< 1 Samuel 15 >

1 Samuẹli wí fún Saulu pé, “Èmi ni Olúwa rán láti fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli; fetísílẹ̀ láti gbọ́ iṣẹ́ tí Olúwa rán mi sí ọ́.
Samuel je tudi rekel Savlu: » Gospod me je poslal, da te mazilim, da bi bil kralj nad njegovim ljudstvom, nad Izraelom. Sedaj torej prisluhni glasu Gospodovih besed.
2 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi yóò jẹ àwọn Amaleki ní yà fún ohun tí wọ́n ti ṣe sí Israẹli nígbà tí wọn dè wọn lọ́nà nígbà tí wọn ń bọ̀ láti Ejibiti.
Tako govori Gospod nad bojevniki: ›Spomnim se tega, kar je Amálek storil Izraelu, kako je prežal nanj na poti, ko je prišel gor iz Egipta.
3 Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọlu Amaleki, kí o sì pa gbogbo ohun tí ó bá jẹ́ tiwọn ní à parun. Má ṣe dá wọn sí, pa ọkùnrin àti obìnrin wọn, ọmọ kékeré àti ọmọ ọmú, màlúù àti àgùntàn, ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.’”
Sedaj pojdi in udari Amáleka in popolnoma uniči vse, kar imajo in ne prizanesi jim, temveč ubij tako moškega kakor žensko, otroka in dojenčka, vola in ovco, kamelo in osla.‹«
4 Bẹ́ẹ̀ ni Saulu kó àwọn ènìyàn jọ, ó sì ka iye wọn ní Talaemu, wọ́n sì jẹ́ ogún ọ̀kẹ́ àwọn ológun ẹlẹ́ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Juda.
Savel je ljudstvo zbral skupaj in jih preštel v Telaímu, dvesto tisoč pešcev in deset tisoč mož iz Juda.
5 Saulu sì lọ sí ìlú Amaleki ó sì gọ dè wọ́n ní àfonífojì kan.
Savel je prišel do mesta Amálečanov in prežal v dolini.
6 Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ará Keni pé, “Ẹ lọ, kúrò ní Amaleki kí èmi má ba à run yín pẹ̀lú wọn; nítorí ẹ̀yin fi àánú hàn fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n gòkè ti Ejibiti wá.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Kenaiti lọ kúrò láàrín àwọn Amaleki.
Savel je Kenéjcem rekel: »Pojdite, odidite dol izmed Amálečanov, da vas ne bi uničil z njimi, kajti izkazali ste prijaznost vsem Izraelovim otrokom, ko so prišli gor iz Egipta.« Tako so Kenéjci odšli izmed Amalečanov.
7 Nígbà náà ni Saulu kọlu àwọn Amaleki láti Hafila dé Ṣuri, tí ó fi dé ìlà-oòrùn Ejibiti.
Savel je udaril Amalečane od Havíle, dokler ne prideš do Šura, ki je nasproti Egiptu.
8 Ó sì mú Agagi ọba Amaleki láààyè, ó sì fi idà rẹ̀ kọlù gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀.
Agága, kralja Amalečanov, je zajel živega in z ostrino meča popolnoma uničil vse ljudstvo.
9 Ṣùgbọ́n Saulu àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ dá Agagi sí àti èyí tí ó dára jùlọ nínú àgùntàn àti màlúù àti ọ̀dọ́-àgùntàn àbọ́pa àti gbogbo nǹkan tó dára. Wọ́n kò sì fẹ́ pa àwọn wọ̀nyí run pátápátá ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan tí kò dára tí kò sì níláárí ni wọ́n parun pátápátá.
Toda Savel in ljudstvo je prizaneslo Agágu in najboljšemu od ovc, od volov, od pitancev in jagnjet in vsega, kar je bilo dobro in niso jih želeli popolnoma uničiti. Toda vsako stvar, ki je bila ničvredna in zavrnjena, to so popolnoma uničili.
10 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Samuẹli wá pé,
Potem je prišla Gospodova beseda Samuelu, rekoč:
11 “Èmi káàánú gidigidi pé mo fi Saulu jẹ ọba, nítorí pé ó ti yípadà kúrò lẹ́yìn mi, kò sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́.” Inú Samuẹli sì bàjẹ́ gidigidi, ó sì ké pe Olúwa ní gbogbo òru náà.
»To me je pokesalo, da sem postavil Savla, da bi bil kralj, kajti obrnil se je nazaj od sledenja meni in ni izvršil mojih zapovedi.« To je užalostilo Samuela in ta je vso noč klical h Gospodu.
12 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Samuẹli sì dìde láti lọ pàdé Saulu, ṣùgbọ́n wọ́n sọ fún un pé, “Saulu ti wá sí Karmeli. Ó ti kọ́ ibìkan fún ara rẹ̀ níbẹ̀, ó sì ti yípadà, ó sì ti sọ̀kalẹ̀ lọ sí Gilgali.”
Ko je Samuel zgodaj vstal, da bi zjutraj srečal Savla, je bilo Samuelu povedano, rekoč: »Savel je prišel v Karmel in glej, postavil si je kraj in potem je šel naokrog, šel naprej in odšel dol do Gilgála.«
13 Nígbà tí Samuẹli sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Saulu sì wí fún un pé, “Olúwa bùkún fún ọ, mo ti ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ.”
Samuel je prišel k Savlu in Savel mu je rekel: »Blagoslovljen bodi od Gospoda. Izpolnil sem Gospodovo zapoved.«
14 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Èwo wá ni igbe àgùntàn tí mo ń gbọ́ ní etí mi? Kí ni igbe màlúù ti mo ń gbọ́ yìí?”
Samuel pa je rekel: »Kaj potem pomeni to blejanje ovc v mojih ušesih in mukanje volov, ki ga slišim?«
15 Saulu sì dáhùn pé, “Àwọn ọmọ-ogun ní o mú wọn láti Amaleki wá, wọ́n dá àwọn àgùntàn, àti màlúù tí ó dára jùlọ sí láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ṣùgbọ́n a pa àwọn tókù run pátápátá.”
Savel je rekel: »Privedli so jih od Amalečanov, kajti ljudstvo je prizaneslo najboljšim izmed ovc in izmed volov, da žrtvujejo Gospodu, tvojemu Bogu, preostalo pa smo popolnoma uničili.«
16 Samuẹli sí wí fún Saulu pé, “Dákẹ́ ná, jẹ́ kí èmi kí ó sọ ohun tí Olúwa wí fún mi ní alẹ́ àná fún ọ.” Saulu sì wí pé, “Sọ fún mi.”
Potem je Samuel rekel Savlu: »Ostani in povedal ti bom kaj mi je to noč povedal Gospod.« In rekel mu je: »Povej.«
17 Samuẹli sì wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ fi ìgbà kan kéré lójú ara rẹ, ǹjẹ́ ìwọ kò ha di olórí ẹ̀yà Israẹli? Olúwa fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.
Samuel je rekel: »Ko si bil majhen v svojem lastnem pogledu, ali nisi bil narejen za poglavarja Izraelovim rodovom in te je Gospod mazilil za kralja nad Izraelom?
18 Olúwa sì rán ọ níṣẹ́ wí pé, ‘Lọ, kí o sì pa àwọn ènìyàn búburú ará Amaleki run pátápátá; gbóguntì wọ́n títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’
Gospod te je poslal na pot in rekel: ›Pojdi in popolnoma uniči grešnike Amalečane in se bori proti njim, dokler ne bodo použiti.‹
19 Èéṣe tí ìwọ kò fi gbọ́ ti Olúwa? Èéṣe tí ìwọ fi sáré sí ìkógun tí o sì ṣe búburú níwájú Olúwa?”
Zakaj potem nisi ubogal Gospodovega glasu, temveč si se vrgel na plen in storil zlo v Gospodovih očeh?«
20 Saulu sì wí fún Samuẹli pé, “Ṣùgbọ́n èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa, èmi sì ti lọ ní ọ̀nà tí Olúwa rán mi. Mo sì ti pa àwọn ará Amaleki run pátápátá, mo sì ti mú Agagi ọba wọn padà wá.
Savel je rekel Samuelu: »Da, ubogal sem Gospodov glas in sem šel na pot, na katero me je poslal Gospod in privedel sem Agága, kralja Amalečanov in popolnoma sem uničil Amálečane.
21 Àwọn ọmọ-ogun ti mú àgùntàn àti màlúù lára ìkógun èyí tí ó dára láti fi fún Olúwa láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní Gilgali.”
Toda ljudstvo je vzelo od plena, ovce in vole, glavne izmed stvari, ki naj bi bile popolnoma uničene, da žrtvujejo Gospodu, tvojemu Bogu v Gilgálu.«
22 Ṣùgbọ́n Samuẹli dáhùn pé, “Olúwa ha ní inú dídùn sí ẹbọ sísun àti ẹbọ ju kí a gba ohùn Olúwa gbọ́? Ìgbọ́ràn sàn ju ẹbọ lọ, ìfetísílẹ̀ sì sàn ju ọ̀rá àgbò lọ.
Samuel je rekel: »Ali ima Gospod tako veliko zadovoljstvo v žgalnih daritvah in klavnih daritvah, kot v ubogljivosti Gospodovemu glasu? Glej, ubogati je bolje kot klavna daritev in poslušati [bolje] kot tolšča ovnov.
23 Nítorí pé ìṣọ̀tẹ̀ dàbí ẹ̀ṣẹ̀ àfọ̀ṣẹ, àti ìgbéraga bí ẹ̀ṣẹ̀ ìbọ̀rìṣà. Nítorí tí ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa, Òun sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba.”
Kajti upor je kakor greh čaranja in trmoglavost je kakor krivičnost in malikovanje. Ker si zavrnil Gospodovo besedo, je tudi on zavrnil tebe, da bi bil kralj.«
24 Nígbà náà ni Saulu wí fún Samuẹli pé, “Èmi ti ṣẹ̀. Mo ti rú òfin Olúwa àti ọ̀rọ̀ rẹ̀. Èmi sì bẹ̀rù àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ ni èmi sì gba ohùn wọn gbọ́.
Savel je rekel Samuelu: »Grešil sem, kajti prekršil sem Gospodovo zapoved in tvoje besede, ker sem se bal ljudstva in ubogal njihov glas.
25 Mo bẹ̀ ọ́ nísinsin yìí, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì, kí ó sì yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè sin Olúwa.”
Zdaj torej, prosim te, odpusti moj greh in se ponovno obrni z menoj, da lahko obožujem Gospoda.«
26 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí fún un pé, “Èmi kò ní bá ọ padà. Ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa sílẹ̀, Olúwa sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba lórí Israẹli!”
Samuel pa je rekel Savlu: »Ne bom se vrnil s teboj, kajti zavrnil si Gospodovo besedo in Gospod je zavrnil tebe, da bi bil kralj nad Izraelom.«
27 Bí Samuẹli sì ti fẹ́ yípadà láti lọ, Saulu sì di ẹ̀wù ìlekè rẹ̀ mú, ó sì fàya;
Medtem ko se je Samuel obrnil naokoli, da gre proč, je zgrabil krajec njegovega plašča in ga odtrgal.
28 Samuẹli sì wí fún un pé, “Olúwa ti fa ìjọba Israẹli ya kúrò lọ́wọ́ ọ̀ rẹ lónìí, ó sì ti fi fún aládùúgbò rẹ kan tí ó sàn jù ọ́ lọ.
Samuel pa mu je rekel: » Gospod je ta dan odtrgal Izraelovo kraljestvo od tebe in ga izročil tvojemu bližnjemu, ki je boljši kakor ti.
29 Ẹni tí ó ń ṣe ògo Israẹli, kì í purọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì í yí ọkàn rẹ̀ padà; nítorí kì í ṣe ènìyàn tí yóò yí ọkàn rẹ̀ padà.”
Tudi Močni Izraelov ne bo lagal niti se kesal, kajti on ni človek, da bi se kesal.«
30 Saulu sì wí pé, “Èmi ti ṣẹ̀, ṣùgbọ́n jọ̀wọ́ bu ọlá fún mi níwájú àwọn àgbàgbà ènìyàn mi, àti níwájú u Israẹli, yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè tẹríba fún Olúwa Ọlọ́run rẹ.”
Potem je rekel: »Grešil sem. Vendar me sedaj počasti, prosim te, pred starešinami mojega ljudstva in pred Izraelom in se ponovno obrni z menoj, da bom lahko oboževal Gospoda, tvojega Boga.«
31 Bẹ́ẹ̀ ni Samuẹli sì yípadà pẹ̀lú Saulu, Saulu sì sin Olúwa.
Tako se je Samuel ponovno obrnil za Savlom, in Savel je oboževal Gospoda.
32 Nígbà náà ni Samuẹli wí pé, “Mú Agagi ọba àwọn ará Amaleki wá fún mi.” Agagi sì tọ̀ ọ́ wá ní ìgboyà pẹ̀lú èrò pé, “Nítòótọ́ ìkorò ikú ti kọjá.”
Potem je Samuel rekel: »Privedite sèm k meni Agága, kralja Amalečanov.« Agág je prefinjeno prišel k njemu. In Agág je rekel: »Zagotovo je grenkoba smrti minila.«
33 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Bí idà rẹ ti sọ àwọn obìnrin di aláìní ọmọ bẹ́ẹ̀ ni ìyá rẹ yóò sì di aláìní ọmọ láàrín obìnrin.” Samuẹli sì pa Agagi níwájú Olúwa ni Gilgali.
Samuel je rekel: »Kakor je tvoj meč naredil ženske brez otrok, tako bo tvoja mati brez otroka med ženskami.« In Samuel je Agága razsekal na koščke pred Gospodom v Gilgálu.
34 Nígbà náà ni Samuẹli lọ sí Rama, Saulu sì gòkè lọ sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah tí Saulu.
Potem je Samuel odšel v Ramo, Savel pa je odšel gor, do svoje hiše, v Savlovo Gíbeo.
35 Samuẹli kò sì padà wá mọ́ láti wo Saulu títí ó fi di ọjọ́ ikú u rẹ̀, ṣùgbọ́n Samuẹli káàánú fún Saulu. Ó sì dun Olúwa pé ó fi Saulu jẹ ọba lórí Israẹli.
Samuel ni več prišel, da bi videl Savla, do dneva svoje smrti, vendar je Samuel žaloval za Savlom. In Gospod se je pokesal, da je Savla postavil [za] kralja nad Izraelom.

< 1 Samuel 15 >