< 1 Samuel 14 >

1 Ní ọjọ́ kan, Jonatani ọmọ Saulu wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a rékọjá lọ sí ìlú olódi àwọn Filistini tí ó wà ní ìhà kejì.” Ṣùgbọ́n kò sọ fún baba rẹ̀.
И бысть во един день, и рече Ионафан сын Саулов отрочищу носящему оружие его: гряди, и прейдем в мессаву иноплеменников иже на оней стране. И отцу своему не возвести сего.
2 Saulu sì dúró ní ìhà etí ìpínlẹ̀ Gibeah lábẹ́ igi pomegiranate èyí tí ó wà ní Migroni. Àwọn ẹgbẹ̀ta ọkùnrin sì wà pẹ̀lú rẹ̀,
И Саул седяше на верху холма под древом яблонным еже в Магдоне, и бяше с ним яко шесть сот мужей.
3 lára wọn ni Ahijah, tí ó wọ efodu. Òun ni ọmọ arákùnrin Ikabodu Ahitubu, ọmọ Finehasi, ọmọ Eli, àlùfáà Olúwa ní Ṣilo kò sí ẹni tí ó mọ̀ pé Jonatani ti lọ.
И Ахиа сын Ахитов, брата Иохаведова, сына Финеесова, сына Илии, иерей Божий в Силоме нося ефуд: и людие не ведяху, яко отиде Ионафан.
4 Ní ọ̀nà tí Jonatani ti ń fẹ́ láti kọjá dé ìlú olódi àwọn Filistini, ní bèbè òkúta mímú kan wá, orúkọ èkínní sì ń jẹ́ Bosesi, orúkọ èkejì sì ń jẹ́ Sene.
Посреде же прехода, идеже хотяше Ионафан прейти в стан иноплеменничь, бысть камень острый отсюду и камень острый отюнуду: имя единому Васес и другому Сенна:
5 Bèbè òkúta kan dúró sí àríwá ní ìhà Mikmasi, èkejì sì wà ní gúúsù ní ìhà Gibeah.
камень един стояше от севера противу Махмаса, и камень вторый от юга противу Гаваи.
6 Jonatani sì wí fún ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó ń ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ sí ìlú olódi àwọn aláìkọlà yìí. Bóyá Olúwa yóò jà fún wa, kò sí ohun tó lè di Olúwa lọ́wọ́ láti gbàlà, yálà nípasẹ̀ púpọ̀ tàbí nípasẹ̀ díẹ̀.”
И рече Ионафан ко отрочищу носящему оружие его: гряди, прейдем в мессаву необрезанных сих, негли что сотворит нам Господь, яко несть Господу не удобно спасти во многих или в малых.
7 Ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì wí pé, “Ṣe gbogbo ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ, tẹ̀síwájú, Èmi wà pẹ̀lú ọkàn àti ẹ̀mí rẹ.”
И рече ему носяй оружие его: твори все, на неже сердце твое склоняется: се, аз с тобою есмь, якоже сердце твое сердце мое.
8 Jonatani sì wí pé, “Wá nígbà náà, àwa yóò rékọjá sí ọ̀dọ̀ ọkùnrin wọ̀nyí, kí a sì jẹ́ kí wọ́n rí wa.
И рече Ионафан: се, мы прейдем к мужем и явимся к ним:
9 Bí wọ́n bá sọ fún wa pé, ‘Ẹ dúró títí àwa yóò fi tọ̀ yín wá,’ àwa yóò dúró sí ibi tí a wà, àwa kì yóò sì gòkè tọ̀ wọ́n lọ.
аще сия рекут к нам: помедлите тамо, дондеже возвестим вам: то постоим сами на месте своем и не пойдем к ним:
10 Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá wí pé, ‘Ẹ gòkè tọ̀ wá wá,’ àwa yóò gòkè lọ, nítorí èyí ni yóò jẹ́ àmì fún wa pé Olúwa ti fi wọ́n lé wa lọ́wọ́.”
аще же к нам сице рекут: взыдите к нам: то взыдем, яко предаде их Господь в руки нашя: сие нам знамение (да будет).
11 Báyìí ní àwọn méjèèjì sì fi ara wọn hàn fún ìlú olódi Filistini. Àwọn Filistini sì wí pé, “Wò ó! Àwọn Heberu ń yọ jáde wá láti inú ihò tí wọ́n fi ara wọn pamọ́ sí.”
И внидоста оба в мессаву иноплеменников. И глаголаша иноплеменницы: се, Еврее исходят из разселин своих, идеже скрышася.
12 Àwọn ọkùnrin ìlú olódi náà sì kígbe sí Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Ẹ gòkè tọ̀ wá wá àwa yóò sì kọ́ ọ yín ní ẹ̀kọ́.” Jonatani sì wí fún ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ pé, “Gòkè tọ̀ mí lẹ́yìn; Olúwa ti fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́.”
И отвещаша мужие мессавли ко Ионафану и к носящему оружие его, и реша: взыдите к нам, и явим вам глагол. И рече Ионафан к носящему оружие его: гряди по мне, яко предаде их Господь в руки Израилевы.
13 Jonatani lo ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀ láti fà gòkè pẹ̀lú ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ ní ọwọ́ ọ̀tún ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀. Àwọn Filistini sì ṣubú níwájú Jonatani ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì tẹ̀lé e, ó sì ń pa lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀.
И взыде Ионафан (ползущь) на руках и на ногах своих, и носяй оружие его за ним. И узреша иноплеменницы лице Ионафане, и порази их: и носяй оружие его идяше вслед его.
14 Ní ìkọlù èkínní yìí, Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ sì pa ogún ọkùnrin ní agbègbè tó tó ìwọ̀n ààbọ̀ sáré ilẹ̀.
И бысть язва первая, еюже порази Ионафан и носяй оружие его, яко двадесять мужей копийцами и каменовержением и кремением полевым.
15 Nígbà náà ni ìbẹ̀rùbojo bá àwọn ọmọ-ogun; àwọn tí ó wà ní ibùdó àti ní pápá, àti àwọn tí ó wà ní ilé ìlú olódi àti àwọn tí ń kó ìkógun, ilẹ̀ sì mì. Ó jẹ́ ìbẹ̀rù tí ó ti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.
И бысть ужас в полце и на селе: и вси людие иже в мессаве и губящии ужаснушася, и тии не хотяху братися: и вострепета земля, и бысть ужас от Господа.
16 Àwọn tí ó ń ṣọ́nà fún Saulu ní Gibeah ti Benjamini sì rí àwọn ọmọ-ogun ń túká ní gbogbo ọ̀nà.
И видеша соглядатае Сауловы в Гаваи Вениамини, и се, полк смятеся семо и онамо.
17 Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ènìyàn tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pé, “Ẹ ka àwọn ènìyàn kí ẹ sì mọ ẹni tí ó jáde kúrò nínú wa.” Nígbà tí wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀, sì wò ó, Jonatani àti ẹni tí ó ru ìhámọ́ra rẹ̀ ni kò sì sí níbẹ̀.
И рече Саул людем сущым с ним: разсмотрите ныне и видите, кто отиде от вас. И разсмотриша, и се, не обретеся Ионафан и носяй оружие его.
18 Saulu sì wí fún Ahijah pé, “Gbé àpótí Ọlọ́run wá.” Àpótí Ọlọ́run wà pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli ní ìgbà náà.
И рече Саул ко Ахии: принеси ефуд, яко бе кивот Божий в той день с сынми Израилевыми.
19 Nígbà tí Saulu sì ń bá àlùfáà sọ̀rọ̀, ariwo ní ibùdó àwọn Filistini sì ń pọ̀ síwájú sí. Saulu sì wí fún àlùfáà pé, “Dá ọwọ́ rẹ dúró.”
И бысть егда глаголаше Саул ко иерею, и шум в полце иноплеменничи ходя идяше и множашеся. И рече Саул ко иерею: пригни руки твоя.
20 Saulu àti gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ sì péjọ, wọ́n sì lọ sí ojú ìjà. Wọ́n sì bá gbogbo àwọn Filistini ní ìdàrúdàpọ̀ ńlá, idà olúkúlùkù sì wà lára ọmọ ẹnìkejì rẹ̀.
И изыде Саул и вси людие иже с ним, и изыдоша до сечи. И се, бысть оружие коегождо на ближняго своего, (и бысть) мятеж велик зело.
21 Àwọn Heberu tí ó ti wà lọ́dọ̀ àwọn Filistini tẹ́lẹ̀, tí wọ́n sì ti gòkè tẹ̀lé wọn lọ sí àgọ́ wọn wá sọ́dọ̀ àwọn ọmọ Israẹli tí wọ́n ti wà pẹ̀lú Saulu àti Jonatani.
Но и раби, иже быша со иноплеменники вчера и третияго дне, вшедшии в полк, обратишася и тии еже быти им со Израилтяны сущими с Саулом и со Ионафаном.
22 Nígbà tí gbogbo àwọn Israẹli tí ó ti pa ara wọn mọ́ nínú òkè ńlá Efraimu gbọ́ pé àwọn Filistini sá, wọ́n darapọ̀ mọ́ ìjà náà ní ìlépa gbígbóná.
И вси Израилтяне скрывшиися в горе Ефремли услышаша, яко отбегоша иноплеменницы: приложишася и тии вслед их на брань.
23 Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì gba Israẹli ní ọjọ́ náà, ìjà náà sì rékọjá sí Beti-Afeni.
И спасе Господь в той день Израиля: брань же пройде даже до Вамофа: и вси людие бяху с Саулом, яко десять тысящ мужей, и бе брань разсыпана во весь град на горе Ефремли.
24 Gbogbo ọkùnrin Israẹli sì wà ní ìpọ́njú ńlá ní ọjọ́ náà, nítorí pé Saulu ti fi àwọn ènìyàn gégùn ún wí pé, “Ègbé ni fún ẹni tí ó jẹ oúnjẹ títí di alẹ́, títí èmi yóò fi gbẹ̀san mi lára àwọn ọ̀tá mi!” Bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnìkankan nínú ọ̀wọ́ ogun náà tí ó fi ẹnu kan oúnjẹ.
И Саул сотвори безумие велие в день той, и закля люди, глаголя: проклят человек, иже ясти будет хлеб даже до вечера, дондеже отмщу врагом моим. И не вкусиша людие вси хлеба:
25 Gbogbo àwọn ènìyàn sì wọ inú igbó, oyin sì wà lórí ilẹ̀ náà.
и вся земля обедаше: и се, бяше дубрава пчелная пред лицем села:
26 Nígbà tí wọ́n dé inú igbó náà, wọ́n sì rí oyin ń sun jáde, kò sí ẹni tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ kan ẹnu rẹ̀ síbẹ̀, nítorí pé wọ́n bẹ̀rù ìfiré.
и внидоша людие во пчелник, и се, исхождаху глаголюще: (яко истече мед, ) и не бе возвращающаго руки своея ко устом своим, яко убояшася людие клятвы Господни.
27 Ṣùgbọ́n Jonatani kò gbọ́ pé baba rẹ̀ ti fi ìfibú kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn náà, bẹ́ẹ̀ ni ó sì tẹ orí ọ̀pá tí ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀ bọ afárá oyin náà, ó sì fi sí ẹnu rẹ̀, ojú rẹ̀ sì dán.
Ионафан же не слышаше, егда заклинаше отец его люди: и простре конец жезла своего, иже в руку ему, и омочи его в соте медвене, и обрати руку свою во уста своя, и прозреша очи его.
28 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ogun sọ fún un pé, “Baba rẹ fi ìfibú kìlọ̀ fún àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Ègbé ni fún ẹni tí ó jẹ oúnjẹ ní òní!’ Ìdí nìyìí tí àárẹ̀ fi mú àwọn ènìyàn.”
И рече един от людий, глаголя: кленый прокля отец твой люди, глаголя: проклят человек, иже ясти будет хлеб в день сей: и изнемогоша людие.
29 Jonatani sì wí pé, “Baba mi ti mú ìdààmú bá ìlú, wò ó bí ojú mi ti dán nígbà tí mo fi ẹnu kan oyin yìí.
И уразуме Ионафан и рече: смути отец мой землю: виждь, яко прозреша очи мои, егда вкусих мало от меда сего:
30 Báwo ni kò bá ti dára tó bí àwọn ènìyàn bá ti jẹ nínú ìkógun àwọn ọ̀tá wọn lónìí, pípa àwọn Filistini ìbá ti pọ̀ tó?”
о, дабы яли ядуще днесь людие от корыстей врагов своих, ихже обретоша, множайшая бы днесь язва была во иноплеменницех.
31 Ní ọjọ́ náà, lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ọmọ Israẹli ti pa nínú àwọn Filistini láti Mikmasi dé Aijaloni, ó sì rẹ àwọn ènìyàn náà.
И поразиша в день той от иноплеменников множае нежели в Махмасе: и утрудишася людие зело.
32 Wọ́n sáré sí ìkógun náà, wọ́n sì mú àgùntàn. Màlúù àti ọmọ màlúù, wọ́n pa wọ́n sórí ilẹ̀, wọ́n sì jẹ wọ́n papọ̀ tẹ̀jẹ́tẹ̀jẹ̀.
И устремишася людие на корысти, и пояша людие стада и буйволы и говяда: и закалаху на земли, и ядоша людие с кровию.
33 Nígbà náà ni ẹnìkan sì wí fún Saulu pé, “Wò ó, àwọn ènìyàn tí ń dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa nípa jíjẹ ẹran tí ó ní ẹ̀jẹ̀ lára.” Ó sì wí pé, “Ẹ̀ṣẹ̀ yín ti pọ̀jù, yí òkúta ńlá sí ibi nísinsin yìí.”
И возвестиша Саулу, глаголюще: согрешиша людие ко Господу, ядуще с кровию. И рече Саул: от гефема привалите мне семо камень велий.
34 Nígbà náà ni ó wí pé, “Ẹ jáde lọ sáàrín àwọn ènìyàn náà kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Kí olúkúlùkù wọn mú màlúù àti àgùntàn tirẹ̀ tọ̀ mí wá, kí wọ́n sì pa wọ́n níhìn-ín, kí wọ́n sì jẹ́. Ẹ má ṣe ṣẹ̀ sí Olúwa, kí ẹ má ṣe jẹ ẹran tòun-tẹ̀jẹ̀.’” Bẹ́ẹ̀ ní olúkúlùkù mú màlúù tirẹ̀ wá ní alẹ́ ọjọ́ náà, wọ́n sì pa wọ́n níbẹ̀.
И рече Саул: шедше к людем рцыте им: да принесет кийждо семо телца своего и кийждо овцу свою, и да заколют на камени сем, и ядите я, и не согрешайте Господу ядуще с кровию. И приведоша нощию вси людие свое кийждо, еже имяше в руце своей, и закалаху тамо.
35 Nígbà náà Saulu kọ́ pẹpẹ kan fún Olúwa; èyí sì jẹ́ ìgbà àkọ́kọ́ tí ó kọ́kọ́ ṣe èyí.
И созда Саул тамо олтарь Господу: сей нача Саул созидати олтарь Господу.
36 Saulu sì wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ tọ Filistini lọ ní òru, kí a bá wọn jà títí di ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, kí a má ṣì ṣe dá ẹnìkankan sí nínú wọn.” Wọ́n sì wí pé, “Ṣe ohun tí ó bá dára ní ojú rẹ̀.” Ṣùgbọ́n àlùfáà wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a ṣe ìwádìí lọ́wọ́ Ọlọ́run níhìn-ín.”
И рече Саул: снидем вслед иноплеменник нощию, и расхитим их, дондеже заря будет, и не оставим от них мужа. И реша: все еже благо пред очима твоима, твори. И рече иерей: приступим семо к Богу.
37 Nígbà náà ni Saulu béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run pé, “Ṣé kí n sọ̀kalẹ̀ tọ àwọn Filistini lọ bí? Ǹjẹ́ ìwọ yóò fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́ bí?” Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò dá a lóhùn ní ọjọ́ náà.
И вопроси Саул Бога: сниду ли вслед иноплеменников? Предаси ли их в руки Израилтяном? И не отвеща ему Господь в день той.
38 Saulu sì wí pé, “Ẹ wá síyìn-ín ín, gbogbo ẹ̀yin tí ẹ jẹ́ olórí ogun, kí a ṣe ìwádìí irú ẹ̀ṣẹ̀ tí ẹ ti ṣẹ̀ lónìí.
И рече Саул: приведите семо вся колена Израилева, и уразумейте и увеждьте, на ком бысть грех сей днесь,
39 Bí Olúwa tí ó gba Israẹli là ti wà, bí ó bá ṣe pé a rí í lára Jonatani ọmọ mi, ó ní láti kú.” Ṣùgbọ́n ẹnìkankan nínú wọn kò sọ ọ̀rọ̀ kan.
яко жив Господь спасый Израиля, яко аще ответ будет на Ионафана сына моего, смертию да умрет. И не бе отвещающаго от всех людий.
40 Nígbà náà ni Saulu wí fún gbogbo àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ lọ sí apá kan; èmi àti Jonatani ọmọ mi yóò lọ sí apá kan.” Gbogbo àwọn ènìyàn sì dáhùn pé, “Ṣe èyí tí ó tọ́ ní ojú rẹ.”
И рече Саул всему Израилю: вы станите на едину страну, аз же и Ионафан сын мой станем на другую страну. И реша людие к Саулу: еже благо пред тобою, твори.
41 Nígbà náà ni Saulu gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli pé, “Fún mi ní ìdáhùn tí ó tọ́.” A sì mú Jonatani àti Saulu nípa ìbò dídì, àwọn ènìyàn náà sì yege.
И рече Саул: Господи Боже Израилев, что яко не отвещал еси рабу Твоему днесь? Или моя есть, или сына моего Ионафана неправда? Господи Боже Израилев, даждь знамение: и аще речеши сия, даждь ныне людем Твоим Израилю, даждь ныне преподобие. И паде жребий на Ионафана и Саула, и людие изыдоша.
42 Saulu sì wí pé, “Ẹ dìbò láàrín èmi àti Jonatani ọmọ mi.” Ìbò náà sì mú Jonatani.
И рече Саул: верзите жребий на мя и на Ионафана сына моего: егоже объявит Господь, смертию да умрет. И реша людие к Саулу: несть сей глагол. И преможе Саул люди, и вергоша о нем и Ионафане сыне его, и паде на Ионафана жребий.
43 Saulu sì wí fún Jonatani pé, “Sọ nǹkan tí ìwọ ṣe fún mi.” Jonatani sì sọ fún un pé, “Mo kàn fi orí ọ̀pá mi tọ́ oyin díẹ̀ wò. Nísinsin yìí ṣé mo ní láti kú?”
И рече Саул ко Ионафану: возвести ми, что сотворил еси? И возвести ему Ионафан и рече: вкушая вкусих мало меду омочив конец жезла, иже в руку моею, и се, аз умираю.
44 Saulu sì wí pé, “Kí Ọlọ́run kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ àti jù bẹ́ẹ̀ lọ sí mi, nítorí pé ìwọ Jonatani yóò sá à kú dandan.”
И рече ему Саул: сия да сотворит ми Бог, и сия да приложит ми, яко смертию умреши днесь.
45 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wí fún Saulu pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí Jonatani kú, ẹni tí ó ti mú ìgbàlà ńlá yìí wá fún Israẹli? Kí a má rí í! Bí Olúwa ti wà, ọ̀kan nínú irun orí rẹ̀ kì yóò bọ́ sílẹ̀, nítorí tí ó ṣe èyí pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́.” Báyìí ni àwọn ènìyàn gba Jonatani sílẹ̀, kò sì kú.
И реша людие к Саулу: еда днесь умрет сотворивый спасение сие велие во Израили? Не буди то, жив Господь, аще падет влас главы его на землю, яко милость Божию сотвори в день сей. И помолишася людие о Ионафане в день той, и не умре.
46 Nígbà náà ni Saulu sì dẹ́kun lílépa àwọn Filistini, àwọn Filistini sì padà sí ìlú wọn.
И не иде Саул вслед иноплеменников: иноплеменницы же отидоша в место свое.
47 Lẹ́yìn ìgbà tí Saulu ti jẹ ọba lórí Israẹli, ó sì bá gbogbo ọ̀tá wọn jà yíká: Moabu àti àwọn ọmọ Ammoni; Edomu, àti àwọn ọba Soba, àti àwọn Filistini. Ibikíbi tí ó bá kọjú sí, ó máa ń fi ìyà jẹ wọ́n.
И Саул укрепися царствовати во Израили, и побеждаше окрест вся враги своя в Моаве и в сынех Аммоних и в сынех Едомлих и в Вефоре и в царствии Сувани и во иноплеменницех: и аможе аще обращашеся, спасашеся.
48 Ó sì jà tagbára tagbára, ó ṣẹ́gun àwọn Amaleki, ó sì ń gba Israẹli sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn tí ó ń kọlù wọ́n.
И сотвори силу, и победи Амалика, и избави Израиля из руки попирающих его.
49 Àwọn ọmọ Saulu sì ni Jonatani, Iṣifi àti Malikiṣua. Orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ àgbà sì ni Merabu àti orúkọ ọmọbìnrin rẹ̀ kékeré ni Mikali.
И беша сынове Сауловы Ионафан и Иисуй и Мелхисуе: имена же двою дщерию его, имя первородней Мерова и имя вторей Мелхола:
50 Orúkọ ìyàwó rẹ̀ ní Ahinoamu ọmọbìnrin Ahimasi. Orúkọ olórí ogun rẹ̀ ni Abneri ọmọ Neri arákùnrin baba Saulu.
имя же жене его Ахиноома, дщерь Ахимаасова: и имя старейшине вой его Авенир сын Нира сына ужика Саулова:
51 Kiṣi baba Saulu àti Neri baba Abneri wọ́n sì jẹ́ ọmọ Abieli.
Кис же отец Саулов, и Нир отец Авениров сын иамина сына Авиилева.
52 Ní gbogbo ọjọ́ Saulu, ogun náà sì gbóná sí àwọn Filistini, níbikíbi tí Saulu bá sì ti rí alágbára tàbí akíkanjú ọkùnrin, a sì mú u láti máa bá a ṣiṣẹ́.
И бе брань крепка на иноплеменники во вся дни Сауловы: и видев Саул всяка мужа сильна и всяка мужа сына силы, собираше их к себе.

< 1 Samuel 14 >