonatani béèrè lọ́wọ́ baba rẹ̀ pé, “Èéṣe tí àwa yóò fi pa á? Kí ni ó ṣe?”
Le hoe ty natoi’ Ionatane amy Saole rae’e: Aa vaho ino ty hañohofan-doza ama’e? Nanao inon-dre?
33 Ṣùgbọ́n Saulu ju ọ̀kọ̀ rẹ̀ sí Jonatani láti gún un pa. Nígbà náà ni Jonatani mọ̀ pé baba rẹ̀ mọ̀ ọ́n mọ̀ fẹ́ pa Dafidi ni.
Aa le nahiriri’ i Saole ama’e i lefo’ey; vaho napota’ Ionatane te tampa-kevetse ty rae’e hanjevoñ’ i Davide.
34 Bẹ́ẹ̀ ni Jonatani sì fi ìbínú dìde kúrò ni ibi oúnjẹ, kò sì jẹun ni ọjọ́ kejì oṣù náà, inú rẹ̀ sì bàjẹ́ gidigidi fún Dafidi, nítorí pé baba rẹ̀ dójútì í.
Niavotse i fandam­bañañey t’Ionatane ampiforoforoañe, naho tsy nikama amy andro faharoe’ i volañeiy; ami’t’ie nirovetse i Davide vaho nisalaren-drae’e.
35 Ó sì ṣe, ní òwúrọ̀ ni Jonatani jáde lọ sí oko ní àkókò tí òun àti Dafidi ti fi àdéhùn sí, ọmọdékùnrin kan sì wá pẹ̀lú rẹ̀.
Ie amy loak’ àndroy, le niavotse mb’ an-kivoke añe t’Ionatane reketse ty anak’ ajalahy amy namantaña’e i Davidey.
36 Ó si wí fún ọmọdékùnrin rẹ̀ pé, “Sáré, kí o si wá àwọn ọfà tí èmi ó ta.” Bí ọmọdé náà sì ti ń sáré, òun sì tafà rékọjá rẹ̀.
Le hoe re amy ajalahiy: Akia, hitrifo an-day o ana-pale hahirirìkoo. Aa ie nilay i ajalahiy le nahirirì’e ty ana-pale hilosora’e amy ajalahiy.
37 Nígbà tí ọmọdékùnrin náà sì dé ibi ọfà tí Jonatani ta, Jonatani sì kọ sí ọmọdékùnrin náà ó sì wí pé, “Ọfà náà kò ha wà níwájú rẹ bi?”
Ie nipok’an-toe’ i ana-pale nahirirì’ Ionataney i ajalahiy, le hoe ty koi’ Ionatane amy ajalahiy, Tsy ambali’o ey hao i ana-paley?
38 Jonatani sì kọ sí ọmọdékùnrin náà pé, “Sáré! Yára! Má ṣe dúró!” Ọmọdékùnrin Jonatani sì ṣa àwọn ọfà náà, ó sì tọ olúwa rẹ̀ wá.
Le hoe ty fipaza’ Ionatane amy ajalahiy: Ma­lisà irehe, masikà, ko mitoboke ey. Le natonto’ i ajalahiy o ana-paleo vaho nimb’ amy talè’ey mb’eo.
39 (Ọmọdékùnrin náà kò sì mọ̀ nǹkan; ṣùgbọ́n Jonatani àti Dafidi ni ó mọ ọ̀ràn náà.)
Fe tsy napota’ i ajalahiy; Ionatane naho i Davide avao ty nahafohiñe.
40 Jonatani sì fi apó àti ọrun rẹ̀ fún ọmọdékùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Lọ, kí o sì mú wọn lọ sí ìlú.”
Natolo’ Ionatane amy ajalahiy o fialia’eo le nanoa’e ty hoe: Akia, endeso an-drova ao retoy.
41 Bí ọmọdékùnrin náà ti lọ tán, Dafidi sì dìde láti ibi ìhà gúúsù òkúta náà, ó sì wólẹ̀, ó sì tẹríba ní ìdojúbolẹ̀ lẹ́ẹ̀mẹ́ta fún Jonatani, wọ́n sì fi ẹnu ko ara wọn lẹ́nu, wọ́n sì jùmọ̀ sọkún, èkínní pẹ̀lú èkejì rẹ̀, ṣùgbọ́n Dafidi sọkún púpọ̀ jù.
Ie añe i ajalahiy, le niongak’ an-toe’e atimo ao t’i Davide, naho nibabok’ an-daha­ra’e an-tane, niondreke intelo; naho nifañoroke iereo vaho nifampirovetse, i Davide ty nandikoatse.
42 Jonatani sì wí fún Dafidi pé, “Máa lọ ní àlàáfíà, bí o ti jẹ́ pé àwa méjèèjì tí jùmọ̀ búra ni orúkọ Olúwa pé, ‘Ki Olúwa ó wà láàrín èmi àti ìwọ, láàrín irú-ọmọ mi àti láàrín irú-ọmọ rẹ̀ láéláé.’” Òun sì dìde, ó sì lọ kúrò: Jonatani sì lọ sí ìlú.
Le hoe t’Ionatane amy Davide: Akia am-panintsiñañe, amy nititihan-tika an-tahina’ Iehovà ty hoe: Ho añivon-tika roe t’Iehovà, naho añivo’ o tirikoo naho o tiri’oo nainai’e. Aa le nienga re nañavelo mb’eo vaho nimoak’ an-drova ao t’Ionatane.

< 1 Samuel 20 >