< 1 Samuel 15 >

1 Samuẹli wí fún Saulu pé, “Èmi ni Olúwa rán láti fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli; fetísílẹ̀ láti gbọ́ iṣẹ́ tí Olúwa rán mi sí ọ́.
Samuel de asemenea i-a spus lui Saul: DOMNUL m-a trimis să te ung împărat peste poporul său, peste Israel; de aceea acum, dă ascultare la vocea cuvintelor DOMNULUI.
2 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi yóò jẹ àwọn Amaleki ní yà fún ohun tí wọ́n ti ṣe sí Israẹli nígbà tí wọn dè wọn lọ́nà nígbà tí wọn ń bọ̀ láti Ejibiti.
Astfel spune DOMNUL oștirilor: Îmi amintesc ceea ce Amalec i-a făcut lui Israel, cum l-a pândit pe cale, când se urca din Egipt.
3 Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọlu Amaleki, kí o sì pa gbogbo ohun tí ó bá jẹ́ tiwọn ní à parun. Má ṣe dá wọn sí, pa ọkùnrin àti obìnrin wọn, ọmọ kékeré àti ọmọ ọmú, màlúù àti àgùntàn, ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.’”
Acum du-te și lovește pe Amalec și nimicește tot ceea ce au ei și nu îi cruța, ci omoară deopotrivă bărbat și femeie, prunc și sugar, bou și oaie, cămilă și măgar.
4 Bẹ́ẹ̀ ni Saulu kó àwọn ènìyàn jọ, ó sì ka iye wọn ní Talaemu, wọ́n sì jẹ́ ogún ọ̀kẹ́ àwọn ológun ẹlẹ́ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Juda.
Și Saul a adunat poporul și i-a numărat în Telaim: două sute de mii de pedeștri și zece mii de bărbați din Iuda.
5 Saulu sì lọ sí ìlú Amaleki ó sì gọ dè wọ́n ní àfonífojì kan.
Și Saul a venit la o cetate a lui Amalec și a pândit în vale.
6 Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ará Keni pé, “Ẹ lọ, kúrò ní Amaleki kí èmi má ba à run yín pẹ̀lú wọn; nítorí ẹ̀yin fi àánú hàn fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n gòkè ti Ejibiti wá.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Kenaiti lọ kúrò láàrín àwọn Amaleki.
Și Saul a spus cheniților: Duceți-vă, plecați, coborâți din mijlocul amaleciților, ca nu cumva să vă nimicesc cu ei, pentru că voi ați arătat bunătate tuturor copiilor lui Israel, când ei se urcau din Egipt. Astfel cheniții s-au depărtat din mijlocul amaleciților.
7 Nígbà náà ni Saulu kọlu àwọn Amaleki láti Hafila dé Ṣuri, tí ó fi dé ìlà-oòrùn Ejibiti.
Și Saul a lovit pe amaleciți de la Havila, cum vii la Șur, care este în fața Egiptului.
8 Ó sì mú Agagi ọba Amaleki láààyè, ó sì fi idà rẹ̀ kọlù gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀.
Și a prins viu pe Agag, împăratul amaleciților, și a nimicit în întregime tot poporul cu ascuțișul sabiei.
9 Ṣùgbọ́n Saulu àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ dá Agagi sí àti èyí tí ó dára jùlọ nínú àgùntàn àti màlúù àti ọ̀dọ́-àgùntàn àbọ́pa àti gbogbo nǹkan tó dára. Wọ́n kò sì fẹ́ pa àwọn wọ̀nyí run pátápátá ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan tí kò dára tí kò sì níláárí ni wọ́n parun pátápátá.
Dar Saul și poporul au cruțat pe Agag și ce era cel mai bun dintre oi și dintre boi și dintre vite îngrășate și miei și tot ce era bun și au refuzat să le nimicească în întregime; dar orice lucru nemernic și rău, pe acela l-au nimicit în întregime.
10 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Samuẹli wá pé,
Atunci cuvântul DOMNULUI a venit la Samuel, spunând:
11 “Èmi káàánú gidigidi pé mo fi Saulu jẹ ọba, nítorí pé ó ti yípadà kúrò lẹ́yìn mi, kò sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́.” Inú Samuẹli sì bàjẹ́ gidigidi, ó sì ké pe Olúwa ní gbogbo òru náà.
Mă pocăiesc că am pus pe Saul împărat, pentru că s-a abătut de la a mă urma și nu a împlinit poruncile mele. Și aceasta a mâhnit pe Samuel; și el a strigat către DOMNUL toată noaptea.
12 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Samuẹli sì dìde láti lọ pàdé Saulu, ṣùgbọ́n wọ́n sọ fún un pé, “Saulu ti wá sí Karmeli. Ó ti kọ́ ibìkan fún ara rẹ̀ níbẹ̀, ó sì ti yípadà, ó sì ti sọ̀kalẹ̀ lọ sí Gilgali.”
Și când Samuel s-a sculat devreme ca să îl întâlnească pe Saul dimineața, i s-a spus lui Samuel, zicând: Saul a venit la Carmel și, iată, și-a înălțat un semn și s-a întors și a trecut mai departe și a coborât la Ghilgal.
13 Nígbà tí Samuẹli sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Saulu sì wí fún un pé, “Olúwa bùkún fún ọ, mo ti ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ.”
Și Samuel a venit la Saul; și Saul i-a spus: Binecuvântat fii de DOMNUL; am împlinit porunca DOMNULUI.
14 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Èwo wá ni igbe àgùntàn tí mo ń gbọ́ ní etí mi? Kí ni igbe màlúù ti mo ń gbọ́ yìí?”
Și Samuel a spus: Ce înseamnă atunci acest behăit de oi în urechile mele și mugetul boilor pe care îl aud?
15 Saulu sì dáhùn pé, “Àwọn ọmọ-ogun ní o mú wọn láti Amaleki wá, wọ́n dá àwọn àgùntàn, àti màlúù tí ó dára jùlọ sí láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ṣùgbọ́n a pa àwọn tókù run pátápátá.”
Și Saul a spus: Le-au adus de la amaleciți, pentru că poporul a cruțat ce era cel mai bun dintre oi și dintre boi, pentru a sacrifica DOMNULUI Dumnezeul tău; și pe celelalte noi le-am nimicit în întregime.
16 Samuẹli sí wí fún Saulu pé, “Dákẹ́ ná, jẹ́ kí èmi kí ó sọ ohun tí Olúwa wí fún mi ní alẹ́ àná fún ọ.” Saulu sì wí pé, “Sọ fún mi.”
Atunci Samuel i-a spus lui Saul: Stai și îți voi spune ce mi-a spus DOMNUL în această noapte. Iar el i-a spus: Spune.
17 Samuẹli sì wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ fi ìgbà kan kéré lójú ara rẹ, ǹjẹ́ ìwọ kò ha di olórí ẹ̀yà Israẹli? Olúwa fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.
Și Samuel a spus: Când erai mic înaintea ochilor tăi, nu ai fost făcut tu capul triburilor lui Israel și nu DOMNUL te-a uns împărat peste Israel?
18 Olúwa sì rán ọ níṣẹ́ wí pé, ‘Lọ, kí o sì pa àwọn ènìyàn búburú ará Amaleki run pátápátá; gbóguntì wọ́n títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’
Și DOMNUL te-a trimis într-o călătorie și a spus: Du-te și nimicește în întregime pe păcătoșii de amaleciți și fă bătălie împotriva lor, până vor fi mistuiți.
19 Èéṣe tí ìwọ kò fi gbọ́ ti Olúwa? Èéṣe tí ìwọ fi sáré sí ìkógun tí o sì ṣe búburú níwájú Olúwa?”
Pentru ce atunci nu ai ascultat de vocea DOMNULUI, ci te-ai năpustit asupra prăzii și ai făcut ce este rău înaintea ochilor DOMNULUI?
20 Saulu sì wí fún Samuẹli pé, “Ṣùgbọ́n èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa, èmi sì ti lọ ní ọ̀nà tí Olúwa rán mi. Mo sì ti pa àwọn ará Amaleki run pátápátá, mo sì ti mú Agagi ọba wọn padà wá.
Și Saul i-a spus lui Samuel: Da, am ascultat de vocea DOMNULUI și am mers pe calea pe care m-a trimis DOMNUL și am adus pe Agag, împăratul amaleciților, și am nimicit în întregime pe amaleciți.
21 Àwọn ọmọ-ogun ti mú àgùntàn àti màlúù lára ìkógun èyí tí ó dára láti fi fún Olúwa láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní Gilgali.”
Dar poporul a luat din pradă, oi și boi, cele mai bune dintre lucruri care trebuiau nimicite în întregime, pentru a sacrifica DOMNULUI Dumnezeul tău în Ghilgal.
22 Ṣùgbọ́n Samuẹli dáhùn pé, “Olúwa ha ní inú dídùn sí ẹbọ sísun àti ẹbọ ju kí a gba ohùn Olúwa gbọ́? Ìgbọ́ràn sàn ju ẹbọ lọ, ìfetísílẹ̀ sì sàn ju ọ̀rá àgbò lọ.
Și Samuel a spus: Îi fac DOMNULUI mai mare desfătare ofrandele arse și sacrificiile, decât ascultarea de vocea DOMNULUI? Iată, a asculta de el este mai bine decât sacrificiul, și a da ascultare decât grăsimea berbecilor.
23 Nítorí pé ìṣọ̀tẹ̀ dàbí ẹ̀ṣẹ̀ àfọ̀ṣẹ, àti ìgbéraga bí ẹ̀ṣẹ̀ ìbọ̀rìṣà. Nítorí tí ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa, Òun sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba.”
Fiindcă răzvrătirea este ca păcatul vrăjitoriei și încăpățânarea este ca nelegiuirea și idolatria. Pentru că ai lepădat cuvântul DOMNULUI și el te-a lepădat ca împărat.
24 Nígbà náà ni Saulu wí fún Samuẹli pé, “Èmi ti ṣẹ̀. Mo ti rú òfin Olúwa àti ọ̀rọ̀ rẹ̀. Èmi sì bẹ̀rù àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ ni èmi sì gba ohùn wọn gbọ́.
Și Saul i-a spus lui Samuel: Am păcătuit, pentru că am călcat porunca DOMNULUI și cuvintele tale; deoarece m-am temut de popor și am făcut ce a poruncit vocea lor.
25 Mo bẹ̀ ọ́ nísinsin yìí, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì, kí ó sì yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè sin Olúwa.”
Și acum, te rog, iartă păcatul meu și întoarce-te cu mine, ca să mă închin DOMNULUI.
26 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí fún un pé, “Èmi kò ní bá ọ padà. Ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa sílẹ̀, Olúwa sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba lórí Israẹli!”
Și Samuel i-a spus lui Saul: Nu mă voi întoarce cu tine, pentru că ai lepădat cuvântul DOMNULUI și DOMNUL te-a lepădat de la a fi împărat peste Israel.
27 Bí Samuẹli sì ti fẹ́ yípadà láti lọ, Saulu sì di ẹ̀wù ìlekè rẹ̀ mú, ó sì fàya;
Și pe când Samuel s-a întors să plece, Saul l-a apucat de poala mantiei sale și aceasta s-a rupt.
28 Samuẹli sì wí fún un pé, “Olúwa ti fa ìjọba Israẹli ya kúrò lọ́wọ́ ọ̀ rẹ lónìí, ó sì ti fi fún aládùúgbò rẹ kan tí ó sàn jù ọ́ lọ.
Și Samuel i-a spus: DOMNUL a rupt împărăția lui Israel de la tine în această zi și a dat-o aproapelui tău, care este mai bun decât tine.
29 Ẹni tí ó ń ṣe ògo Israẹli, kì í purọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì í yí ọkàn rẹ̀ padà; nítorí kì í ṣe ènìyàn tí yóò yí ọkàn rẹ̀ padà.”
Și de asemenea Tăria lui Israel nu va minți, nici nu se va pocăi, pentru că el nu este un om, ca să se pocăiască.
30 Saulu sì wí pé, “Èmi ti ṣẹ̀, ṣùgbọ́n jọ̀wọ́ bu ọlá fún mi níwájú àwọn àgbàgbà ènìyàn mi, àti níwájú u Israẹli, yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè tẹríba fún Olúwa Ọlọ́run rẹ.”
Atunci el a spus: Am păcătuit; totuși onorează-mă acum, te rog, înaintea bătrânilor poporului meu și înaintea lui Israel și întoarce-te cu mine, ca să mă închin DOMNULUI Dumnezeul tău.
31 Bẹ́ẹ̀ ni Samuẹli sì yípadà pẹ̀lú Saulu, Saulu sì sin Olúwa.
Astfel Samuel s-a întors după Saul; și Saul s-a închinat DOMNULUI.
32 Nígbà náà ni Samuẹli wí pé, “Mú Agagi ọba àwọn ará Amaleki wá fún mi.” Agagi sì tọ̀ ọ́ wá ní ìgboyà pẹ̀lú èrò pé, “Nítòótọ́ ìkorò ikú ti kọjá.”
Atunci Samuel a spus: Aduceți la mine pe Agag, împăratul amaleciților. Și Agag a venit la el cu multă delicatețe. Și Agag a spus: Într-adevăr amărăciunea morții a trecut.
33 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Bí idà rẹ ti sọ àwọn obìnrin di aláìní ọmọ bẹ́ẹ̀ ni ìyá rẹ yóò sì di aláìní ọmọ láàrín obìnrin.” Samuẹli sì pa Agagi níwájú Olúwa ni Gilgali.
Iar Samuel a spus: Precum sabia ta a făcut pe femei fără copii, tot astfel mama ta va fi fără copii printre femei. Și Samuel a tăiat pe Agag în bucăți înaintea DOMNULUI la Ghilgal.
34 Nígbà náà ni Samuẹli lọ sí Rama, Saulu sì gòkè lọ sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah tí Saulu.
Apoi Samuel a mers la Rama; și Saul s-a urcat la casa lui în Ghibea lui Saul.
35 Samuẹli kò sì padà wá mọ́ láti wo Saulu títí ó fi di ọjọ́ ikú u rẹ̀, ṣùgbọ́n Samuẹli káàánú fún Saulu. Ó sì dun Olúwa pé ó fi Saulu jẹ ọba lórí Israẹli.
Și Samuel nu a mai venit să îl vadă pe Saul până în ziua morții sale; totuși Samuel l-a jelit pe Saul; și DOMNUL s-a pocăit că l-a făcut pe Saul împărat peste Israel.

< 1 Samuel 15 >