< 1 Samuel 15 >

1 Samuẹli wí fún Saulu pé, “Èmi ni Olúwa rán láti fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí àwọn ènìyàn rẹ̀ Israẹli; fetísílẹ̀ láti gbọ́ iṣẹ́ tí Olúwa rán mi sí ọ́.
And Samuel seide to Saul, The Lord sente me, that Y schulde anoynte thee in to `kyng on his puple Israel; now therfor here thou the vois `of the Lord.
2 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, ‘Èmi yóò jẹ àwọn Amaleki ní yà fún ohun tí wọ́n ti ṣe sí Israẹli nígbà tí wọn dè wọn lọ́nà nígbà tí wọn ń bọ̀ láti Ejibiti.
The Lord of oostis seith thes thingis, Y haue rikenyd what euer thingis Amalech dide to Israel; hou Amalech ayenstood Israel in the weie, whanne he stiede from Egipt.
3 Lọ nísinsin yìí, kí o sì kọlu Amaleki, kí o sì pa gbogbo ohun tí ó bá jẹ́ tiwọn ní à parun. Má ṣe dá wọn sí, pa ọkùnrin àti obìnrin wọn, ọmọ kékeré àti ọmọ ọmú, màlúù àti àgùntàn, ìbákasẹ àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn.’”
Now therfor go thou, and sle Amalech, and distruye thou alle `thingis of hym; spare thou not hym, and coueyte thou not ony thing of hise thingis; but sle thou fro man `til to womman, and a litil child, and soukynge, an oxe, and scheep, and camel, and asse.
4 Bẹ́ẹ̀ ni Saulu kó àwọn ènìyàn jọ, ó sì ka iye wọn ní Talaemu, wọ́n sì jẹ́ ogún ọ̀kẹ́ àwọn ológun ẹlẹ́ṣẹ̀, pẹ̀lú ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá àwọn ọkùnrin Juda.
Therfor Saul comaundide to the puple, and he noumbride hem as lambren twei hundrid thousynde of foot men, and ten thousynde of men of Juda.
5 Saulu sì lọ sí ìlú Amaleki ó sì gọ dè wọ́n ní àfonífojì kan.
And whanne Saul cam to the citee of Amalech, he made redi buyschementis in the stronde.
6 Nígbà náà ni ó wí fún àwọn ará Keni pé, “Ẹ lọ, kúrò ní Amaleki kí èmi má ba à run yín pẹ̀lú wọn; nítorí ẹ̀yin fi àánú hàn fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli nígbà tí wọ́n gòkè ti Ejibiti wá.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Kenaiti lọ kúrò láàrín àwọn Amaleki.
And Saul seide to Cyney, Go ye, departe ye, and go ye awei fro Amalech, lest perauenture Y wlappe thee in with hem; for thou didist mercy with alle the sones of Israel, whanne thei stieden fro Egipt. And Cyney departide fro the myddis of Amalech.
7 Nígbà náà ni Saulu kọlu àwọn Amaleki láti Hafila dé Ṣuri, tí ó fi dé ìlà-oòrùn Ejibiti.
And Saul smoot Amalech fro Euila, til thou come to Sur, which is ayens Egipt.
8 Ó sì mú Agagi ọba Amaleki láààyè, ó sì fi idà rẹ̀ kọlù gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀.
And he took Agag quyke, the kyng of Amalech; sotheli he killide bi the scharpnesse of swerd alle the comyn puple.
9 Ṣùgbọ́n Saulu àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ dá Agagi sí àti èyí tí ó dára jùlọ nínú àgùntàn àti màlúù àti ọ̀dọ́-àgùntàn àbọ́pa àti gbogbo nǹkan tó dára. Wọ́n kò sì fẹ́ pa àwọn wọ̀nyí run pátápátá ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan tí kò dára tí kò sì níláárí ni wọ́n parun pátápátá.
And Saul and the puple sparide Agag, and the beste flockis of scheep, and of grete beestis, and clothis, and rammes, and alle thingis that weren faire; and thei nolden destrie tho; sotheli what euer thing was vijl, and repreuable, thei distrieden this.
10 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Samuẹli wá pé,
Forsothe the word of the Lord was maad to Samuel,
11 “Èmi káàánú gidigidi pé mo fi Saulu jẹ ọba, nítorí pé ó ti yípadà kúrò lẹ́yìn mi, kò sì pa ọ̀rọ̀ mi mọ́.” Inú Samuẹli sì bàjẹ́ gidigidi, ó sì ké pe Olúwa ní gbogbo òru náà.
and seide, It repentith me, that Y made Saul kyng; for he forsook me, and fillide not my wordis in werk. And Samuel was sory, and he criede to the Lord in al the nyyt.
12 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Samuẹli sì dìde láti lọ pàdé Saulu, ṣùgbọ́n wọ́n sọ fún un pé, “Saulu ti wá sí Karmeli. Ó ti kọ́ ibìkan fún ara rẹ̀ níbẹ̀, ó sì ti yípadà, ó sì ti sọ̀kalẹ̀ lọ sí Gilgali.”
And whanne Samuel hadde rise bi nyyt to go eerly to Saul, it was teld to Samuel, that Saul hadde come in to Carmel, and hadde reisid to hym a signe of victorye; and that he hadde turned ayen, and hadde passid, and hadde go doun in to Galgala. Therfor Samuel cam to Saul, and Saul offride brent sacrifice to the Lord of the cheef thingis of preies, whiche he hadde brouyt fro Amalech.
13 Nígbà tí Samuẹli sì dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, Saulu sì wí fún un pé, “Olúwa bùkún fún ọ, mo ti ṣe ohun tí Olúwa pàṣẹ.”
And the while Samuel cam to Saul, Saul seide to hym, Blessid be thou of the Lord, Y haue fillid the `word of the Lord.
14 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Èwo wá ni igbe àgùntàn tí mo ń gbọ́ ní etí mi? Kí ni igbe màlúù ti mo ń gbọ́ yìí?”
And Samuel seide, And what is the vois of flockis, that sowneth in myn eeris, and of grete beestis, whiche Y here?
15 Saulu sì dáhùn pé, “Àwọn ọmọ-ogun ní o mú wọn láti Amaleki wá, wọ́n dá àwọn àgùntàn, àti màlúù tí ó dára jùlọ sí láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ, ṣùgbọ́n a pa àwọn tókù run pátápátá.”
And Saul seide, Thei brouyten tho fro Amalech, for the puple sparide the betere scheep and grete beestis, that tho schulden be offrid to thi Lord God; sotheli we killiden the tothere beestis.
16 Samuẹli sí wí fún Saulu pé, “Dákẹ́ ná, jẹ́ kí èmi kí ó sọ ohun tí Olúwa wí fún mi ní alẹ́ àná fún ọ.” Saulu sì wí pé, “Sọ fún mi.”
Forsothe Samuel seide to Saul, Suffre thou me, and Y schal schewe to thee what thingis the Lord spak to me in the nyyt. And he seide to Samuel, Speke thou.
17 Samuẹli sì wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìwọ fi ìgbà kan kéré lójú ara rẹ, ǹjẹ́ ìwọ kò ha di olórí ẹ̀yà Israẹli? Olúwa fi àmì òróró yàn ọ́ ní ọba lórí Israẹli.
And Samuel seide, Whether not, whanne thou were litil in thin iyen, thou were maade heed in the lynages of Israel, and the Lord anoyntide thee in to kyng on Israel;
18 Olúwa sì rán ọ níṣẹ́ wí pé, ‘Lọ, kí o sì pa àwọn ènìyàn búburú ará Amaleki run pátápátá; gbóguntì wọ́n títí ìwọ yóò fi run wọ́n.’
and the Lord sente thee in to the weie, and seide, Go thou, and sle the synneris of Amalech, and thou schalt fiyte ayens hem `til to sleyng of hem.
19 Èéṣe tí ìwọ kò fi gbọ́ ti Olúwa? Èéṣe tí ìwọ fi sáré sí ìkógun tí o sì ṣe búburú níwájú Olúwa?”
Whi therfor herdist thou not the vois of the Lord, but thou were turned to prey, and didist yuel in the `iyen of the Lord?
20 Saulu sì wí fún Samuẹli pé, “Ṣùgbọ́n èmi ti ṣe ìgbọ́ràn sí Olúwa, èmi sì ti lọ ní ọ̀nà tí Olúwa rán mi. Mo sì ti pa àwọn ará Amaleki run pátápátá, mo sì ti mú Agagi ọba wọn padà wá.
And Saul seide to Samuel, Yhis, Y herde the `vois of the Lord, and Y yede in the weie, bi which the Lord sente me, and Y haue brouyt Agag, the kyng of Amalech, and Y killide Amalech.
21 Àwọn ọmọ-ogun ti mú àgùntàn àti màlúù lára ìkógun èyí tí ó dára láti fi fún Olúwa láti fi rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run rẹ ní Gilgali.”
Forsothe the puple took of the prey, scheep and oxun, the firste fruytis of tho thingis, that ben slayn, that thei make sacrifice to her Lord God in Galgalis.
22 Ṣùgbọ́n Samuẹli dáhùn pé, “Olúwa ha ní inú dídùn sí ẹbọ sísun àti ẹbọ ju kí a gba ohùn Olúwa gbọ́? Ìgbọ́ràn sàn ju ẹbọ lọ, ìfetísílẹ̀ sì sàn ju ọ̀rá àgbò lọ.
And Samuel seide, Whether the Lord wole brent sacrifices, ethir slayn sacrifices, and not more that me obeie to the vois of the Lord? For obedience is betere than sacrifices, and to `herkene Goddis word is more than to offre the ynnere fatnesse of rammes;
23 Nítorí pé ìṣọ̀tẹ̀ dàbí ẹ̀ṣẹ̀ àfọ̀ṣẹ, àti ìgbéraga bí ẹ̀ṣẹ̀ ìbọ̀rìṣà. Nítorí tí ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa, Òun sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba.”
for it is as the synne of mawmetrie to `fiyte ayens Goddis heest, and it is as the wickidnesse of ydolatrie to nyle `ascente to Goddis heest. Therfor for that, that thou castidist awey the word of the Lord, the Lord castide thee awei, that thou be not kyng.
24 Nígbà náà ni Saulu wí fún Samuẹli pé, “Èmi ti ṣẹ̀. Mo ti rú òfin Olúwa àti ọ̀rọ̀ rẹ̀. Èmi sì bẹ̀rù àwọn ènìyàn bẹ́ẹ̀ ni èmi sì gba ohùn wọn gbọ́.
And Saul seide to Samuel, Y synnede, for Y brak the word of the Lord, and thi wordis; `and Y dredde the puple, `and obeiede to `the vois of hem; but now,
25 Mo bẹ̀ ọ́ nísinsin yìí, dárí ẹ̀ṣẹ̀ mi jì, kí ó sì yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè sin Olúwa.”
Y biseche, bere thou my synne, and turne thou ayen with me, that Y worschipe the Lord.
26 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí fún un pé, “Èmi kò ní bá ọ padà. Ìwọ ti kọ ọ̀rọ̀ Olúwa sílẹ̀, Olúwa sì ti kọ̀ ọ́ ní ọba lórí Israẹli!”
And Samuel seide to Saul, Y schal not turne ayen with thee, for thou castidist awey the word of the Lord, and the Lord castide awei thee, that thou be not king on Israel.
27 Bí Samuẹli sì ti fẹ́ yípadà láti lọ, Saulu sì di ẹ̀wù ìlekè rẹ̀ mú, ó sì fàya;
And Samuel turnede to go a wey; sotheli Saul took the ende of the mentil of Samuel, which also was to-rent.
28 Samuẹli sì wí fún un pé, “Olúwa ti fa ìjọba Israẹli ya kúrò lọ́wọ́ ọ̀ rẹ lónìí, ó sì ti fi fún aládùúgbò rẹ kan tí ó sàn jù ọ́ lọ.
And Samuel seide to hym, The Lord hath kit the rewme of Israel fro thee to dai, and yaf it to thi neiybore betere than thou;
29 Ẹni tí ó ń ṣe ògo Israẹli, kì í purọ́, bẹ́ẹ̀ ni kì í yí ọkàn rẹ̀ padà; nítorí kì í ṣe ènìyàn tí yóò yí ọkàn rẹ̀ padà.”
certis the ouercomere in Israel schal not spare, and he schal not be bowid bi repentaunce; for he is not man, `that is, chaungeable, that he do repentaunce.
30 Saulu sì wí pé, “Èmi ti ṣẹ̀, ṣùgbọ́n jọ̀wọ́ bu ọlá fún mi níwájú àwọn àgbàgbà ènìyàn mi, àti níwájú u Israẹli, yípadà pẹ̀lú mi, kí èmi kí ó lè tẹríba fún Olúwa Ọlọ́run rẹ.”
And Saul seide, Y synnede; but now onoure thou me bifor the eldere men of my puple, and bifor Israel, and turne thou ayen with me, that Y worschipe thi Lord God.
31 Bẹ́ẹ̀ ni Samuẹli sì yípadà pẹ̀lú Saulu, Saulu sì sin Olúwa.
Therfor Samuel turnede ayen, and suede Saul, and Saul worschipide the Lord.
32 Nígbà náà ni Samuẹli wí pé, “Mú Agagi ọba àwọn ará Amaleki wá fún mi.” Agagi sì tọ̀ ọ́ wá ní ìgboyà pẹ̀lú èrò pé, “Nítòótọ́ ìkorò ikú ti kọjá.”
And Samuel seide, Brynge ye to me Agag, the kyng of Amalech. And Agag `moost fat tremblynge was brouyt to hym. And Agag seide, Whether thus departith bitter deeth?
33 Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Bí idà rẹ ti sọ àwọn obìnrin di aláìní ọmọ bẹ́ẹ̀ ni ìyá rẹ yóò sì di aláìní ọmọ láàrín obìnrin.” Samuẹli sì pa Agagi níwájú Olúwa ni Gilgali.
And Samuel seide, As thi swerd made wymmen with out fre children, so thi modir schal be with out fre children among wymmen. And Samuel kittide hym in to gobetis bifor the Lord in Galgalis.
34 Nígbà náà ni Samuẹli lọ sí Rama, Saulu sì gòkè lọ sí ilé e rẹ̀ ní Gibeah tí Saulu.
Forsothe Samuel yede in to Ramatha; sotheli Saul stiede in to his hows in Gabaa.
35 Samuẹli kò sì padà wá mọ́ láti wo Saulu títí ó fi di ọjọ́ ikú u rẹ̀, ṣùgbọ́n Samuẹli káàánú fún Saulu. Ó sì dun Olúwa pé ó fi Saulu jẹ ọba lórí Israẹli.
And Samuel siy no more Saul `til to the dai of his deeth; netheles Samuel biweilide Saul, for it repentide the Lord, that he hadde ordeyned Saul kyng on Israel.

< 1 Samuel 15 >