< 1 Samuel 15 >

1 Samuẹli wí fún Saulu pé, “Èmi ni Olúwa rán láti fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli; fetísílẹ̀ láti gbọ́ iṣẹ́ tí Olúwa rán mi sí ọ́.
Na ka mea a Hamuera ki a Haora, I tonoa mai ahau e Ihowa ki te whakawahi i a koe hei kingi mo tana iwi, mo Iharaira: na whakarongo mai ki te reo o nga kupu a Ihowa.
2 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi yóò jẹ àwọn Amaleki ní yà fún ohun tí wọ́n ti ṣe sí Israẹli nígbà tí wọn dè wọn lọ́nà nígbà tí wọn ń bọ̀ láti Ejibiti.
Ko te kupu tenei a Ihowa o nga mano, E whakaaro ana ahau ki ta Amareke i mea ai ki a Iharaira, ki tana whanganga i a ia i te ara i tona haerenga mai i Ihipa.
3 Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọlu Amaleki, kí o sì pa gbogbo ohun tí ó bá jẹ́ tiwọn ní à parun. Má ṣe dá wọn sí, pa ọkùnrin àti obìnrin wọn, ọmọ kékeré àti ọmọ ọmú, màlúù àti àgùntàn, ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.’”
Na tikina, patua a Amareke, whakangaromia rawatia a ratou mea katoa, kaua hoki ratou e tohungia; engari whakamatea ngatahitia te tane me te wahine, te potiki me te mea ngote u, te kau me te hipi, te kamera me te kaihe.
4 Bẹ́ẹ̀ ni Saulu kó àwọn ènìyàn jọ, ó sì ka iye wọn ní Talaemu, wọ́n sì jẹ́ ogún ọ̀kẹ́ àwọn ológun ẹlẹ́ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Juda.
Na ka huihuia te iwi e Haora, a taua ana e ia ki Teraimi, e rua rau mano, he hunga haere i raro, me nga tangata hoki o Hura, kotahi tekau mano.
5 Saulu sì lọ sí ìlú Amaleki ó sì gọ dè wọ́n ní àfonífojì kan.
Na ko te haerenga atu o Haora ki te pa o Amareke, a whakatakoto pehipehi ana i roto i te awaawa.
6 Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ará Keni pé, “Ẹ lọ, kúrò ní Amaleki kí èmi má ba à run yín pẹ̀lú wọn; nítorí ẹ̀yin fi àánú hàn fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n gòkè ti Ejibiti wá.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Kenaiti lọ kúrò láàrín àwọn Amaleki.
I mea hoki a Haora ki nga Keni, Whakatika, mawehe atu, haere ki raro i roto i nga Amareki, kei huna tahitia koe e ahau me ratou; i puta hoki ta koutou atawhai ki nga tamariki katoa a Iharaira i to ratou haerenga mai i Ihipa. Heoi ka mawehe nga Ke ni i roto i a Amareki.
7 Nígbà náà ni Saulu kọlu àwọn Amaleki láti Hafila dé Ṣuri, tí ó fi dé ìlà-oòrùn Ejibiti.
Na tukitukia ana e Haora nga Amareki i Hawira atu a tae noa koe ki Huru, ki te ritenga atu o Ihipa.
8 Ó sì mú Agagi ọba Amaleki láààyè, ó sì fi idà rẹ̀ kọlù gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀.
Hopukia oratia ana hoki e ia a Akaka kingi o Amareke, ko te iwi katoa hoki i whakangaromia rawatia e ia ki te mata o te hoari.
9 Ṣùgbọ́n Saulu àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ dá Agagi sí àti èyí tí ó dára jùlọ nínú àgùntàn àti màlúù àti ọ̀dọ́-àgùntàn àbọ́pa àti gbogbo nǹkan tó dára. Wọ́n kò sì fẹ́ pa àwọn wọ̀nyí run pátápátá ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan tí kò dára tí kò sì níláárí ni wọ́n parun pátápátá.
Otiia i tohungia e Haora ratou ko te iwi a Akaka, me nga mea papai o nga hipi, o nga kau, o nga mea momona hoki, me nga reme, me nga mea pai katoa, kihai hoki i aro ki te whakangaro i a ratou: engari nga mea e whakaparahakotia ana, e rukea ana, k o ena a ratou i whakangaro ai.
10 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Samuẹli wá pé,
Katahi ka puta te kupu a Ihowa ki a Hamuera, ka mea,
11 “Èmi káàánú gidigidi pé mo fi Saulu jẹ ọba, nítorí pé ó ti yípadà kúrò lẹ́yìn mi, kò sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́.” Inú Samuẹli sì bàjẹ́ gidigidi, ó sì ké pe Olúwa ní gbogbo òru náà.
Kua puta ke oku whakaaro i meinga ai e ahau a Haora hei kingi; kua hoki atu hoki ia i te whai i ahau, a kihai hoki i whakamana i aku kupu. Na ka oho te riri a Hamuera; a pau katoa taua po i a ia e tangi ana ki a Ihowa.
12 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Samuẹli sì dìde láti lọ pàdé Saulu, ṣùgbọ́n wọ́n sọ fún un pé, “Saulu ti wá sí Karmeli. Ó ti kọ́ ibìkan fún ara rẹ̀ níbẹ̀, ó sì ti yípadà, ó sì ti sọ̀kalẹ̀ lọ sí Gilgali.”
Na ka maranga wawe a Hamuera i te ata ki te whakatau i a Haora; a ka korerotia ki a Hamuera, ka meatia, I te mai a Haora ki Karamere, na whakaturia ana e ia he tohu mana, a haere awhio atu ana, kua pahemo atu, kua riro ki raro, ki Kirikara.
13 Nígbà tí Samuẹli sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Saulu sì wí fún un pé, “Olúwa bùkún fún ọ, mo ti ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ.”
Na ka tae atu a Hamuera ki a Haora, a ka mea a Haora ki a ia, Kia manaakitia koe e Ihowa, kua whakamana e ahau te kupu a Ihowa.
14 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Èwo wá ni igbe àgùntàn tí mo ń gbọ́ ní etí mi? Kí ni igbe màlúù ti mo ń gbọ́ yìí?”
Na ka mea a Hamuera, He aha koia tenei tangi o nga hipi i roto nei i oku taringa, me te tangi o nga kau e rongo nei ahau?
15 Saulu sì dáhùn pé, “Àwọn ọmọ-ogun ní o mú wọn láti Amaleki wá, wọ́n dá àwọn àgùntàn, àti màlúù tí ó dára jùlọ sí láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ṣùgbọ́n a pa àwọn tókù run pátápátá.”
Ano ra ko Haora, He mea mau mai e ratou i nga Amareki: i tohungia hoki e te iwi nga mea papai o nga hipi, o nga kau, hei mea patunga tapu ki a Ihowa, ki tou Atua; a ko te toenga, whakangaromia iho e matou.
16 Samuẹli sí wí fún Saulu pé, “Dákẹ́ ná, jẹ́ kí èmi kí ó sọ ohun tí Olúwa wí fún mi ní alẹ́ àná fún ọ.” Saulu sì wí pé, “Sọ fún mi.”
Katahi ka mea a Hamuera ki a Haora, Kati, kia korerotia e ahau ki a koe ta Ihowa i mea ai ki ahau i tenei po. Ano ra ko tera, Korero.
17 Samuẹli sì wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ fi ìgbà kan kéré lójú ara rẹ, ǹjẹ́ ìwọ kò ha di olórí ẹ̀yà Israẹli? Olúwa fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.
A ka mea a Hamuera, I a koe e iti ana ki tou whakaaro, kihai ianei koe i meinga hei upoko mo nga iwi o Iharaira, i whakawahia e Ihowa hei kingi mo Iharaira?
18 Olúwa sì rán ọ níṣẹ́ wí pé, ‘Lọ, kí o sì pa àwọn ènìyàn búburú ará Amaleki run pátápátá; gbóguntì wọ́n títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’
Na ka tono a Ihowa i a koe kia haere, ka mea, Tikina, whakangaromia te hunga hara, nga Amareki, whawhai hoki ki a ratou a poto noa ratou.
19 Èéṣe tí ìwọ kò fi gbọ́ ti Olúwa? Èéṣe tí ìwọ fi sáré sí ìkógun tí o sì ṣe búburú níwájú Olúwa?”
He aha koe te whakarongo ai ki te reo o Ihowa, i aurara atu ai ki nga taonga parakete, i mahi ai i te kino i te tirohanga a Ihowa?
20 Saulu sì wí fún Samuẹli pé, “Ṣùgbọ́n èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa, èmi sì ti lọ ní ọ̀nà tí Olúwa rán mi. Mo sì ti pa àwọn ará Amaleki run pátápátá, mo sì ti mú Agagi ọba wọn padà wá.
Na ka mea a Haora ki a Hamuera, Ina, i whakarongo ano ahau ki te reo o Ihowa, i haere i te ara i tonoa ai ahau e Ihowa, kua kawea mai ano hoki e ahau a Akaka kingi o Amareke; ko nga Amareki ano hoki, whakangaromia iho e ahau.
21 Àwọn ọmọ-ogun ti mú àgùntàn àti màlúù lára ìkógun èyí tí ó dára láti fi fún Olúwa láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní Gilgali.”
Na te iwi hoki i tango etahi o nga taonga, o nga hipi, o nga kau, nga mea tino papai o nga mea e whakangaromia ana hei mea patunga tapu ki a Ihowa, ki tou Atua, ki Kirikara.
22 Ṣùgbọ́n Samuẹli dáhùn pé, “Olúwa ha ní inú dídùn sí ẹbọ sísun àti ẹbọ ju kí a gba ohùn Olúwa gbọ́? Ìgbọ́ràn sàn ju ẹbọ lọ, ìfetísílẹ̀ sì sàn ju ọ̀rá àgbò lọ.
Ano ra ko Hamuera, Ki ta Ihowa, he pera ranei te ahuareka o nga tahunga tinana, o nga patunga tapu, me te whakarongo ki te reo o Ihowa? Nana, pai atu te whakarongo i te patunga tapu, te ngakau mahara i te ngako o nga hipi toa.
23 Nítorí pé ìṣọ̀tẹ̀ dàbí ẹ̀ṣẹ̀ àfọ̀ṣẹ, àti ìgbéraga bí ẹ̀ṣẹ̀ ìbọ̀rìṣà. Nítorí tí ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa, Òun sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba.”
Rite tonu hoki te tutu ki te hara makutu; te whakatuturi ki te kino, ki te karakia whakapakoko. He whakaparahako nau ki te kupu a Ihowa, ka whakaparahako hoki ia ki a koe hei kingi.
24 Nígbà náà ni Saulu wí fún Samuẹli pé, “Èmi ti ṣẹ̀. Mo ti rú òfin Olúwa àti ọ̀rọ̀ rẹ̀. Èmi sì bẹ̀rù àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ ni èmi sì gba ohùn wọn gbọ́.
Na ka ki a Haora ki a Hamuera, Kua hara ahau, i ahau i takahi nei i te kupu a Ihowa, i au kupu ano hoki: i wehi hoki ahau i te iwi, i whakarongo ki to ratou reo.
25 Mo bẹ̀ ọ́ nísinsin yìí, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì, kí ó sì yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè sin Olúwa.”
Tena ra, whakarerea noatia iho toku hara, kia hoki atu taua, kia koropiko ai ahau ki a Ihowa.
26 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí fún un pé, “Èmi kò ní bá ọ padà. Ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa sílẹ̀, Olúwa sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba lórí Israẹli!”
Ano ra ko Hamuera ki a Haora, E kore ahau e hoki tahi taua; he mea hoki kua whakaparahako koe ki te kupu a Ihowa, a kua whakaparahako a Ihowa ki a koe hei kingi mo Iharaira.
27 Bí Samuẹli sì ti fẹ́ yípadà láti lọ, Saulu sì di ẹ̀wù ìlekè rẹ̀ mú, ó sì fàya;
A, i te tahuritanga o Hamuera ki te haere, ka mau tera ki te pito o tona kakahu, a kua pakaru.
28 Samuẹli sì wí fún un pé, “Olúwa ti fa ìjọba Israẹli ya kúrò lọ́wọ́ ọ̀ rẹ lónìí, ó sì ti fi fún aládùúgbò rẹ kan tí ó sàn jù ọ́ lọ.
Na ka mea a Hamuera ki a ia, Kua haea mai e Ihowa inaianei tou kingitanga i roto i a Iharaira, kua hoatu ki tou hoa e pai atu ana i a koe.
29 Ẹni tí ó ń ṣe ògo Israẹli, kì í purọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì í yí ọkàn rẹ̀ padà; nítorí kì í ṣe ènìyàn tí yóò yí ọkàn rẹ̀ padà.”
E kore ano hoki te Kaha o Iharaira e teka; e kore ano hoki e puta ke ona whakaaro; no te mea ehara ia i te tangata e puta ke ai ona whakaaro.
30 Saulu sì wí pé, “Èmi ti ṣẹ̀, ṣùgbọ́n jọ̀wọ́ bu ọlá fún mi níwájú àwọn àgbàgbà ènìyàn mi, àti níwájú u Israẹli, yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè tẹríba fún Olúwa Ọlọ́run rẹ.”
Ano ra ko tera, Kua hara ahau: otiia whakahonoretia ahau aianei i te aroaro o nga kaumatua o toku iwi, i te aroaro o Iharaira, kia hoki tahi taua, kia koropiko ai ahau ki a Ihowa, ki tou Atua.
31 Bẹ́ẹ̀ ni Samuẹli sì yípadà pẹ̀lú Saulu, Saulu sì sin Olúwa.
Heoi hoki ana a Hamuera i muri i a Haora, a karakia ana a Haora ki a Ihowa.
32 Nígbà náà ni Samuẹli wí pé, “Mú Agagi ọba àwọn ará Amaleki wá fún mi.” Agagi sì tọ̀ ọ́ wá ní ìgboyà pẹ̀lú èrò pé, “Nítòótọ́ ìkorò ikú ti kọjá.”
Katahi a Hamuera ka mea, Kawea mai ki ahau a Akaka kingi o Amareke. Na ka ata hikoi a Akaka ki a ia. A ka mea a Akaka, He pono kua pahemo ke te ngau kino a te mate.
33 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Bí idà rẹ ti sọ àwọn obìnrin di aláìní ọmọ bẹ́ẹ̀ ni ìyá rẹ yóò sì di aláìní ọmọ láàrín obìnrin.” Samuẹli sì pa Agagi níwájú Olúwa ni Gilgali.
Ano ra ko Hamuera, Na tau hoari i kore ai nga uri o nga wahine, ka pena ano tou whaea te urikore i roto i nga wahine. Na haua iho a Akaka e Hamuera i te aroaro o Ihowa i Kirikara.
34 Nígbà náà ni Samuẹli lọ sí Rama, Saulu sì gòkè lọ sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah tí Saulu.
Katahi ka haere a Hamuera ki Rama; ko Haora ia i haere ki runga ki tona whare, ki Kipea o Haora.
35 Samuẹli kò sì padà wá mọ́ láti wo Saulu títí ó fi di ọjọ́ ikú u rẹ̀, ṣùgbọ́n Samuẹli káàánú fún Saulu. Ó sì dun Olúwa pé ó fi Saulu jẹ ọba lórí Israẹli.
Kihai hoki a Haora i tirotirohia e Hamuera i muri iho a taea noatia te ra i mate ai ia: heoi tangihia ana a Haora e Hamuera: i puta ke ano hoki nga whakaaro o Ihowa i meinga ai e ia a Haora hei kingi mo Iharaira.

< 1 Samuel 15 >