< 1 Samuel 17 >
1 Filistini kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ fún ogun ní Soko ti Juda. Wọ́n pàgọ́ sí Efesi-Damimu, láàrín Soko àti Aseka,
Əmma Filistiylǝr jǝng ⱪilix üqün ⱪoxunlirini yiƣdi. Ular Yǝⱨudaƣa tǝwǝ Sokoⱨda jǝm bolup, Sokoⱨ bilǝn Azikaⱨ otturisidiki Əfǝs-Dammimda qedirlarni tikti.
2 Saulu àti àwọn ọmọ Israẹli wọ́n kò ara wọ́n jọ pọ̀, wọ́n sì pàgọ́ ní àfonífojì Ela, wọ́n sì gbé ogun wọn sókè ní ọ̀nà láti pàdé àwọn Filistini.
Saul bilǝn Israillarmu jǝm bolup Elaⱨ jilƣisida qedirlirini tikip Filistiylǝr bilǝn jǝng ⱪilƣili sǝp tüzdi.
3 Àwọn Filistini sì wà ní orí òkè kan àwọn ọmọ Israẹli sì wà ní orí òkè mìíràn, àfonífojì sì wà láàrín wọn.
Filistiylǝr bir tǝrǝptiki taƣda, Israillar yǝnǝ bir tǝrǝptiki taƣda turatti; otturisida jilƣa bar idi.
4 Ọ̀gágun tí a ń pè ní Goliati, tí ó jẹ́ ará Gati, ó wá láti ibùdó Filistini. Ó ga ní ìgbọ̀nwọ́ mẹ́fà àti ìnà ìka kan ní ìbú.
Xu waⱪitta Filistiylǝrning lǝxkǝrgaⱨidin Gatliⱪ Goliat isimlik bir qempiyon palwan qiⱪip kǝldi. Uning egizliki altǝ gǝz bir ƣeriq idi.
5 Ó ní àṣíborí idẹ ní orí rẹ̀, ó sì wọ ẹ̀wù tí a fi idẹ pẹlẹbẹ ṣe, ìwọ̀n ẹ̀wù náà sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ṣékélì idẹ.
Bexiƣa mis dubulƣa, uqisiƣa ⱪasiraⱪliⱪ sawut kiygǝnidi. Uning bu mis sawuti bolsa bǝx ming xǝkǝl kelǝtti.
6 Òun sì wọ ìhámọ́ra idẹ sí ẹsẹ̀ rẹ̀ àti àpáta idẹ kan láàrín ẹ̀yìn rẹ̀.
Paqaⱪliriƣa mistin tizliⱪ baƣliƣan, ɵxnisigǝ mis atma nǝyzǝ ⱪisturiwalƣanidi.
7 Ọ̀pá ọ̀kọ̀ rẹ̀ rí bí apásá ìhunṣọ, orí ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì wọn ẹgbẹ̀ta kilogiramu méje irin, ẹni tí ó ru asà ogun rẹ̀ lọ ṣáájú u rẹ̀.
Uning nǝyzisining sepi bolsa bapkarning hadisidǝk idi; nǝyzisining bexi altǝ ming xǝkǝl kelǝtti; ⱪalⱪan kɵtürgüqisi uning aldida mangatti.
8 Goliati dìde, ó sì kígbe sí ogun Israẹli pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi jáde wá, tí ẹ ṣe tò fún ogun? Ṣé èmi kì í ṣe Filistini ni, àbí ẹ̀yin kì í ṣe ìránṣẹ́ Saulu? Yan ọkùnrin kan kí o sì jẹ́ kí ó sọ̀kalẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
U ornida turup Israilning ⱪoxunliriƣa mundaⱪ towlaytti: — «Silǝr nemixⱪa jǝng ⱪilix üqün sǝp tüzgǝnsilǝr? Mǝn Filistiy ǝmǝsmu? Silǝr bolsanglar Saulning ⱪulliriƣu? Aranglardin bir adǝmni tallap qiⱪinglar, u mǝn bilǝn elixixⱪa qüxsun!
9 Tí òhun bá sì le jà tí ó sì pa mí, àwa yóò di ẹrú u yín, ṣùgbọ́n tí èmi bá lè ṣẹ́gun rẹ̀ tí mo sì pa á, ẹ̀yin yóò di ẹrú u wa, ẹ̀yin yóò sì máa sìn wá.”
U mǝn bilǝn elixip meni urup ɵltürǝlsǝ, biz silǝrning ⱪulliringlar bolimiz. Lekin mǝn uni mǝƣlup ⱪilip ɵltürsǝm, silǝr bizning ⱪullirimiz bolup bizning hizmitimizdǝ bolusilǝr».
10 Nígbà náà Filistini náà wí pé, “Èmi fi ìjà lọ ogun Israẹli ní òní! Ẹ mú ọkùnrin kan wá kí ẹ sì jẹ́ kí a bá ara wa jà.”
Xu Filistiy yǝnǝ sɵz ⱪilip: — Mǝn bügün Israilning ⱪoxuniƣa ⱨaⱪarǝt ⱪildimƣu? Silǝr bir adǝmni qiⱪiringlar, biz elixayli! — dedi.
11 Nígbà tí Saulu àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Filistini, ìdààmú bá wọn.
Saul bilǝn ⱨǝmmǝ Israil bu Filistiyning sɵzlirini anglap, alaⱪzadǝ bolup bǝk ⱪorⱪti.
12 Nísinsin yìí Dafidi jẹ́ ọmọ ará Efrata kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jese, tí ó wá láti Bẹtilẹhẹmu ní Juda, Jese ní ọmọ mẹ́jọ, ní àsìkò Saulu ó ti darúgbó ẹni ọdún púpọ̀.
Dawut Yǝⱨuda yurtidiki Bǝyt-Lǝⱨǝmdǝ olturuⱪluⱪ Yǝssǝ degǝn Əfratliⱪ adǝmning oƣli idi. Yǝssǝning sǝkkiz oƣli bar idi. Saulning künliridǝ u heli yaxinip ⱪalƣanidi.
13 Àwọn ọmọ Jese mẹ́tẹ̀ẹ̀ta tí ó ti dàgbà bá Saulu lọ sí ojú ogun, èyí àkọ́bí ni Eliabu, èyí èkejì ni Abinadabu, èyí ẹ̀kẹta sì ní Ṣamma.
Yǝssǝning üq qong oƣli Saul bilǝn jǝnggǝ qiⱪⱪanidi. Jǝnggǝ qiⱪⱪan üq oƣulning tunjisining ismi Eliab, ikkinqisining ismi Abinadab wǝ üqinqisining Xammaⱨ idi.
14 Dafidi ni ó kéré jù nínú wọn. Àwọn àgbà mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì tẹ̀lé Saulu,
Dawut ⱨǝmmidin kiqiki idi. Üq qong oƣli Saulƣa ǝgixip qiⱪⱪanidi.
15 ṣùgbọ́n Dafidi padà lẹ́yìn Saulu, láti máa tọ́jú àgùntàn baba rẹ̀ ní Bẹtilẹhẹmu.
Bǝzidǝ Dawut Saulning ⱪexidin ɵz atisining ⱪoylirini beⱪix üqün ⱪaytip kelǝtti.
16 Fún ogójì ọjọ́, Filistini wá síwájú ní àràárọ̀ àti ní ìrọ̀lẹ́ wọ́n sì fi ara wọn hàn.
Axu Filistiy bolsa ⱪiriⱪ küngiqilik ⱨǝr ǝtigǝn wǝ kǝqtǝ qiⱪip turdi.
17 Nísinsin yìí Jese wí fún ọmọ rẹ̀ Dafidi pé, “Mú ìwọ̀n efa àti àgbàdo yíyan àti ìṣù àkàrà mẹ́wàá lọ fún àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ kí o sì súré lọ sí ibùdó o wọn.
Yǝssǝ oƣli Dawutⱪa: — Bu ǝfaⱨ ⱪomaqni wǝ bu on nanni elip lǝxkǝrgaⱨƣa tez berip akiliringƣa bǝrgin,
18 Kí o sì mú wàrà mẹ́wàá yìí lọ́wọ́ fún adarí ogun tiwọn. Wo bí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ ṣe wà kí o sì padà wá fún mi ní àmì ìdánilójú láti ọ̀dọ̀ wọn.
bu on parqǝ ⱪurutni ularning mingbexiƣa berip akiliringning ǝⱨwalini sorap ularning kepil hetini elip kǝlgin, dedi.
19 Wọ́n wà pẹ̀lú Saulu àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli ní àfonífojì Ela, wọ́n bá àwọn Filistini jà.”
Saul, xu [üq oƣul] wǝ Israilning ⱨǝmmǝ adǝmliri Elaⱨ jilƣisida turup Filistiylǝrgǝ ⱪarxi jǝng ⱪilatti.
20 Ní àárọ̀ kùtùkùtù Dafidi fi agbo ẹran rẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn olùtọ́jú, ó di ẹrù, ó sì mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n gẹ́gẹ́ bí Jese ti sọ fún un. Ó dé ibùdó bí àwọn ọmọ-ogun ti ń lọ láti dúró ní ipò wọn ní ojú ogun, wọ́n hó ìhó ogun.
Dawut bolsa ǝtisi sǝⱨǝr ⱪopup ⱪoylarni bir baⱪⱪuqining ⱪoliƣa tapxurup, axliⱪ-tülükni elip Yǝssǝ uningƣa tapiliƣandǝk, ⱪoxun istiⱨkamiƣa yǝtkǝndǝ, jǝnggǝ qiⱪidiƣan lǝxkǝrlǝr sɵrǝn kɵtürüwatⱪanidi.
21 Israẹli àti Filistini lọ sí ojú ìjà wọ́n da ojú ìjà kọ ara wọn.
Israil wǝ Filistiylǝr bir-birigǝ udulmu’udul turup soⱪuxⱪa sǝp tüzdi.
22 Dafidi sì kó ẹrù rẹ̀ ti àwọn olùtọ́jú ohun èlò, ó sì sálọ sí ojú ogun ó sì kí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
Dawut bolsa elip kǝlgǝn nǝrsilǝrni yük-taⱪlarƣa ⱪariƣuqining ⱪoliƣa tapxurup sǝp arisiƣa yügürüp berip akiliridin tinqliⱪ soridi.
23 Bí ó ṣe ń bá wọn sọ̀rọ̀, Goliati akíkanjú Filistini tí ó wá láti Gati bọ́ sí iwájú ní ojú ogun, ó sì kígbe fún ìpèníjà, Dafidi sì gbọ́.
U ular bilǝn sɵzlixip turƣanda, Filistiylǝrdin bolƣan Goliat degǝn qempion palwan Filistiylǝrning sepidin qiⱪip yǝnǝ ⱨeliⱪi gǝpni ⱪildi; Dawut uni anglidi.
24 Nígbà tí àwọn Israẹli rí ọkùnrin náà, gbogbo wọn sì sá fún un ní ìbẹ̀rù bojo.
Israilning ⱨǝmmǝ adǝmliri bu adǝmni kɵrgǝndǝ ⱪeqip ketixti wǝ bǝk ⱪorⱪti.
25 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin Israẹli wí pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò rí i bí ọkùnrin yìí ṣe ń jáde wá? Ó jáde wá láti pe Israẹli níjà. Ọba yóò fún ọkùnrin tí ó bá pa á ní ọrọ̀ púpọ̀. Yóò tún fi ọmọ rẹ̀ obìnrin fún un ní ìyàwó, yóò sì sọ ilé e baba rẹ̀ di òmìnira kúrò nínú sísan owó orí ní Israẹli.”
Israilning adǝmliri bir-birigǝ: — Qiⱪiwatⱪan bu adǝmni kɵrdünglarmu? U Israilƣa ⱨaⱪarǝt ⱪilix üqün qiⱪidu. Xundaⱪ boliduki, uni ɵltürgǝn adǝmgǝ padixaⱨ kɵp mal-mülük in’am ⱪilidu, ɵz ⱪizini uningƣa hotunluⱪⱪa beridu ⱨǝm atisining jǝmǝtini Israil tǝwǝsidǝ baj-alwandin halas ⱪilidu, dedi.
26 Dafidi béèrè lọ́wọ́ ọkùnrin tí ó dúró ní ẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Kí ni a yóò ṣe fún ọkùnrin náà tí ó bá pa Filistini yìí, tí ó sì mú ẹ̀gàn kúrò lára Israẹli? Ta ni aláìkọlà Filistini tí ó jẹ́ wí pé yóò máa gan ogun Ọlọ́run alààyè?”
Dawut ɵz yenida turƣan adǝmlǝrdin: — Bu Filistiyni ɵltürüp Israilƣa ⱪilinƣan xu ⱨaⱪarǝtni yoⱪatⱪan kixigǝ nemǝ ⱪilinidu? Qünki bu hǝtnisiz Filistiy zadi kim? U ⱪandaⱪsigǝ mǝnggü ⱨayat bolƣuqi Hudaning ⱪoxunliriƣa ⱨaⱪarǝt ⱪilixⱪa petinidu? — dedi.
27 Wọ́n tún sọ fún un ohun tí wọ́n ti ń sọ, wọ́n sì wí pé, “Èyí ni ohun tí wọn yóò ṣe fún ọkùnrin tí ó bá pa á.”
halayiⱪ uningƣa aldinⱪilarning degǝn sɵzi boyiqǝ jawab berip: — Uni ɵltürgǝn kixigǝ mundaⱪ-mundaⱪ ⱪilinidu, dedi.
28 Nígbà tí Eliabu ẹ̀gbọ́n Dafidi gbọ́ nígbà tí ó ń bá ọkùnrin yìí sọ̀rọ̀, ó bínú sí i, ó sì wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi sọ̀kalẹ̀ wá síbí? Àti pé ta ni ìwọ fi àwọn àgùntàn kékeré tókù ṣọ́ ní aginjù? Èmi mọ ìgbéraga rẹ, àti búburú ọkàn rẹ: ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá nìkan láti wòran ogun.”
Lekin uning qong akisi Eliab uning u adǝmlǝr bilǝn sɵzlǝxkinini anglap ⱪaldi; Eliabning Dawutⱪa aqqiⱪi kelip: — Nemixⱪa bu yǝrgǝ kǝlding? Qɵldiki u azƣinǝ ⱪoyni kimgǝ taxlap ⱪoydung? Mǝn kibirlikingni wǝ kɵnglüngning yamanliⱪini bilimǝn. Sǝn alayitǝn jǝngni kɵrgili kǝlding, dedi.
29 Dafidi wí pé, “Kí ni mo ṣe nísinsin yìí? Ǹjẹ́ mo lè sọ̀rọ̀ bí?”
Dawut: — Mǝn nemǝ ⱪildim? Pǝⱪǝt bir sɵz ⱪilsam bolmamdikǝn? — dedi.
30 Ó sì yípadà sí ẹlòmíràn, ó sì ń sọ̀rọ̀ kan náà, ọkùnrin náà sì dáhùn bí ti ẹni ìṣáájú.
Dawut burulup baxⱪisidin aldinⱪidǝk soridi, hǝlⱪ aldida eytⱪandǝk uningƣa jawab bǝrdi.
31 Àwọn ènìyàn gbọ́ ohun tí Dafidi sọ wọ́n sọ fún Saulu, Saulu sì ránṣẹ́ sí i.
Əmma birsi Dawutning eytⱪan sɵzlirini anglap ⱪelip Saulƣa yǝtküzdi; u Dawutni qaⱪirtip kǝldi.
32 Dafidi sọ fún Saulu pé, “Kí ẹnikẹ́ni má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí Filistini yìí, ìránṣẹ́ rẹ yóò lọ láti bá a jà.”
Dawut Saulƣa: — Bu kixining sǝwǝbidin ⱨeqkimning yüriki su bolmisun. Silining ⱪulliri bu Filistiy bilǝn soⱪuxⱪili qiⱪidu, dedi.
33 Saulu sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò tó láti jáde lọ pàdé ogun Filistini yìí àti láti bá a jà; ọmọdé ni ìwọ, òun sì ti ń jagun láti ìgbà èwe rẹ̀ wá.”
Saul Dawutⱪa: — Sǝn bu Filistiy bilǝn soⱪuxⱪili barsang bolmaydu! Sǝn tehi yax, ǝmma u yaxliⱪidin tartipla jǝngqi idi, dedi.
34 Ṣùgbọ́n Dafidi sọ fún Saulu pé, “Ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ti ń tọ́jú agbo àgùntàn baba rẹ̀. Nígbà tí kìnnìún tàbí àmọ̀tẹ́kùn bá wá láti wá gbé àgùntàn láti inú igbó.
Dawut Saulƣa: — Ⱪulliri ɵz atisining ⱪoylirini beⱪip kǝldim. Bir xir yaki eyiⱪ kelip padidin bir ⱪozini elip kǝtsǝ,
35 Mo sá tẹ̀lé e, mo lù ú, mo sì gba àgùntàn náà kúrò lẹ́nu rẹ̀. Nígbà tí ó kọjú sí mi, mo fi irun rẹ̀ gbá a mú, mo sì lù ú mo sì pa á.
mǝn uning kǝynidin ⱪoƣlap uni urup ⱪozini aƣzidin ⱪutⱪuzup alattim. Əgǝr ⱪopup manga ⱨujum ⱪilsa mǝn uni yaylidin tutuwelip urup ɵltürǝttim.
36 Ìránṣẹ́ rẹ ti pa kìnnìún àti àmọ̀tẹ́kùn, aláìkọlà Filistini yìí yóò jẹ́ ọ̀kan lára wọn, nítorí ó ti pe ogun Ọlọ́run alààyè ní ìjà.
Ⱪulliri ⱨǝm xir ⱨǝm eyiⱪni ɵltürgǝn; bu hǝtnisiz Filistiymu ularƣa ohxax bolidu. Qünki u mǝnggü ⱨayat bolƣuqi Hudaning ⱪoxuniƣa ⱨaⱪarǝt kǝltürdi — dedi.
37 Olúwa tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìhàlẹ̀ kìnnìún àti ti ìhàlẹ̀ àmọ̀tẹ́kùn yóò gbà mí kúrò lọ́wọ́ Filistini yìí.” Saulu wí fún Dafidi pé, “Lọ kí Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
Dawut sɵzini dawam ⱪilip: — Meni xirning qanggilidin wǝ eyiⱪning qanggilidin ⱪutⱪuzƣan Pǝrwǝrdigar ohxaxla bu Filistiyning ⱪolidin ⱪutⱪuzidu, dedi. Saul Dawutⱪa: — Barƣin, Pǝrwǝrdigar sening bilǝn billǝ bolƣay, dedi.
38 Saulu fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ wọ Dafidi, ó wọ̀ ọ́ ní aṣọ ìhámọ́ra ogun, ó sì fi ìbòrí idẹ kan bò ó ní orí.
Andin Saul Dawutⱪa ɵz jǝng kiyimlirini kiygüzüp, bexiƣa mis dubulƣini taⱪap wǝ uningƣa bir jǝng sawutini kiygüzdi.
39 Dafidi si di idà rẹ̀ mọ́ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní rìn káàkiri nítorí wí pé kò mọ́ ọ lára. Ó sọ fún Saulu pé, “Èmi kò le wọ èyí lọ, kò mọ́ mi lára.” Ó sì bọ́ wọn kúrò.
Dawut bolsa Saulning ⱪiliqini kiyimning üstigǝ esip, mengip baⱪti; qünki u bularni kiyip baⱪmiƣanidi. Xuning bilǝn Dawut Saulƣa: — Mǝn bularni kiyip mangalmaydikǝnmǝn; qünki burun kiyip baⱪmiƣan, dǝp ularni seliwǝtti.
40 Nígbà náà, ó sì mú ọ̀pá rẹ̀ lọ́wọ́, ó ṣá òkúta dídán márùn-ún létí odò, ó kó wọn sí àpò olùṣọ́-àgùntàn tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kànnàkànnà, ó sì súnmọ́ Filistini náà.
U ⱪoliƣa ⱨasisini elip, eriⱪtin bǝx siliⱪ tax ilƣap padiqi haltisining yanquⱪiƣa saldi; u salƣusini ⱪoliƣa elip Filistiygǝ yeⱪin bardi.
41 Lákòókò yìí, Filistini pẹ̀lú ẹni tí ń gbé ìhámọ́ra ààbò wà níwájú rẹ̀, ó ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ Dafidi.
Filistiy bolsa qiⱪip Dawutⱪa yeⱪinlaxti, ⱪalⱪan kɵtürgüqisimu uning aldida mangdi.
42 Nígbà tí Filistini náà sì wo Dafidi láti òkè délẹ̀, ó sì rí i wí pé ọmọ kékeré kùnrin ni, ó pọ́n ó sì lẹ́wà lójú, ó sì kẹ́gàn an rẹ̀.
Filistiy Dawutⱪa birⱪur sǝpselip ⱪarap mǝshirǝ ⱪildi. Qünki u tehi yax, buƣday ɵnglük wǝ kelixkǝn yigit idi.
43 Ó sì wí fún Dafidi pé, “Ṣé ajá ni mí ni? Tí o fi tọ̀ mí wá pẹ̀lú ọ̀pá?” Filistini sì fi Dafidi bú pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.
Filistiy Dawutⱪa: — Sǝn ⱨasa kɵtürüp aldimƣa kǝpsǝn? Sǝn meni it dǝp oylap ⱪaldingmu? — dǝp ɵz butlirining namlirini tilƣa elip Dawutni ⱪarƣidi.
44 Filistini náà sì wí Dafidi pé, “Wá níbí, èmi yóò fi ẹran-ara rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run jẹ àti fún àwọn ẹranko tí ó wà nínú igbó!”
Filistiy Dawutⱪa yǝnǝ: — Bu yaⱪⱪa kǝl, mǝn gɵxüngni asmandiki uqar-ⱪanatlarƣa wǝ dalalardiki yirtⱪuqlarƣa yǝm ⱪilimǝn, dedi.
45 Dafidi sì wí fún Filistini pé, “Ìwọ dojú ìjà kọ mí pẹ̀lú idà, ọ̀kọ̀ àti ọfà, ṣùgbọ́n èmi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ pẹ̀lú orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli tí ìwọ tí gàn.
Dawut Filistiykǝ: — Sǝn ⱪiliq, nǝyzǝ wǝ atma nǝyzini kɵtürüp manga ⱨujum ⱪilƣili kǝlding; lekin mǝn sǝn ⱨaⱪarǝt ⱪilƣan, Israilning ⱪoxunlirining Hudasi bolƣan Pǝrwǝrdigarning nami bilǝn aldingƣa ⱨujumƣa qiⱪtim — dedi.
46 Lónìí yìí ni Olúwa yóò fi ọ́ lé mi lọ́wọ́, èmi yóò sì pa ọ́, èmi yóò sì gé orí rẹ. Lónìí èmi yóò fi òkú ogun Filistini fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko igbó, gbogbo ayé yóò sì mọ̀ pé Ọlọ́run wà ní Israẹli.
«Dǝl bügün Pǝrwǝrdigar seni mening ⱪolumƣa tapxuridu. Mǝn seni ɵltürüp bexingni kesip alimǝn; mǝn lǝxkǝrgaⱨdiki Filistiylǝrning jǝsǝtlirinimu asmandiki uqar-ⱪanatlarƣa wǝ dalalardiki yirtⱪuqliriƣa yǝm ⱪilimǝn. Buning bilǝn pütkül jaⱨan Israilda bir Hudaning bar ikǝnlikini bilidu
47 Gbogbo àwọn tí ó péjọ níbí ni yóò mọ̀ pé kì í ṣe nípa ọ̀kọ̀ tàbí idà ni Olúwa fi ń gbàlà; ogun náà ti Olúwa ni, yóò sì fi gbogbo yín lé ọwọ́ wa.”
wǝ bu pütkül jamaǝt Pǝrwǝrdigarning nusrǝt berixining ⱪiliq, nǝyzǝ bilǝn ǝmǝs ikǝnlikini bilidu; qünki bu jǝng bolsa Pǝrwǝrdigarningkidur, U seni ⱪolimizƣa tapxuridu».
48 Bí Filistini ṣe súnmọ́ iwájú láti pàdé e rẹ̀. Dafidi yára sáré sí òun náà láti pàdé e rẹ̀.
Filistiy Dawutⱪa ⱨujum ⱪilƣili ⱪopup yeⱪin kǝlgǝndǝ Dawut uningƣa ⱨujum ⱪilƣili Filistiy ⱪoxunining sepigǝ ⱪarap yügürdi.
49 Dafidi ti ọwọ́ sí àpò rẹ̀, ó sì mú òkúta jáde wá ó sì fì í, ó sì jù ú sí ọ̀kọ́kán iwájú orí Filistini. Òkúta náà sì wọ̀ ọ́ níwájú orí, ó sì ṣubú ó sì dojúbolẹ̀ ní orí ilẹ̀.
Dawut ⱪolini haltisiƣa tiⱪip bir taxni qiⱪirip salƣuƣa selip Filistiygǝ ⱪaritip atti; tax Filistiyning pexanisigǝ tǝgdi. Tax uning pexanisigǝ petip kǝtti, u düm qüxüp yǝrgǝ yiⱪildi.
50 Dafidi yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí Filistini pẹ̀lú kànnàkànnà àti òkúta, láìsí idà ní ọwọ́ rẹ̀, ó lu Filistini, ó sì pa á.
Xundaⱪ ⱪilip Dawut Filistiyni salƣu wǝ tax bilǝn mǝƣlup ⱪilip uni urup ɵltürdi; Dawutning ⱪolida ⱨeq ⱪiliq yoⱪ idi.
51 Dafidi sì sáré ó sì dúró lórí rẹ̀. Ó sì mú idà Filistini, ó sì fà á yọ nínú àkọ̀ ọ rẹ̀. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti pa á tan, ó sì gé orí rẹ̀ pẹ̀lú idà. Nígbà tí àwọn ará Filistini rí i wí pé akọni wọn ti kú, wọ́n yípadà wọ́n sì sálọ.
Dawut yügürüp berip, Filistiyning üstidǝ turup, ⱪiliqini ⱪinidin tartip elip uni ɵltürüp, uning bexini aldi. Filistiylǝr ɵz baturining ɵlginini kɵrüpla, bǝdǝr ⱪaqti.
52 Nígbà náà, àwọn ọkùnrin Israẹli àti ti Juda súnmọ́ iwájú pẹ̀lú ariwo, wọ́n sì lépa àwọn ará Filistini dé ẹnu ibodè Gati àti títí dé ẹnu ibodè Ekroni. Àwọn tí ó kú wà káàkiri ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà Ṣaaraimu àti títí dé ọ̀nà Gati àti Ekroni.
Israillar bilǝn Yǝⱨudalar bolsa ornidin ⱪopup sɵrǝn selixip Filistiylǝrni jilƣiƣiqǝ wǝ Əkron dǝrwaziliriƣiqǝ kǝynidin ⱪoƣlap kǝldi; ɵltürülgǝn Filistiylǝr Xaaraimƣa baridiƣan yolda Gat wǝ Əkronƣiqǝ yetip kǝtkǝnidi.
53 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli sì padà láti máa lé àwọn ará Filistini, wọ́n sì ba ibùdó wọn jẹ́.
Israil Filistiylǝrni ⱪoƣlaxtin yenip kelip ularning lǝxkǝrgaⱨini bulang-talang ⱪildi.
54 Dafidi gé orí Filistini ó sì gbé e wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó àwọn ohun ìjà Filistini sínú àgọ́ tirẹ̀.
Dawut Filistiyning bexini Yerusalemƣa elip bardi; uning yariƣini bolsa ɵz qediriƣa ⱪoydi.
55 Bí Saulu sì ti wo Dafidi bí ó ṣe ń jáde lọ pàdé Filistini, ó wí fún Abneri, olórí àwọn ológun rẹ̀ pé, “Abneri, ọmọ ta ni ọmọdékùnrin yìí?” Abneri dáhùn pe, “Bí ọkàn rẹ̀ ti ń bẹ ní ààyè, ọba èmi kò mọ̀.”
Saul Dawutning Filistiyning aldiƣa qiⱪⱪinini kɵrgǝndǝ ⱪoxunning sǝrdari Abnǝrdin: — I Abnǝr, bu yigit kimning oƣli? — dǝp soridi. Abnǝr: — I padixaⱨ, ⱨayating bilǝn ⱪǝsǝm ⱪilimǝnki, bilmǝymǝn, dedi.
56 Ọba sì wí pé, “Wádìí ọmọ ẹni tí ọmọdékùnrin náà ń ṣe.”
Padixaⱨ: — Bu yigit kimning oƣli ikǝn dǝp sorap baⱪⱪin, dedi.
57 Kété tí ó dé láti ibi tí ó ti lọ pa Filistini, Abneri sì mú u wá síwájú Saulu, orí Filistini sì wà ní ọwọ́ Dafidi.
Dawut Filistiyni ⱪirip ⱪaytip kǝlgǝndǝ Abnǝr uni padixaⱨning ⱪexiƣa elip bardi; Filistiyning bexi tehiqǝ uning ⱪolida turatti.
58 Saulu béèrè pé, “Ọmọdékùnrin, ọmọ ta ni ọ́?” Dafidi dáhùn pé, “Èmi ni ọmọ ìránṣẹ́ rẹ Jese ti Bẹtilẹhẹmu.”
Saul uningdin: — I yigit, kimning oƣlisǝn? dǝp soridi. Dawut: — Mǝn silining ⱪulliri Bǝyt-Lǝⱨǝmlik Yǝssǝning oƣlimǝn, dǝp jawab bǝrdi.