< 1 Samuel 16 >
1 Olúwa sọ fún Samuẹli pé, “Yóò ha ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò máa dárò Saulu, nígbà tí ó jẹ́ pé mo ti kọ̀ ọ́ ní ọba lórí Israẹli? Rọ òróró kún inú ìwo rẹ, kí o sì mú ọ̀nà rẹ pọ̀n, Èmi rán ọ sí Jese ará Bẹtilẹhẹmu. Èmi ti yan ọ̀kan lára àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ ọba.”
RAB Samuel'e, “Ben Saul'un İsrail Kralı olmasını reddettim diye sen daha ne zamana dek onun için üzüleceksin?” dedi, “Yağ boynuzunu yağla doldurup yola çık. Seni Beytlehemli İşay'ın evine gönderiyorum. Çünkü onun oğullarından birini kral seçtim.”
2 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Báwo ni èmi yóò ṣe lọ? Bí Saulu bá gbọ́ nípa rẹ̀, yóò pa mi.” Olúwa wí pé, “Mú abo ẹgbọrọ màlúù kan pẹ̀lú rẹ, kí o sì wí pé, ‘Èmi wá láti wá rú ẹbọ sí Olúwa.’
Samuel, “Nasıl gidebilirim? Saul bunu duyarsa beni öldürür!” dedi. RAB şöyle yanıtladı: “Yanına bir düve al ve, ‘RAB'be kurban sunmak için geldim’ de.
3 Pe Jese wá sí ibi ìrúbọ náà, Èmi yóò sì fi ohun tí ìwọ yóò ṣe hàn ọ́. Ìwọ yóò fi òróró yàn fún mi, ẹni tí èmi bá fihàn ọ́.”
İşay'ı kurban törenine çağır. O zaman ne yapman gerektiğini ben sana bildireceğim. Sana belirteceğim kişiyi benim adıma kral olarak meshedeceksin.”
4 Samuẹli ṣe ohun tí Olúwa sọ. Nígbà tí ó dé Bẹtilẹhẹmu, àyà gbogbo àgbàgbà ìlú já, nígbà tí wọ́n pàdé rẹ̀. Wọ́n béèrè pé, “Ṣé àlàáfíà ní ìwọ bá wá?”
Samuel RAB'bin sözüne uyarak Beytlehem Kenti'ne gitti. Kentin ileri gelenleri onu titreyerek karşıladılar ve, “Barış için mi geldin?” diye sordular.
5 Samuẹli sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni àlàáfíà ni; mo wá láti wá rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ ya ara yín sí mímọ́, kí ẹ sì wá rú ẹbọ pẹ̀lú mi.” Nígbà náà ni ó sì ya Jese sí mímọ́ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì pè wọ́n wá sí ibi ìrúbọ náà.
Samuel, “Evet, barış için” diye yanıtladı, “RAB'be kurban sunmaya geldim. Kendinizi kutsayıp benimle birlikte kurban törenine gelin.” Sonra İşay ile oğullarını kutsayıp kurban törenine çağırdı.
6 Nígbà tí wọ́n dé, Samuẹli rí Eliabu, ó rò nínú ara rẹ̀ pé lóòótọ́ ẹni òróró Olúwa dúró níbí níwájú Olúwa.
İşay ile oğulları gelince Samuel Eliav'ı gördü ve, “Gerçekten RAB'bin önünde duran bu adam O'nun meshettiği kişidir” diye düşündü.
7 Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Samuẹli pé, “Má ṣe wo ti ìrísí rẹ̀ tàbí ti gíga rẹ̀, nítorí èmi ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Olúwa kì í wo ohun tí ènìyàn máa ń wò. Ènìyàn máa ń wo òde ara ṣùgbọ́n Olúwa máa ń wo ọkàn.”
Ama RAB Samuel'e, “Onun yakışıklı ve uzun boylu olduğuna bakma” dedi, “Ben onu reddettim. Çünkü RAB insanın gördüğü gibi görmez; insan dış görünüşe, RAB ise yüreğe bakar.”
8 Nígbà náà ni Jese pe Abinadabu, ó sì jẹ́ kí ó rìn kọjá ní iwájú Samuẹli. Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Olúwa kò yan ẹni yìí.”
İşay, oğlu Avinadav'ı çağırıp Samuel'in önünden geçirdi. Ama Samuel, “RAB bunu da seçmedi” dedi.
9 Jese sì jẹ́ kí Ṣamma rìn kọjá ní iwájú Samuẹli, ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Olúwa kò yan ẹni yìí náà.”
Bunun üzerine İşay Şamma'yı da geçirdi. Samuel yine, “RAB bunu da seçmedi” dedi.
10 Jese jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ méje rìn kọjá ní iwájú Samuẹli ṣùgbọ́n Samuẹli sọ fún un pé, “Olúwa kò yan àwọn wọ̀nyí.”
Böylece İşay yedi oğlunu da Samuel'in önünden geçirdi. Ama Samuel, “RAB bunlardan hiçbirini seçmedi” dedi.
11 Nígbà náà ni ó béèrè lọ́wọ́ Jese pé, “Ṣé èyí ni gbogbo àwọn ọmọ rẹ?” Jese dáhùn pé, “Ó ku àbíkẹ́yìn wọn, ó ń tọ́jú agbo àgùntàn.” Samuẹli sì wí pé, “Rán ìránṣẹ́ lọ pè é wá; àwa kò ní jókòó títí òun yóò fi dé.”
Sonra İşay'a, “Oğullarının hepsi bunlar mı?” diye sordu. İşay, “Bir de en küçüğü var” dedi, “Sürüyü güdüyor.” Samuel, “Birini gönder de onu getirsin” dedi, “O buraya gelmeden yemeğe oturmayacağız.”
12 Ó sì ránṣẹ́ sí i, wọ́n sì mú un wọlé wá, ó jẹ́ ẹni tó mọ́ra, àwọ̀ ara rẹ̀ dùn ún wò, ó jẹ́ arẹwà gidigidi. Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Dìde kí o sì fi òróró yàn án, òun ni ẹni náà.”
İşay birini gönderip oğlunu getirtti. Çocuk kızıl saçlı, yakışıklı, gözleri pırıl pırıl bir delikanlıydı. RAB Samuel'e, “Kalk, onu meshet. Seçtiğim kişi odur” dedi.
13 Nígbà náà ni Samuẹli mú ìwo òróró, ó sì ta á sí i ní orí ní iwájú àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀, láti ọjọ́ náà lọ, Ẹ̀mí Mímọ́ Olúwa wá sí orí Dafidi nínú agbára. Samuẹli sì lọ sí Rama.
Samuel yağ boynuzunu alıp kardeşlerinin önünde çocuğu meshetti. O günden başlayarak RAB'bin Ruhu Davut'un üzerine güçlü bir biçimde indi. Bundan sonra Samuel kalkıp Rama'ya döndü.
14 Nísinsin yìí, ẹ̀mí Olúwa ti kúrò lára Saulu, ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Olúwa sì ń yọ ọ́ lẹ́nu.
Bu sıralarda RAB'bin Ruhu Saul'dan ayrılmıştı. RAB'bin gönderdiği kötü bir ruh ona sıkıntı çektiriyordu.
15 Àwọn ìránṣẹ́ Saulu sì wí fún un pé, “Wò ó, ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ń yọ ọ́ lẹ́nu.
Hizmetkârları Saul'a, “Bak, Tanrı'nın gönderdiği kötü bir ruh sana sıkıntı çektiriyor” dediler,
16 Jẹ́ kí olúwa wa pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó wà níhìn-ín láti wa ẹnìkan tí ó lè fi dùùrù kọrin. Yóò sì ṣe é nígbà tí ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run bá bà lé ọ, ìwọ yóò sì sàn.”
“Efendimiz, biz hizmetkârlarına buyruk ver, iyi lir çalan birini bulalım. Öyle ki, Tanrı'nın gönderdiği kötü ruh üzerine gelince, o lir çalar, sen de rahatlarsın.”
17 Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ wá ẹnìkan tí ó lè kọrin dáradára kí ẹ sì mú u wá fún mi.”
Saul hizmetkârlarına, “İyi lir çalan birini bulup bana getirin” diye buyurdu.
18 Ọ̀kan nínú ìránṣẹ́ náà dáhùn pé, “Èmi ti ri ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Jese ti Bẹtilẹhẹmu tí ó mọ orin kọ, ó jẹ́ alágbára àti ológun. Ó ní ọgbọ́n ọ̀rọ̀ òun sì dára ní wíwò. Olúwa sì wà pẹ̀lú u rẹ̀.”
Hizmetkârlardan biri, “Beytlehemli İşay'ın oğullarından birini gördüm” dedi, “İyi lir çalar. Üstelik yürekli, güçlü bir savaşçıdır; akıllıca konuşur, yakışıklıdır. RAB de onunladır.”
19 Saulu sì rán oníṣẹ́ sí Jese wí pé, “Rán Dafidi ọmọ rẹ sí mi, ẹni tí ó ń ṣọ́ àgùntàn.”
Bunun üzerine Saul İşay'a ulaklar göndererek, “Sürüyü güden oğlun Davut'u bana gönder” dedi.
20 Jese sì mú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ti a di ẹrù lé àti ìgò ọtí wáìnì àti ọmọ ewúrẹ́; ó sì rán wọn nípa ọwọ́ Dafidi ọmọ rẹ̀ sí Saulu.
İşay ekmek yüklü bir eşek, bir tulum şarap, bir de oğlak alıp oğlu Davut'la birlikte Saul'a gönderdi.
21 Dafidi sì tọ Saulu lọ, ó sì dúró níwájú rẹ̀, òun sì fẹ́ ẹ gidigidi, Dafidi sì wá di ọ̀kan nínú àwọn tí ń ru ìhámọ́ra rẹ̀.
Davut Saul'un yanına varıp onun hizmetine girdi. Saul Davut'u çok sevdi ve ona silahlarını taşıma görevini verdi.
22 Nígbà náà ni Saulu ránṣẹ́ sí Jese pé, “Jẹ́ kí Dafidi dúró níwájú mi, nítorí tí ó wù mí.”
Saul İşay'a şu haberi gönderdi: “İzin ver de Davut hizmetimde kalsın; ondan hoşnudum.”
23 Ó sì ṣe, nígbà tí ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá bá dé sí Saulu, Dafidi a sì fi ọwọ́ rẹ̀ kọrin lára dùùrù: a sì san fún Saulu, ara rẹ̀ a sì dá; ẹ̀mí búburú náà a sì fi sílẹ̀.
O günden sonra, Tanrı'nın gönderdiği kötü ruh ne zaman Saul'un üzerine gelse, Davut liri alıp çalar, Saul rahatlayıp kendine gelirdi. Kötü ruh da ondan uzaklaşırdı.