< 1 Samuel 17 >

1 Filistini kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ fún ogun ní Soko ti Juda. Wọ́n pàgọ́ sí Efesi-Damimu, láàrín Soko àti Aseka,
Wtedy Filistyni zebrali swoje wojska do walki i zgromadzili się w Soko, które należy do Judy, rozbili obóz między Soko a Azeką, w Efes-Dammim.
2 Saulu àti àwọn ọmọ Israẹli wọ́n kò ara wọ́n jọ pọ̀, wọ́n sì pàgọ́ ní àfonífojì Ela, wọ́n sì gbé ogun wọn sókè ní ọ̀nà láti pàdé àwọn Filistini.
Saul zaś i Izraelici zebrali się i rozbili obóz w dolinie Ela, i ustawili się w szyku bojowym przeciw Filistynom.
3 Àwọn Filistini sì wà ní orí òkè kan àwọn ọmọ Israẹli sì wà ní orí òkè mìíràn, àfonífojì sì wà láàrín wọn.
Filistyni stali na górze po jednej stronie, Izraelici zaś stali na górze po drugiej stronie, a między nimi była dolina.
4 Ọ̀gágun tí a ń pè ní Goliati, tí ó jẹ́ ará Gati, ó wá láti ibùdó Filistini. Ó ga ní ìgbọ̀nwọ́ mẹ́fà àti ìnà ìka kan ní ìbú.
Wtedy z obozu Filistynów wyszedł pewien wojownik z Gat imieniem Goliat, wysoki na sześć łokci i jedną piędź.
5 Ó ní àṣíborí idẹ ní orí rẹ̀, ó sì wọ ẹ̀wù tí a fi idẹ pẹlẹbẹ ṣe, ìwọ̀n ẹ̀wù náà sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ṣékélì idẹ.
Na głowie [miał] spiżowy hełm i był ubrany w łuskowy pancerz; waga pancerza [wynosiła] pięć tysięcy syklów miedzi.
6 Òun sì wọ ìhámọ́ra idẹ sí ẹsẹ̀ rẹ̀ àti àpáta idẹ kan láàrín ẹ̀yìn rẹ̀.
Miał również spiżowe nagolenice na nogach i spiżową tarczę między ramionami.
7 Ọ̀pá ọ̀kọ̀ rẹ̀ rí bí apásá ìhunṣọ, orí ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì wọn ẹgbẹ̀ta kilogiramu méje irin, ẹni tí ó ru asà ogun rẹ̀ lọ ṣáájú u rẹ̀.
Drzewce jego włóczni były jak wał tkacki, grot jego włóczni [ważył] sześćset syklów żelaza, a przed nim szedł człowiek niosący [jego] tarczę.
8 Goliati dìde, ó sì kígbe sí ogun Israẹli pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi jáde wá, tí ẹ ṣe tò fún ogun? Ṣé èmi kì í ṣe Filistini ni, àbí ẹ̀yin kì í ṣe ìránṣẹ́ Saulu? Yan ọkùnrin kan kí o sì jẹ́ kí ó sọ̀kalẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
Stanął on i zawołał do wojsk Izraela: Po co ustawiacie się w szyku bojowym? Czy ja nie jestem Filistynem, a wy sługami Saula? Wybierzcie spośród siebie człowieka i niech zejdzie do mnie.
9 Tí òhun bá sì le jà tí ó sì pa mí, àwa yóò di ẹrú u yín, ṣùgbọ́n tí èmi bá lè ṣẹ́gun rẹ̀ tí mo sì pa á, ẹ̀yin yóò di ẹrú u wa, ẹ̀yin yóò sì máa sìn wá.”
Jeśli zdoła ze mną walczyć i zabije mnie, będziemy waszymi niewolnikami. Lecz jeśli ja go pokonam i go zabiję, wy będziecie naszymi niewolnikami i będziecie nam służyć.
10 Nígbà náà Filistini náà wí pé, “Èmi fi ìjà lọ ogun Israẹli ní òní! Ẹ mú ọkùnrin kan wá kí ẹ sì jẹ́ kí a bá ara wa jà.”
Filistyn dodał: Rzucam dziś wyzwanie wojskom Izraela. Dajcie mi człowieka, a będziemy ze sobą walczyć.
11 Nígbà tí Saulu àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Filistini, ìdààmú bá wọn.
Gdy Saul i cały Izrael usłyszeli słowa Filistyna, zlękli się i bardzo zatrwożyli.
12 Nísinsin yìí Dafidi jẹ́ ọmọ ará Efrata kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jese, tí ó wá láti Bẹtilẹhẹmu ní Juda, Jese ní ọmọ mẹ́jọ, ní àsìkò Saulu ó ti darúgbó ẹni ọdún púpọ̀.
Dawid [był] synem tego Efratejczyka z Betlejem judzkiego, imieniem Jesse, który miał ośmiu synów. Za czasów Saula był on stary i podeszły w latach.
13 Àwọn ọmọ Jese mẹ́tẹ̀ẹ̀ta tí ó ti dàgbà bá Saulu lọ sí ojú ogun, èyí àkọ́bí ni Eliabu, èyí èkejì ni Abinadabu, èyí ẹ̀kẹta sì ní Ṣamma.
Trzej starsi synowie Jessego wyruszyli i udali się za Saulem na wojnę. Imiona jego trzech synów, którzy poszli na wojnę, [to]: Eliab, pierworodny, drugi po nim – Abinadab i trzeci – Szamma.
14 Dafidi ni ó kéré jù nínú wọn. Àwọn àgbà mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì tẹ̀lé Saulu,
A Dawid był najmłodszy, a trzej najstarsi poszli za Saulem.
15 ṣùgbọ́n Dafidi padà lẹ́yìn Saulu, láti máa tọ́jú àgùntàn baba rẹ̀ ní Bẹtilẹhẹmu.
Dawid zaś odchodził od Saula i wracał, aby paść trzodę swego ojca w Betlejem.
16 Fún ogójì ọjọ́, Filistini wá síwájú ní àràárọ̀ àti ní ìrọ̀lẹ́ wọ́n sì fi ara wọn hàn.
A Filistyn występował rano i wieczorem i stawał tak przez czterdzieści dni.
17 Nísinsin yìí Jese wí fún ọmọ rẹ̀ Dafidi pé, “Mú ìwọ̀n efa àti àgbàdo yíyan àti ìṣù àkàrà mẹ́wàá lọ fún àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ kí o sì súré lọ sí ibùdó o wọn.
I Jesse powiedział do swego syna Dawida: Weź teraz dla swych braci tę efę prażonego ziarna i tych dziesięć chlebów i biegnij do obozu, do swoich braci.
18 Kí o sì mú wàrà mẹ́wàá yìí lọ́wọ́ fún adarí ogun tiwọn. Wo bí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ ṣe wà kí o sì padà wá fún mi ní àmì ìdánilójú láti ọ̀dọ̀ wọn.
Zanieś też tych dziesięć serów dowódcy oddziału, dowiedz się, jak się mają twoi bracia, i weź ich zastaw.
19 Wọ́n wà pẹ̀lú Saulu àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli ní àfonífojì Ela, wọ́n bá àwọn Filistini jà.”
A Saul wraz z nimi i wszystkimi synami Izraela byli w dolinie Ela, walcząc z Filistynami.
20 Ní àárọ̀ kùtùkùtù Dafidi fi agbo ẹran rẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn olùtọ́jú, ó di ẹrù, ó sì mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n gẹ́gẹ́ bí Jese ti sọ fún un. Ó dé ibùdó bí àwọn ọmọ-ogun ti ń lọ láti dúró ní ipò wọn ní ojú ogun, wọ́n hó ìhó ogun.
Wstał więc Dawid wcześnie rano, powierzył trzodę stróżowi, zabrał to wszystko i wyruszył, tak jak mu Jesse nakazał. Gdy przybył do obozu, wojsko wyruszało do bitwy i wydało okrzyk wojenny.
21 Israẹli àti Filistini lọ sí ojú ìjà wọ́n da ojú ìjà kọ ara wọn.
Izraelici i Filistyni ustawili się [już] bowiem w szyku bojowym, szyk przeciwko szykowi.
22 Dafidi sì kó ẹrù rẹ̀ ti àwọn olùtọ́jú ohun èlò, ó sì sálọ sí ojú ogun ó sì kí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
Wtedy Dawid zostawił toboły pod opieką stróża taboru i pobiegł na pole bitwy. Gdy przybył, przywitał się ze swoimi braćmi.
23 Bí ó ṣe ń bá wọn sọ̀rọ̀, Goliati akíkanjú Filistini tí ó wá láti Gati bọ́ sí iwájú ní ojú ogun, ó sì kígbe fún ìpèníjà, Dafidi sì gbọ́.
Gdy z nimi rozmawiał, oto wojownik imieniem Goliat, Filistyn z Gat, wystąpił z szeregów filistyńskich i zaczął wypowiadać te same słowa. I Dawid to usłyszał.
24 Nígbà tí àwọn Israẹli rí ọkùnrin náà, gbogbo wọn sì sá fún un ní ìbẹ̀rù bojo.
A wszyscy Izraelici na widok tego człowieka uciekali przed nim i bardzo się bali.
25 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin Israẹli wí pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò rí i bí ọkùnrin yìí ṣe ń jáde wá? Ó jáde wá láti pe Israẹli níjà. Ọba yóò fún ọkùnrin tí ó bá pa á ní ọrọ̀ púpọ̀. Yóò tún fi ọmọ rẹ̀ obìnrin fún un ní ìyàwó, yóò sì sọ ilé e baba rẹ̀ di òmìnira kúrò nínú sísan owó orí ní Israẹli.”
I Izraelici mówili: Czy widzicie tego człowieka, który występuje? Występuje, by rzucać wyzwanie Izraelowi. Lecz tego, kto go zabije, król wzbogaci wielkim bogactwem i da mu swoją córkę, a dom jego ojca uczyni wolnym w Izraelu.
26 Dafidi béèrè lọ́wọ́ ọkùnrin tí ó dúró ní ẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Kí ni a yóò ṣe fún ọkùnrin náà tí ó bá pa Filistini yìí, tí ó sì mú ẹ̀gàn kúrò lára Israẹli? Ta ni aláìkọlà Filistini tí ó jẹ́ wí pé yóò máa gan ogun Ọlọ́run alààyè?”
Wtedy Dawid zapytał ludzi stojących przy nim: Co dadzą temu, kto zabije tego Filistyna i odejmie hańbę z Izraela? Bo kim jest ten nieobrzezany Filistyn, że rzuca wyzwanie wojskom Boga żywego?
27 Wọ́n tún sọ fún un ohun tí wọ́n ti ń sọ, wọ́n sì wí pé, “Èyí ni ohun tí wọn yóò ṣe fún ọkùnrin tí ó bá pa á.”
I lud odpowiedział mu te same słowa: To dadzą temu, kto go zabije.
28 Nígbà tí Eliabu ẹ̀gbọ́n Dafidi gbọ́ nígbà tí ó ń bá ọkùnrin yìí sọ̀rọ̀, ó bínú sí i, ó sì wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi sọ̀kalẹ̀ wá síbí? Àti pé ta ni ìwọ fi àwọn àgùntàn kékeré tókù ṣọ́ ní aginjù? Èmi mọ ìgbéraga rẹ, àti búburú ọkàn rẹ: ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá nìkan láti wòran ogun.”
A jego starszy brat, Eliab, usłyszał, że rozmawia z tymi ludźmi. I Eliab zapłonął gniewem na Dawida, i powiedział: Po co tu przyszedłeś i komu zostawiłeś tych parę owiec na pustyni? Znam twoją pychę i przewrotność twego serca, bo przyszedłeś, aby przypatrywać się bitwie.
29 Dafidi wí pé, “Kí ni mo ṣe nísinsin yìí? Ǹjẹ́ mo lè sọ̀rọ̀ bí?”
Wtedy Dawid powiedział: Cóż teraz uczyniłem? Czy nie mam [tu] sprawy?
30 Ó sì yípadà sí ẹlòmíràn, ó sì ń sọ̀rọ̀ kan náà, ọkùnrin náà sì dáhùn bí ti ẹni ìṣáájú.
I odwrócił się od niego do kogoś innego, i pytał się jak przedtem. A lud odpowiedział mu tak jak poprzednio.
31 Àwọn ènìyàn gbọ́ ohun tí Dafidi sọ wọ́n sọ fún Saulu, Saulu sì ránṣẹ́ sí i.
I usłyszano słowa, które wypowiedział Dawid, i powtórzono je Saulowi. [Saul] wezwał go więc do siebie.
32 Dafidi sọ fún Saulu pé, “Kí ẹnikẹ́ni má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí Filistini yìí, ìránṣẹ́ rẹ yóò lọ láti bá a jà.”
Wtedy Dawid powiedział do Saula: Niech niczyje serce nie upada z jego powodu. Twój sługa pójdzie i będzie walczył z tym Filistynem.
33 Saulu sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò tó láti jáde lọ pàdé ogun Filistini yìí àti láti bá a jà; ọmọdé ni ìwọ, òun sì ti ń jagun láti ìgbà èwe rẹ̀ wá.”
Lecz Saul odpowiedział Dawidowi: Ty nie możesz iść przeciwko temu Filistynowi, by z nim walczyć. Jesteś bowiem chłopcem, a on jest wojownikiem od swojej młodości.
34 Ṣùgbọ́n Dafidi sọ fún Saulu pé, “Ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ti ń tọ́jú agbo àgùntàn baba rẹ̀. Nígbà tí kìnnìún tàbí àmọ̀tẹ́kùn bá wá láti wá gbé àgùntàn láti inú igbó.
Dawid odpowiedział Saulowi: Twój sługa pasł trzodę swego ojca, a gdy przychodził lew lub niedźwiedź i porywał barana z trzody;
35 Mo sá tẹ̀lé e, mo lù ú, mo sì gba àgùntàn náà kúrò lẹ́nu rẹ̀. Nígbà tí ó kọjú sí mi, mo fi irun rẹ̀ gbá a mú, mo sì lù ú mo sì pa á.
Wtedy goniłem go, uderzałem na niego i wyrywałem mu [go] z paszczy. I [kiedy] rzucał się na mnie, chwytałem go za gardło, biłem i zabijałem go.
36 Ìránṣẹ́ rẹ ti pa kìnnìún àti àmọ̀tẹ́kùn, aláìkọlà Filistini yìí yóò jẹ́ ọ̀kan lára wọn, nítorí ó ti pe ogun Ọlọ́run alààyè ní ìjà.
Twój sługa zabił i lwa, i niedźwiedzia. Ten nieobrzezany Filistyn będzie jak jeden z nich, gdyż rzucił wyzwanie wojskom Boga żywego.
37 Olúwa tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìhàlẹ̀ kìnnìún àti ti ìhàlẹ̀ àmọ̀tẹ́kùn yóò gbà mí kúrò lọ́wọ́ Filistini yìí.” Saulu wí fún Dafidi pé, “Lọ kí Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
Ponadto Dawid powiedział: PAN, który wyrwał mnie z łapy lwa i niedźwiedzia, wyrwie mnie również z rąk tego Filistyna. Wtedy Saul powiedział do Dawida: Idź i niech PAN będzie z tobą.
38 Saulu fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ wọ Dafidi, ó wọ̀ ọ́ ní aṣọ ìhámọ́ra ogun, ó sì fi ìbòrí idẹ kan bò ó ní orí.
I Saul ubrał Dawida w swoją zbroję, włożył mu na głowę spiżowy hełm i ubrał go w pancerz.
39 Dafidi si di idà rẹ̀ mọ́ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní rìn káàkiri nítorí wí pé kò mọ́ ọ lára. Ó sọ fún Saulu pé, “Èmi kò le wọ èyí lọ, kò mọ́ mi lára.” Ó sì bọ́ wọn kúrò.
Dawid przypasał też jego miecz do swojej zbroi i próbował chodzić, bo nigdy [wcześniej] tego nie nosił. Wtedy Dawid powiedział do Saula: Nie mogę w tym chodzić, bo nie przywykłem do tego. I Dawid zdjął to z siebie.
40 Nígbà náà, ó sì mú ọ̀pá rẹ̀ lọ́wọ́, ó ṣá òkúta dídán márùn-ún létí odò, ó kó wọn sí àpò olùṣọ́-àgùntàn tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kànnàkànnà, ó sì súnmọ́ Filistini náà.
Potem wziął do ręki swój kij i wybrał sobie pięć gładkich kamieni z potoku, i włożył je do torby pasterskiej, którą miał przy sobie, i z procą w ręku przybliżył się do Filistyna.
41 Lákòókò yìí, Filistini pẹ̀lú ẹni tí ń gbé ìhámọ́ra ààbò wà níwájú rẹ̀, ó ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ Dafidi.
Filistyn również ruszył i zbliżał się do Dawida, a jego giermek szedł przed nim.
42 Nígbà tí Filistini náà sì wo Dafidi láti òkè délẹ̀, ó sì rí i wí pé ọmọ kékeré kùnrin ni, ó pọ́n ó sì lẹ́wà lójú, ó sì kẹ́gàn an rẹ̀.
A gdy Filistyn spojrzał i zobaczył Dawida, wzgardził nim, dlatego że był młodzieńcem – rudym i przystojnym.
43 Ó sì wí fún Dafidi pé, “Ṣé ajá ni mí ni? Tí o fi tọ̀ mí wá pẹ̀lú ọ̀pá?” Filistini sì fi Dafidi bú pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.
I Filistyn powiedział do Dawida: Czyż jestem psem, że przychodzisz do mnie z kijem? I przeklinał Filistyn Dawida przez swoich bogów.
44 Filistini náà sì wí Dafidi pé, “Wá níbí, èmi yóò fi ẹran-ara rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run jẹ àti fún àwọn ẹranko tí ó wà nínú igbó!”
Filistyn powiedział jeszcze do Dawida: Chodź do mnie, a dam twoje ciało ptakom powietrznym i zwierzętom polnym.
45 Dafidi sì wí fún Filistini pé, “Ìwọ dojú ìjà kọ mí pẹ̀lú idà, ọ̀kọ̀ àti ọfà, ṣùgbọ́n èmi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ pẹ̀lú orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli tí ìwọ tí gàn.
Wtedy Dawid odpowiedział Filistynowi: Ty przychodzisz do mnie z mieczem, włócznią i tarczą, a ja przychodzę do ciebie w imię PANA zastępów, Boga wojsk Izraela, któremu rzuciłeś wyzwanie.
46 Lónìí yìí ni Olúwa yóò fi ọ́ lé mi lọ́wọ́, èmi yóò sì pa ọ́, èmi yóò sì gé orí rẹ. Lónìí èmi yóò fi òkú ogun Filistini fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko igbó, gbogbo ayé yóò sì mọ̀ pé Ọlọ́run wà ní Israẹli.
Dziś PAN wyda cię w moje ręce, a ja cię zabiję i odetnę ci głowę, a dam dzisiaj trupy wojsk Filistynów ptakom powietrznym i dzikim zwierzętom. I cała ziemia pozna, że jest Bóg w Izraelu;
47 Gbogbo àwọn tí ó péjọ níbí ni yóò mọ̀ pé kì í ṣe nípa ọ̀kọ̀ tàbí idà ni Olúwa fi ń gbàlà; ogun náà ti Olúwa ni, yóò sì fi gbogbo yín lé ọwọ́ wa.”
I całe to zgromadzenie pozna, że nie mieczem ani włócznią wybawia PAN, gdyż walka należy do PANA i on wyda was w nasze ręce.
48 Bí Filistini ṣe súnmọ́ iwájú láti pàdé e rẹ̀. Dafidi yára sáré sí òun náà láti pàdé e rẹ̀.
A gdy Filistyn wstał, ruszył i zbliżał się do Dawida, Dawid również pośpiesznie pobiegł na pole walki naprzeciw Filistyna.
49 Dafidi ti ọwọ́ sí àpò rẹ̀, ó sì mú òkúta jáde wá ó sì fì í, ó sì jù ú sí ọ̀kọ́kán iwájú orí Filistini. Òkúta náà sì wọ̀ ọ́ níwájú orí, ó sì ṣubú ó sì dojúbolẹ̀ ní orí ilẹ̀.
I Dawid sięgnął ręką do torby, wyjął z niej kamień, cisnął [go] z procy i ugodził Filistyna w czoło tak, że kamień utkwił mu w czole. I [ten] upadł twarzą na ziemię.
50 Dafidi yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí Filistini pẹ̀lú kànnàkànnà àti òkúta, láìsí idà ní ọwọ́ rẹ̀, ó lu Filistini, ó sì pa á.
Tak Dawid zwyciężył Filistyna procą i kamieniem. Uderzył Filistyna i zabił go, choć Dawid nie miał w ręku miecza.
51 Dafidi sì sáré ó sì dúró lórí rẹ̀. Ó sì mú idà Filistini, ó sì fà á yọ nínú àkọ̀ ọ rẹ̀. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti pa á tan, ó sì gé orí rẹ̀ pẹ̀lú idà. Nígbà tí àwọn ará Filistini rí i wí pé akọni wọn ti kú, wọ́n yípadà wọ́n sì sálọ.
Dawid podbiegł, stanął nad Filistynem, wziął jego miecz, dobył go z pochwy, zabił go i odciął mu nim głowę. A kiedy Filistyni zobaczyli, że ich bohater umarł, uciekli.
52 Nígbà náà, àwọn ọkùnrin Israẹli àti ti Juda súnmọ́ iwájú pẹ̀lú ariwo, wọ́n sì lépa àwọn ará Filistini dé ẹnu ibodè Gati àti títí dé ẹnu ibodè Ekroni. Àwọn tí ó kú wà káàkiri ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà Ṣaaraimu àti títí dé ọ̀nà Gati àti Ekroni.
Wtedy powstali Izraelici i Judejczycy, wydali okrzyk i ścigali Filistynów aż do wejścia do doliny i aż do bram Ekronu. I ranni Filistyni padali na drodze od Szaaraim aż do Gat i Ekronu.
53 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli sì padà láti máa lé àwọn ará Filistini, wọ́n sì ba ibùdó wọn jẹ́.
Potem synowie Izraela wrócili z pościgu za Filistynami i złupili ich obóz.
54 Dafidi gé orí Filistini ó sì gbé e wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó àwọn ohun ìjà Filistini sínú àgọ́ tirẹ̀.
A Dawid wziął głowę tego Filistyna i przyniósł ją do Jerozolimy, a jego zbroję włożył do swego namiotu.
55 Bí Saulu sì ti wo Dafidi bí ó ṣe ń jáde lọ pàdé Filistini, ó wí fún Abneri, olórí àwọn ológun rẹ̀ pé, “Abneri, ọmọ ta ni ọmọdékùnrin yìí?” Abneri dáhùn pe, “Bí ọkàn rẹ̀ ti ń bẹ ní ààyè, ọba èmi kò mọ̀.”
Gdy Saul zobaczył, że Dawid wyrusza naprzeciw Filistyna, zapytał Abnera, dowódcę wojska: Czyim synem jest ten młodzieniec, Abnerze? Abner odpowiedział: Jak żyje twoja dusza, królu, nie wiem.
56 Ọba sì wí pé, “Wádìí ọmọ ẹni tí ọmọdékùnrin náà ń ṣe.”
Wtedy król powiedział: Dowiedz się, czyim synem jest ten młodzieniec.
57 Kété tí ó dé láti ibi tí ó ti lọ pa Filistini, Abneri sì mú u wá síwájú Saulu, orí Filistini sì wà ní ọwọ́ Dafidi.
Kiedy Dawid wracał po zabiciu Filistynów, Abner wziął go i przyprowadził przed Saula, a głowa Filistyna była jeszcze w jego ręku.
58 Saulu béèrè pé, “Ọmọdékùnrin, ọmọ ta ni ọ́?” Dafidi dáhùn pé, “Èmi ni ọmọ ìránṣẹ́ rẹ Jese ti Bẹtilẹhẹmu.”
I Saul zapytał go: Czyim synem jesteś, młodzieńcze? Dawid odpowiedział: [Jestem] synem twego sługi Jessego Betlejemity.

< 1 Samuel 17 >