< 1 Samuel 15 >

1 Samuẹli wí fún Saulu pé, “Èmi ni Olúwa rán láti fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli; fetísílẹ̀ láti gbọ́ iṣẹ́ tí Olúwa rán mi sí ọ́.
És szólt Sámuel Sáulhoz: Engem küldött az Örökkévaló, hogy fölkenjelek királyul népe fölé, Izrael fölé; most tehát hallgass az Örökkévaló beszédjének szavára.
2 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi yóò jẹ àwọn Amaleki ní yà fún ohun tí wọ́n ti ṣe sí Israẹli nígbà tí wọn dè wọn lọ́nà nígbà tí wọn ń bọ̀ láti Ejibiti.
Így szól az Örökkévaló, a Seregek ura: gondolok arra, amit Izraellel cselekedett Amálék, hogy lest vetett neki az úton, mikor fölvonult Egyiptomból.
3 Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọlu Amaleki, kí o sì pa gbogbo ohun tí ó bá jẹ́ tiwọn ní à parun. Má ṣe dá wọn sí, pa ọkùnrin àti obìnrin wọn, ọmọ kékeré àti ọmọ ọmú, màlúù àti àgùntàn, ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.’”
Most, menj és verd meg Amáléket, pusztítsatok el mindent, ami az övé s ne szánakozzál rajta; öld meg férfiastul, nőstül, kisdedestül, csecsemőstül, ökröstül, bárányostul, tevéstül, szamarastul.
4 Bẹ́ẹ̀ ni Saulu kó àwọn ènìyàn jọ, ó sì ka iye wọn ní Talaemu, wọ́n sì jẹ́ ogún ọ̀kẹ́ àwọn ológun ẹlẹ́ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Juda.
Egybehívta Sául a népet és megszámlálta Teláímban: kétszázezer gyalogost meg tízezret, Jehúda embereit.
5 Saulu sì lọ sí ìlú Amaleki ó sì gọ dè wọ́n ní àfonífojì kan.
És eljutott Sául Amálék városáig és lesbe állt a völgyben.
6 Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ará Keni pé, “Ẹ lọ, kúrò ní Amaleki kí èmi má ba à run yín pẹ̀lú wọn; nítorí ẹ̀yin fi àánú hàn fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n gòkè ti Ejibiti wá.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Kenaiti lọ kúrò láàrín àwọn Amaleki.
Ekkor szólt Sául a Kénihez: Menjetek, távozzatok el, vonuljatok le az amáléki közepéből, nehogy elveszítselek vele együtt, holott te szeretetet műveltél mind az Izrael fiaival, mikor fölvonultak Egyiptomból. És eltávozott a Kéni Amálék közepéből.
7 Nígbà náà ni Saulu kọlu àwọn Amaleki láti Hafila dé Ṣuri, tí ó fi dé ìlà-oòrùn Ejibiti.
És megverte Sául Amáléket Chavílától fogva Súr felé, mely Egyiptom előtt van.
8 Ó sì mú Agagi ọba Amaleki láààyè, ó sì fi idà rẹ̀ kọlù gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀.
És elfogta Agágot, Amálék királyát elevenen, az egész népet pedig elpusztította a kard élével.
9 Ṣùgbọ́n Saulu àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ dá Agagi sí àti èyí tí ó dára jùlọ nínú àgùntàn àti màlúù àti ọ̀dọ́-àgùntàn àbọ́pa àti gbogbo nǹkan tó dára. Wọ́n kò sì fẹ́ pa àwọn wọ̀nyí run pátápátá ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan tí kò dára tí kò sì níláárí ni wọ́n parun pátápátá.
De szánakozott Sául meg a nép Agágon meg az apró jószág és a marha legjaván, a másodelletteken és a kövér juhokon és mindazon, ami jó, és nem akarták elpusztítani; de minden hitvány és silány dolgot elpusztítottak,
10 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Samuẹli wá pé,
És lett az Örökkévaló igéje Sámuelhez, mondván:
11 “Èmi káàánú gidigidi pé mo fi Saulu jẹ ọba, nítorí pé ó ti yípadà kúrò lẹ́yìn mi, kò sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́.” Inú Samuẹli sì bàjẹ́ gidigidi, ó sì ké pe Olúwa ní gbogbo òru náà.
Megbántam, hogy királlyá tettem Sáult, mert ő elpártolt tőlem és szavaimat nem teljesítette. Ez bosszúságára volt Sámuelnek, és kiáltott az Örökkévalóhoz egész éjjel.
12 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Samuẹli sì dìde láti lọ pàdé Saulu, ṣùgbọ́n wọ́n sọ fún un pé, “Saulu ti wá sí Karmeli. Ó ti kọ́ ibìkan fún ara rẹ̀ níbẹ̀, ó sì ti yípadà, ó sì ti sọ̀kalẹ̀ lọ sí Gilgali.”
És kora reggel fölkelt Sámuel Sául elejébe; akkor tudtára adták Sámuelnek, mondván: Karmellbe érkezett Sául és íme fölállít magának emlékjelt, majd megfordult, tovavonult és lement Gilgálba.
13 Nígbà tí Samuẹli sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Saulu sì wí fún un pé, “Olúwa bùkún fún ọ, mo ti ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ.”
Odament Sámuel Sáulhoz, és mondta neki Sául: Áldott legyél az Örökkévalótól, teljesítettem az Örökkévaló igéjét.
14 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Èwo wá ni igbe àgùntàn tí mo ń gbọ́ ní etí mi? Kí ni igbe màlúù ti mo ń gbọ́ yìí?”
Mondta Sámuel: Micsoda hát a juhoknak e hangja füleimben, meg a marhának hangja, amit hallok?
15 Saulu sì dáhùn pé, “Àwọn ọmọ-ogun ní o mú wọn láti Amaleki wá, wọ́n dá àwọn àgùntàn, àti màlúù tí ó dára jùlọ sí láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ṣùgbọ́n a pa àwọn tókù run pátápátá.”
És mondta Sául: Az amálékítől hozták, mivel szánakozott a nép az apró jószág és a marha legjaván azért, hogy áldozzanak az Örökkévalónak, a te Istenednek: a többit pedig elpusztítottuk.
16 Samuẹli sí wí fún Saulu pé, “Dákẹ́ ná, jẹ́ kí èmi kí ó sọ ohun tí Olúwa wí fún mi ní alẹ́ àná fún ọ.” Saulu sì wí pé, “Sọ fún mi.”
Erre szólt Sámuel Sáulhoz: Engedd, hadd adom tudtodra, azt, amit mondott nekem az Örökkévaló az éjjel. Mondta neki: Beszélj!
17 Samuẹli sì wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ fi ìgbà kan kéré lójú ara rẹ, ǹjẹ́ ìwọ kò ha di olórí ẹ̀yà Israẹli? Olúwa fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.
És mondta Sámuel: Nemde, bár kicsiny vagy szemeidben, feje vagy te Izrael törzseinek; fölkent téged az Örökkévaló királyul Izrael fölé.
18 Olúwa sì rán ọ níṣẹ́ wí pé, ‘Lọ, kí o sì pa àwọn ènìyàn búburú ará Amaleki run pátápátá; gbóguntì wọ́n títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’
És útra küldött téged az Örökkévaló és mondta: Menj és pusztítsd el a vétkeseket, Amáléket, harcolj vele, míg meg nem semmisíted őket.
19 Èéṣe tí ìwọ kò fi gbọ́ ti Olúwa? Èéṣe tí ìwọ fi sáré sí ìkógun tí o sì ṣe búburú níwájú Olúwa?”
Hát miért nem hallgattál az Örökkévaló szavára, hanem nekiestél a zsákmánynak és tetted ami rossz az Örökkévaló szemeiben?
20 Saulu sì wí fún Samuẹli pé, “Ṣùgbọ́n èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa, èmi sì ti lọ ní ọ̀nà tí Olúwa rán mi. Mo sì ti pa àwọn ará Amaleki run pátápátá, mo sì ti mú Agagi ọba wọn padà wá.
Szólt Sául Sámuelhez: Mivel hallgattam az Örökkévaló szavára és jártam az úton, melyre küldött engem az Örökkévaló; el is hoztam Agágot, Amálék királyát, Amáléket pedig elpusztítottam!
21 Àwọn ọmọ-ogun ti mú àgùntàn àti màlúù lára ìkógun èyí tí ó dára láti fi fún Olúwa láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní Gilgali.”
De vett a nép a zsákmányból apró jószágot és marhát, az örökszentség javát, hogy áldozzanak az Örökkévalónak, a te Istenednek Gilgálban.
22 Ṣùgbọ́n Samuẹli dáhùn pé, “Olúwa ha ní inú dídùn sí ẹbọ sísun àti ẹbọ ju kí a gba ohùn Olúwa gbọ́? Ìgbọ́ràn sàn ju ẹbọ lọ, ìfetísílẹ̀ sì sàn ju ọ̀rá àgbò lọ.
És mondta Sámuel: Vajon olyan kedve van-e az Örökkévalónak égő- és vágóáldozatokban, mint abban, hogy hallgatunk az Örökkévaló szavára? Íme engedelmesség jobb az áldozatnál, figyelem a kosok zsiradékánál.
23 Nítorí pé ìṣọ̀tẹ̀ dàbí ẹ̀ṣẹ̀ àfọ̀ṣẹ, àti ìgbéraga bí ẹ̀ṣẹ̀ ìbọ̀rìṣà. Nítorí tí ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa, Òun sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba.”
Mert kuruzslás vétke az engedetlenség, bálvány és teráfim az ellenszegülés! Minthogy megvetetted az Örökkévaló igéjét, megvetett ő téged, hogy ne legyél király.
24 Nígbà náà ni Saulu wí fún Samuẹli pé, “Èmi ti ṣẹ̀. Mo ti rú òfin Olúwa àti ọ̀rọ̀ rẹ̀. Èmi sì bẹ̀rù àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ ni èmi sì gba ohùn wọn gbọ́.
Szólt Sául Sámuelhez: Vétkeztem, mert megszegtem az Örökkévaló parancsát meg a te szavaidat; mert féltem a néptől és hallgattam szavukra.
25 Mo bẹ̀ ọ́ nísinsin yìí, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì, kí ó sì yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè sin Olúwa.”
Most hát bocsásd csak meg vétkemet, térj vissza velem, és majd leborulok az Örökkévaló előtt.
26 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí fún un pé, “Èmi kò ní bá ọ padà. Ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa sílẹ̀, Olúwa sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba lórí Israẹli!”
És szólt Sámuel Sáulhoz: Nem térek vissza veled; mert megvetetted az Örökkévaló igéjét, megvetett téged az Örökkévaló, hogy ne legyél király Izrael fölött.
27 Bí Samuẹli sì ti fẹ́ yípadà láti lọ, Saulu sì di ẹ̀wù ìlekè rẹ̀ mú, ó sì fàya;
Mikor fordult Sámuel, hogy elmenjen, megragadta köntösének szárnyát, és elszakadt.
28 Samuẹli sì wí fún un pé, “Olúwa ti fa ìjọba Israẹli ya kúrò lọ́wọ́ ọ̀ rẹ lónìí, ó sì ti fi fún aládùúgbò rẹ kan tí ó sàn jù ọ́ lọ.
Ekkor szólt hozzá Sámuel: Elszakította tőled az Örökkévaló Izrael királyságát e napon, és adja majd társadnak, ki jobb nálad.
29 Ẹni tí ó ń ṣe ògo Israẹli, kì í purọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì í yí ọkàn rẹ̀ padà; nítorí kì í ṣe ènìyàn tí yóò yí ọkàn rẹ̀ padà.”
S bizony, Izrael Erőse nem hazudik s nem bánja meg; mert nem ember ő, hogy megbánná.
30 Saulu sì wí pé, “Èmi ti ṣẹ̀, ṣùgbọ́n jọ̀wọ́ bu ọlá fún mi níwájú àwọn àgbàgbà ènìyàn mi, àti níwájú u Israẹli, yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè tẹríba fún Olúwa Ọlọ́run rẹ.”
Mondta: Vétkeztem; most tisztelj meg, kérlek, népem vénei előtt és Izrael előtt s térj vissza velem, hogy leboruljak az Örökkévaló, a te Istened előtt.
31 Bẹ́ẹ̀ ni Samuẹli sì yípadà pẹ̀lú Saulu, Saulu sì sin Olúwa.
S visszatért Sámuel Sául után és leborult Sául az Örökkévaló előtt.
32 Nígbà náà ni Samuẹli wí pé, “Mú Agagi ọba àwọn ará Amaleki wá fún mi.” Agagi sì tọ̀ ọ́ wá ní ìgboyà pẹ̀lú èrò pé, “Nítòótọ́ ìkorò ikú ti kọjá.”
Ekkor mondta Sámuel: Hozzátok ide hozzám Agágot, Amálék királyát. És ment Agág hozzá vidáman; és mondta Agág: Valóban, távozott a halál keserűsége!
33 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Bí idà rẹ ti sọ àwọn obìnrin di aláìní ọmọ bẹ́ẹ̀ ni ìyá rẹ yóò sì di aláìní ọmọ láàrín obìnrin.” Samuẹli sì pa Agagi níwájú Olúwa ni Gilgali.
És mondta Sámuel: Amint megfosztott gyermekektől asszonyokat a te kardod, úgy legyen az asszonyok közül gyermekektől megfosztva az anyád. Erre szétvágta Sámuel Agágot az Örökkévaló színe előtt Gilgálban.
34 Nígbà náà ni Samuẹli lọ sí Rama, Saulu sì gòkè lọ sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah tí Saulu.
És elment Sámuel Rámába; Sáíul pedig fölment házába. Gibeát-Sáulba.
35 Samuẹli kò sì padà wá mọ́ láti wo Saulu títí ó fi di ọjọ́ ikú u rẹ̀, ṣùgbọ́n Samuẹli káàánú fún Saulu. Ó sì dun Olúwa pé ó fi Saulu jẹ ọba lórí Israẹli.
És többé nem látta Sámuel Sáult halála napjáig, mert gyászolt Sámuel Sául miatt; az Örökkévaló pedig megbánta, hogy királlyá tette Sáult Izrael fölött.

< 1 Samuel 15 >