< 1 Samuel 15 >
1 Samuẹli wí fún Saulu pé, “Èmi ni Olúwa rán láti fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli; fetísílẹ̀ láti gbọ́ iṣẹ́ tí Olúwa rán mi sí ọ́.
И рече Самуил к Саулу: посла мя Господь помазати тя на царство в людех Его во Израили: и ныне послушай гласа словес Господних:
2 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi yóò jẹ àwọn Amaleki ní yà fún ohun tí wọ́n ti ṣe sí Israẹli nígbà tí wọn dè wọn lọ́nà nígbà tí wọn ń bọ̀ láti Ejibiti.
сия рече Господь Саваоф: ныне отмщу, яже сотвори Амалик Израилю, егда срете его на пути, восходящу ему от Египта:
3 Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọlu Amaleki, kí o sì pa gbogbo ohun tí ó bá jẹ́ tiwọn ní à parun. Má ṣe dá wọn sí, pa ọkùnrin àti obìnrin wọn, ọmọ kékeré àti ọmọ ọmú, màlúù àti àgùntàn, ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.’”
и ныне ты иди, и поразиши Амалика и Иерима, и вся яже суть его, и не снабдиши от них (ничтоже), и искорениши его: и прокленеши его и вся сущая его, и не пощадиши его: и да убиеши от мужеска полу и до женска и от юнош и до ссущих млеко, и от говяд до овец и от велблюд до ослят.
4 Bẹ́ẹ̀ ni Saulu kó àwọn ènìyàn jọ, ó sì ka iye wọn ní Talaemu, wọ́n sì jẹ́ ogún ọ̀kẹ́ àwọn ológun ẹlẹ́ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Juda.
И собра люди Саул и сочте я в Галгалех двесте тысящ пеших и десять тысящ от Иуды в полцех:
5 Saulu sì lọ sí ìlú Amaleki ó sì gọ dè wọ́n ní àfonífojì kan.
и прииде Саул до градов Амаликовых и засяде в потоце.
6 Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ará Keni pé, “Ẹ lọ, kúrò ní Amaleki kí èmi má ba à run yín pẹ̀lú wọn; nítorí ẹ̀yin fi àánú hàn fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n gòkè ti Ejibiti wá.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Kenaiti lọ kúrò láàrín àwọn Amaleki.
И рече Саул ко Кинеови: иди и уклонися от среды Амалика, да не погублю тя с ним, ты бо сотворил еси милость с сынми Израилевыми, егда исхождаху из Египта. И уклонися Киней от среды Амалика.
7 Nígbà náà ni Saulu kọlu àwọn Amaleki láti Hafila dé Ṣuri, tí ó fi dé ìlà-oòrùn Ejibiti.
И порази Саул Амалика от Евилы даже до Сура, иже пред лицем Египта:
8 Ó sì mú Agagi ọba Amaleki láààyè, ó sì fi idà rẹ̀ kọlù gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀.
и ят Агага царя Амаликова жива, и вся люди изби, и Иерима уби мечем.
9 Ṣùgbọ́n Saulu àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ dá Agagi sí àti èyí tí ó dára jùlọ nínú àgùntàn àti màlúù àti ọ̀dọ́-àgùntàn àbọ́pa àti gbogbo nǹkan tó dára. Wọ́n kò sì fẹ́ pa àwọn wọ̀nyí run pátápátá ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan tí kò dára tí kò sì níláárí ni wọ́n parun pátápátá.
И сохрани Саул и вси людие Агага царя жива и благая от стад и буйволов, и снедей (и одежд), и виноградов и от всех благих: и не хотяху искоренити я, точию хуждшее и уничиженое истребиша.
10 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Samuẹli wá pé,
И бысть глаголгол Господень к Самуилу, глаголя:
11 “Èmi káàánú gidigidi pé mo fi Saulu jẹ ọba, nítorí pé ó ti yípadà kúrò lẹ́yìn mi, kò sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́.” Inú Samuẹli sì bàjẹ́ gidigidi, ó sì ké pe Olúwa ní gbogbo òru náà.
раскаяхся, яко помазах Саула на царство, понеже отвратися от Мене и словес Моих не соблюде. И опечалися Самуил и вопияше ко Господу всю нощь.
12 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Samuẹli sì dìde láti lọ pàdé Saulu, ṣùgbọ́n wọ́n sọ fún un pé, “Saulu ti wá sí Karmeli. Ó ti kọ́ ibìkan fún ara rẹ̀ níbẹ̀, ó sì ti yípadà, ó sì ti sọ̀kalẹ̀ lọ sí Gilgali.”
И воста рано Самуил, и идяше на сретение Израилтяном рано. И возвестиша Самуилу, глаголюще: идет Саул в Кармил, и се, воздвиже руку себе, и возврати колесницу, и сниде в Галгалы. И прииде Самуил к Саулу, и се, той возношаше всесожжение Господу, первая от корыстей, ихже взя от Амаликов.
13 Nígbà tí Samuẹli sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Saulu sì wí fún un pé, “Olúwa bùkún fún ọ, mo ti ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ.”
И прииде Самуил к Саулу, и рече ему Саул: благословен ты Господу, сотворих бо вся, елика (ми) глагола Господь.
14 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Èwo wá ni igbe àgùntàn tí mo ń gbọ́ ní etí mi? Kí ni igbe màlúù ti mo ń gbọ́ yìí?”
И рече Самуил: и кий глас стад сих во ушию моею, и глас говяд, егоже аз слышу?
15 Saulu sì dáhùn pé, “Àwọn ọmọ-ogun ní o mú wọn láti Amaleki wá, wọ́n dá àwọn àgùntàn, àti màlúù tí ó dára jùlọ sí láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ṣùgbọ́n a pa àwọn tókù run pátápátá.”
И рече Саул: от Амалика пригнах я, ихже сохраниша людие лучшая от стад и от волов, еже пожрети я Господу Богу твоему, прочая же избих.
16 Samuẹli sí wí fún Saulu pé, “Dákẹ́ ná, jẹ́ kí èmi kí ó sọ ohun tí Olúwa wí fún mi ní alẹ́ àná fún ọ.” Saulu sì wí pé, “Sọ fún mi.”
И рече Самуил к Саулу: потерпи, и возвещу ти, яже глагола Господь ко мне нощию.
17 Samuẹli sì wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ fi ìgbà kan kéré lójú ara rẹ, ǹjẹ́ ìwọ kò ha di olórí ẹ̀yà Israẹli? Olúwa fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.
И рече ему (Саул): глаголи. И рече Самуил к Саулу: еда не мал был еси ты пред Ним, и не властелина ли тя постави хоругви колена Израилева? И помаза тя Господь на царство Израилево:
18 Olúwa sì rán ọ níṣẹ́ wí pé, ‘Lọ, kí o sì pa àwọn ènìyàn búburú ará Amaleki run pátápátá; gbóguntì wọ́n títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’
и посла тя Господь путем и рече тебе: иди и искорени Амалика, и погуби согрешших предо Мною, и воюй их, дондеже скончаеши их:
19 Èéṣe tí ìwọ kò fi gbọ́ ti Olúwa? Èéṣe tí ìwọ fi sáré sí ìkógun tí o sì ṣe búburú níwájú Olúwa?”
и почто не послушал еси гласа Господня по всему, елико глагола тебе, но устремился еси на корысти и сотворил еси лукавое пред Господем?
20 Saulu sì wí fún Samuẹli pé, “Ṣùgbọ́n èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa, èmi sì ti lọ ní ọ̀nà tí Olúwa rán mi. Mo sì ti pa àwọn ará Amaleki run pátápátá, mo sì ti mú Agagi ọba wọn padà wá.
И рече Саул к Самуилу: послушах гласа людий и идох путем, имже посла мя Господь, и приведох Агага царя Амаликова, и Амалики искорених:
21 Àwọn ọmọ-ogun ti mú àgùntàn àti màlúù lára ìkógun èyí tí ó dára láti fi fún Olúwa láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní Gilgali.”
и взяша людие корысти от стад и буйволы, первая от истребляемых на пожрение Господу Богу нашему в Галгалех.
22 Ṣùgbọ́n Samuẹli dáhùn pé, “Olúwa ha ní inú dídùn sí ẹbọ sísun àti ẹbọ ju kí a gba ohùn Olúwa gbọ́? Ìgbọ́ràn sàn ju ẹbọ lọ, ìfetísílẹ̀ sì sàn ju ọ̀rá àgbò lọ.
И рече Самуил: еда угодны Господу всесожжения и жертвы, якоже послушати гласа Господня? Се, послушание паче жертвы благи, и покорение паче тука овня:
23 Nítorí pé ìṣọ̀tẹ̀ dàbí ẹ̀ṣẹ̀ àfọ̀ṣẹ, àti ìgbéraga bí ẹ̀ṣẹ̀ ìbọ̀rìṣà. Nítorí tí ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa, Òun sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba.”
якоже грех есть чарование, тако (грех есть) противление, и якоже грех есть идолопоклонение, тако непокорение: понеже уничижил еси глаголгол Господень, и уничижит тя Господь не быти тебе царем во Израили.
24 Nígbà náà ni Saulu wí fún Samuẹli pé, “Èmi ti ṣẹ̀. Mo ti rú òfin Olúwa àti ọ̀rọ̀ rẹ̀. Èmi sì bẹ̀rù àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ ni èmi sì gba ohùn wọn gbọ́.
И рече Саул к Самуилу: согреших, яко преступих слово Господне и глагол твой, убояхся бо людий и послушах гласа их:
25 Mo bẹ̀ ọ́ nísinsin yìí, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì, kí ó sì yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè sin Olúwa.”
и ныне возми грех мой и возвратися со мною, да поклонюся Господу Богу твоему.
26 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí fún un pé, “Èmi kò ní bá ọ padà. Ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa sílẹ̀, Olúwa sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba lórí Israẹli!”
И рече Самуил к Саулу: не возвращуся с тобою, яко уничижил еси глаголгол Господень, и уничижит тя Господь не быти тебе царем во Израили.
27 Bí Samuẹli sì ti fẹ́ yípadà láti lọ, Saulu sì di ẹ̀wù ìlekè rẹ̀ mú, ó sì fàya;
И отврати Самуил лице свое еже отити: и ят Саул за воскрилие ризы его и раздра е.
28 Samuẹli sì wí fún un pé, “Olúwa ti fa ìjọba Israẹli ya kúrò lọ́wọ́ ọ̀ rẹ lónìí, ó sì ti fi fún aládùúgbò rẹ kan tí ó sàn jù ọ́ lọ.
И рече ему Самуил: раздра Господь царство Израилево от руку твоею днесь, и даст е ближнему твоему, лучшему паче тебе,
29 Ẹni tí ó ń ṣe ògo Israẹli, kì í purọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì í yí ọkàn rẹ̀ padà; nítorí kì í ṣe ènìyàn tí yóò yí ọkàn rẹ̀ padà.”
и разделится Израиль на двое: и не обратится, ниже раскается Святый Израилев, занеже не яко человек есть, еже раскаятися Ему, запретит, и не пребудет.
30 Saulu sì wí pé, “Èmi ti ṣẹ̀, ṣùgbọ́n jọ̀wọ́ bu ọlá fún mi níwájú àwọn àgbàgbà ènìyàn mi, àti níwájú u Israẹli, yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè tẹríba fún Olúwa Ọlọ́run rẹ.”
И рече Саул: согреших, но прослави мя ныне пред старейшины Израилевы и пред людьми моими, и возвратися со мною, и поклонюся Господу Богу твоему.
31 Bẹ́ẹ̀ ni Samuẹli sì yípadà pẹ̀lú Saulu, Saulu sì sin Olúwa.
И возвратися Самуил вслед Саула, и поклонися Саул Господу.
32 Nígbà náà ni Samuẹli wí pé, “Mú Agagi ọba àwọn ará Amaleki wá fún mi.” Agagi sì tọ̀ ọ́ wá ní ìgboyà pẹ̀lú èrò pé, “Nítòótọ́ ìkorò ikú ti kọjá.”
И рече Самуил: приведите ми Агага царя Амаликова. И прииде к нему Агаг трепеща, и рече Агаг: тако ли горька смерть?
33 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Bí idà rẹ ti sọ àwọn obìnrin di aláìní ọmọ bẹ́ẹ̀ ni ìyá rẹ yóò sì di aláìní ọmọ láàrín obìnrin.” Samuẹli sì pa Agagi níwájú Olúwa ni Gilgali.
И рече Самуил ко агагу: якоже обезчадствова жен оружие твое, тако обезчадится в женах мати твоя. И закла Самуил Агага пред Господем в Галгалех.
34 Nígbà náà ni Samuẹli lọ sí Rama, Saulu sì gòkè lọ sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah tí Saulu.
И отиде Самуил во Армафем: и Саул отиде в дом свой в Гаваю.
35 Samuẹli kò sì padà wá mọ́ láti wo Saulu títí ó fi di ọjọ́ ikú u rẹ̀, ṣùgbọ́n Samuẹli káàánú fún Saulu. Ó sì dun Olúwa pé ó fi Saulu jẹ ọba lórí Israẹli.
И не приложи Самуил ктому видети Саула даже до дне смерти своея, понеже плакаше Самуил о Сауле, занеже раскаяся Господь, яко постави Саула царя во Израили.