< 1 Samuel 2 >

1 Hana sì gbàdúrà pé, “Ọkàn mi yọ̀ sí Olúwa; ìwo agbára mi ni a sì gbé sókè sí Olúwa. Ẹnu mi sì gbòòrò lórí àwọn ọ̀tá mi, nítorí ti èmi yọ̀ ni ìgbàlà rẹ̀.
Тогава Анна се помоли, като казваше: - Развесели се сърцето ми в Господа; Въздигна се рога ми чрез Господа; Разшириха се устата ми срещу неприятелите ми, Защото се развеселих в спасението Ти.
2 “Kò sí ẹni tí ó mọ́ bi Olúwa; kò sí ẹlòmíràn bí kò ṣe ìwọ; kò sì sí àpáta bi Ọlọ́run wa.
Няма свет какъвто е Господ; Защото няма друг освен Тебе, Нито канара като нашия Бог.
3 “Má ṣe halẹ̀; má ṣe jẹ́ kí ìgbéraga ti ẹnu yín jáde nítorí pé Ọlọ́run olùmọ̀ ni Olúwa, láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá ni a ti ń wọn ìwà.
Не продължавайте да говорите горделиво; Да не излезе високомерие из устата ви; Защото Господ е Бог на знания, И от него се претеглят делата.
4 “Ọ̀run àwọn alágbára ti ṣẹ́, àwọn tí ó ṣe aláìlera ni a fi agbára dì ní àmùrè.
Лъковете на силните се строшиха; И немощните се препасаха със сила.
5 Àwọn tí ó yọ̀ fún oúnjẹ ti fi ara wọn ṣe alágbàṣe, àwọn tí ebi ń pa kò sì ṣe aláìní. Tó bẹ́ẹ̀ tí àgàn fi bí méje. Ẹni tí ó bímọ púpọ̀ sì di aláìlágbára.
Ситите се пазариха за хляб; А гладните престанаха да гладуват. Ей, и не плодната роди седем, А многодетната изнемощя.
6 “Olúwa pa ó sì sọ di ààyè; ó mú sọ̀kalẹ̀ lọ sí isà òkú, ó sì gbé dìde. (Sheol h7585)
Господ умъртвява, и съживява; Сваля в ада, и възвежда. (Sheol h7585)
7 Olúwa sọ di tálákà; ó sì sọ di ọlọ́rọ̀; ó rẹ̀ sílẹ̀, ó sì gbé sókè.
Господ осиромашава човека, и обогатява; Смирява човека, и въздига.
8 Ó gbé tálákà sókè láti inú erùpẹ̀ wá, ó gbé alágbe sókè láti orí òkìtì eérú wá, láti mú wọn jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ-aládé, láti mu wọn jogún ìtẹ́ ògo, “Nítorí pé ọ̀wọ́n ayé ti Olúwa ni, ó sì ti gbé ayé ka orí wọn.
Въздига бедния от пръстта, И възвишава сиромаха от бунището, За да ги направи да седнат между князете, И да наследят славен престол; Защото стълбовете на земята са на Господа, Който и постави на тях вселената.
9 Yóò pa ẹsẹ̀ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ mọ́, àwọn ènìyàn búburú ni yóò dákẹ́ ní òkùnkùn. “Nípa agbára kò sí ọkùnrin tí yóò borí.
Ще пази нозете на светиите Си; А нечестивите ще погинат в тъмнината; Понеже със сила не ще надделее човек.
10 A ó fọ́ àwọn ọ̀tá Olúwa túútúú; láti ọ̀run wá ni yóò sán àrá sí wọn; Olúwa yóò ṣe ìdájọ́ òpin ayé. “Yóò fi agbára fún ọba rẹ̀, yóò si gbé ìwo ẹni àmì òróró rẹ̀ sókè.”
Противниците на Господа ще се сломят; Ще гръмне от небето против тях; Господ ще съди краищата на земята, И ще даде сила на царя Си, И ще въздигне рога на помазаника Си.
11 Elkana sì lọ sí Rama, sí ilé rẹ̀, ọmọ náà sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún Olúwa níwájú Eli àlùfáà.
Тогава Елкана си отида у дома си в Рама. А детето слугуваше Господу пред свещеника Илия.
12 Àwọn ọmọ Eli sì jẹ́ ọmọ Beliali; wọn kò mọ Olúwa.
А Илиевите синове бяха лоши човеци, които не познаваха Господа.
13 Iṣẹ́ àwọn àlùfáà pẹ̀lú àwọn ènìyàn ni pé nígbà tí ẹnìkan bá ṣe ìrúbọ, ìránṣẹ́ àlùfáà á dé, nígbà tí ẹran náà bá ń hó lórí iná, pẹ̀lú ọ̀pá-ẹran náà oníga mẹ́ta ní ọwọ́ rẹ̀.
Тия свещеници постъпваха към людете така: когато някой принасяше жертва, като се вареше месото, слугата на свещеника дохождаше с тризъбна вилица в ръка
14 Òun a sì fi gún inú apẹ, tàbí àgé tàbí ọpọ́n, tàbí ìkòkò, gbogbo èyí tí ọ̀pá-ẹran oníga náà bá mú wá sí òkè, àlùfáà á mú un fún ara rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń ṣe sí gbogbo Israẹli tí ó wá sí ibẹ̀ ní Ṣilo.
и забождаше я в тенджерата или в котела, или в котлето, или в гърнето; и каквото издигаше вилицата, свещеникът го вземаше за себе си. Така постъпваха в Сило с всичките израилтяни, които дохождаха там.
15 Pẹ̀lú, kí wọn tó sun ọ̀rá náà, ìránṣẹ́ àlùfáà á dé, á sì wí fún ọkùnrin tí ó ń ṣe ìrúbọ pé, “Fi ẹran fún mi láti sun fún àlùfáà; nítorí tí kì yóò gba ẹran sísè lọ́wọ́ rẹ, bí kò ṣe tútù.”
Даже и преди да изгорят тлъстината, слугата на свещеника дохождаше та казваше на човека, който принасяше жертвата: Дай на свещеника месото за печене, защото няма да приеме от тебе варено месо, но сурово.
16 Bí ọkùnrin náà bá sì wí fún un pé, “Jẹ́ kí wọn ó sun ọ̀rá náà nísinsin yìí, kí o sì mú iyekíye tí ọkàn rẹ̀ bá fẹ́,” nígbà náà ni yóò dá a lóhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, ṣùgbọ́n kí ìwọ ó fi í fún mi nísinsin yìí, bí kó ṣe bẹ́ẹ̀, èmi ó fi agbára gbà á.”
И ако човекът му речеше: Нека изгорят първо тлъстината, и сетне си вземи колкото желае душата ти, тогава казваше: Не, но сега ще дадеш, и ако не, ще взема на сила.
17 Ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin náà sì tóbi gidigidi níwájú Olúwa: nítorí tí àwọn ènìyàn kórìíra ẹbọ Olúwa.
Така грехът на тия младежи беше твърде голям пред Господа; защото човеците се отвращаваха от Господната жертва.
18 Ṣùgbọ́n Samuẹli ń ṣe ìránṣẹ́ níwájú Olúwa, ọmọdé, ti a wọ̀ ní efodu ọ̀gbọ̀.
А Самуил слугуваше пред Господа, дете препасано с ленен ефод.
19 Pẹ̀lúpẹ̀lú, ìyá rẹ̀ máa ń dá aṣọ ìlekè péńpé fún un, a sì máa mú wá fún un lọ́dọọdún, nígbà tí ó bá bá ọkọ rẹ̀ gòkè wá láti ṣe ìrúbọ ọdún.
И майка му правеше за него горна дрешка та му донасяше всяка година, когато дохождаше с мъжа си, за да принесе годишната жертва.
20 Eli súre fún Elkana àti aya rẹ̀ pé, “Kí Olúwa fún ọ ní irú-ọmọ láti ara obìnrin yìí wá, nítorí ẹ̀bùn tí ó béèrè tí ó sì tún fún Olúwa.” Wọ́n sì lọ sí ilé wọn.
И Илий благослови Елкана и жена му, като каза: Господ да ти даде рожба от тая жена вместо заема, който дадохте на Господа. И те отидоха на мястото си.
21 Olúwa si bojú wo Hana, ó sì lóyún, ó bí ọmọkùnrin mẹ́ta àti ọmọbìnrin méjì. Samuẹli ọmọ náà sì ń dàgbà níwájú Olúwa.
И Господ посети Анна; и тя зачна и роди три сина и две дъщери. А детето Самуил растеше пред Господа.
22 Eli sì di arúgbó gidigidi, ó sì gbọ́ gbogbo èyí ti àwọn ọmọ rẹ̀ ṣe sí gbogbo Israẹli; àti bi wọ́n ti máa ń bá àwọn obìnrin sùn, tí wọ́n máa ń péjọ ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ.
А като беше Илий много стар, чу всичко, що прави синовете му на целия Израил, и как лежали с жените, които слугували при входа на шатъра за срещане.
23 Ó sì wí fún wọn pé, kí ni ó ti ri “Èétirí tí èmi fi ń gbọ́ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ sí yín? Nítorí tí èmi ń gbọ́ iṣẹ́ búburú yín láti ọ̀dọ̀ gbogbo ènìyàn.
И той им рече: Защо правите такива работи? понеже слушам лоши работи за вас от всички тия люде.
24 Bẹ́ẹ̀ kọ́ ẹ̀yin ọmọ mi, nítorí kì ṣe ìròyìn rere èmi gbọ́; ẹ̀yin mú ènìyàn Olúwa dẹ́ṣẹ̀.
Недейте, чада мои; защото не е добър слухът, който чувам; вие правите Господните люде да стават престъпници.
25 Bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí ẹnìkejì, onídàájọ́ yóò ṣe ìdájọ́ rẹ̀: ṣùgbọ́n bí ẹnìkan bá ṣẹ̀ sí Olúwa, ta ni yóò bẹ̀bẹ̀ fún un?” Wọn kò sì fi etí sí ohùn baba wọn, nítorí tí Olúwa ń fẹ́ pa wọ́n.
Ако сгреши човек на човека ще стане моление Богу за него; но ако съгреши някой Господу, кой ще се моли за него? Но те не послушаха гласа на баща си, защото Господ щеше да ги погуби.
26 Ọmọ náà Samuẹli ń dàgbà, ó sì rí ojúrere lọ́dọ̀ Olúwa, àti ènìyàn pẹ̀lú.
А детето Самуил растеше и придобиваше благоволението и на Господа и на човеците.
27 Ènìyàn Ọlọ́run kan tọ Eli wá, ó sì wí fún un pé, “Báyìí ni Olúwa wí, ‘Èmi fi ara mi hàn ní gbangba fún ilé baba rẹ, nígbà tí wọ́n ń bẹ ní Ejibiti nínú ilé Farao.
Тогава дойде един Божий човек при Илия та му рече: Така казва Господ: Не съм ли Се открил явно на бащиния ти дом когато те бяха в Египет у Фараоновия дом?
28 Èmi sì yàn án kúrò láàrín gbogbo ẹ̀yà Israẹli láti jẹ́ àlùfáà mi, láti rú ẹbọ lórí pẹpẹ mi, láti fi tùràrí jóná, láti wọ efodu níwájú mi, èmi sì fi gbogbo ẹbọ tí ọmọ Israẹli máa ń fi iná sun fún ìdílé baba rẹ̀.
И не съм ли избрал него измежду всичките Израилеви племена за Мой свещеник, за да принесе жертвата на олтара Ми, да гори темян и да носи ефод пред Мене? И не съм ли дал на бащиния ти дом всичките приноси чрез огън от израилтяните?
29 Èéha ṣe tí ẹ̀yin fi tàpá sí ẹbọ àti ọrẹ mi, tí mo pàṣẹ ní ibùjókòó mi, ìwọ sì bu ọlá fún àwọn ọmọ rẹ jù mí lọ, tí ẹ sì fi gbogbo àṣàyàn ẹbọ Israẹli àwọn ènìyàn mi mú ara yín sanra.’
Защо, прочее, ритате жертвата Ми и приноса Ми, който съм заповядал да принасят в жилището Ми, и почитат синовете си повече от Мене, за да се гоите с по-доброто от всичките приноси на людете Ми Израиля?
30 “Nítorí náà Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí pé, ‘Èmi ti wí nítòótọ́ pé, ilé rẹ àti ilé baba rẹ, yóò máa rìn níwájú mi títí.’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa wí pé, ‘Kí á má rí i! Àwọn tí ó bú ọlá fún mi ni èmi yóò bu ọlá fún, àti àwọn tí kò kà mí sí ni a ó sì ṣe aláìkàsí.
Затова Господ Израилевият Бог каза: Аз наистина думах, че твоят дом и домът на баща ти ще да ходят пред Мене до века; но сега Господ каза: Далеч от Мене! защото ония, които славят Мене, тях ще прославя Аз, а ония, които Ме презират, ще бъдат презрени.
31 Kíyèsi i, àwọn ọjọ́ ń bọ̀ tí èmi ó gé agbára rẹ kúrò, àti agbára baba rẹ, tí kì yóò sí arúgbó kan nínú ilé rẹ.
Ето, идат дните, когато ще пресека мишцата на бащиния ти дом, така щото да няма старец в дома ти.
32 Ìwọ yóò rí wàhálà ti Àgọ́, nínú gbogbo ọlá tí Ọlọ́run yóò fi fún Israẹli; kì yóò sí arúgbó kan nínú ilé rẹ láéláé.
И според всичките блага, които ще се дадат на Израиля, в жилището Ми ще видиш утеснение; и не ще има старец в дома ти до века.
33 Ọkùnrin tí ó jẹ́ tìrẹ, tí èmi kì yóò gé kúrò ní ibi pẹpẹ mi ni a ó dá sí láti sọkún yọ lójú àti láti banújẹ́. Ṣùgbọ́n gbogbo irú-ọmọ ilé rẹ̀ ni a ó fi idà pa ní ààbọ̀ ọjọ́ wọn.
И оня от твоите, когото не отсека от олтара Си, ще бъде за изнуряване на очите ти и за огорчаване на душата ти; и всичките внуци на дома ти ще умират в средна възраст.
34 “‘Kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí àwọn ọmọ ọkùnrin rẹ̀ méjèèjì, Hofini àti Finehasi, yóò jẹ́ àmì fún ọ—àwọn méjèèjì yóò kú ní ọjọ́ kan náà.
И това, което ще дойде върху двамата ти сина, върху Офния и Финееса, ще ти бъде знамение: в един ден и двамата ще умрат.
35 Èmi yóò dìde fún ara mi láti gbé àlùfáà olódodo dìde fún ara mi, ẹni tí yóò ṣe gẹ́gẹ́ bí ohun tí ó wà ní ọkàn mi àti inú mi. Èmi yóò fi ẹsẹ̀ ilé rẹ̀ múlẹ̀ gbọningbọnin òun yóò sì ṣe òjíṣẹ́ níwájú ẹni òróró mi ní ọjọ́ gbogbo.
И Аз ще си въздигна верен свещеник, който ще постъпва според това, което е в сърцето Ми и в душата Ми; и ще съградя непоколебим дом; и той ще ходи пред помазаника Ми до века.
36 Nígbà náà olúkúlùkù ẹnikẹ́ni tí ó bá kù ní ìdílé yín, yóò jáde wá yóò sì foríbalẹ̀ níwájú rẹ̀ nítorí ẹyọ fàdákà àti nítorí èépá àkàrà àti ẹ̀bẹ̀ pé, “Jọ̀wọ́ yàn mí sí ọ̀kan nínú iṣẹ́ àwọn àlùfáà, kí èmi kí ó le máa rí oúnjẹ jẹ.”’”
А всеки, който остане в твоя дом, ще дохожда да му се кланя за малко пари и за един хляб, и ще казва: Назначи ме, моля, на някоя от свещеническите служби, за да ям едно късче хляб.

< 1 Samuel 2 >