< 1 Samuel 17 >

1 Filistini kó àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ jọ fún ogun ní Soko ti Juda. Wọ́n pàgọ́ sí Efesi-Damimu, láàrín Soko àti Aseka,
Na kua huihui nga Pirihitini i a ratou ope ki te whawhai, a ka whakaminea ki Hokoho o Hura, noho ana i waenganui o Hokoho, o Ateka, i Epeheramime.
2 Saulu àti àwọn ọmọ Israẹli wọ́n kò ara wọ́n jọ pọ̀, wọ́n sì pàgọ́ ní àfonífojì Ela, wọ́n sì gbé ogun wọn sókè ní ọ̀nà láti pàdé àwọn Filistini.
I huihui ano a Haora ratou ko nga tangata o Iharaira, i noho ki te raorao o Eraha; a ka whakatakoto i a ratou ngohi mo te whawhai ki nga Pirihitini.
3 Àwọn Filistini sì wà ní orí òkè kan àwọn ọmọ Israẹli sì wà ní orí òkè mìíràn, àfonífojì sì wà láàrín wọn.
Na i runga nga Pirihitini i te maunga i tenei taha e tu ana, me Iharaira i te maunga i tera taha e tu ana: he wharua hoki i waenganui o ratou.
4 Ọ̀gágun tí a ń pè ní Goliati, tí ó jẹ́ ará Gati, ó wá láti ibùdó Filistini. Ó ga ní ìgbọ̀nwọ́ mẹ́fà àti ìnà ìka kan ní ìbú.
Na ko te putanga o tetahi tangata, he papatu, i roto i te puni o nga Pirihitini, ko tona ingoa, ko Koriata, no Kata, e ono whatianga kotahi hoki whanganga a te ringa tona roa.
5 Ó ní àṣíborí idẹ ní orí rẹ̀, ó sì wọ ẹ̀wù tí a fi idẹ pẹlẹbẹ ṣe, ìwọ̀n ẹ̀wù náà sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún márùn-ún ṣékélì idẹ.
A he parahi te potae o tona matenga, he pukupuku unahi hoki tona kakahu: ko te taimaha o te pukupuku e rima mano hekere parahi.
6 Òun sì wọ ìhámọ́ra idẹ sí ẹsẹ̀ rẹ̀ àti àpáta idẹ kan láàrín ẹ̀yìn rẹ̀.
He whakapuru tao parahi kei ona waewae, a i ona pokohiwi he timata parahi.
7 Ọ̀pá ọ̀kọ̀ rẹ̀ rí bí apásá ìhunṣọ, orí ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì wọn ẹgbẹ̀ta kilogiramu méje irin, ẹni tí ó ru asà ogun rẹ̀ lọ ṣáájú u rẹ̀.
Rite tonu hoki ki te rakau a te kaiwhatu te kakau o tana taora; na, ko te taimaha o te tete o tana taoroa e ono rau hekere rino: i mua ano i a ia e haere ana te kaimau o tana whakangungu rakau.
8 Goliati dìde, ó sì kígbe sí ogun Israẹli pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi jáde wá, tí ẹ ṣe tò fún ogun? Ṣé èmi kì í ṣe Filistini ni, àbí ẹ̀yin kì í ṣe ìránṣẹ́ Saulu? Yan ọkùnrin kan kí o sì jẹ́ kí ó sọ̀kalẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi.
Na ka tu ia, a ka karanga ki nga ngohi a Iharaira, ka mea ki a ratou, He aha koutou i puta mai ai ki te whakatakoto i a koutou ngohi: ehara ianei ahau i te Pirihitini, ko koutou he pononga na Haora? whiriwhiria he tangata ma koutou, a kia heke ih o ia ki ahau.
9 Tí òhun bá sì le jà tí ó sì pa mí, àwa yóò di ẹrú u yín, ṣùgbọ́n tí èmi bá lè ṣẹ́gun rẹ̀ tí mo sì pa á, ẹ̀yin yóò di ẹrú u wa, ẹ̀yin yóò sì máa sìn wá.”
Ki te kaha ia ki te whawhai ki ahau, ki te patu i ahau, na ko matou hei pononga ma koutou: ki te kaha ia ko ahau i a ia, ki te patu i a ia, na hei pononga koutou ma matou, a me mahi koutou ki a matou.
10 Nígbà náà Filistini náà wí pé, “Èmi fi ìjà lọ ogun Israẹli ní òní! Ẹ mú ọkùnrin kan wá kí ẹ sì jẹ́ kí a bá ara wa jà.”
I mea ano taua Pirihitini, Tenei taku whakatara inaianei mo nga ngohi a Iharaira; homai he tangata ki ahau kia whawhai maua.
11 Nígbà tí Saulu àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ ọ̀rọ̀ Filistini, ìdààmú bá wọn.
A, i te rongonga o Haora ratou ko Iharaira katoa ki enei kupu a te Pirihitini, hopi noa iho ratou, nui atu te wehi.
12 Nísinsin yìí Dafidi jẹ́ ọmọ ará Efrata kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jese, tí ó wá láti Bẹtilẹhẹmu ní Juda, Jese ní ọmọ mẹ́jọ, ní àsìkò Saulu ó ti darúgbó ẹni ọdún púpọ̀.
Na, he tama a Rawiri na taua Eparati o Peterehema Hura, ko Hehe nei tona ingoa, tokowaru hoki ana tama: a i nga ra o Haora kua koroheketia taua tangata i roto i nga tangata.
13 Àwọn ọmọ Jese mẹ́tẹ̀ẹ̀ta tí ó ti dàgbà bá Saulu lọ sí ojú ogun, èyí àkọ́bí ni Eliabu, èyí èkejì ni Abinadabu, èyí ẹ̀kẹta sì ní Ṣamma.
Na, tokotoru nga tama a Hehe, ko nga kaumatua, i haere, i aru i a Haora ki te pakanga: ko nga ingoa enei o ana tama tokotoru i haere nei ki te pakanga, ko Eriapa te matamua, ko to muri iho i a ia ko Apinarapa, a ko Hamaha te tuatoru.
14 Dafidi ni ó kéré jù nínú wọn. Àwọn àgbà mẹ́tẹ̀ẹ̀ta sì tẹ̀lé Saulu,
Ko Rawiri hoki to muri rawa: na aru ana nga mea kaumatua tokotoru i a Haora.
15 ṣùgbọ́n Dafidi padà lẹ́yìn Saulu, láti máa tọ́jú àgùntàn baba rẹ̀ ní Bẹtilẹhẹmu.
Na haere ai a Rawiri, a ka hoki atu i a Haora ki te tiaki i nga hipi a tona papa i Peterehema.
16 Fún ogójì ọjọ́, Filistini wá síwájú ní àràárọ̀ àti ní ìrọ̀lẹ́ wọ́n sì fi ara wọn hàn.
Na i te ata, i te ahiahi, ka whakatata mai taua Pirihitini, ka whakaatu i a ia, e wha tekau nga ra.
17 Nísinsin yìí Jese wí fún ọmọ rẹ̀ Dafidi pé, “Mú ìwọ̀n efa àti àgbàdo yíyan àti ìṣù àkàrà mẹ́wàá lọ fún àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ kí o sì súré lọ sí ibùdó o wọn.
Na ka mea a Hehe ki tana tama, ki a Rawiri, Tena, maua atu tetahi wahi o tenei witi pahuhu, kia kotahi epa, ma ou tuakana, me enei taro kotahi tekau, rere atu ki te puni, ki ou tuakana;
18 Kí o sì mú wàrà mẹ́wàá yìí lọ́wọ́ fún adarí ogun tiwọn. Wo bí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ ṣe wà kí o sì padà wá fún mi ní àmì ìdánilójú láti ọ̀dọ̀ wọn.
Maua atu hoki enei tiihi kotahi tekau ki to ratou rangatira mano, ka tirotiro atu kei te pehea ou tuakana, ka tango mai ai i a ratou tohu.
19 Wọ́n wà pẹ̀lú Saulu àti gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli ní àfonífojì Ela, wọ́n bá àwọn Filistini jà.”
Na i te raorao o Eraha a Haora me ratou, me nga tangata katoa hoki o Iharaira e whawhai ana ki nga Pirihitini.
20 Ní àárọ̀ kùtùkùtù Dafidi fi agbo ẹran rẹ̀ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn olùtọ́jú, ó di ẹrù, ó sì mú ọ̀nà rẹ̀ pọ̀n gẹ́gẹ́ bí Jese ti sọ fún un. Ó dé ibùdó bí àwọn ọmọ-ogun ti ń lọ láti dúró ní ipò wọn ní ojú ogun, wọ́n hó ìhó ogun.
Na ka maranga wawe a Rawiri i te ata, tukua atu ana e ia nga hipi ki te kaitiaki, a mauria ana aua mea e ia, haere ana; pera ana ia me ta Hehe i whakahau ai ki a ia. A, no tona taenga ki te parepare e haere ana te ope ki te whawhai, e hamama ana, mo te whai.
21 Israẹli àti Filistini lọ sí ojú ìjà wọ́n da ojú ìjà kọ ara wọn.
Kua oti hoki i a Iharaira ratou ko nga Pirihitini nga ngohi te whakatakoto, tenei ngohi hei whawhai ki tera ngohi.
22 Dafidi sì kó ẹrù rẹ̀ ti àwọn olùtọ́jú ohun èlò, ó sì sálọ sí ojú ogun ó sì kí àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀.
Na tukua ana e Rawiri tana pikaunga ki te ringa o te kaitiaki o nga pikaunga, a rere ana ki te taua, ka tae, ka oha ki ona tuakana.
23 Bí ó ṣe ń bá wọn sọ̀rọ̀, Goliati akíkanjú Filistini tí ó wá láti Gati bọ́ sí iwájú ní ojú ogun, ó sì kígbe fún ìpèníjà, Dafidi sì gbọ́.
I a ia ano e korero ana ki a ratou, na ko taua papatu, ko te Pirihitini o Kata, ko Koriata tona ingoa, e haere mai ana i roto i nga ngohi a nga Pirihitini, a ka korero ko aua korero ra ano, a ka rongo a Rawiri.
24 Nígbà tí àwọn Israẹli rí ọkùnrin náà, gbogbo wọn sì sá fún un ní ìbẹ̀rù bojo.
A, i te kitenga o nga tangata katoa o Iharaira i taua tangata, rere ana ratou i tona aroaro, a nui atu to ratou wehi.
25 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin Israẹli wí pé, “Ǹjẹ́ ẹ̀yin kò rí i bí ọkùnrin yìí ṣe ń jáde wá? Ó jáde wá láti pe Israẹli níjà. Ọba yóò fún ọkùnrin tí ó bá pa á ní ọrọ̀ púpọ̀. Yóò tún fi ọmọ rẹ̀ obìnrin fún un ní ìyàwó, yóò sì sọ ilé e baba rẹ̀ di òmìnira kúrò nínú sísan owó orí ní Israẹli.”
Na ka mea nga tangata o Iharaira, I kite ranei koutou i taua tangata i haere mai nei? He pono he whakatara mo Iharaira i haere mai ai ia: na, ko te tangata e patua ai ia, nui atu nga taonga e homai e te kingi ki a ia, ka homai ano e ia tana tama hine ki a ia, ka whakarangatiratia ano te whare o tona papa i roto i a Iharaira.
26 Dafidi béèrè lọ́wọ́ ọkùnrin tí ó dúró ní ẹ̀gbẹ́ ẹ rẹ̀ pé, “Kí ni a yóò ṣe fún ọkùnrin náà tí ó bá pa Filistini yìí, tí ó sì mú ẹ̀gàn kúrò lára Israẹli? Ta ni aláìkọlà Filistini tí ó jẹ́ wí pé yóò máa gan ogun Ọlọ́run alààyè?”
Na ka korero a Rawiri ki nga tangata e tu ana i tona taha, ka mea, Ka peheatia te tangata e patua ai tenei Pirihitini, e mutu ai te tawai o Iharaira? ko wai hoki tenei Pirihitini kokotikore i whakatara ai ia ki nga ngohi a te Atua ora?
27 Wọ́n tún sọ fún un ohun tí wọ́n ti ń sọ, wọ́n sì wí pé, “Èyí ni ohun tí wọn yóò ṣe fún ọkùnrin tí ó bá pa á.”
Na ka penei te whakahoki a te iwi ki a ia, ka mea ratou, Ka pera ano te hanga ki te tangata, e patua ai ia.
28 Nígbà tí Eliabu ẹ̀gbọ́n Dafidi gbọ́ nígbà tí ó ń bá ọkùnrin yìí sọ̀rọ̀, ó bínú sí i, ó sì wí pé, “Kí ni ó dé tí ìwọ fi sọ̀kalẹ̀ wá síbí? Àti pé ta ni ìwọ fi àwọn àgùntàn kékeré tókù ṣọ́ ní aginjù? Èmi mọ ìgbéraga rẹ, àti búburú ọkàn rẹ: ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá nìkan láti wòran ogun.”
A, no te rongonga o Eriapa, o tona tuakana matamua, i a ia e korero ana ki aua tangata, ko te tino muranga o te riri o Eriapa ki a Rawiri, ka mea ia He aha koe i haere mai ai? i tukua e koe ki a wai aua hipi torutoru ra i te koraha? e mohio ana ahau ki tou whakapehapeha, ki te kino ano hoki o tou ngakau, he matakitaki hoki i te whawhai i haere mai ai koe ki raro nei.
29 Dafidi wí pé, “Kí ni mo ṣe nísinsin yìí? Ǹjẹ́ mo lè sọ̀rọ̀ bí?”
Na ka mea a Rawiri, I aha koia ahau? Kahore ranei he take?
30 Ó sì yípadà sí ẹlòmíràn, ó sì ń sọ̀rọ̀ kan náà, ọkùnrin náà sì dáhùn bí ti ẹni ìṣáájú.
Na ka tahuri atu ia i a ia ki tetahi atu, a ka korero atu ko aua kupu ano; a rite tonu ki te kupu tuatahi te kupu i whakahokia mai e te iwi ki a ia.
31 Àwọn ènìyàn gbọ́ ohun tí Dafidi sọ wọ́n sọ fún Saulu, Saulu sì ránṣẹ́ sí i.
A, no ka rangona nga kupu i korerotia e Rawiri, korerotia ana e ratou ki a Haora; a ka tono ia kia tikina ia.
32 Dafidi sọ fún Saulu pé, “Kí ẹnikẹ́ni má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí Filistini yìí, ìránṣẹ́ rẹ yóò lọ láti bá a jà.”
Na ka mea a Rawiri ki a Haora, Kei hopi te ngakau o tetahi ki a ia: ma tau pononga e haere ki te whawhai ki tenei Pirihitini.
33 Saulu sì wí fún Dafidi pé, “Ìwọ kò tó láti jáde lọ pàdé ogun Filistini yìí àti láti bá a jà; ọmọdé ni ìwọ, òun sì ti ń jagun láti ìgbà èwe rẹ̀ wá.”
Na ka mea a Haora ki a Rawiri, E kore e taea e koe te haere ki tenei Pirihitini whawhai ai: he tamariki nei hoki koe, he tangata hapai patu ia no tona tamarikitanga ake.
34 Ṣùgbọ́n Dafidi sọ fún Saulu pé, “Ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ ti ń tọ́jú agbo àgùntàn baba rẹ̀. Nígbà tí kìnnìún tàbí àmọ̀tẹ́kùn bá wá láti wá gbé àgùntàn láti inú igbó.
Na ka mea a Rawiri ki a Haora, I te tiaki tau pononga i nga hipi a tona papa; na ko te haerenga mai o tetahi raiona, o tetahi pea, kahakina atu ana he reme i roto i te kahui;
35 Mo sá tẹ̀lé e, mo lù ú, mo sì gba àgùntàn náà kúrò lẹ́nu rẹ̀. Nígbà tí ó kọjú sí mi, mo fi irun rẹ̀ gbá a mú, mo sì lù ú mo sì pa á.
Na ka puta atu ahau ki te whai i a ia, a patua ana ia e ahau: tangohia mai ana hoki te reme i roto i tona waha; a, no tona whakatikanga mai ki ahau, hopukia ana tona kumikumi e ahau, patua iho kia mate.
36 Ìránṣẹ́ rẹ ti pa kìnnìún àti àmọ̀tẹ́kùn, aláìkọlà Filistini yìí yóò jẹ́ ọ̀kan lára wọn, nítorí ó ti pe ogun Ọlọ́run alààyè ní ìjà.
I patua ruruatia te raiona me te pea e tau pononga; a ka rite tenei Pirihitini kokotikore ki tetahi o raua; mona i whakatara ki nga ngohi a te Atua ora.
37 Olúwa tí ó gbà mí kúrò lọ́wọ́ ìhàlẹ̀ kìnnìún àti ti ìhàlẹ̀ àmọ̀tẹ́kùn yóò gbà mí kúrò lọ́wọ́ Filistini yìí.” Saulu wí fún Dafidi pé, “Lọ kí Olúwa wà pẹ̀lú rẹ.”
I mea ano a Rawiri, Ma Ihowa nana nei ahau i whakaora i te wae o te raiona, i te wae o te pea, mana ahau e whakaora i te ringa o tenei Pirihitini. Ano ra ko Haora ki a Rawiri, Haere, hei a koe ano a Ihowa.
38 Saulu fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ wọ Dafidi, ó wọ̀ ọ́ ní aṣọ ìhámọ́ra ogun, ó sì fi ìbòrí idẹ kan bò ó ní orí.
Na ka whakakakahuria a Rawiri e Haora ki ona kakahu, i potaea ano tona matenga e ia ki te potae parahi: i whakakakahuria ano hoki e ia he pukupuku rino ki a ia.
39 Dafidi si di idà rẹ̀ mọ́ àwọ̀tẹ́lẹ̀ rẹ̀ ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní rìn káàkiri nítorí wí pé kò mọ́ ọ lára. Ó sọ fún Saulu pé, “Èmi kò le wọ èyí lọ, kò mọ́ mi lára.” Ó sì bọ́ wọn kúrò.
A whitikiria ana e Rawiri tana hoari ki waho ake o ona kakahu; ka anga, ka haere; kihai hoki i whakamatauria e ia. Na ka mea a Rawiri ki a Haora, E kore e tika taku haere i enei, kahore hoki i whakamatauria e ahau. Na whakarerea atu ana e Rawiri.
40 Nígbà náà, ó sì mú ọ̀pá rẹ̀ lọ́wọ́, ó ṣá òkúta dídán márùn-ún létí odò, ó kó wọn sí àpò olùṣọ́-àgùntàn tí ó wà lọ́wọ́ rẹ̀ pẹ̀lú kànnàkànnà, ó sì súnmọ́ Filistini náà.
Na ka maua atu e ia ko tana tokotoko i tona ringa; i whiriwhiria ano etahi kohatu maeneene e rima mana i roto i te awa, a whaowhina ana ki roto ki tana peke hepara, ara ki te putea; i tona ringa ano tana kotaha, na ko tona whakatatanga atu ki te Pirihitini.
41 Lákòókò yìí, Filistini pẹ̀lú ẹni tí ń gbé ìhámọ́ra ààbò wà níwájú rẹ̀, ó ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ Dafidi.
A i haere tonu mai te Pirihitini, i whakatata mai ki a Rawiri; ko te kaimau ano o tana whakangungu rakau i haere i mua i a ia.
42 Nígbà tí Filistini náà sì wo Dafidi láti òkè délẹ̀, ó sì rí i wí pé ọmọ kékeré kùnrin ni, ó pọ́n ó sì lẹ́wà lójú, ó sì kẹ́gàn an rẹ̀.
A, no te tirotirohanga o te Pirihitini, ka kite i a Rawiri, whakahawea ana ki a ia; he taitamariki hoki ia, he kiri puwhero, he ataahua hoki.
43 Ó sì wí fún Dafidi pé, “Ṣé ajá ni mí ni? Tí o fi tọ̀ mí wá pẹ̀lú ọ̀pá?” Filistini sì fi Dafidi bú pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.
Na ka mea te Pirihitini ki a Rawiri, He kuri ahau i haere mai ai koe me nga tokotoko ki ahau? Na, kanga iho a Rawiri e te Pirihitini ki ona atua.
44 Filistini náà sì wí Dafidi pé, “Wá níbí, èmi yóò fi ẹran-ara rẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run jẹ àti fún àwọn ẹranko tí ó wà nínú igbó!”
I mea ano te Pirihitini ki a Rawiri, Haere mai ki ahau, a ka hoatu e ahau ou kikokiko ma nga manu o te rangi, ma nga kararehe o te parae.
45 Dafidi sì wí fún Filistini pé, “Ìwọ dojú ìjà kọ mí pẹ̀lú idà, ọ̀kọ̀ àti ọfà, ṣùgbọ́n èmi wá sí ọ̀dọ̀ rẹ pẹ̀lú orúkọ Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli tí ìwọ tí gàn.
Katahi ka mea a Rawiri ki te Pirihitini, I haere mai koe ki ahau me te hoari, me te taoroa, me te timata: ko ahau ia ka haere atu nei ki a koe i runga i te ingoa o Ihowa o nga mano, o te Atua o nga taua a Iharaira, o tau i whakatara ake na.
46 Lónìí yìí ni Olúwa yóò fi ọ́ lé mi lọ́wọ́, èmi yóò sì pa ọ́, èmi yóò sì gé orí rẹ. Lónìí èmi yóò fi òkú ogun Filistini fún ẹyẹ ojú ọ̀run àti fún ẹranko igbó, gbogbo ayé yóò sì mọ̀ pé Ọlọ́run wà ní Israẹli.
Ko aianei koe tukua mai ai e Ihowa ki toku ringa, a ka patua koe e ahau, ka tangohia tou upoko i a koe, a ka hoatu aianei nga tinana o te ope o nga Pirihitini ma nga manu o te rangi, ma nga kararehe mohoao o te whenua, a ka mohio te whenua katoa he Atua ano to Iharaira.
47 Gbogbo àwọn tí ó péjọ níbí ni yóò mọ̀ pé kì í ṣe nípa ọ̀kọ̀ tàbí idà ni Olúwa fi ń gbàlà; ogun náà ti Olúwa ni, yóò sì fi gbogbo yín lé ọwọ́ wa.”
A ka mohio tenei whakaminenga katoa, ehara te hoari, te taoroa ranei, i ta Ihowa mea hei whakaora: na Ihowa hoki te whawhai, a mana koutou e homai ki o matou ringa.
48 Bí Filistini ṣe súnmọ́ iwájú láti pàdé e rẹ̀. Dafidi yára sáré sí òun náà láti pàdé e rẹ̀.
Na ka whakatika te Pirihitini, ka haere mai, ka whakatata ki te whakatutaki i a Rawiri, na ka hohoro a Rawiri, a rere ana ki te taua kia tutaki ki te Pirihitini.
49 Dafidi ti ọwọ́ sí àpò rẹ̀, ó sì mú òkúta jáde wá ó sì fì í, ó sì jù ú sí ọ̀kọ́kán iwájú orí Filistini. Òkúta náà sì wọ̀ ọ́ níwájú orí, ó sì ṣubú ó sì dojúbolẹ̀ ní orí ilẹ̀.
Na kua totoro iho te ringa o Rawiri ki roto ki te peke, kei te tango i tetahi kohatu i roto, piua atu ana e ia, na kua tu te rae o te Pirihitini, toremi atu te kohatu ki roto ki tona rae. Na hinga tapapa iho ana ia ki te whenua.
50 Dafidi yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí Filistini pẹ̀lú kànnàkànnà àti òkúta, láìsí idà ní ọwọ́ rẹ̀, ó lu Filistini, ó sì pa á.
Heoi he kotaha, he kohatu ta Rawiri, a hinga ana i a ia te Pirihitini, patua ana e ia, mate rawa. Otiia kahore he hoari i te ringa o Rawiri
51 Dafidi sì sáré ó sì dúró lórí rẹ̀. Ó sì mú idà Filistini, ó sì fà á yọ nínú àkọ̀ ọ rẹ̀. Lẹ́yìn ìgbà tí ó ti pa á tan, ó sì gé orí rẹ̀ pẹ̀lú idà. Nígbà tí àwọn ará Filistini rí i wí pé akọni wọn ti kú, wọ́n yípadà wọ́n sì sálọ.
Katahi ka rere a Rawiri, a tu ana i runga i te Pirihitini, na ka mau ki tana hoari, unuhia ana e ia i roto i te takotoranga, na whakamatea ana ia, a tapahia ana tona upoko ki taua hoari. A, no te kitenga o nga Pirihitini kua mate to ratou toa, w hati ana ratou.
52 Nígbà náà, àwọn ọkùnrin Israẹli àti ti Juda súnmọ́ iwájú pẹ̀lú ariwo, wọ́n sì lépa àwọn ará Filistini dé ẹnu ibodè Gati àti títí dé ẹnu ibodè Ekroni. Àwọn tí ó kú wà káàkiri ẹ̀gbẹ́ ọ̀nà Ṣaaraimu àti títí dé ọ̀nà Gati àti Ekroni.
Na ka whakatika nga tangata o Iharaira ratou ko Hura, hamama ana, na whaia ana e ratou nga Pirihitini a tae noa koe ki te raorao, ki nga kuwaha o Ekerono. Na hinga ana nga mea i patua o nga Pirihitini i te ara ki Haaraimi a tae noa ki Kata, ki E kerono.
53 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli sì padà láti máa lé àwọn ará Filistini, wọ́n sì ba ibùdó wọn jẹ́.
Na ka hoki nga tama a Iharaira i te whai i nga Pirihitini, na kei te pahua i to ratou puni.
54 Dafidi gé orí Filistini ó sì gbé e wá sí Jerusalẹmu, ó sì kó àwọn ohun ìjà Filistini sínú àgọ́ tirẹ̀.
Na ka mau a Rawiri ki te upoko o te Pirihitini, a kawea ana ki Hiruharama: ko ana mea ia mo te patu i waiho e ia i tona teneti.
55 Bí Saulu sì ti wo Dafidi bí ó ṣe ń jáde lọ pàdé Filistini, ó wí fún Abneri, olórí àwọn ológun rẹ̀ pé, “Abneri, ọmọ ta ni ọmọdékùnrin yìí?” Abneri dáhùn pe, “Bí ọkàn rẹ̀ ti ń bẹ ní ààyè, ọba èmi kò mọ̀.”
Na, i te kitenga o Haora i a Rawiri e haere atu ana ki te tu i te Pirihitini, ka mea ia ki a Apanere, ki te rangatira ope, E Apanere, he tama na wai tena tamaiti? ka mea a Apanere, E ora ana tou wairua, e te kingi, kahore ahau e mohio.
56 Ọba sì wí pé, “Wádìí ọmọ ẹni tí ọmọdékùnrin náà ń ṣe.”
Na ka mea te kingi, Ui atu he tama na wai taua tamaiti.
57 Kété tí ó dé láti ibi tí ó ti lọ pa Filistini, Abneri sì mú u wá síwájú Saulu, orí Filistini sì wà ní ọwọ́ Dafidi.
Na i te hokinga mai o Rawiri i te patu i te Pirihitini, ka mau a Apanere ki a ia, a kawea ana ki te aroaro o Haora, me te pane ano o te Pirihitini i tona ringa.
58 Saulu béèrè pé, “Ọmọdékùnrin, ọmọ ta ni ọ́?” Dafidi dáhùn pé, “Èmi ni ọmọ ìránṣẹ́ rẹ Jese ti Bẹtilẹhẹmu.”
Na ka mea a Haora ki a ia, E tama, na wai koe tamaiti? Ano ra ko Rawiri, He tama ahau na tau pononga, na Hehe o Peterehema.

< 1 Samuel 17 >