< 1 Samuel 15 >

1 Samuẹli wí fún Saulu pé, “Èmi ni Olúwa rán láti fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli; fetísílẹ̀ láti gbọ́ iṣẹ́ tí Olúwa rán mi sí ọ́.
Əmdi Samuil Saulƣa: — Pǝrwǝrdigar seni Ɵz hǝlⱪi Israil üstigǝ padixaⱨ bolux üqün mǝsiⱨ ⱪilƣili meni ǝwǝtkǝnidi; ǝmdi Pǝrwǝrdigarning sɵzini angliƣin.
2 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi yóò jẹ àwọn Amaleki ní yà fún ohun tí wọ́n ti ṣe sí Israẹli nígbà tí wọn dè wọn lọ́nà nígbà tí wọn ń bọ̀ láti Ejibiti.
Samawi ⱪoxunlarning Sǝrdari bolƣan Pǝrwǝrdigar mundaⱪ dǝydu: — Mǝn Amalǝklǝrning Israilƣa ⱪilƣan muamilisini, yǝni Israil Misirdin qiⱪⱪanda ularning yolda ularƣa ⱪandaⱪ ⱪarxiliⱪ kɵrsǝtkǝnlikini kɵnglümgǝ pükkǝnmǝn.
3 Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọlu Amaleki, kí o sì pa gbogbo ohun tí ó bá jẹ́ tiwọn ní à parun. Má ṣe dá wọn sí, pa ọkùnrin àti obìnrin wọn, ọmọ kékeré àti ọmọ ọmú, màlúù àti àgùntàn, ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.’”
Əmdi berip Amalǝklǝrni urup ularning ⱨǝmmisini wǝyran ⱪilip ularni ⱨeq ayimayla, ǝr bolsun, ayal bolsun, ɵsmür bolsun, bowaⱪ bolsun, kala-ⱪoy, tɵgǝ wǝ ixǝk ⱨǝmmisini yoⱪatⱪin, dedi.
4 Bẹ́ẹ̀ ni Saulu kó àwọn ènìyàn jọ, ó sì ka iye wọn ní Talaemu, wọ́n sì jẹ́ ogún ọ̀kẹ́ àwọn ológun ẹlẹ́ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Juda.
Saul hǝlⱪni jǝm ⱪilip ularni Tǝlaim xǝⱨiridǝ saniwidi, ikki yüz ming piyadǝ ǝskǝr, Yǝⱨuda ⱪǝbilisidin on ming adǝm qiⱪti.
5 Saulu sì lọ sí ìlú Amaleki ó sì gọ dè wọ́n ní àfonífojì kan.
Saul Amalǝklǝrning xǝⱨirigǝ kǝlgǝndǝ xu yǝrdiki wadida bɵktürmǝ ⱪoydi.
6 Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ará Keni pé, “Ẹ lọ, kúrò ní Amaleki kí èmi má ba à run yín pẹ̀lú wọn; nítorí ẹ̀yin fi àánú hàn fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n gòkè ti Ejibiti wá.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Kenaiti lọ kúrò láàrín àwọn Amaleki.
Andin Saul Keniylǝrgǝ: — Qiⱪip ketinglar, silǝrni ular bilǝn ⱪoxup yoⱪatmasliⱪim üqün Amalǝklǝrning arisidin qiⱪip ketinglar; qünki Israil Misirdin qiⱪⱪanda silǝr ularning ⱨǝmmisigǝ meⱨribanliⱪ kɵrsǝtkǝnsilǝr, dedi. Xuning bilǝn Keniylǝr Amalǝklǝrdin qiⱪip kǝtti.
7 Nígbà náà ni Saulu kọlu àwọn Amaleki láti Hafila dé Ṣuri, tí ó fi dé ìlà-oòrùn Ejibiti.
Əmdi Saul Amalǝklǝrni Ⱨawilaⱨdin tartip Misirning udulidiki Xurƣiqǝ ⱪoƣlap urdi.
8 Ó sì mú Agagi ọba Amaleki láààyè, ó sì fi idà rẹ̀ kọlù gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀.
U Amalǝklǝrning padixaⱨi Agagni tirik tutti, ǝmma barliⱪ hǝlⱪni ⱪiliq bisi bilǝn pütünlǝy yoⱪatti.
9 Ṣùgbọ́n Saulu àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ dá Agagi sí àti èyí tí ó dára jùlọ nínú àgùntàn àti màlúù àti ọ̀dọ́-àgùntàn àbọ́pa àti gbogbo nǹkan tó dára. Wọ́n kò sì fẹ́ pa àwọn wọ̀nyí run pátápátá ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan tí kò dára tí kò sì níláárí ni wọ́n parun pátápátá.
Lekin Saul bilǝn hǝlⱪ Agagni ayidi wǝ ⱪoy-kala, bordalƣan mal wǝ ⱪozilardin ǝng esillǝrning ⱨǝmmisini, jümlidin nemǝ yahxi bolsa xuni ayap ularni ⱨalak ⱪilixⱪa ⱪoli barmidi; lekin nemǝ yarimas wǝ zǝip bolsa xularning ⱨǝmmisini ular yoⱪatti.
10 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Samuẹli wá pé,
Xuning bilǝn Pǝrwǝrdigarning sɵzi Samuilƣa kelip mundaⱪ deyildi: —
11 “Èmi káàánú gidigidi pé mo fi Saulu jẹ ọba, nítorí pé ó ti yípadà kúrò lẹ́yìn mi, kò sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́.” Inú Samuẹli sì bàjẹ́ gidigidi, ó sì ké pe Olúwa ní gbogbo òru náà.
«Saulni padixaⱨ ⱪilƣinimƣa puxayman ⱪildim, qünki u manga ǝgixixtin yenip Mening sɵzümgǝ ǝmǝl ⱪilmidi». Samuil azar qekip pütkül bir keqǝ Pǝrwǝrdigarƣa pǝryad kɵtürdi.
12 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Samuẹli sì dìde láti lọ pàdé Saulu, ṣùgbọ́n wọ́n sọ fún un pé, “Saulu ti wá sí Karmeli. Ó ti kọ́ ibìkan fún ara rẹ̀ níbẹ̀, ó sì ti yípadà, ó sì ti sọ̀kalẹ̀ lọ sí Gilgali.”
Ətisi Samuil Saulning aldiƣa qiⱪix üqün tang sǝⱨǝrdila ornidin turdi. Samuilƣa: — Saul Karmǝlgǝ bardi wǝ mana, u ɵzigǝ bir abidǝ turƣuzup andin yenip Gilgalƣa qüxüptu, degǝn hǝwǝr berildi.
13 Nígbà tí Samuẹli sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Saulu sì wí fún un pé, “Olúwa bùkún fún ọ, mo ti ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ.”
Samuil Saulning ⱪexiƣa kǝlgǝndǝ Saul uningƣa: — Pǝrwǝrdigar seni mubarǝkligǝy! Pǝrwǝrdigarning sɵzlirigǝ ǝmǝl ⱪildim, dedi.
14 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Èwo wá ni igbe àgùntàn tí mo ń gbọ́ ní etí mi? Kí ni igbe màlúù ti mo ń gbọ́ yìí?”
Lekin Samuil: — Undaⱪ bolsa ⱪuliⱪimƣa anglanƣan ⱪoyning mǝrixi bilǝn mǝn anglawatⱪan kalining mɵrixi zadi nǝdin kǝldi? — dedi.
15 Saulu sì dáhùn pé, “Àwọn ọmọ-ogun ní o mú wọn láti Amaleki wá, wọ́n dá àwọn àgùntàn, àti màlúù tí ó dára jùlọ sí láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ṣùgbọ́n a pa àwọn tókù run pátápátá.”
Saul jawab berip: — Ular Amalǝklǝrdin elip kelindi; qünki hǝlⱪ Hudaying Pǝrwǝrdigarƣa ⱪurbanliⱪ ⱪilix üqün ⱪoy-kalining esillirini ayap ⱪaldurup ⱪoydi; ⱪalƣinini bolsa pütünlǝy yoⱪattuⱪ, dedi.
16 Samuẹli sí wí fún Saulu pé, “Dákẹ́ ná, jẹ́ kí èmi kí ó sọ ohun tí Olúwa wí fún mi ní alẹ́ àná fún ọ.” Saulu sì wí pé, “Sọ fún mi.”
Samuil Saulƣa: — Ⱪoy, bu gepingni! Mǝn Pǝrwǝrdigarning bu keqǝ manga nemǝ deginini sanga eytip berǝy, dedi. U uningƣa: — Eytⱪin, dedi.
17 Samuẹli sì wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ fi ìgbà kan kéré lójú ara rẹ, ǹjẹ́ ìwọ kò ha di olórí ẹ̀yà Israẹli? Olúwa fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.
Samuil mundaⱪ dedi: — Ɵz nǝziringdǝ kiqik ⱨesablanƣan waⱪtingdila Pǝrwǝrdigar seni Israilning üstigǝ padixaⱨ bolsun dǝp, mǝsiⱨ ⱪilixi bilǝn sǝn Israil ⱪǝbililirining bexi bolƣan ǝmǝsmiding?
18 Olúwa sì rán ọ níṣẹ́ wí pé, ‘Lọ, kí o sì pa àwọn ènìyàn búburú ará Amaleki run pátápátá; gbóguntì wọ́n títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’
Andin Pǝrwǝrdigar seni: — Sǝn berip gunaⱨkar Amalǝklǝrni ⱨalak ⱪilƣin; ularni yoⱪatⱪuqǝ ular bilǝn soⱪuxⱪin, dǝp ǝwǝtkǝnidi.
19 Èéṣe tí ìwọ kò fi gbọ́ ti Olúwa? Èéṣe tí ìwọ fi sáré sí ìkógun tí o sì ṣe búburú níwájú Olúwa?”
Əmdi nemixⱪa Pǝrwǝrdigarning sɵzigǝ ⱪulaⱪ salmay, bǝlki olja üstigǝ düm qüxüp, Pǝrwǝrdigarning nǝziridǝ yaman bolƣanni ⱪilding?
20 Saulu sì wí fún Samuẹli pé, “Ṣùgbọ́n èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa, èmi sì ti lọ ní ọ̀nà tí Olúwa rán mi. Mo sì ti pa àwọn ará Amaleki run pátápátá, mo sì ti mú Agagi ọba wọn padà wá.
Saul Samuilƣa: — Mǝn ⱨǝⱪiⱪǝtǝn Pǝrwǝrdigarning sɵzigǝ ⱪulaⱪ saldimƣu! Pǝrwǝrdigar meni ǝwǝtkǝn yol bilǝn mangdim wǝ Amalǝklǝrning padixaⱨi Agagni elip kelip Amalǝklǝrning ɵzini pütünlǝy yoⱪattim.
21 Àwọn ọmọ-ogun ti mú àgùntàn àti màlúù lára ìkógun èyí tí ó dára láti fi fún Olúwa láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní Gilgali.”
Əmma hǝlⱪ bolsa oljidin ⱪoy bilǝn kala, yǝni yoⱪitixⱪa bekitilgǝn nǝrsilǝrdin ǝng esilini elip Hudaying Pǝrwǝrdigarƣa Gilgalda ⱪurbanliⱪ ⱪilix üqün elip kǝldi, dedi.
22 Ṣùgbọ́n Samuẹli dáhùn pé, “Olúwa ha ní inú dídùn sí ẹbọ sísun àti ẹbọ ju kí a gba ohùn Olúwa gbọ́? Ìgbọ́ràn sàn ju ẹbọ lọ, ìfetísílẹ̀ sì sàn ju ọ̀rá àgbò lọ.
Samuil: — Pǝrwǝrdigar kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪlar bilǝn tǝxǝkkür ⱪurbanliⱪlirini kǝltürüxtin sɵyünǝmdu, ya Pǝrwǝrdigarning sɵzigǝ itaǝt ⱪilixtin süyünǝmdu? Mana itaǝt ⱪilmaⱪliⱪ ⱪurbanliⱪ ⱪilmaⱪliⱪtin ǝwzǝl, kɵngül ⱪoyux ⱪoqⱪar yeƣini sunuxtin ǝwzǝldur.
23 Nítorí pé ìṣọ̀tẹ̀ dàbí ẹ̀ṣẹ̀ àfọ̀ṣẹ, àti ìgbéraga bí ẹ̀ṣẹ̀ ìbọ̀rìṣà. Nítorí tí ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa, Òun sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba.”
Qünki asiyliⱪ bolsa jadugǝrlik gunaⱨi bilǝn ohxaxtur, Baxpaxtaⱪliⱪ ⱪǝbiⱨlik wǝ butpǝrǝslikkǝ barawǝrdur. Sǝn Pǝrwǝrdigarning sɵzini taxliƣining üqün, Pǝrwǝrdigar seni taxlap padixaⱨliⱪtin mǝⱨrum ⱪildi, — dedi.
24 Nígbà náà ni Saulu wí fún Samuẹli pé, “Èmi ti ṣẹ̀. Mo ti rú òfin Olúwa àti ọ̀rọ̀ rẹ̀. Èmi sì bẹ̀rù àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ ni èmi sì gba ohùn wọn gbọ́.
Saul Samuilƣa: — Mǝn gunaⱨ sadir ⱪildim, qünki mǝn Pǝrwǝrdigarning ǝmridin wǝ sening sɵzüngdinmu qiⱪtim; qünki mǝn hǝlⱪtin ⱪorⱪup ularning sɵzigǝ kirdim.
25 Mo bẹ̀ ọ́ nísinsin yìí, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì, kí ó sì yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè sin Olúwa.”
Əmdi gunaⱨimni ǝpu ⱪilƣin; mening Pǝrwǝrdigarƣa sǝjdǝ ⱪilixim üqün mening bilǝn ⱪaytip barƣin, dedi.
26 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí fún un pé, “Èmi kò ní bá ọ padà. Ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa sílẹ̀, Olúwa sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba lórí Israẹli!”
Samuil Saulƣa: — Mǝn sening bilǝn ⱪaytip barmaymǝn; qünki sǝn Pǝrwǝrdigarning sɵzini taxliƣansǝn, wǝ Pǝrwǝrdigar seni taxlap padixaⱨliⱪtin mǝⱨrum ⱪildi, dedi.
27 Bí Samuẹli sì ti fẹ́ yípadà láti lọ, Saulu sì di ẹ̀wù ìlekè rẹ̀ mú, ó sì fàya;
Samuil ketixkǝ burulƣinida Saul uning tonining pexini tutuwaldi, u yirtilip kǝtti.
28 Samuẹli sì wí fún un pé, “Olúwa ti fa ìjọba Israẹli ya kúrò lọ́wọ́ ọ̀ rẹ lónìí, ó sì ti fi fún aládùúgbò rẹ kan tí ó sàn jù ọ́ lọ.
Samuil uningƣa: — Pǝrwǝrdigar bügün Israilning padixaⱨliⱪini sǝndin yirtip elip sǝndin ǝwzǝl bolƣan bir yeⱪiningƣa tapxurdi.
29 Ẹni tí ó ń ṣe ògo Israẹli, kì í purọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì í yí ọkàn rẹ̀ padà; nítorí kì í ṣe ènìyàn tí yóò yí ọkàn rẹ̀ padà.”
Israilning Janabiy Aliyisi Bolƣuqi yalƣan sɵzlimǝydu yaki niyitidin yanmaydu; qünki u adǝm balisidǝk niyitidin yanƣuqi ǝmǝstur, dedi.
30 Saulu sì wí pé, “Èmi ti ṣẹ̀, ṣùgbọ́n jọ̀wọ́ bu ọlá fún mi níwájú àwọn àgbàgbà ènìyàn mi, àti níwájú u Israẹli, yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè tẹríba fún Olúwa Ọlọ́run rẹ.”
Saul: — Mǝn gunaⱨ sadir ⱪildim. Lekin hǝlⱪimning aⱪsaⱪallirining wǝ Israilning aldida manga izzǝt ⱪilip mening bilǝn yenip barƣin; xuning bilǝn Hudaying Pǝrwǝrdigarƣa sǝjdǝ ⱪilalaymǝn, dedi.
31 Bẹ́ẹ̀ ni Samuẹli sì yípadà pẹ̀lú Saulu, Saulu sì sin Olúwa.
Xuning bilǝn Samuil Saul bilǝn yenip bardi wǝ Saul Pǝrwǝrdigarƣa sǝjdǝ ⱪildi.
32 Nígbà náà ni Samuẹli wí pé, “Mú Agagi ọba àwọn ará Amaleki wá fún mi.” Agagi sì tọ̀ ọ́ wá ní ìgboyà pẹ̀lú èrò pé, “Nítòótọ́ ìkorò ikú ti kọjá.”
Andin Samuil: — Amalǝklǝrning padixaⱨi Agagni mening aldimƣa elip kelinglar, dedi. Agag bolsa huxluⱪ bilǝn uning ⱪexiƣa bardi. Agag kɵnglidǝ: — Xübⱨisizki, ɵlüm dǝⱨxiti ɵtüp kǝtti, dedi.
33 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Bí idà rẹ ti sọ àwọn obìnrin di aláìní ọmọ bẹ́ẹ̀ ni ìyá rẹ yóò sì di aláìní ọmọ láàrín obìnrin.” Samuẹli sì pa Agagi níwájú Olúwa ni Gilgali.
Əmma Samuil: — Sening ⱪiliqing hotunlarni balisiz ⱪilƣandǝk sening anangmu hotunlarning arisida balisiz bolidu, dewidi, Samuil Agagni Gilgalda Pǝrwǝrdigarning aldida qanap parǝ-parǝ ⱪildi.
34 Nígbà náà ni Samuẹli lọ sí Rama, Saulu sì gòkè lọ sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah tí Saulu.
Andin Samuil Ramaⱨⱪa bardi. Saul bolsa «Saulning yurti Gibeaⱨ» degǝn jaydiki ɵyigǝ qiⱪip kǝtti.
35 Samuẹli kò sì padà wá mọ́ láti wo Saulu títí ó fi di ọjọ́ ikú u rẹ̀, ṣùgbọ́n Samuẹli káàánú fún Saulu. Ó sì dun Olúwa pé ó fi Saulu jẹ ọba lórí Israẹli.
Samuil ɵlgǝn künigiqǝ Saul bilǝn ⱪayta kɵrüxmidi. Əmma Samuil Saul üqün ⱪayƣurdi. Pǝrwǝrdigar Saulni Israilning üstigǝ padixaⱨ ⱪilƣanliⱪidin ǝpsuslandi.

< 1 Samuel 15 >